< 1 Chronicles 21 >

1 Satani sì dúró ti Israẹli, ó sì ti Dafidi láti ka iye Israẹli.
Satan el tuh lungse elan aklokoalokye mwet Israel, na pa el oru tuh David elan nunkeak elan oakla pisen mwet uh.
2 Bẹ́ẹ̀ ni Dafidi sì wí fún Joabu àti àwọn olórí àwọn ènìyàn pé, “Lọ kí o ka iye àwọn ọmọ Israẹli láti Beerṣeba títí dé Dani. Kí o sì padà mú iye wọn fún mi wa, kí èmi kí ó le mọ iye tí wọ́n jẹ́.”
David el sapkin nu sel Joab ac mwet pwapa lal saya, “Kowos fahla ac sasla nu in facl Israel nufon, mutawauk e epang me oatula safla eir, ac oakla pisen mwet uh. Nga lungse etu lah elos mwet ekasr nufon.”
3 Ṣùgbọ́n Joabu dá a lóhùn pé, “Kí Olúwa kí ó mú àwọn ènìyàn rẹ̀ pọ̀ sí ní ìgbà ọgọ́rùn-ún ju ti tẹ́lẹ̀ lọ, ọba olúwa mi, gbogbo wọn kì í ha ṣe ìránṣẹ́ olúwa ni? Kí ni ó dé tí olúwa mi ṣe fẹ́ ṣè yìí? Kí ni ó de tí yóò fi mú ẹ̀bi wá sórí Israẹli?”
Na Joab el fahk, “Finsrak LEUM GOD Elan oru tuh mwet Israel in puseni pacl siofok liki pisalos misenge! Leum Fulat, elos nukewa mwet kulansap lom. Na efu ku kom lungsum in oru ma se inge, ac sang mwatan mutunfacl se inge nufon?”
4 Ṣùgbọ́n ọ̀rọ̀ ọba borí tí Joabu. Bẹ́ẹ̀ ni Joabu jáde lọ, ó sì la gbogbo Israẹli já, ó sí dé Jerusalẹmu.
Tusruktu, nunak lal tokosra ku lukel Joab, pwanang Joab el illa ac fahsr sasla in facl Israel nufon, na el folok nu Jerusalem.
5 Joabu sì fi àpapọ̀ iye àwọn ènìyàn náà fún Dafidi. Ní gbogbo Israẹli, ó sì jẹ́ ẹgbẹ̀rún ẹgbẹ̀rún àti ọ̀kẹ́ márùn-ún ènìyàn tí ń kọ́ idà, Juda sì jẹ́ ọ̀kẹ́ mẹ́tàlélógún lé ẹgbàárùn-ún ọkùnrin tí ń kọ́ idà.
El fahkak nu sel Tokosra David pisen mukul nukewa ma fal in wi mweun: oasr sie million siofok tausin mwet Israel, ac mwet angfoko itngoul tausin mwet Judah.
6 Ṣùgbọ́n Joabu kó àwọn Lefi àti Benjamini mọ́ iye wọn, nítorí àṣẹ ọba jẹ́ ìríra fún un.
Ke sripen Joab el tiana insese nu ke sap se lal tokosra inge, el tiana oakla mwet in sruf lal Levi ac Benjamin.
7 Àṣẹ yìí pẹ̀lú sì jẹ́ búburú lójú Ọlọ́run, bẹ́ẹ̀ ni ó sì díyàjẹ Israẹli.
God El tia insewowo ke ma orek inge, na pa El sang kai upa nu fin mwet Israel.
8 Nígbà náà Dafidi sọ fún Ọlọ́run pé, èmi ti dẹ́ṣẹ̀ gidigidi nípa ṣíṣe èyí. Nísinsin yìí, èmi bẹ̀ ọ́, mú ìjẹ̀bi àwọn ìránṣẹ́ rẹ kúrò. Èmi ti hùwà aṣiwèrè gidigidi.
Ac David el fahk nu sin God, “Nga orala ma koluk na yohk se. Nunak munas, sisla koluk luk. Ma na lalfon se pa nga orala.”
9 Olúwa sì fi fún Gadi, aríran Dafidi pé.
Na LEUM GOD El fahk nu sel Gad, mwet palu lal David,
10 “Lọ kí o sì wí fún Dafidi pé, ‘Báyìí ni Olúwa wí, èmi fi nǹkan mẹ́ta lọ̀ ọ́; yan ọ̀kan nínú wọn, kí èmi ó sì ṣe é sí ọ.’”
“Fahla fahk nu sel David lah nga fah sang nu sel ke mwe sulela tolu, ac el enenu in sulela sie. Nga ac fah oru ma se ma el ac sulela an.”
11 Bẹ́ẹ̀ ni Gadi tọ Dafidi wá, ó sì wí fún un pé, “Báyìí ni Olúwa wí: ‘Yan fún ara rẹ.
Gad el som ac fahk nu sel David ma LEUM GOD El fahk, na el siyuk sel, “Ma ya kac kom lungse uh?
12 Ọdún mẹ́ta ìyàn, tàbí ìparun ní oṣù mẹ́ta níwájú àwọn ọ̀tá rẹ, pẹ̀lú idà wọn láti lé ọ bá, tàbí ọjọ́ mẹ́ta idà Olúwa ọjọ́ àjàkálẹ̀-ààrùn ní ilẹ̀ náà, pẹ̀lú àwọn angẹli Olúwa láti pa gbogbo agbègbè Israẹli run.’ Nísinsin yìí ǹjẹ́, rò ó wò, èsì wo ni èmi yóò mú padà tọ ẹni tí ó rán mi.”
In oasr sracl fin facl sum ke yac tolu? Ku kom in kaing liki un mwet mweun lun mwet lokoalok lom ke malem tolu? Ku LEUM GOD Elan mweuni kom ke cutlass natul ac supwama mas upa, ac sie lipufan in use misa nu fin acn Israel nufon ke len tolu? Mea nga ac fahk in topuk LEUM GOD?”
13 Dafidi sì wí fún Gadi pé, “Ìyọnu ńlá bá mi. Jẹ́ kí èmi kí ó ṣubú sí ọwọ́ Olúwa nísinsin yìí, nítorí tí àánú rẹ̀ pọ̀ gidigidi, ṣùgbọ́n má ṣe jẹ́ kí èmi kí o ṣubú sí ọwọ́ àwọn ènìyàn.”
Na David el fahk nu sel Gad, “Nga arulana fohsak ac nikinyula! Tusruktu nga tia lungse ngan kalyeiyuk sin mwet uh. Lela in LEUM GOD na pa orek kaiyuk nu sesr, tuh El pakoten.”
14 Bẹ́ẹ̀ ni Olúwa rán àjàkálẹ̀-ààrùn lórí Israẹli, àwọn tí ó ṣubú ní Israẹli jẹ́ ẹgbẹ̀rún ní ọ̀nà àádọ́rin ènìyàn.
Na LEUM GOD El supwala mas na upa se nu fin mwet Israel, ac mwet itngoul tausin selos misa.
15 Ọlọ́run sì rán angẹli kan sí Jerusalẹmu láti pa wọ́n run. Ṣùgbọ́n bí angẹli ti ń pa wọ́n run, Olúwa sì wò. Ó sì káàánú nítorí ibi náà, ó sì wí fún angẹli tí ó pa àwọn ènìyàn náà run pé, “Ó ti tó! Dá ọwọ́ rẹ dúró.” Angẹli Olúwa náà sì dúró níbi ilẹ̀ ìpakà Arauna ará Jebusi.
Na El supwala sie lipufan in kunausla acn Jerusalem, tusruktu El sifil ekulla nunak lal ac fahk nu sin lipufan sac, “Tui! Tari fal!” Lipufan sac el tuyak ke acn in kulkul wheat lal Araunah, mwet Jebus.
16 Dafidi sì wòkè ó sì rí angẹli Olúwa dúró láàrín ọ̀run àti ayé pẹ̀lú idà fífàyọ ní ọwọ́ rẹ̀ tí ó sì nà án sórí Jerusalẹmu. Nígbà náà Dafidi àti àwọn àgbàgbà, sì wọ aṣọ ọ̀fọ̀, wọ́n sì da ojú wọn bolẹ̀.
David el liye lipufan sac ke el tu yen engyeng uh ac el sruok cutlass natul inpaol ac akola in kunausla acn Jerusalem. David ac mwet kol lun mwet Israel elos nokomang nuknuk in eoksra, ac elos srimi nwe ten ac mutalos pusral fin fohk uh.
17 Dafidi sì wí fún Ọlọ́run pé, “Èmi ha kọ́ ni mo pàṣẹ àti ka àwọn jagunjagun ènìyàn? Èmi ni ẹni náà tí ó dẹ́ṣẹ̀ tí ó sì ṣe ohun búburú pàápàá, ṣùgbọ́n bí ó ṣe ti àgùntàn wọ̀nyí, kí ni wọ́n ṣe? Èmí bẹ̀ ọ́ Olúwa Ọlọ́run mi, jẹ́ kí ọwọ́ rẹ kí ó wà lára mi àti àwọn ìdílé baba mi, ṣùgbọ́n má ṣe jẹ́ kí àjàkálẹ̀-ààrùn yìí kí ó dúró lórí àwọn ènìyàn rẹ.”
Ac David el pre ac fahk, “O God, nga pa oru ma koluk se inge. Nga pa sapkin in oaoala mwet uh. Mea mwet inge orala? LEUM GOD luk, fal kom in kaiyu ac sou luk, ac fuhlela mwet lom inge.”
18 Nígbà náà angẹli Olúwa náà pàṣẹ fún Gadi láti sọ fún Dafidi pé, kí Dafidi kí ó gòkè lọ, kí ó sì tẹ́ pẹpẹ kan fún Olúwa lórí ilẹ̀ ìpakà Arauna ará Jebusi.
Na lipufan lun LEUM GOD el fahk nu sel Gad elan sapkin nu sel David tuh elan som ac etoak sie loang in acn in kulkul wheat lal Araunah.
19 Bẹ́ẹ̀ ni Dafidi sì gòkè lọ pẹ̀lú ìgbọ́ràn sí ọ̀rọ̀ tí Gadi ti sọ ní orúkọ Olúwa.
David el akos sap lun LEUM GOD ac som, oana ma Gad el tuh fahk nu sel.
20 Nígbà tí Arauna sì ń pakà lọ́wọ́, ó sì yípadà ó sì rí angẹli; àwọn ọmọ rẹ̀ mẹ́rẹ̀ẹ̀rin tí ó wà pẹ̀lú rẹ̀ pa ará wọn mọ́.
Ke nien kulkul wheat ah, Araunah ac wen akosr natul elos muta kulkul wheat. Ke elos liye lipufan sac, wen ekasr ah kaing ac wikla.
21 Bí Dafidi sì ti dé ọ̀dọ̀ Arauna, Arauna sì wò, ó sì rí Dafidi, ó sì ti ibi ilẹ̀ ìpakà rẹ̀ jáde, ó sì wólẹ̀, ó dojúbolẹ̀ níwájú Dafidi.
Ke pacl se Araunah el liyalak Tokosra David ke el fahsru ac apkuranme, el som liki nien kulkul wheat uh, ac srimi nwe ten ac mutal pusral infohk uh.
22 Dafidi sì wí fún Arauna pé, “Jẹ́ kí èmi kí ó ni ibi ìpakà rẹ kí èmi kí ó sì lè tẹ́ pẹpẹ kan níbẹ̀ fún Olúwa, ìwọ ó sì fi fún mi ni iye owó rẹ̀ pípé, kí a lè dá àjàkálẹ̀-ààrùn dúró lọ́dọ̀ àwọn ènìyàn.”
David el fahk nu sel, “Kukakunma nien kulkul wheat lom uh, tuh nga in etoak sie loang nu sin LEUM GOD, in tulokinya mas upa se orek inge. Nga lungse molela nufon.”
23 Arauna sì wí fún Dafidi pé, “Mú un fún ara rẹ, sì jẹ́ kí olúwa mi ọba kí ó ṣe ohun tí ó dára lójú rẹ̀. Wò ó, èmí yóò fún ọ ní àwọn màlúù fún ẹbọ sísun, àti ohun èlò ìpakà fún igi, àti ọkà fún ọrẹ oúnjẹ. Èmi yóò fun ọ ní gbogbo èyí.”
Ac Araunah el fahk, “O Tokosra, eis na lom ac orekmakin nu ke enenu lom. Cow mukul pa inge, kom ku in orek mwe kisa firir kac fin loang an, ac ipin sak ke acn in kulkul wheat uh ku in orekmakinyuk mwe etong, oayapa wheat tuh in mwe sang lom. Ma inge kewa nga sot nu sum.”
24 Ṣùgbọ́n ọba Dafidi dá Arauna lóhùn pé, “Bẹ́ẹ̀ kọ́, ṣùgbọ́n èmi yóò rà á ní iye owó rẹ̀ ní pípé, nítorí èmi kì yóò èyí tí ó jẹ́ tìrẹ fún Olúwa, tàbí láti rú ẹbọ sísun tí kò ná mi ní ohun kan.”
Tusruktu tokosra el topuk, “Mo, nga ac moli nufon ma inge. Nga ac tia kisakin nu sin LEUM GOD ma su ma lom, ma tuku nu sik ke wangin molo.”
25 Bẹ́ẹ̀ ni Dafidi san ẹgbẹ̀ta ṣékélì wúrà fún Arauna nípa ìwọ̀n fún ibẹ̀ náà.
Na el sang ipin gold onfoko nu sel Araunah, molin acn in kulkul wheat sac.
26 Dafidi sì tẹ́ pẹpẹ fún Olúwa níbẹ̀ ó sì rú ẹbọ sísun àti ẹbọ ọpẹ́. Ó sì ké pe Olúwa, Olúwa sì fi iná dá a lóhùn láti òkè ọ̀run wá lórí pẹpẹ fún ẹbọ ọrẹ sísun.
David el etoak sie loang nu sin LEUM GOD we, ac kisakin mwe kisa firir, ac mwe kisa in akinsewowo. El pre, ac LEUM GOD El topuk pre lal, ac supweya e lucng me in akosak mwe kisa fin loang uh.
27 Nígbà náà Olúwa sọ̀rọ̀ sí angẹli, ó sì gbé idà padà bọ̀ sínú àkọ̀ rẹ̀.
LEUM GOD El fahk nu sin lipufan sac tuh elan filiya cutlass natul ah, ac lipufan sac akos.
28 Ní àkókò náà nígbà tí Dafidi sì rí wí pé Olúwa ti dá a lóhùn lórí ilẹ̀ ìpakà ti Arauna ará Jebusi, ó sì rú ẹbọ sísun níbẹ̀.
Ke David el liye ma inge el akilen lah LEUM GOD El topuk pre lal, na el oru mwe kisa lal fin loang uh ke acn in kulkul wheat lal Araunah.
29 Àgọ́ Olúwa tí Mose ti ṣe ní aginjù, àti pẹpẹ ẹbọ sísun wà lórí ibi gíga ní Gibeoni ní àkókò náà.
Lohm Nuknuk sin LEUM GOD su Moses el tuh orala yen mwesis, oayapa loang se mwe kisa uh orek fac, srakna oan ke nien alu in acn Gibeon in pacl se inge.
30 Ṣùgbọ́n Dafidi kò lè lọ síwájú rẹ̀ láti béèrè lọ́wọ́ Ọlọ́run, nítorí tí ó bẹ̀rù nípa idà ọwọ́ angẹli Olúwa.
Tusruktu David el tia ku in som alu nu sin God we, mweyen el sangeng ke cutlass se nutin lipufan lun LEUM GOD.

< 1 Chronicles 21 >