< 1 Chronicles 23 >
1 Nígbà tí Dafidi sì dàgbà, tí ó sì di arúgbó, ó sì fi Solomoni ọmọ rẹ̀ jẹ ọba lórí Israẹli.
A tak Dawid będąc stary i pełen dni, postanowił królem Salomona, syna swego nad Izraelem.
2 Ó sì kó gbogbo àgbàgbà Israẹli jọ, àti gẹ́gẹ́ bí àwọn àlùfáà àti àwọn ará Lefi.
I zgromadził wszystkich książąt Izraelskich, i kapłanów, i Lewitów;
3 Àwọn ọmọ Lefi láti ọgbọ̀n ọdún tàbí jù bẹ́ẹ̀ lọ ni wọ́n kà àpapọ̀ iye àwọn ọkùnrin wọn sì jẹ́ ẹgbàá mọ́kàndínlógún.
A policzono Lewitów od trzydziestu lat i wyżej; i był poczet ich według głów ich osób trzydzieści i ośm tysięcy.
4 Dafidi sì wí pe, ní ti èyí, ẹgbàá méjìlá ni kí wọn jẹ́ alábojútó iṣẹ́ ilé fún Olúwa àti ẹgbẹ̀rún mẹ́fà ni kí ó ṣe olórí àti onídàájọ́.
Z których postanowiono na posługę domu Pańskiego dwadzieścia i cztery tysiące, a przełożonych i sędziów sześć tysięcy.
5 Ẹgbàajì ni kí ó jẹ́ olùtọ́jú ẹnu-ọ̀nà àti ẹgbàajì ni kí o sì jẹ́ ẹni ti yóò máa yin Olúwa pẹ̀lú ohun èlò orin, mo ti ṣe èyí fún ìdí pàtàkì yìí.
Nadto cztery tysiące odźwiernych, i cztery tysiące chwalących Pana na instrumentach, których nasprawiał Dawid ku chwaleniu Boga.
6 Dafidi sì pín àwọn ọmọ Lefi sí ẹgbẹgbẹ́ láàrín àwọn ọmọ Lefi: Gerṣoni, Kohati àti Merari.
I rozdzielił ich Dawid na pewne hufy według synów Lewiego, to jest, Giersona, Kaata, i Merarego.
7 Àwọn tí ó jẹ́ ọmọ Gerṣoni: Laadani àti Ṣimei.
Z Giersona byli Laadam, i Semej.
8 Àwọn ọmọ Laadani Jehieli ẹni àkọ́kọ́, Setamu àti Joẹli, mẹ́ta ní gbogbo wọn.
Synowie Laadanowi: przedniejszy Jachijel, i Zetam, i Joel, ci trzej.
9 Àwọn ọmọ Ṣimei: Ṣelomiti, Hasieli àti Harani mẹ́ta ní gbogbo wọn. Àwọn wọ̀nyí sì ni olórí àwọn ìdílé Laadani.
Synowie Semejowi: Salomit, i Hazyjel, i Haran, ci trzej. Cić byli przedniejsi domów ojcowskich z Laadana.
10 Àti ọmọ Ṣimei: Jahati, Sina, Jeuṣi àti Beriah. Àwọn wọ̀nyí ni ọmọ Ṣimei mẹ́rin ni gbogbo wọn.
A synowie Semejowi: Jachat, Zyna, i Jehus, i Baryjasz; cić synowie Semejowi czterej.
11 Jahati sì ni alákọ́kọ́ Sinah sì ni ẹlẹ́ẹ̀kejì, ṣùgbọ́n Jeuṣi àti Beriah kò ní àwọn ọmọ púpọ̀; bẹ́ẹ̀ ni wọ́n sì ka ara wọn sí ìdílé kan pẹ̀lú ìfilé lọ́wọ́ kan.
A Jachat był pierwszym, a Zyza wtóry; ale Jehus i Baryjasz nie mieli wiele synów; przetoż byli w domu ojcowskim policzeni za jednę familiję.
12 Àwọn ọmọ Kohati: Amramu, Isari, Hebroni àti Usieli mẹ́rin ni gbogbo wọn.
Synowie Kaatowi: Amram, Izaar, Hebron, i Husyjel, czterej.
13 Àwọn ọmọ Amramu. Aaroni àti Mose. A sì ya Aaroni sọ́tọ̀ òun àti àwọn ọmọ rẹ̀ títí láéláé, láti kọjú sí ohun mímọ́ jùlọ, láti fi rú ẹbọ sísun níwájú Olúwa, láti máa ṣe òjíṣẹ́ níwájú rẹ̀ àti láti kéde ìbùkún ní orúkọ rẹ̀ títí láéláé.
Synowie Amramowi: Aaron i Mojżesz. Lecz Aaron był odłączony, aby służył w świątnicy najświętszej, sam i synowie jego aż na wieki, i aby kadzili przed Panem, a służyli mu, i błogosławili w imieniu jego aż na wieki.
14 Àwọn ọmọ Mose ènìyàn Ọlọ́run ni wọ́n kà gẹ́gẹ́ bí apá kan ẹ̀yà Lefi.
Ale synowie Mojżesza, męża Bożego, policzeni są w pokoleniu Lewiego.
15 Àwọn ọmọ Mose: Gerṣomu àti Elieseri.
Synowie Mojżeszowi: Gierson i Eliezer.
16 Àwọn ọmọ Gerṣomu: Ṣubaeli sì ni alákọ́kọ́.
Synowie Giersonowi: Sebujel pierwszy.
17 Àwọn ọmọ Elieseri: Rehabiah sì ni ẹni àkọ́kọ́. Elieseri kò sì tún ní ọmọ mìíràn, ṣùgbọ́n àwọn ọmọ Rehabiah wọ́n sì pọ̀ níye.
A synowie Eliezerowi byli Rechabijasz pierwszy. I nie miał Eliezer synów innych; ale synowie Rechabijaszowi rozmnożyli się bardzo.
18 Àwọn ọmọ Isari: Ṣelomiti sì ni ẹni àkọ́kọ́.
Synowie Izaarowi: Salomit pierwszy.
19 Àwọn ọmọ Hebroni: Jeriah sì ni ẹni àkọ́kọ́, Amariah sì ni ẹni ẹ̀ẹ̀kejì, Jahasieli sì ni ẹ̀ẹ̀kẹ́ta àti Jekameamu ẹ̀ẹ̀kẹrin.
Synowie Hebronowi: Jeryjasz pierwszy, Amaryjasz wtóry, Jehazyjel trzeci, a Jekmaan czwarty.
20 Àwọn ọmọ Usieli: Mika ni àkọ́kọ́ àti Iṣiah ẹ̀ẹ̀kejì.
Synowie Husyjelowi: Micha pierwszy, a Jesyjasz wtóry.
21 Àwọn ọmọ Merari: Mahili àti Muṣi. Àwọn ọmọ Mahili: Eleasari àti Kiṣi.
Synowie Merarego: Mahelin i Musy; a synowie Mahelego: Eleazar i Cys.
22 Eleasari sì kú pẹ̀lú àìní àwọn ọmọkùnrin: Ó ní ọmọbìnrin nìkan. Àwọn ọmọ ẹ̀gbọ́n, àwọn ọmọ Kiṣi, sì fẹ́ wọn.
I umarł Eleazar, a nie miał synów, tylko córki, które pojmowali synowie Cysowi, bracia ich.
23 Àwọn ọmọ Muṣi: Mahili, Ederi àti Jerimoti mẹ́ta ni gbogbo wọn.
Synowie Musy: Maheli, i Eder, i Jerymot, trzej.
24 Àwọn wọ̀nyí sì ni ọmọ Lefi bí ìdílé wọn. Olórí ìdílé gẹ́gẹ́ bí wọ́n ti fi orúkọ sílẹ̀ lábẹ́ orúkọ wọn, ó sì kà wọn ní ẹyọ kọ̀ọ̀kan, wí pé, àwọn òṣìṣẹ́ tí ó jẹ́ ogún ọdún tàbí jù bẹ́ẹ̀ lọ tí ń ṣiṣẹ́ ìsìn nínú ilé Olúwa.
Cić są synowie Lewiego według domów ojców swych, przedniejsi domów ojcowskich, którzy policzeni byli według pocztu imion i osób swych z osobna, którzy odprawowali prace usługiwania w domu Pańskim od dwudziestu lat i wyżej.
25 Nítorí pé Dafidi ti sọ pé, “Níwọ̀n ìgbà tí Olúwa Ọlọ́run Israẹli, ti fi ìsinmi fún àwọn ènìyàn tí ó kù tí sì ń gbé Jerusalẹmu títí láéláé,
Albowiem rzekł Dawid: Dał odpocznienie Pan, Bóg Izraelski, ludowi swemu, i będzie mieszkał w Jeruzalemie aż na wieki.
26 àwọn ọmọ Lefi kò sì tún ru àgọ́ tàbí ọ̀kankan lára àwọn ohun èlò tí wọ́n ń lò níbi ìsìn rẹ̀.”
Do tego i Lewitowie nie będą więcej nosić przybytku i wszystkiego naczynia jego ku posługiwaniu jego;
27 Gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ ìkẹyìn Dafidi sí, àwọn ọmọ Lefi, wọ́n sì kà wọ́n, bẹ̀rẹ̀ láti orí àwọn ọmọ ogún ọdún tàbí jù bẹ́ẹ̀ lọ.
Ale według postanowienia Dawidowego ostatniego, byli policzeni synowie Lewiego od dwudziestu lat i wyżej;
28 Iṣẹ́ àwọn ọmọ Lefi ni láti ran àwọn ọmọ Aaroni lọ́wọ́ nínú iṣẹ́ wọn fún ti ilé Olúwa: láti wà lábẹ́ ìkáwọ́ agbára ìlú, àti ẹ̀gbẹ́ ilé, àti ìwẹ̀nùmọ́ ti gbogbo ohun ìyàsọ́tọ̀ àti ṣíṣe ohun tí í ṣe iṣẹ́ ìsìn nínú ilé Olúwa.
Aby zostawali pod ręką synów Aaronowych ku usłudze domu Pańskiego w przysionkach i w gmachach, i ku oczyszczaniu wszelkich rzeczy poświęconych, i ku pracy około usługi domu Bożego;
29 Wọ́n sì wà ní ìkáwọ́ àkàrà tí wọ́n mú jáde láti orí tábìlì, àti ìyẹ̀fun fún ẹbọ, àti àkàrà aláìwú, àti fún púpọ̀ àti èyí tí a pòpọ̀, àti gbogbo onírúurú ìwọ̀n àti wíwọ̀n àti òsùwọ̀n.
I około chleba pokładnego, i około mąki na ofiarę, i około placków niekwaszonych, i około panewek, i około rzeczy smażonych, i około wszelkiej miary i odmierzania;
30 Wọ́n sì gbọdọ̀ dúró ní gbogbo òwúrọ̀ láti dúpẹ́ àti láti yin Olúwa. Wọ́n sì gbọdọ̀ ṣe irú kan náà ní àṣálẹ́.
A iżby stali na każdy poranek ku wysławianiu, i ku chwaleniu Pana, także i w wieczór;
31 Àti láti rú ẹbọ sísun fún Olúwa ní ọjọ́ ìsinmi àti ní àsìkò oṣù tuntun àti ní àjọ̀dún tí a yàn. Wọ́n gbọdọ̀ sìn níwájú Olúwa lójoojúmọ́ ní iye tó yẹ àti ní ọ̀nà tí a ti pàṣẹ fún wọn.
Nadto, przy każdem ofiarowaniu całopalenia Panu w sabaty, na nowiu miesiąca, i w uroczyste święta, według liczby i porządku ich ustawicznie przed Panem;
32 Bẹ́ẹ̀ ni nígbà náà, àwọn ọmọ Lefi gbé ìgbékalẹ̀ jáde fún ìpàdé àgọ́, fún Ibi Mímọ́ àti, lábẹ́ àwọn arákùnrin àwọn ọmọ Aaroni fún ìsìn ilé Olúwa.
A tak aby pilnowali straży namiotu zgromadzenia, i straży świątnicy, i straży synów Aaronowych, braci swych, w usłudze domu Pańskiego.