< 1 Chronicles 23 >

1 Nígbà tí Dafidi sì dàgbà, tí ó sì di arúgbó, ó sì fi Solomoni ọmọ rẹ̀ jẹ ọba lórí Israẹli.
Therfor Dauid was eld and ful of daies, and ordeynede Salomon, his sone, kyng on Israel.
2 Ó sì kó gbogbo àgbàgbà Israẹli jọ, àti gẹ́gẹ́ bí àwọn àlùfáà àti àwọn ará Lefi.
And he gaderide togidere alle the princes of Israel, and the preestis, and dekenes;
3 Àwọn ọmọ Lefi láti ọgbọ̀n ọdún tàbí jù bẹ́ẹ̀ lọ ni wọ́n kà àpapọ̀ iye àwọn ọkùnrin wọn sì jẹ́ ẹgbàá mọ́kàndínlógún.
and the dekenes weren noumbrid fro twenti yeer and aboue, and eiyte and thretti thousynde of men weren foundun.
4 Dafidi sì wí pe, ní ti èyí, ẹgbàá méjìlá ni kí wọn jẹ́ alábojútó iṣẹ́ ilé fún Olúwa àti ẹgbẹ̀rún mẹ́fà ni kí ó ṣe olórí àti onídàájọ́.
And foure and twenty thousynde men weren chosun of hem, and weren departid in to the seruyce of the hows of the Lord; sotheli of souereyns, and iugis, sixe thousynde;
5 Ẹgbàajì ni kí ó jẹ́ olùtọ́jú ẹnu-ọ̀nà àti ẹgbàajì ni kí o sì jẹ́ ẹni ti yóò máa yin Olúwa pẹ̀lú ohun èlò orin, mo ti ṣe èyí fún ìdí pàtàkì yìí.
forsothe foure thousynde `porteris weren, and so many syngeris, syngynge to the Lord in orguns, whiche Dauid hadde maad for to synge.
6 Dafidi sì pín àwọn ọmọ Lefi sí ẹgbẹgbẹ́ láàrín àwọn ọmọ Lefi: Gerṣoni, Kohati àti Merari.
And Dauid departide hem bi the whilis of the sones of Leuy, that is, of Gerson, and of Caath, and Merary.
7 Àwọn tí ó jẹ́ ọmọ Gerṣoni: Laadani àti Ṣimei.
And the sones of Gerson weren Leedan and Semeye.
8 Àwọn ọmọ Laadani Jehieli ẹni àkọ́kọ́, Setamu àti Joẹli, mẹ́ta ní gbogbo wọn.
The sones of Leedan weren thre, the prince Jehiel, and Ethan, and Johel.
9 Àwọn ọmọ Ṣimei: Ṣelomiti, Hasieli àti Harani mẹ́ta ní gbogbo wọn. Àwọn wọ̀nyí sì ni olórí àwọn ìdílé Laadani.
The sones of Semei weren thre, Salamyth, and Oziel, and Aram; these weren the princes of the meynees of Leedan.
10 Àti ọmọ Ṣimei: Jahati, Sina, Jeuṣi àti Beriah. Àwọn wọ̀nyí ni ọmọ Ṣimei mẹ́rin ni gbogbo wọn.
Forsothe the sones of Semeye weren Leeth, and Ziza, and Yaus, and Baria, these foure weren the sones of Semei.
11 Jahati sì ni alákọ́kọ́ Sinah sì ni ẹlẹ́ẹ̀kejì, ṣùgbọ́n Jeuṣi àti Beriah kò ní àwọn ọmọ púpọ̀; bẹ́ẹ̀ ni wọ́n sì ka ara wọn sí ìdílé kan pẹ̀lú ìfilé lọ́wọ́ kan.
Sotheli Leeth was the formere, and Ziza the secounde; forsothe Yaus and Baria hadden not ful many sones, and therfor thei weren rikenyd in o meynee and oon hows.
12 Àwọn ọmọ Kohati: Amramu, Isari, Hebroni àti Usieli mẹ́rin ni gbogbo wọn.
The sones of Caath weren foure, Amram, and Ysaac, Ebron, and Oziel.
13 Àwọn ọmọ Amramu. Aaroni àti Mose. A sì ya Aaroni sọ́tọ̀ òun àti àwọn ọmọ rẹ̀ títí láéláé, láti kọjú sí ohun mímọ́ jùlọ, láti fi rú ẹbọ sísun níwájú Olúwa, láti máa ṣe òjíṣẹ́ níwájú rẹ̀ àti láti kéde ìbùkún ní orúkọ rẹ̀ títí láéláé.
The sones of Amram weren Aaron and Moyses; and Aaron was departid, that he schulde mynystre in the hooli thing of hooli thingis, he and hise sones with outen ende, and to brenne encense to the Lord bi his custom, and to blesse his name with outen ende.
14 Àwọn ọmọ Mose ènìyàn Ọlọ́run ni wọ́n kà gẹ́gẹ́ bí apá kan ẹ̀yà Lefi.
Also the sones of Moyses, man of God, weren noumbrid in the lynage of Leuy.
15 Àwọn ọmọ Mose: Gerṣomu àti Elieseri.
The sones of Moises weren Gerson and Elieser.
16 Àwọn ọmọ Gerṣomu: Ṣubaeli sì ni alákọ́kọ́.
The sones of Gerson; `Subuhel the firste.
17 Àwọn ọmọ Elieseri: Rehabiah sì ni ẹni àkọ́kọ́. Elieseri kò sì tún ní ọmọ mìíràn, ṣùgbọ́n àwọn ọmọ Rehabiah wọ́n sì pọ̀ níye.
Sotheli the sones of Eliezer weren Roboya the firste, and othere sones weren not to Eliezer; forsothe the sones of Roboia weren multipliede ful miche.
18 Àwọn ọmọ Isari: Ṣelomiti sì ni ẹni àkọ́kọ́.
The sones of Isaar; `Salumuth the firste.
19 Àwọn ọmọ Hebroni: Jeriah sì ni ẹni àkọ́kọ́, Amariah sì ni ẹni ẹ̀ẹ̀kejì, Jahasieli sì ni ẹ̀ẹ̀kẹ́ta àti Jekameamu ẹ̀ẹ̀kẹrin.
The sones of Ebron; `Jerian the firste, Amarias the secounde, Jaziel the thridde, Jethamaan the fourthe.
20 Àwọn ọmọ Usieli: Mika ni àkọ́kọ́ àti Iṣiah ẹ̀ẹ̀kejì.
The sones of Oziel; `Mycha the firste, Jesia the secounde.
21 Àwọn ọmọ Merari: Mahili àti Muṣi. Àwọn ọmọ Mahili: Eleasari àti Kiṣi.
The sones of Merari weren Mooli and Musi. The sones of Mooli weren Eleazar, and Cys.
22 Eleasari sì kú pẹ̀lú àìní àwọn ọmọkùnrin: Ó ní ọmọbìnrin nìkan. Àwọn ọmọ ẹ̀gbọ́n, àwọn ọmọ Kiṣi, sì fẹ́ wọn.
Sotheli Eleazar was deed, and hadde not sones, but douytris; and the sones of Cys, the britheren of hem, weddiden hem.
23 Àwọn ọmọ Muṣi: Mahili, Ederi àti Jerimoti mẹ́ta ni gbogbo wọn.
The sones of Musi weren thre, Mooli, and Heder, and Jerymuth.
24 Àwọn wọ̀nyí sì ni ọmọ Lefi bí ìdílé wọn. Olórí ìdílé gẹ́gẹ́ bí wọ́n ti fi orúkọ sílẹ̀ lábẹ́ orúkọ wọn, ó sì kà wọn ní ẹyọ kọ̀ọ̀kan, wí pé, àwọn òṣìṣẹ́ tí ó jẹ́ ogún ọdún tàbí jù bẹ́ẹ̀ lọ tí ń ṣiṣẹ́ ìsìn nínú ilé Olúwa.
These weren the sones of Leuy in her kynredis and meynees, prynces bi whilis, and noumbre of alle heedis, that diden the trauel of the seruyce of the hows of the Lord, fro twenti yeer and aboue.
25 Nítorí pé Dafidi ti sọ pé, “Níwọ̀n ìgbà tí Olúwa Ọlọ́run Israẹli, ti fi ìsinmi fún àwọn ènìyàn tí ó kù tí sì ń gbé Jerusalẹmu títí láéláé,
For Dauid seide, The Lord God of Israel hath youe reste to his puple, and a dwellyng in Jerusalem til in to with outen ende;
26 àwọn ọmọ Lefi kò sì tún ru àgọ́ tàbí ọ̀kankan lára àwọn ohun èlò tí wọ́n ń lò níbi ìsìn rẹ̀.”
and it schal not be the office of dekenes for to bere more the tabernacle, and alle vessels therof for to mynystre.
27 Gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ ìkẹyìn Dafidi sí, àwọn ọmọ Lefi, wọ́n sì kà wọ́n, bẹ̀rẹ̀ láti orí àwọn ọmọ ogún ọdún tàbí jù bẹ́ẹ̀ lọ.
Also bi the laste comaundementis of Dauid the noumbre of the sones of Leuy schulen be rikened fro twenti yeer and aboue;
28 Iṣẹ́ àwọn ọmọ Lefi ni láti ran àwọn ọmọ Aaroni lọ́wọ́ nínú iṣẹ́ wọn fún ti ilé Olúwa: láti wà lábẹ́ ìkáwọ́ agbára ìlú, àti ẹ̀gbẹ́ ilé, àti ìwẹ̀nùmọ́ ti gbogbo ohun ìyàsọ́tọ̀ àti ṣíṣe ohun tí í ṣe iṣẹ́ ìsìn nínú ilé Olúwa.
and thei schulen be vndir the hond of the sones of Aaron in to the worschipe of the hows of the Lord, in porchis, and in chaumbris, and in the place of clensyng, and in the seyntuarie, and in alle werkis of the seruyce of the temple of the Lord.
29 Wọ́n sì wà ní ìkáwọ́ àkàrà tí wọ́n mú jáde láti orí tábìlì, àti ìyẹ̀fun fún ẹbọ, àti àkàrà aláìwú, àti fún púpọ̀ àti èyí tí a pòpọ̀, àti gbogbo onírúurú ìwọ̀n àti wíwọ̀n àti òsùwọ̀n.
Forsothe preestis schulen be ouer the looues of proposicioun, and to the sacrifice of flour, and to the pastis sodun in watir, and to the therf looues, and friyng panne, and to hoot flour, and to seenge, and ouer al weiyte and mesure.
30 Wọ́n sì gbọdọ̀ dúró ní gbogbo òwúrọ̀ láti dúpẹ́ àti láti yin Olúwa. Wọ́n sì gbọdọ̀ ṣe irú kan náà ní àṣálẹ́.
Forsothe the dekenes schulen be, that thei stonde eerli, for to knowleche and synge to the Lord, and lijk maner at euentide,
31 Àti láti rú ẹbọ sísun fún Olúwa ní ọjọ́ ìsinmi àti ní àsìkò oṣù tuntun àti ní àjọ̀dún tí a yàn. Wọ́n gbọdọ̀ sìn níwájú Olúwa lójoojúmọ́ ní iye tó yẹ àti ní ọ̀nà tí a ti pàṣẹ fún wọn.
as wel in the offryng of brent sacrifices of the Lord, as in sabatis, and kalendis, and othere solempnytees, bi the noumbre and cerymonyes of eche thing contynueli bifor the Lord;
32 Bẹ́ẹ̀ ni nígbà náà, àwọn ọmọ Lefi gbé ìgbékalẹ̀ jáde fún ìpàdé àgọ́, fún Ibi Mímọ́ àti, lábẹ́ àwọn arákùnrin àwọn ọmọ Aaroni fún ìsìn ilé Olúwa.
and that thei kepe the obseruaunces of the tabernacle of the boond of pees of the Lord, and the custum of the seyntuarie, and the obseruaunce of the sones of Aaron, her britheren, that thei mynystre in the hows of the Lord.

< 1 Chronicles 23 >