< 1 Chronicles 23 >

1 Nígbà tí Dafidi sì dàgbà, tí ó sì di arúgbó, ó sì fi Solomoni ọmọ rẹ̀ jẹ ọba lórí Israẹli.
David était vieux et rassasié de jours, et il établit Salomon, son fils, roi d'Israël.
2 Ó sì kó gbogbo àgbàgbà Israẹli jọ, àti gẹ́gẹ́ bí àwọn àlùfáà àti àwọn ará Lefi.
Il rassembla tous les chefs d'Israël, avec les sacrificateurs et les Lévites.
3 Àwọn ọmọ Lefi láti ọgbọ̀n ọdún tàbí jù bẹ́ẹ̀ lọ ni wọ́n kà àpapọ̀ iye àwọn ọkùnrin wọn sì jẹ́ ẹgbàá mọ́kàndínlógún.
Les Lévites furent comptés depuis l'âge de trente ans et au-dessus, et leur nombre, par tête, fut de trente-huit mille.
4 Dafidi sì wí pe, ní ti èyí, ẹgbàá méjìlá ni kí wọn jẹ́ alábojútó iṣẹ́ ilé fún Olúwa àti ẹgbẹ̀rún mẹ́fà ni kí ó ṣe olórí àti onídàájọ́.
David dit: « Parmi eux, vingt-quatre mille étaient chargés de surveiller les travaux de la maison de Yahvé, six mille étaient officiers et juges,
5 Ẹgbàajì ni kí ó jẹ́ olùtọ́jú ẹnu-ọ̀nà àti ẹgbàajì ni kí o sì jẹ́ ẹni ti yóò máa yin Olúwa pẹ̀lú ohun èlò orin, mo ti ṣe èyí fún ìdí pàtàkì yìí.
quatre mille étaient portiers, et quatre mille louaient Yahvé avec les instruments que j'avais fabriqués pour le louer. »
6 Dafidi sì pín àwọn ọmọ Lefi sí ẹgbẹgbẹ́ láàrín àwọn ọmọ Lefi: Gerṣoni, Kohati àti Merari.
David les répartit en divisions selon les fils de Lévi: Guershon, Kehath et Merari.
7 Àwọn tí ó jẹ́ ọmọ Gerṣoni: Laadani àti Ṣimei.
Des Gershonites: Ladan et Shimei.
8 Àwọn ọmọ Laadani Jehieli ẹni àkọ́kọ́, Setamu àti Joẹli, mẹ́ta ní gbogbo wọn.
Fils de Ladan: Jehiel, le chef, Zetham et Joël, trois.
9 Àwọn ọmọ Ṣimei: Ṣelomiti, Hasieli àti Harani mẹ́ta ní gbogbo wọn. Àwọn wọ̀nyí sì ni olórí àwọn ìdílé Laadani.
Fils de Schimeï: Schelomoth, Hatsiel et Haran, trois. Ce sont les chefs de famille de Ladan.
10 Àti ọmọ Ṣimei: Jahati, Sina, Jeuṣi àti Beriah. Àwọn wọ̀nyí ni ọmọ Ṣimei mẹ́rin ni gbogbo wọn.
Fils de Schimeï: Jahath, Zina, Jeush et Beriah. Ces quatre-là étaient les fils de Schimeï.
11 Jahati sì ni alákọ́kọ́ Sinah sì ni ẹlẹ́ẹ̀kejì, ṣùgbọ́n Jeuṣi àti Beriah kò ní àwọn ọmọ púpọ̀; bẹ́ẹ̀ ni wọ́n sì ka ara wọn sí ìdílé kan pẹ̀lú ìfilé lọ́wọ́ kan.
Jahath était le chef, et Zina le second; mais Jeush et Beriah n'avaient pas beaucoup de fils; c'est pourquoi ils formaient une maison de pères en un seul compte.
12 Àwọn ọmọ Kohati: Amramu, Isari, Hebroni àti Usieli mẹ́rin ni gbogbo wọn.
Fils de Kehath: Amram, Izhar, Hebron et Uzziel, quatre.
13 Àwọn ọmọ Amramu. Aaroni àti Mose. A sì ya Aaroni sọ́tọ̀ òun àti àwọn ọmọ rẹ̀ títí láéláé, láti kọjú sí ohun mímọ́ jùlọ, láti fi rú ẹbọ sísun níwájú Olúwa, láti máa ṣe òjíṣẹ́ níwájú rẹ̀ àti láti kéde ìbùkún ní orúkọ rẹ̀ títí láéláé.
Fils d'Amram: Aaron et Moïse. Aaron fut séparé pour sanctifier les choses très saintes, lui et ses fils à jamais, pour offrir des parfums devant l'Éternel, pour le servir et pour bénir en son nom à jamais.
14 Àwọn ọmọ Mose ènìyàn Ọlọ́run ni wọ́n kà gẹ́gẹ́ bí apá kan ẹ̀yà Lefi.
Quant à Moïse, homme de Dieu, ses fils furent désignés dans la tribu de Lévi.
15 Àwọn ọmọ Mose: Gerṣomu àti Elieseri.
Fils de Moïse: Gershom et Eliezer.
16 Àwọn ọmọ Gerṣomu: Ṣubaeli sì ni alákọ́kọ́.
Fils de Guershom: Shebuel, le chef.
17 Àwọn ọmọ Elieseri: Rehabiah sì ni ẹni àkọ́kọ́. Elieseri kò sì tún ní ọmọ mìíràn, ṣùgbọ́n àwọn ọmọ Rehabiah wọ́n sì pọ̀ níye.
Fils d'Éliézer: Rehabia, le chef. Éliézer n'eut pas d'autres fils, mais les fils de Rehabia furent très nombreux.
18 Àwọn ọmọ Isari: Ṣelomiti sì ni ẹni àkọ́kọ́.
Fils de Jitsehar: Shelomith, le chef.
19 Àwọn ọmọ Hebroni: Jeriah sì ni ẹni àkọ́kọ́, Amariah sì ni ẹni ẹ̀ẹ̀kejì, Jahasieli sì ni ẹ̀ẹ̀kẹ́ta àti Jekameamu ẹ̀ẹ̀kẹrin.
Fils de Hébron: Jeriah, le chef, Amaria, le second, Jahaziel, le troisième, et Jekameam, le quatrième.
20 Àwọn ọmọ Usieli: Mika ni àkọ́kọ́ àti Iṣiah ẹ̀ẹ̀kejì.
Fils d'Uzziel: Michée, le chef, et Ischia, le second.
21 Àwọn ọmọ Merari: Mahili àti Muṣi. Àwọn ọmọ Mahili: Eleasari àti Kiṣi.
Fils de Merari: Mahli et Mushi. Les fils de Mahli: Éléazar et Kish.
22 Eleasari sì kú pẹ̀lú àìní àwọn ọmọkùnrin: Ó ní ọmọbìnrin nìkan. Àwọn ọmọ ẹ̀gbọ́n, àwọn ọmọ Kiṣi, sì fẹ́ wọn.
Éléazar mourut et n'eut pas de fils, mais seulement des filles; leurs parents, les fils de Kis, les prirent pour femmes.
23 Àwọn ọmọ Muṣi: Mahili, Ederi àti Jerimoti mẹ́ta ni gbogbo wọn.
Fils de Muschi: Mahli, Eder et Jérémoth, au nombre de trois.
24 Àwọn wọ̀nyí sì ni ọmọ Lefi bí ìdílé wọn. Olórí ìdílé gẹ́gẹ́ bí wọ́n ti fi orúkọ sílẹ̀ lábẹ́ orúkọ wọn, ó sì kà wọn ní ẹyọ kọ̀ọ̀kan, wí pé, àwọn òṣìṣẹ́ tí ó jẹ́ ogún ọdún tàbí jù bẹ́ẹ̀ lọ tí ń ṣiṣẹ́ ìsìn nínú ilé Olúwa.
Ce sont là les fils de Lévi, selon leurs maisons de pères, les chefs de maisons de pères de ceux qui furent comptés individuellement, au nombre des noms selon les sondages, qui faisaient le service de la maison de l'Éternel, depuis l'âge de vingt ans et au-dessus.
25 Nítorí pé Dafidi ti sọ pé, “Níwọ̀n ìgbà tí Olúwa Ọlọ́run Israẹli, ti fi ìsinmi fún àwọn ènìyàn tí ó kù tí sì ń gbé Jerusalẹmu títí láéláé,
Car David avait dit: « L'Éternel, le Dieu d'Israël, a donné du repos à son peuple, et il habite à Jérusalem pour toujours.
26 àwọn ọmọ Lefi kò sì tún ru àgọ́ tàbí ọ̀kankan lára àwọn ohun èlò tí wọ́n ń lò níbi ìsìn rẹ̀.”
Aussi les Lévites n'auront plus besoin de porter le tabernacle et tous ses ustensiles pour son service. »
27 Gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ ìkẹyìn Dafidi sí, àwọn ọmọ Lefi, wọ́n sì kà wọ́n, bẹ̀rẹ̀ láti orí àwọn ọmọ ogún ọdún tàbí jù bẹ́ẹ̀ lọ.
En effet, selon les dernières paroles de David, les fils de Lévi ont été comptés, à partir de vingt ans et plus.
28 Iṣẹ́ àwọn ọmọ Lefi ni láti ran àwọn ọmọ Aaroni lọ́wọ́ nínú iṣẹ́ wọn fún ti ilé Olúwa: láti wà lábẹ́ ìkáwọ́ agbára ìlú, àti ẹ̀gbẹ́ ilé, àti ìwẹ̀nùmọ́ ti gbogbo ohun ìyàsọ́tọ̀ àti ṣíṣe ohun tí í ṣe iṣẹ́ ìsìn nínú ilé Olúwa.
Car ils étaient chargés de servir les fils d'Aaron pour le service de la maison de Yahvé, dans les parvis, dans les chambres, pour la purification de toutes les choses saintes, pour le service de la maison de Dieu,
29 Wọ́n sì wà ní ìkáwọ́ àkàrà tí wọ́n mú jáde láti orí tábìlì, àti ìyẹ̀fun fún ẹbọ, àti àkàrà aláìwú, àti fún púpọ̀ àti èyí tí a pòpọ̀, àti gbogbo onírúurú ìwọ̀n àti wíwọ̀n àti òsùwọ̀n.
pour les pains de proposition et pour la farine fine destinée à l'offrande, qu'il s'agisse de galettes sans levain, de galettes cuites au four ou de galettes trempées, et pour toutes les mesures de quantité et de taille;
30 Wọ́n sì gbọdọ̀ dúró ní gbogbo òwúrọ̀ láti dúpẹ́ àti láti yin Olúwa. Wọ́n sì gbọdọ̀ ṣe irú kan náà ní àṣálẹ́.
Ils se tiendront debout tous les matins pour remercier et louer Yahvé, ainsi que le soir;
31 Àti láti rú ẹbọ sísun fún Olúwa ní ọjọ́ ìsinmi àti ní àsìkò oṣù tuntun àti ní àjọ̀dún tí a yàn. Wọ́n gbọdọ̀ sìn níwájú Olúwa lójoojúmọ́ ní iye tó yẹ àti ní ọ̀nà tí a ti pàṣẹ fún wọn.
ils offriront à Yahvé tous les holocaustes aux sabbats, aux nouvelles lunes et aux fêtes, en nombre suffisant, selon les règles qui leur sont prescrites, en permanence devant Yahvé;
32 Bẹ́ẹ̀ ni nígbà náà, àwọn ọmọ Lefi gbé ìgbékalẹ̀ jáde fún ìpàdé àgọ́, fún Ibi Mímọ́ àti, lábẹ́ àwọn arákùnrin àwọn ọmọ Aaroni fún ìsìn ilé Olúwa.
ils s'acquitteront des fonctions de la tente d'assignation, des fonctions du lieu saint et des fonctions des fils d'Aaron, leurs frères, pour le service de la maison de Yahvé.

< 1 Chronicles 23 >