< 1 Chronicles 23 >

1 Nígbà tí Dafidi sì dàgbà, tí ó sì di arúgbó, ó sì fi Solomoni ọmọ rẹ̀ jẹ ọba lórí Israẹli.
David te patong coeng tih khohnin khaw cum coeng. Te dongah a capa Solomon te Israel soah a manghai sak.
2 Ó sì kó gbogbo àgbàgbà Israẹli jọ, àti gẹ́gẹ́ bí àwọn àlùfáà àti àwọn ará Lefi.
Te phoeiah Israel mangpa boeih neh khosoih rhoek khaw, Levi rhoek khaw a coi.
3 Àwọn ọmọ Lefi láti ọgbọ̀n ọdún tàbí jù bẹ́ẹ̀ lọ ni wọ́n kà àpapọ̀ iye àwọn ọkùnrin wọn sì jẹ́ ẹgbàá mọ́kàndínlógún.
Te vaengah Levi rhoek te tongpa kum sawmthum lamloh a so hang te a tae tih amih kah hlangmi te a pum la hlang thawng sawmthum neh thawng rhet om.
4 Dafidi sì wí pe, ní ti èyí, ẹgbàá méjìlá ni kí wọn jẹ́ alábojútó iṣẹ́ ilé fún Olúwa àti ẹgbẹ̀rún mẹ́fà ni kí ó ṣe olórí àti onídàájọ́.
Te rhoek khuiah BOEIPA im kah bitat aka mawt te thawng kul thawng li om tih rhoiboei rhoek neh laitloek rhoek he thawng rhuk om.
5 Ẹgbàajì ni kí ó jẹ́ olùtọ́jú ẹnu-ọ̀nà àti ẹgbàajì ni kí o sì jẹ́ ẹni ti yóò máa yin Olúwa pẹ̀lú ohun èlò orin, mo ti ṣe èyí fún ìdí pàtàkì yìí.
Thoh tawt rhoek te thawng li, thangthen ham ka saii bangla tumbael neh BOEIPA aka thangthen te thawng li lo.
6 Dafidi sì pín àwọn ọmọ Lefi sí ẹgbẹgbẹ́ láàrín àwọn ọmọ Lefi: Gerṣoni, Kohati àti Merari.
David loh amih te boelnah neh a tael. Gershon kah Levi koca rhoek ah Kohath neh Merari.
7 Àwọn tí ó jẹ́ ọmọ Gerṣoni: Laadani àti Ṣimei.
Gershon lamloh Ladan neh Shimei.
8 Àwọn ọmọ Laadani Jehieli ẹni àkọ́kọ́, Setamu àti Joẹli, mẹ́ta ní gbogbo wọn.
Ladan koca ah a lucuek te Jehiel tih Zetham neh a pathum te Joel.
9 Àwọn ọmọ Ṣimei: Ṣelomiti, Hasieli àti Harani mẹ́ta ní gbogbo wọn. Àwọn wọ̀nyí sì ni olórí àwọn ìdílé Laadani.
Shimei koca rhoek Shelmoth neh Haziel, Haran neh pathum lo. Te rhoek te Ladan napa rhoek khuiah a lu la om uh.
10 Àti ọmọ Ṣimei: Jahati, Sina, Jeuṣi àti Beriah. Àwọn wọ̀nyí ni ọmọ Ṣimei mẹ́rin ni gbogbo wọn.
Shimei koca rhoek ah Jahath, Zina, Jeush neh Beriah. He rhoek pali he Shimei koca rhoek ni.
11 Jahati sì ni alákọ́kọ́ Sinah sì ni ẹlẹ́ẹ̀kejì, ṣùgbọ́n Jeuṣi àti Beriah kò ní àwọn ọmọ púpọ̀; bẹ́ẹ̀ ni wọ́n sì ka ara wọn sí ìdílé kan pẹ̀lú ìfilé lọ́wọ́ kan.
Jahath te a lucuek tih Zizah he a pabae la om. Tedae Jeush neh Beriah tah a ca ping pawh. Te dongah napa pakhat imkhui pakhat bangla cawhkung pakhat la om uh.
12 Àwọn ọmọ Kohati: Amramu, Isari, Hebroni àti Usieli mẹ́rin ni gbogbo wọn.
Kohath koca rhoek la Amram, Izhar, Hebron, Uzziel neh pali lo.
13 Àwọn ọmọ Amramu. Aaroni àti Mose. A sì ya Aaroni sọ́tọ̀ òun àti àwọn ọmọ rẹ̀ títí láéláé, láti kọjú sí ohun mímọ́ jùlọ, láti fi rú ẹbọ sísun níwájú Olúwa, láti máa ṣe òjíṣẹ́ níwájú rẹ̀ àti láti kéde ìbùkún ní orúkọ rẹ̀ títí láéláé.
Amram koca ah Aaron neh Moses dae, Aaron tah amah loh a cim kah a cim koek la ciim ham, anih neh anih koca rhoek tah kumhal hil BOEIPA mikhmuh ah aka phum uh la, a taengah aka thotat la, a ming neh kumhal hil aka uem la a hoep.
14 Àwọn ọmọ Mose ènìyàn Ọlọ́run ni wọ́n kà gẹ́gẹ́ bí apá kan ẹ̀yà Lefi.
Pathen kah hlang Moses neh anih koca rhoek te Levi koca la a khue uh.
15 Àwọn ọmọ Mose: Gerṣomu àti Elieseri.
Moses koca ah Gershom neh Eliezer.
16 Àwọn ọmọ Gerṣomu: Ṣubaeli sì ni alákọ́kọ́.
Gershom koca kah boeilu tah Shubael.
17 Àwọn ọmọ Elieseri: Rehabiah sì ni ẹni àkọ́kọ́. Elieseri kò sì tún ní ọmọ mìíràn, ṣùgbọ́n àwọn ọmọ Rehabiah wọ́n sì pọ̀ níye.
Eliezer koca aka om rhoek khuiah Rehabiah he boeilu dae Eliezer te ca a tloe om pawh. Tedae Rehabiah koca rhoek tah a pueh la ping uh.
18 Àwọn ọmọ Isari: Ṣelomiti sì ni ẹni àkọ́kọ́.
Izhar koca khuiah Shelomith he boeilu la om.
19 Àwọn ọmọ Hebroni: Jeriah sì ni ẹni àkọ́kọ́, Amariah sì ni ẹni ẹ̀ẹ̀kejì, Jahasieli sì ni ẹ̀ẹ̀kẹ́ta àti Jekameamu ẹ̀ẹ̀kẹrin.
Hebron koca ah Jeriah te a cacuek, Amariah te a pabae, Jahaziel a pathum, Jekameam tah a pali.
20 Àwọn ọmọ Usieli: Mika ni àkọ́kọ́ àti Iṣiah ẹ̀ẹ̀kejì.
Uzziel koca rhoek ah Maikah te a cacuek tih Isshiah te a pabae.
21 Àwọn ọmọ Merari: Mahili àti Muṣi. Àwọn ọmọ Mahili: Eleasari àti Kiṣi.
Merari koca ah Mahli neh Mushi, Mahli koca ah Eleazar neh Kish.
22 Eleasari sì kú pẹ̀lú àìní àwọn ọmọkùnrin: Ó ní ọmọbìnrin nìkan. Àwọn ọmọ ẹ̀gbọ́n, àwọn ọmọ Kiṣi, sì fẹ́ wọn.
Eleazar a duek vaengah he a taengah ca tongpa a om moenih. Tedae ca huta rhoek bueng om tih amih te a manuca Kish koca rhoek loh a loh uh.
23 Àwọn ọmọ Muṣi: Mahili, Ederi àti Jerimoti mẹ́ta ni gbogbo wọn.
Mushi koca rhoek la Mahli, Eder, Jerimoth neh pathum lo.
24 Àwọn wọ̀nyí sì ni ọmọ Lefi bí ìdílé wọn. Olórí ìdílé gẹ́gẹ́ bí wọ́n ti fi orúkọ sílẹ̀ lábẹ́ orúkọ wọn, ó sì kà wọn ní ẹyọ kọ̀ọ̀kan, wí pé, àwọn òṣìṣẹ́ tí ó jẹ́ ogún ọdún tàbí jù bẹ́ẹ̀ lọ tí ń ṣiṣẹ́ ìsìn nínú ilé Olúwa.
He rhoek tah Levi koca rhoek kah a napa rhoek imkhui lamloh a napa boeilu rhoek ni. Tongpa kum kul neh a so hang lamloh BOEIPA im kah thothuengnah ham bitat a saii uh. Amih te a hlangmi neh a ming tarhing la a soep uh.
25 Nítorí pé Dafidi ti sọ pé, “Níwọ̀n ìgbà tí Olúwa Ọlọ́run Israẹli, ti fi ìsinmi fún àwọn ènìyàn tí ó kù tí sì ń gbé Jerusalẹmu títí láéláé,
David loh, “Israel Pathen BOEIPA loh a pilnam te a duem sak tih Jerusalem ah kumhal due kho a sak.
26 àwọn ọmọ Lefi kò sì tún ru àgọ́ tàbí ọ̀kankan lára àwọn ohun èlò tí wọ́n ń lò níbi ìsìn rẹ̀.”
Levi te khaw dungtlungim neh a thothuengnah dongkah a hnopai boeih te a koh ham moenih,” a ti.
27 Gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ ìkẹyìn Dafidi sí, àwọn ọmọ Lefi, wọ́n sì kà wọ́n, bẹ̀rẹ̀ láti orí àwọn ọmọ ogún ọdún tàbí jù bẹ́ẹ̀ lọ.
David kah hnukkhueng ol dongkah bangla amih Levi koca rhoek kah hlangmi tah tongpa kum kul neh a so hang lamkah ni a tae.
28 Iṣẹ́ àwọn ọmọ Lefi ni láti ran àwọn ọmọ Aaroni lọ́wọ́ nínú iṣẹ́ wọn fún ti ilé Olúwa: láti wà lábẹ́ ìkáwọ́ agbára ìlú, àti ẹ̀gbẹ́ ilé, àti ìwẹ̀nùmọ́ ti gbogbo ohun ìyàsọ́tọ̀ àti ṣíṣe ohun tí í ṣe iṣẹ́ ìsìn nínú ilé Olúwa.
Amih kah ngolhmuen ngawn tah BOEIPA im kah thothuengnah khuiah khaw, vongup ah khaw, imkhui ah khaw, hmuencim boeih kah ciimnah dongah khaw, Pathen im thothuengnah bibi dongah khaw Aaron koca rhoek kah a kut a kho la om uh.
29 Wọ́n sì wà ní ìkáwọ́ àkàrà tí wọ́n mú jáde láti orí tábìlì, àti ìyẹ̀fun fún ẹbọ, àti àkàrà aláìwú, àti fún púpọ̀ àti èyí tí a pòpọ̀, àti gbogbo onírúurú ìwọ̀n àti wíwọ̀n àti òsùwọ̀n.
Rhungkung buh dongah khaw, khocang vaidam dongah khaw, vaidamding vaidamrhawm dongah khaw, thiphael dongah khaw, a kae dongah khaw, khoe neh cungnueh boeih dongah khaw om uh.
30 Wọ́n sì gbọdọ̀ dúró ní gbogbo òwúrọ̀ láti dúpẹ́ àti láti yin Olúwa. Wọ́n sì gbọdọ̀ ṣe irú kan náà ní àṣálẹ́.
Mincang, mincang ah pai tih BOEIPA aka uem ham neh aka thangthen hamla, hlaem ah khaw te tlam te aka thangthen la om uh.
31 Àti láti rú ẹbọ sísun fún Olúwa ní ọjọ́ ìsinmi àti ní àsìkò oṣù tuntun àti ní àjọ̀dún tí a yàn. Wọ́n gbọdọ̀ sìn níwájú Olúwa lójoojúmọ́ ní iye tó yẹ àti ní ọ̀nà tí a ti pàṣẹ fún wọn.
A cungkuem dongah BOEIPA taengkah hmueihhlutnah te Sabbath ah khaw, Hlasae ah khaw, tingtunnah dongah BOEIPA mikhmuh kah laitloeknah bangla a tarhing neh phat a khuen uh.
32 Bẹ́ẹ̀ ni nígbà náà, àwọn ọmọ Lefi gbé ìgbékalẹ̀ jáde fún ìpàdé àgọ́, fún Ibi Mímọ́ àti, lábẹ́ àwọn arákùnrin àwọn ọmọ Aaroni fún ìsìn ilé Olúwa.
Te dongah tingtunnah dap kah a kuek neh hmuencim kah a kuek khaw, BOEIPA im kah thothuengnah dongkah a manuca Aaron koca rhoek kah a kuek khaw a ngaithuen uh.

< 1 Chronicles 23 >