< 1 Chronicles 23 >

1 Nígbà tí Dafidi sì dàgbà, tí ó sì di arúgbó, ó sì fi Solomoni ọmọ rẹ̀ jẹ ọba lórí Israẹli.
Dawut qérip künliri toshay dep qalghanda, oghli Sulaymanni Israil üstige padishah qilip tiklidi.
2 Ó sì kó gbogbo àgbàgbà Israẹli jọ, àti gẹ́gẹ́ bí àwọn àlùfáà àti àwọn ará Lefi.
Dawut Israildiki emeldarlarni, kahinlarni we Lawiylarni yighdi.
3 Àwọn ọmọ Lefi láti ọgbọ̀n ọdún tàbí jù bẹ́ẹ̀ lọ ni wọ́n kà àpapọ̀ iye àwọn ọkùnrin wọn sì jẹ́ ẹgbàá mọ́kàndínlógún.
Lawiylardin ottuz yashtin ashqanlarning hemmisi sanaqtin ötküzüldi; tizimlan’ghini boyiche, ulardin erler jemiy ottuz sekkiz ming kishi idi.
4 Dafidi sì wí pe, ní ti èyí, ẹgbàá méjìlá ni kí wọn jẹ́ alábojútó iṣẹ́ ilé fún Olúwa àti ẹgbẹ̀rún mẹ́fà ni kí ó ṣe olórí àti onídàájọ́.
Dawut: «Bularning ichide yigirme töt ming kishi Perwerdigarning öyini bashqurush xizmitige, alte ming kishi emeldar we sotchiliqqa,
5 Ẹgbàajì ni kí ó jẹ́ olùtọ́jú ẹnu-ọ̀nà àti ẹgbàajì ni kí o sì jẹ́ ẹni ti yóò máa yin Olúwa pẹ̀lú ohun èlò orin, mo ti ṣe èyí fún ìdí pàtàkì yìí.
töt ming kishi derwaziwenlikke we yene töt ming kishi men yasighan sazlar bilen Perwerdigargha hemdusana oqush ishigha qoyulsun» — dédi.
6 Dafidi sì pín àwọn ọmọ Lefi sí ẹgbẹgbẹ́ láàrín àwọn ọmọ Lefi: Gerṣoni, Kohati àti Merari.
Dawut ularni Lawiyning oghli Gershon, Kohat we Merari jemetliri boyiche guruppilargha böldi: —
7 Àwọn tí ó jẹ́ ọmọ Gerṣoni: Laadani àti Ṣimei.
Gershoniylardin Ladan bilen Shimey bar idi;
8 Àwọn ọmọ Laadani Jehieli ẹni àkọ́kọ́, Setamu àti Joẹli, mẹ́ta ní gbogbo wọn.
Ladanning oghli: tunji oghli Yehiyel, yene Zitam bilen Yoéldin ibaret üch kishi idi;
9 Àwọn ọmọ Ṣimei: Ṣelomiti, Hasieli àti Harani mẹ́ta ní gbogbo wọn. Àwọn wọ̀nyí sì ni olórí àwọn ìdílé Laadani.
Shimeyning oghlidin Shélomit, Haziyel we Harandin ibaret üch kishi idi; yuqiriqilar Ladanning jemet bashliqliri idi.
10 Àti ọmọ Ṣimei: Jahati, Sina, Jeuṣi àti Beriah. Àwọn wọ̀nyí ni ọmọ Ṣimei mẹ́rin ni gbogbo wọn.
Shimeyning oghulliri Jahat, Zina, Yeush we Bériyah, bu töteylenning hemmisi Shimeyning oghli idi.
11 Jahati sì ni alákọ́kọ́ Sinah sì ni ẹlẹ́ẹ̀kejì, ṣùgbọ́n Jeuṣi àti Beriah kò ní àwọn ọmọ púpọ̀; bẹ́ẹ̀ ni wọ́n sì ka ara wọn sí ìdílé kan pẹ̀lú ìfilé lọ́wọ́ kan.
Jahat tunji oghul, Ziza ikkinchi oghul idi; Yeush bilen Bériyahning ewladliri köp bolmighachqa, bir [jemet guruppisi] dep hésablan’ghan.
12 Àwọn ọmọ Kohati: Amramu, Isari, Hebroni àti Usieli mẹ́rin ni gbogbo wọn.
Kohatning oghulliri Amram, Izhar, Hébron we Uzziyeldin ibaret töt kishi idi.
13 Àwọn ọmọ Amramu. Aaroni àti Mose. A sì ya Aaroni sọ́tọ̀ òun àti àwọn ọmọ rẹ̀ títí láéláé, láti kọjú sí ohun mímọ́ jùlọ, láti fi rú ẹbọ sísun níwájú Olúwa, láti máa ṣe òjíṣẹ́ níwájú rẹ̀ àti láti kéde ìbùkún ní orúkọ rẹ̀ títí láéláé.
Amramning oghli Harun bilen Musa idi. Harun bilen uning ewladliri eng muqeddes buyumlarni paklash, Perwerdigarning aldida menggüge [qurbanliqlarni] sunush, uning xizmitini qilish, menggü uning namidin bext tilep dua bérishke ayrilghanidi.
14 Àwọn ọmọ Mose ènìyàn Ọlọ́run ni wọ́n kà gẹ́gẹ́ bí apá kan ẹ̀yà Lefi.
Xudaning adimi Musagha kelsek, uning ewladliri Lawiy qebilisidin dep hésablinip pütülgen.
15 Àwọn ọmọ Mose: Gerṣomu àti Elieseri.
Musaning oghli Gershom bilen Eliézer idi.
16 Àwọn ọmọ Gerṣomu: Ṣubaeli sì ni alákọ́kọ́.
Gershomning oghulliridin Shebuyel chong oghli idi.
17 Àwọn ọmọ Elieseri: Rehabiah sì ni ẹni àkọ́kọ́. Elieseri kò sì tún ní ọmọ mìíràn, ṣùgbọ́n àwọn ọmọ Rehabiah wọ́n sì pọ̀ níye.
Eliézerning oghli Rehabiya idi; Eliézerning bashqa oghli bolmighan, lékin Rehabiyaning oghulliri nahayiti köp idi.
18 Àwọn ọmọ Isari: Ṣelomiti sì ni ẹni àkọ́kọ́.
Izharning tunji oghli Shélomit idi.
19 Àwọn ọmọ Hebroni: Jeriah sì ni ẹni àkọ́kọ́, Amariah sì ni ẹni ẹ̀ẹ̀kejì, Jahasieli sì ni ẹ̀ẹ̀kẹ́ta àti Jekameamu ẹ̀ẹ̀kẹrin.
Hébronning oghulliri: tunji oghli Yériya, ikkinchi oghli Amariya, üchinchi oghli Yahaziyel, tötinchi oghli Jekamiyam idi.
20 Àwọn ọmọ Usieli: Mika ni àkọ́kọ́ àti Iṣiah ẹ̀ẹ̀kejì.
Uzziyelning oghulliri: tunji oghli Mikah, ikkinchi oghli Yishiya idi.
21 Àwọn ọmọ Merari: Mahili àti Muṣi. Àwọn ọmọ Mahili: Eleasari àti Kiṣi.
Merarining oghli Mahli bilen Mushi idi; Mahlining oghli Eliazar bilen Kish idi.
22 Eleasari sì kú pẹ̀lú àìní àwọn ọmọkùnrin: Ó ní ọmọbìnrin nìkan. Àwọn ọmọ ẹ̀gbọ́n, àwọn ọmọ Kiṣi, sì fẹ́ wọn.
Eliazar ölgende oghli yoq, qizlirila bar idi; ularning tughqanliri, yeni Kishning oghulliri u qizlarni emrige aldi.
23 Àwọn ọmọ Muṣi: Mahili, Ederi àti Jerimoti mẹ́ta ni gbogbo wọn.
Mushining Mahli, Éder we Yeremot dégen üchla oghli bar idi.
24 Àwọn wọ̀nyí sì ni ọmọ Lefi bí ìdílé wọn. Olórí ìdílé gẹ́gẹ́ bí wọ́n ti fi orúkọ sílẹ̀ lábẹ́ orúkọ wọn, ó sì kà wọn ní ẹyọ kọ̀ọ̀kan, wí pé, àwọn òṣìṣẹ́ tí ó jẹ́ ogún ọdún tàbí jù bẹ́ẹ̀ lọ tí ń ṣiṣẹ́ ìsìn nínú ilé Olúwa.
Yuqiriqilarning hemmisi Lawiyning ewladliri bolup, jemetliri boyiche, yeni jemet bashliri boyiche yigirme yashtin ashqan erkekler royxetke élin’ghan; ular Perwerdigarning öyidiki wezipilerni öteshke ismiliri boyiche tizimlan’ghanidi.
25 Nítorí pé Dafidi ti sọ pé, “Níwọ̀n ìgbà tí Olúwa Ọlọ́run Israẹli, ti fi ìsinmi fún àwọn ènìyàn tí ó kù tí sì ń gbé Jerusalẹmu títí láéláé,
Chünki Dawut: «Israilning Xudasi Perwerdigar Öz xelqige aram bérip, Özi menggü Yérusalémda makan qilidu;
26 àwọn ọmọ Lefi kò sì tún ru àgọ́ tàbí ọ̀kankan lára àwọn ohun èlò tí wọ́n ń lò níbi ìsìn rẹ̀.”
shuning bilen Lawiylarning muqeddes chédirni we uning ichidiki herqaysi qacha-eswablarni kötürüp yürüshning hajiti yoq» dégenidi.
27 Gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ ìkẹyìn Dafidi sí, àwọn ọmọ Lefi, wọ́n sì kà wọ́n, bẹ̀rẹ̀ láti orí àwọn ọmọ ogún ọdún tàbí jù bẹ́ẹ̀ lọ.
Shunga Dawutning jan üzüsh aldidiki wesiyiti boyiche, Lawiylarning yigirme yashtin yuqirilirining hemmisi sanaqtin ötküzülgenidi.
28 Iṣẹ́ àwọn ọmọ Lefi ni láti ran àwọn ọmọ Aaroni lọ́wọ́ nínú iṣẹ́ wọn fún ti ilé Olúwa: láti wà lábẹ́ ìkáwọ́ agbára ìlú, àti ẹ̀gbẹ́ ilé, àti ìwẹ̀nùmọ́ ti gbogbo ohun ìyàsọ́tọ̀ àti ṣíṣe ohun tí í ṣe iṣẹ́ ìsìn nínú ilé Olúwa.
Ularning wezipisi bolsa Harunning ewladlirining yénida turup, Perwerdigarning öyining ishlirini qilish idi; ular hoyla-aramlarni bashqurush, barliq muqeddes buyumlarni pakiz tutush, qisqisi, Perwerdigarning öyining xizmet wezipilirini béjirishke mes’ul idi;
29 Wọ́n sì wà ní ìkáwọ́ àkàrà tí wọ́n mú jáde láti orí tábìlì, àti ìyẹ̀fun fún ẹbọ, àti àkàrà aláìwú, àti fún púpọ̀ àti èyí tí a pòpọ̀, àti gbogbo onírúurú ìwọ̀n àti wíwọ̀n àti òsùwọ̀n.
yene «tizilghan teqdim nan», ash hediye unliri, pétir qoturmachlar, qazan nanliri we mayliq nanlargha, shundaqla herxil ölchesh eswablirigha mes’ul idi;
30 Wọ́n sì gbọdọ̀ dúró ní gbogbo òwúrọ̀ láti dúpẹ́ àti láti yin Olúwa. Wọ́n sì gbọdọ̀ ṣe irú kan náà ní àṣálẹ́.
ular yene herküni etigende öre turup Perwerdigargha teshekkür éytip hemdusana oquytti, herküni kechlikimu shundaq qilatti.
31 Àti láti rú ẹbọ sísun fún Olúwa ní ọjọ́ ìsinmi àti ní àsìkò oṣù tuntun àti ní àjọ̀dún tí a yàn. Wọ́n gbọdọ̀ sìn níwájú Olúwa lójoojúmọ́ ní iye tó yẹ àti ní ọ̀nà tí a ti pàṣẹ fún wọn.
Yene shabat küni, her yéngi ayda, shuningdek békitilgen héyt-bayramlarda sunulidighan barliq köydürme qurbanliqlargha mes’ul idi. Özlirige qaritilghan belgilime boyiche, ular daim Perwerdigarning aldigha békitiligen sani we nöwiti bilen xizmette turatti.
32 Bẹ́ẹ̀ ni nígbà náà, àwọn ọmọ Lefi gbé ìgbékalẹ̀ jáde fún ìpàdé àgọ́, fún Ibi Mímọ́ àti, lábẹ́ àwọn arákùnrin àwọn ọmọ Aaroni fún ìsìn ilé Olúwa.
Ular jamaet chédirini hem muqeddes jayni baqatti, shundaqla özlirining Perwerdigarning öyidiki xizmette boluwatqan qérindashliri, yeni Harunning ewladlirigha qaraytti.

< 1 Chronicles 23 >