< 1 Chronicles 21 >
1 Satani sì dúró ti Israẹli, ó sì ti Dafidi láti ka iye Israẹli.
Ale szatan powstał przeciw Izraelowi a pobudził Dawida, aby policzył Izraela.
2 Bẹ́ẹ̀ ni Dafidi sì wí fún Joabu àti àwọn olórí àwọn ènìyàn pé, “Lọ kí o ka iye àwọn ọmọ Israẹli láti Beerṣeba títí dé Dani. Kí o sì padà mú iye wọn fún mi wa, kí èmi kí ó le mọ iye tí wọ́n jẹ́.”
Przetoż rzekł Dawid do Joaba i do przełożonych nad ludem: Idźcie, obliczcie Izraela od Beerseba aż do Dan, a odnieście do mnie, żebym wiedział poczet ich.
3 Ṣùgbọ́n Joabu dá a lóhùn pé, “Kí Olúwa kí ó mú àwọn ènìyàn rẹ̀ pọ̀ sí ní ìgbà ọgọ́rùn-ún ju ti tẹ́lẹ̀ lọ, ọba olúwa mi, gbogbo wọn kì í ha ṣe ìránṣẹ́ olúwa ni? Kí ni ó dé tí olúwa mi ṣe fẹ́ ṣè yìí? Kí ni ó de tí yóò fi mú ẹ̀bi wá sórí Israẹli?”
Ale rzekł Joab: Niech przymnoży Pan ludu swego, jako teraz jest, tyle sto kroć; izali królu, panie mój! nie są wszyscy oni sługami pana mego? Przeczże się tego dowiaduje pan mój? Przeczżeby to miało być na upadek Izraelowi?
4 Ṣùgbọ́n ọ̀rọ̀ ọba borí tí Joabu. Bẹ́ẹ̀ ni Joabu jáde lọ, ó sì la gbogbo Israẹli já, ó sí dé Jerusalẹmu.
Wszakże słowo królewskie przemogło Joaba; przetoż wyszedł Joab, a obszedłszy wszystkiego Izraela, wrócił się potem do Jeruzalem.
5 Joabu sì fi àpapọ̀ iye àwọn ènìyàn náà fún Dafidi. Ní gbogbo Israẹli, ó sì jẹ́ ẹgbẹ̀rún ẹgbẹ̀rún àti ọ̀kẹ́ márùn-ún ènìyàn tí ń kọ́ idà, Juda sì jẹ́ ọ̀kẹ́ mẹ́tàlélógún lé ẹgbàárùn-ún ọkùnrin tí ń kọ́ idà.
I oddał Joab poczet porachowanego ludu Dawidowi. A było wszystkiego Izraela tysiąc tysięcy i sto tysięcy, mężów godnych ku bojowi; a z Judy było cztery kroć sto tysięcy, i siedmdziesięt tysięcy mężów walecznych.
6 Ṣùgbọ́n Joabu kó àwọn Lefi àti Benjamini mọ́ iye wọn, nítorí àṣẹ ọba jẹ́ ìríra fún un.
Lecz Lwitów i Benjamitów nie policzył między nich, gdyż przykre było rozkazanie królewskie Joabowi.
7 Àṣẹ yìí pẹ̀lú sì jẹ́ búburú lójú Ọlọ́run, bẹ́ẹ̀ ni ó sì díyàjẹ Israẹli.
Owszem nie podobała się Bogu ta rzecz; przetoż pokarał Izraela.
8 Nígbà náà Dafidi sọ fún Ọlọ́run pé, èmi ti dẹ́ṣẹ̀ gidigidi nípa ṣíṣe èyí. Nísinsin yìí, èmi bẹ̀ ọ́, mú ìjẹ̀bi àwọn ìránṣẹ́ rẹ kúrò. Èmi ti hùwà aṣiwèrè gidigidi.
I rzekł Dawid do Boga: Zgrzeszyłem bardzo, żem to uczynił; ale teraz oddal, proszę, nieprawość sługi twego; bom bardzo głupio uczynił.
9 Olúwa sì fi fún Gadi, aríran Dafidi pé.
Zatem rzekł Pan do Gada, proroka Dawidowego, mówiąc:
10 “Lọ kí o sì wí fún Dafidi pé, ‘Báyìí ni Olúwa wí, èmi fi nǹkan mẹ́ta lọ̀ ọ́; yan ọ̀kan nínú wọn, kí èmi ó sì ṣe é sí ọ.’”
Idź, powiedz Dawidowi, a rzecz: Tak mówi Pan: Trzyć rzeczy podaję; obierz sobie jednę z nich, abym ci czynił.
11 Bẹ́ẹ̀ ni Gadi tọ Dafidi wá, ó sì wí fún un pé, “Báyìí ni Olúwa wí: ‘Yan fún ara rẹ.
Tedy przyszedł Gad do Dawida, i rzekł mu: Tak mówi Pan: Obierz sobie:
12 Ọdún mẹ́ta ìyàn, tàbí ìparun ní oṣù mẹ́ta níwájú àwọn ọ̀tá rẹ, pẹ̀lú idà wọn láti lé ọ bá, tàbí ọjọ́ mẹ́ta idà Olúwa ọjọ́ àjàkálẹ̀-ààrùn ní ilẹ̀ náà, pẹ̀lú àwọn angẹli Olúwa láti pa gbogbo agbègbè Israẹli run.’ Nísinsin yìí ǹjẹ́, rò ó wò, èsì wo ni èmi yóò mú padà tọ ẹni tí ó rán mi.”
Albo przez trzy lata głód, albo żebyś przez trzy miesiące ginął od nieprzyjaciół twych, a miecz nieprzyjaciół twoich żeby cię ścigał, albo żeby przez trzy dni miecz Pański i mor był w ziemi, a Anioł Pański żeby niszczył wszystkie granice Izraelskie. Przetoż teraz uważ, co mam odpowiedzieć temu, który mię posłał.
13 Dafidi sì wí fún Gadi pé, “Ìyọnu ńlá bá mi. Jẹ́ kí èmi kí ó ṣubú sí ọwọ́ Olúwa nísinsin yìí, nítorí tí àánú rẹ̀ pọ̀ gidigidi, ṣùgbọ́n má ṣe jẹ́ kí èmi kí o ṣubú sí ọwọ́ àwọn ènìyàn.”
I rzekł Dawid do Gada: Bardzom ściśniony; niech wpadnę, proszę, w ręce Pańskie, gdyż bardzo wielkie są zlitowania jego, a w ręce ludzkie niechaj nie wpadam.
14 Bẹ́ẹ̀ ni Olúwa rán àjàkálẹ̀-ààrùn lórí Israẹli, àwọn tí ó ṣubú ní Israẹli jẹ́ ẹgbẹ̀rún ní ọ̀nà àádọ́rin ènìyàn.
Tedy przepuścił Pan powietrze morowe na Izraela. I poległo z Izraela siedmdziesiąt tysięcy mężów.
15 Ọlọ́run sì rán angẹli kan sí Jerusalẹmu láti pa wọ́n run. Ṣùgbọ́n bí angẹli ti ń pa wọ́n run, Olúwa sì wò. Ó sì káàánú nítorí ibi náà, ó sì wí fún angẹli tí ó pa àwọn ènìyàn náà run pé, “Ó ti tó! Dá ọwọ́ rẹ dúró.” Angẹli Olúwa náà sì dúró níbi ilẹ̀ ìpakà Arauna ará Jebusi.
Posłał też Bóg Anioła do Jeruzalemu, aby ich tracił. A gdy ich tracił, ujrzał Pan, i użalił się nad tem złem, i rzekł Aniołowi tracącemu: Dosyć już, zawściągnij rękę twą. A Anioł Pański stał podle bojewiska Ornana Jebuzejczyka.
16 Dafidi sì wòkè ó sì rí angẹli Olúwa dúró láàrín ọ̀run àti ayé pẹ̀lú idà fífàyọ ní ọwọ́ rẹ̀ tí ó sì nà án sórí Jerusalẹmu. Nígbà náà Dafidi àti àwọn àgbàgbà, sì wọ aṣọ ọ̀fọ̀, wọ́n sì da ojú wọn bolẹ̀.
Wtem podniósłszy Dawid oczy swe ujrzał Anioła Pańskiego, który stał między ziemią i między niebem, a w ręce jego miecz jego dobyty, wyciągniony przeciw Jeruzalemowi. I upadł Dawid i starsi, oblekłszy się w wory, na twarze swoje.
17 Dafidi sì wí fún Ọlọ́run pé, “Èmi ha kọ́ ni mo pàṣẹ àti ka àwọn jagunjagun ènìyàn? Èmi ni ẹni náà tí ó dẹ́ṣẹ̀ tí ó sì ṣe ohun búburú pàápàá, ṣùgbọ́n bí ó ṣe ti àgùntàn wọ̀nyí, kí ni wọ́n ṣe? Èmí bẹ̀ ọ́ Olúwa Ọlọ́run mi, jẹ́ kí ọwọ́ rẹ kí ó wà lára mi àti àwọn ìdílé baba mi, ṣùgbọ́n má ṣe jẹ́ kí àjàkálẹ̀-ààrùn yìí kí ó dúró lórí àwọn ènìyàn rẹ.”
Zatem rzekł Dawid do Boga: Izalim nie ja rozkazał liczyć ludu? Jamci jest sam, którym zgrzeszył, i bardzo źle uczynił; ale te owce cóż uczyniły? Panie, Boże mój! niech się obróci, proszę, ręka twoja na mię i na dom ojca mego; ale przeciwko ludowi twemu niech się nie sroży ta plaga.
18 Nígbà náà angẹli Olúwa náà pàṣẹ fún Gadi láti sọ fún Dafidi pé, kí Dafidi kí ó gòkè lọ, kí ó sì tẹ́ pẹpẹ kan fún Olúwa lórí ilẹ̀ ìpakà Arauna ará Jebusi.
Zatem Anioł Pański rzekł do Gada, aby mówił Dawidowi, żeby szedł i zbudował ołtarz Panu na bojewisku Ornana Jebuzejczyka.
19 Bẹ́ẹ̀ ni Dafidi sì gòkè lọ pẹ̀lú ìgbọ́ràn sí ọ̀rọ̀ tí Gadi ti sọ ní orúkọ Olúwa.
A tak szedł Dawid według słowa Gadowego, które mówił imieniem Pańskiem.
20 Nígbà tí Arauna sì ń pakà lọ́wọ́, ó sì yípadà ó sì rí angẹli; àwọn ọmọ rẹ̀ mẹ́rẹ̀ẹ̀rin tí ó wà pẹ̀lú rẹ̀ pa ará wọn mọ́.
Tedy obejrzawszy się Ornan ujrzał onego Anioła; a czterej synowie jego, którzy byli z nim, skryli się; a Ornan młócił pszenicę.
21 Bí Dafidi sì ti dé ọ̀dọ̀ Arauna, Arauna sì wò, ó sì rí Dafidi, ó sì ti ibi ilẹ̀ ìpakà rẹ̀ jáde, ó sì wólẹ̀, ó dojúbolẹ̀ níwájú Dafidi.
Wtem przyszedł Dawid do Ornana; a spojrzawszy Ornan obaczył Dawida, i wyszedłszy z bojewiska, pokłonił się Dawidowi twarzą do ziemi.
22 Dafidi sì wí fún Arauna pé, “Jẹ́ kí èmi kí ó ni ibi ìpakà rẹ kí èmi kí ó sì lè tẹ́ pẹpẹ kan níbẹ̀ fún Olúwa, ìwọ ó sì fi fún mi ni iye owó rẹ̀ pípé, kí a lè dá àjàkálẹ̀-ààrùn dúró lọ́dọ̀ àwọn ènìyàn.”
I rzekł Dawid do Ornana: Daj mi plac tego bojewiska, abym zbudował na nim ołtarz Panu; za słuszne pieniądze spuść mi je, a będzie odwrócona ta plaga od ludu.
23 Arauna sì wí fún Dafidi pé, “Mú un fún ara rẹ, sì jẹ́ kí olúwa mi ọba kí ó ṣe ohun tí ó dára lójú rẹ̀. Wò ó, èmí yóò fún ọ ní àwọn màlúù fún ẹbọ sísun, àti ohun èlò ìpakà fún igi, àti ọkà fún ọrẹ oúnjẹ. Èmi yóò fun ọ ní gbogbo èyí.”
I rzekł Ornan do Dawida: Weźmij je sobie, a niech uczyni król, pan mój, co mu się dobrego widzi; otoć przydaję i woły na całopalenia, i wóz na drwa, i pszenicę na ofiarę śniedną: toć to wszystko daję.
24 Ṣùgbọ́n ọba Dafidi dá Arauna lóhùn pé, “Bẹ́ẹ̀ kọ́, ṣùgbọ́n èmi yóò rà á ní iye owó rẹ̀ ní pípé, nítorí èmi kì yóò èyí tí ó jẹ́ tìrẹ fún Olúwa, tàbí láti rú ẹbọ sísun tí kò ná mi ní ohun kan.”
I rzekł król Dawid do Ornana: Nie tak, ale raczej kupię za słuszne pieniądze; bo nie wezmę co twego jest, ani będę ofiarował Panu całopalenia darowanego.
25 Bẹ́ẹ̀ ni Dafidi san ẹgbẹ̀ta ṣékélì wúrà fún Arauna nípa ìwọ̀n fún ibẹ̀ náà.
A tak Dawid dał Ornanowi za on plac sześć syklów złota dobrej wagi.
26 Dafidi sì tẹ́ pẹpẹ fún Olúwa níbẹ̀ ó sì rú ẹbọ sísun àti ẹbọ ọpẹ́. Ó sì ké pe Olúwa, Olúwa sì fi iná dá a lóhùn láti òkè ọ̀run wá lórí pẹpẹ fún ẹbọ ọrẹ sísun.
I zbudował tam Dawid ołtarz Panu, a ofiarował całopalenia i ofiary spokojne, i wzywał Pana, który go wysłuchał, spuściwszy ogień z nieba na ołtarz całopalenia.
27 Nígbà náà Olúwa sọ̀rọ̀ sí angẹli, ó sì gbé idà padà bọ̀ sínú àkọ̀ rẹ̀.
I rzekł Pan do Anioła, aby obrócił miecz swój w pochwy swoje.
28 Ní àkókò náà nígbà tí Dafidi sì rí wí pé Olúwa ti dá a lóhùn lórí ilẹ̀ ìpakà ti Arauna ará Jebusi, ó sì rú ẹbọ sísun níbẹ̀.
Onego czasu widząc Dawid, iż go wysłuchał Pan na bojewisku Ornana Jebuzejczyka, ofiarował tam ofiary.
29 Àgọ́ Olúwa tí Mose ti ṣe ní aginjù, àti pẹpẹ ẹbọ sísun wà lórí ibi gíga ní Gibeoni ní àkókò náà.
Albowiem przybytek Pański, który uczynił Mojżesz na puszczy, i ołtarz całopalenia, naonczas był na wyżynie w Gabaonie.
30 Ṣùgbọ́n Dafidi kò lè lọ síwájú rẹ̀ láti béèrè lọ́wọ́ Ọlọ́run, nítorí tí ó bẹ̀rù nípa idà ọwọ́ angẹli Olúwa.
A nie mógł Dawid iść do niego, aby się radził Boga; bo przestraszony był mieczem Anioła Pańskiego.