< 1 Chronicles 21 >

1 Satani sì dúró ti Israẹli, ó sì ti Dafidi láti ka iye Israẹli.
Et le diable se leva contre Israël; il excita le roi David à faire le dénombrement du peuple.
2 Bẹ́ẹ̀ ni Dafidi sì wí fún Joabu àti àwọn olórí àwọn ènìyàn pé, “Lọ kí o ka iye àwọn ọmọ Israẹli láti Beerṣeba títí dé Dani. Kí o sì padà mú iye wọn fún mi wa, kí èmi kí ó le mọ iye tí wọ́n jẹ́.”
Le roi dit donc à Joab et aux chefs de l'armée: Allez et faites le dénombrement d'Israël, depuis Dan jusqu'à Bersabée; puis, rapportez-le-moi, et je saurai leur nombre.
3 Ṣùgbọ́n Joabu dá a lóhùn pé, “Kí Olúwa kí ó mú àwọn ènìyàn rẹ̀ pọ̀ sí ní ìgbà ọgọ́rùn-ún ju ti tẹ́lẹ̀ lọ, ọba olúwa mi, gbogbo wọn kì í ha ṣe ìránṣẹ́ olúwa ni? Kí ni ó dé tí olúwa mi ṣe fẹ́ ṣè yìí? Kí ni ó de tí yóò fi mú ẹ̀bi wá sórí Israẹli?”
Joab répondit: Puisse le Seigneur ajouter à son peuple et le rendre cent fois aussi nombreux qu'il l'est, et puisse le roi mon maître le voir de ses yeux; puissent le voir aussi les serviteurs de mon maître; mais pourquoi mon maître a-t-il formé ce dessein? Est-ce pour qu'il soit imputé à péché au peuple d'Israël?
4 Ṣùgbọ́n ọ̀rọ̀ ọba borí tí Joabu. Bẹ́ẹ̀ ni Joabu jáde lọ, ó sì la gbogbo Israẹli já, ó sí dé Jerusalẹmu.
Mais, la volonté du roi prévalut sur Joab, et Joab partit, et il parcourut tout Israël, et il revint à Jérusalem.
5 Joabu sì fi àpapọ̀ iye àwọn ènìyàn náà fún Dafidi. Ní gbogbo Israẹli, ó sì jẹ́ ẹgbẹ̀rún ẹgbẹ̀rún àti ọ̀kẹ́ márùn-ún ènìyàn tí ń kọ́ idà, Juda sì jẹ́ ọ̀kẹ́ mẹ́tàlélógún lé ẹgbàárùn-ún ọkùnrin tí ń kọ́ idà.
Et Joab remit à David le dénombrement du peuple qu'il avait recensé: il y avait en tout Israël onze cent mille hommes tirant l'épée, et en Juda étaient quatre cent soixante-dix mille hommes tirant l'épée.
6 Ṣùgbọ́n Joabu kó àwọn Lefi àti Benjamini mọ́ iye wọn, nítorí àṣẹ ọba jẹ́ ìríra fún un.
Et Joab n'avait compté ni Lévi, ni Benjamin, parce qu'il avait cédé à contre-cœur au roi.
7 Àṣẹ yìí pẹ̀lú sì jẹ́ búburú lójú Ọlọ́run, bẹ́ẹ̀ ni ó sì díyàjẹ Israẹli.
Et la chose fut mauvaise devant Dieu, et il frappa Israël.
8 Nígbà náà Dafidi sọ fún Ọlọ́run pé, èmi ti dẹ́ṣẹ̀ gidigidi nípa ṣíṣe èyí. Nísinsin yìí, èmi bẹ̀ ọ́, mú ìjẹ̀bi àwọn ìránṣẹ́ rẹ kúrò. Èmi ti hùwà aṣiwèrè gidigidi.
Et David dit à Dieu: J'ai gravement péché en ce que je viens de faire, et maintenant remettez à votre serviteur son iniquité, car j'ai commis une insigne folie.
9 Olúwa sì fi fún Gadi, aríran Dafidi pé.
Et le Seigneur parla à Gad le voyant, et il lui dit:
10 “Lọ kí o sì wí fún Dafidi pé, ‘Báyìí ni Olúwa wí, èmi fi nǹkan mẹ́ta lọ̀ ọ́; yan ọ̀kan nínú wọn, kí èmi ó sì ṣe é sí ọ.’”
Pars et adresse-toi à David, disant: Voici ce que dit le Seigneur: Je t'apporte trois choses; choisis pour toi l'une d'elles, et tu l'auras.
11 Bẹ́ẹ̀ ni Gadi tọ Dafidi wá, ó sì wí fún un pé, “Báyìí ni Olúwa wí: ‘Yan fún ara rẹ.
Gad alla trouver David, et il lui dit: Voici ce que dit le Seigneur: Choisis pour toi,
12 Ọdún mẹ́ta ìyàn, tàbí ìparun ní oṣù mẹ́ta níwájú àwọn ọ̀tá rẹ, pẹ̀lú idà wọn láti lé ọ bá, tàbí ọjọ́ mẹ́ta idà Olúwa ọjọ́ àjàkálẹ̀-ààrùn ní ilẹ̀ náà, pẹ̀lú àwọn angẹli Olúwa láti pa gbogbo agbègbè Israẹli run.’ Nísinsin yìí ǹjẹ́, rò ó wò, èsì wo ni èmi yóò mú padà tọ ẹni tí ó rán mi.”
Ou trois ans de famine, ou trois mois pendant lesquels tu fuiras devant tes ennemis qui te détruiront par le glaive, ou trois jours de mort causée par l'épée du Seigneur en toute cette terre, et par l'ange exterminateur parcourant tout l'héritage d'Israël: vois donc ce que je dois répondre à Celui qui m'envoie te répéter sa parole.
13 Dafidi sì wí fún Gadi pé, “Ìyọnu ńlá bá mi. Jẹ́ kí èmi kí ó ṣubú sí ọwọ́ Olúwa nísinsin yìí, nítorí tí àánú rẹ̀ pọ̀ gidigidi, ṣùgbọ́n má ṣe jẹ́ kí èmi kí o ṣubú sí ọwọ́ àwọn ènìyàn.”
Et David dit à Gad: Le choix des trois parts m'est cruel; mais j'aime mieux me livrer aux mains du Seigneur, parce qu'il a eu souvent compassion de moi; je ne tomberai point dans les mains des hommes.
14 Bẹ́ẹ̀ ni Olúwa rán àjàkálẹ̀-ààrùn lórí Israẹli, àwọn tí ó ṣubú ní Israẹli jẹ́ ẹgbẹ̀rún ní ọ̀nà àádọ́rin ènìyàn.
Et le Seigneur envoya la mort en Israël, et soixante-dix mille hommes d'Israël périrent.
15 Ọlọ́run sì rán angẹli kan sí Jerusalẹmu láti pa wọ́n run. Ṣùgbọ́n bí angẹli ti ń pa wọ́n run, Olúwa sì wò. Ó sì káàánú nítorí ibi náà, ó sì wí fún angẹli tí ó pa àwọn ènìyàn náà run pé, “Ó ti tó! Dá ọwọ́ rẹ dúró.” Angẹli Olúwa náà sì dúró níbi ilẹ̀ ìpakà Arauna ará Jebusi.
Le Seigneur envoya aussi l'ange à Jérusalem pour l'exterminer, et comme il frappait, le Seigneur le vit et se repentit de tout ce mal, et il dit à l'ange exterminateur: C'est assez, arrête ta main. Or, l'ange du Seigneur était auprès de l'aire d'Orna le Jébuséen.
16 Dafidi sì wòkè ó sì rí angẹli Olúwa dúró láàrín ọ̀run àti ayé pẹ̀lú idà fífàyọ ní ọwọ́ rẹ̀ tí ó sì nà án sórí Jerusalẹmu. Nígbà náà Dafidi àti àwọn àgbàgbà, sì wọ aṣọ ọ̀fọ̀, wọ́n sì da ojú wọn bolẹ̀.
David, ayant levé les yeux, vit l'ange du Seigneur se tenant entre la terre et le ciel; il avait à la main son épée nue, et il l'étendait sur Jérusalem. Et David et les anciens couverts de cilices tombèrent la face contre terre.
17 Dafidi sì wí fún Ọlọ́run pé, “Èmi ha kọ́ ni mo pàṣẹ àti ka àwọn jagunjagun ènìyàn? Èmi ni ẹni náà tí ó dẹ́ṣẹ̀ tí ó sì ṣe ohun búburú pàápàá, ṣùgbọ́n bí ó ṣe ti àgùntàn wọ̀nyí, kí ni wọ́n ṣe? Èmí bẹ̀ ọ́ Olúwa Ọlọ́run mi, jẹ́ kí ọwọ́ rẹ kí ó wà lára mi àti àwọn ìdílé baba mi, ṣùgbọ́n má ṣe jẹ́ kí àjàkálẹ̀-ààrùn yìí kí ó dúró lórí àwọn ènìyàn rẹ.”
Et David dit à Dieu: N'est-ce pas moi qui ai prescrit de faire le dénombrement du peuple? C'est moi qui suis le coupable; j'ai grandement péché. Mais ces brebis qu'ont-elles fait? Seigneur mon Dieu, que votre main soit contre moi et contre la maison de mon père; qu'elle épargne ce peuple qui périt, ô Seigneur.
18 Nígbà náà angẹli Olúwa náà pàṣẹ fún Gadi láti sọ fún Dafidi pé, kí Dafidi kí ó gòkè lọ, kí ó sì tẹ́ pẹpẹ kan fún Olúwa lórí ilẹ̀ ìpakà Arauna ará Jebusi.
Et l'ange du Seigneur dit à Gad de prescrire à David qu'il allât élever un autel au Seigneur dans l'aire d'Orna le Jébuséen.
19 Bẹ́ẹ̀ ni Dafidi sì gòkè lọ pẹ̀lú ìgbọ́ràn sí ọ̀rọ̀ tí Gadi ti sọ ní orúkọ Olúwa.
Et David sortit, selon la parole que Gad lui avait dite au nom du Seigneur.
20 Nígbà tí Arauna sì ń pakà lọ́wọ́, ó sì yípadà ó sì rí angẹli; àwọn ọmọ rẹ̀ mẹ́rẹ̀ẹ̀rin tí ó wà pẹ̀lú rẹ̀ pa ará wọn mọ́.
Et Orna se retourna, et il vit le roi et quatre de ses fils, tous se cachant, et Orna était à vanner du froment.
21 Bí Dafidi sì ti dé ọ̀dọ̀ Arauna, Arauna sì wò, ó sì rí Dafidi, ó sì ti ibi ilẹ̀ ìpakà rẹ̀ jáde, ó sì wólẹ̀, ó dojúbolẹ̀ níwájú Dafidi.
Et David arriva auprès d'Orna, et Orna, quittant l'aire, se prosterna la face contre terre devant David.
22 Dafidi sì wí fún Arauna pé, “Jẹ́ kí èmi kí ó ni ibi ìpakà rẹ kí èmi kí ó sì lè tẹ́ pẹpẹ kan níbẹ̀ fún Olúwa, ìwọ ó sì fi fún mi ni iye owó rẹ̀ pípé, kí a lè dá àjàkálẹ̀-ààrùn dúró lọ́dọ̀ àwọn ènìyàn.”
Et David dit à Orna: Donne-moi l'emplacement de ton aire, et j'y bâtirai un autel au Seigneur; donne-le-moi à prix d'argent, et le fléau cessera de frapper le peuple.
23 Arauna sì wí fún Dafidi pé, “Mú un fún ara rẹ, sì jẹ́ kí olúwa mi ọba kí ó ṣe ohun tí ó dára lójú rẹ̀. Wò ó, èmí yóò fún ọ ní àwọn màlúù fún ẹbọ sísun, àti ohun èlò ìpakà fún igi, àti ọkà fún ọrẹ oúnjẹ. Èmi yóò fun ọ ní gbogbo èyí.”
Et Orna dit à David: Que le roi mon maître prenne et consacre ce que bon lui semble. Voici mes bœufs pour l'holocauste, ma charrue pour le briller, et mon blé pour le sacrifice; je te donne tout.
24 Ṣùgbọ́n ọba Dafidi dá Arauna lóhùn pé, “Bẹ́ẹ̀ kọ́, ṣùgbọ́n èmi yóò rà á ní iye owó rẹ̀ ní pípé, nítorí èmi kì yóò èyí tí ó jẹ́ tìrẹ fún Olúwa, tàbí láti rú ẹbọ sísun tí kò ná mi ní ohun kan.”
Et le roi David dit à Orna: Nullement; certes, j'achèterai toutes ces choses, car elles valent de l'argent; je ne prendrai, pour le Seigneur, rien de ce qui est à toi; je ne présenterai pas au Seigneur un holocauste qui ne me coûte rien.
25 Bẹ́ẹ̀ ni Dafidi san ẹgbẹ̀ta ṣékélì wúrà fún Arauna nípa ìwọ̀n fún ibẹ̀ náà.
David donna donc à Orna, pour son terrain, six cents sicles d'or, au poids du sicle du sanctuaire.
26 Dafidi sì tẹ́ pẹpẹ fún Olúwa níbẹ̀ ó sì rú ẹbọ sísun àti ẹbọ ọpẹ́. Ó sì ké pe Olúwa, Olúwa sì fi iná dá a lóhùn láti òkè ọ̀run wá lórí pẹpẹ fún ẹbọ ọrẹ sísun.
Il bâtit l'autel du Seigneur, sur lequel il offrit des holocaustes et des hosties pacifiques; enfin, il cria au Seigneur, et le Seigneur l'exauça; le feu du ciel, descendant sur l'autel de l'holocauste, consuma la victime.
27 Nígbà náà Olúwa sọ̀rọ̀ sí angẹli, ó sì gbé idà padà bọ̀ sínú àkọ̀ rẹ̀.
Et le Seigneur parla à l'ange, et l'ange remit l'épée dans le fourreau.
28 Ní àkókò náà nígbà tí Dafidi sì rí wí pé Olúwa ti dá a lóhùn lórí ilẹ̀ ìpakà ti Arauna ará Jebusi, ó sì rú ẹbọ sísun níbẹ̀.
Dès lors, David, ayant vu que le Seigneur lui répondait dans l'aire d'Orna le Jébuséen, en fit un lieu de sacrifices.
29 Àgọ́ Olúwa tí Mose ti ṣe ní aginjù, àti pẹpẹ ẹbọ sísun wà lórí ibi gíga ní Gibeoni ní àkókò náà.
Or, en ce temps-là, le tabernacle du Seigneur que Moïse avait fait dans le désert, et l'autel des holocaustes, étaient sur le haut lieu de Gabaon. Par crainte de l'ange exterminateur.
30 Ṣùgbọ́n Dafidi kò lè lọ síwájú rẹ̀ láti béèrè lọ́wọ́ Ọlọ́run, nítorí tí ó bẹ̀rù nípa idà ọwọ́ angẹli Olúwa.
Et David n'avait pu s'y transporter pour prier le Seigneur; il ne s'était point empressé d'y aller, à cause de l'épée de l'ange du Seigneur.

< 1 Chronicles 21 >