< 1 Chronicles 21 >
1 Satani sì dúró ti Israẹli, ó sì ti Dafidi láti ka iye Israẹli.
Hahoi Setan ni Isarelnaw taran lahoi a thaw teh, Isarelnaw milu touk sak hanelah Devit hah a tacuek.
2 Bẹ́ẹ̀ ni Dafidi sì wí fún Joabu àti àwọn olórí àwọn ènìyàn pé, “Lọ kí o ka iye àwọn ọmọ Israẹli láti Beerṣeba títí dé Dani. Kí o sì padà mú iye wọn fún mi wa, kí èmi kí ó le mọ iye tí wọ́n jẹ́.”
Hatdawkvah, Devit ni Joab hoi a taminaw kahrawikung koe, Isarel miphun pueng Dan kho hoi Beersheba kho totouh cet awh nateh, tami nâyittouh maw tie ka panue thai nahan touk awh nateh kai koe bout na dei awh han telah atipouh.
3 Ṣùgbọ́n Joabu dá a lóhùn pé, “Kí Olúwa kí ó mú àwọn ènìyàn rẹ̀ pọ̀ sí ní ìgbà ọgọ́rùn-ún ju ti tẹ́lẹ̀ lọ, ọba olúwa mi, gbogbo wọn kì í ha ṣe ìránṣẹ́ olúwa ni? Kí ni ó dé tí olúwa mi ṣe fẹ́ ṣè yìí? Kí ni ó de tí yóò fi mú ẹ̀bi wá sórí Israẹli?”
Hatei, Joab ni siangpahrang koevah, BAWIPA ni taminaw teh a let 100 touh haiyah pungdaw sak naseh, siangpahrang ka bawipa e misa lah koung kaawm nahoehmaw, ka bawipa ni bangkongmaw hot hah panue han na ngai, bangdawkmaw Isarelnaw kâtapoe sak hanelah na sak vaw atipouh.
4 Ṣùgbọ́n ọ̀rọ̀ ọba borí tí Joabu. Bẹ́ẹ̀ ni Joabu jáde lọ, ó sì la gbogbo Israẹli já, ó sí dé Jerusalẹmu.
Hateiteh siangpahrang e lawk teh Joab ni ek thai hoeh. Hatdawkvah, Joab ni Isarel ram pueng dawk a cei teh, Jerusalem vah bout a ban.
5 Joabu sì fi àpapọ̀ iye àwọn ènìyàn náà fún Dafidi. Ní gbogbo Israẹli, ó sì jẹ́ ẹgbẹ̀rún ẹgbẹ̀rún àti ọ̀kẹ́ márùn-ún ènìyàn tí ń kọ́ idà, Juda sì jẹ́ ọ̀kẹ́ mẹ́tàlélógún lé ẹgbàárùn-ún ọkùnrin tí ń kọ́ idà.
Joab ni tami kaawm e yit touh Devit koe bout a dei pouh. Isarel ram dawk tahloi ka patuem e 1, 100, 000 touh a pha awh.
6 Ṣùgbọ́n Joabu kó àwọn Lefi àti Benjamini mọ́ iye wọn, nítorí àṣẹ ọba jẹ́ ìríra fún un.
Hateiteh, Levihnaw hoi Benjaminnaw teh touk awh hoeh. Bangkongtetpawiteh, siangpahrang e lawk teh Joab hanelah panuet a tho.
7 Àṣẹ yìí pẹ̀lú sì jẹ́ búburú lójú Ọlọ́run, bẹ́ẹ̀ ni ó sì díyàjẹ Israẹli.
Hote kong teh Cathut ni a ngai hoeh dawkvah, Isarelnaw hah a thei.
8 Nígbà náà Dafidi sọ fún Ọlọ́run pé, èmi ti dẹ́ṣẹ̀ gidigidi nípa ṣíṣe èyí. Nísinsin yìí, èmi bẹ̀ ọ́, mú ìjẹ̀bi àwọn ìránṣẹ́ rẹ kúrò. Èmi ti hùwà aṣiwèrè gidigidi.
Devit ni Cathut koe hete ka sak e dawkvah puenghoi ka payon toe. Hatei nakunghai na sanpa kai ni ka payon, kai heh na pahren nateh, na ngaithoum yawkaw ei. Bangkongtetpawiteh, pathunae hno ka sak toe telah ati.
9 Olúwa sì fi fún Gadi, aríran Dafidi pé.
BAWIPA ni Devit e profet Gad koe vah,
10 “Lọ kí o sì wí fún Dafidi pé, ‘Báyìí ni Olúwa wí, èmi fi nǹkan mẹ́ta lọ̀ ọ́; yan ọ̀kan nínú wọn, kí èmi ó sì ṣe é sí ọ.’”
Cet nateh, Devit koe hettelah dei pouh. Hno kathum touh nang koe na patue. Nang dawk kai ni ka sak hane buetbuet touh kârawi leih telah dei pouh telah atipouh.
11 Bẹ́ẹ̀ ni Gadi tọ Dafidi wá, ó sì wí fún un pé, “Báyìí ni Olúwa wí: ‘Yan fún ara rẹ.
Gad teh Devit koe a cei teh, BAWIPA ni hettelah a dei, na ngai e kârawi leih.
12 Ọdún mẹ́ta ìyàn, tàbí ìparun ní oṣù mẹ́ta níwájú àwọn ọ̀tá rẹ, pẹ̀lú idà wọn láti lé ọ bá, tàbí ọjọ́ mẹ́ta idà Olúwa ọjọ́ àjàkálẹ̀-ààrùn ní ilẹ̀ náà, pẹ̀lú àwọn angẹli Olúwa láti pa gbogbo agbègbè Israẹli run.’ Nísinsin yìí ǹjẹ́, rò ó wò, èsì wo ni èmi yóò mú padà tọ ẹni tí ó rán mi.”
BAWIPA ni a dei e teh, kum thum touh thung takang ka tho sak maw na ngai, Nahoeh pawiteh, thapa yung thum touh tarannaw ni na pâlei maw na ngai, Nahoeh pawiteh, hnin thum touh thung Lacik ka phasak maw na ngai. Na kapatounkung koe bangtelamaw ka dei pouh han, atu kâpouk nateh, dei haw telah atipouh.
13 Dafidi sì wí fún Gadi pé, “Ìyọnu ńlá bá mi. Jẹ́ kí èmi kí ó ṣubú sí ọwọ́ Olúwa nísinsin yìí, nítorí tí àánú rẹ̀ pọ̀ gidigidi, ṣùgbọ́n má ṣe jẹ́ kí èmi kí o ṣubú sí ọwọ́ àwọn ènìyàn.”
Devit ni Gad koevah, ka lung rei a thai, kho lah king a bing. BAWIPA e kut dawk ka bawt yawkaw naseh. Bangkongtetpawiteh, a lungmanae teh a len. Tami e a kut dawk teh na phat sak hanh telah atipouh.
14 Bẹ́ẹ̀ ni Olúwa rán àjàkálẹ̀-ààrùn lórí Israẹli, àwọn tí ó ṣubú ní Israẹli jẹ́ ẹgbẹ̀rún ní ọ̀nà àádọ́rin ènìyàn.
Hatdawkvah, BAWIPA ni Isarelnaw thung lacik a pha sak teh, Isarelnaw tami 70, 000 touh a due awh.
15 Ọlọ́run sì rán angẹli kan sí Jerusalẹmu láti pa wọ́n run. Ṣùgbọ́n bí angẹli ti ń pa wọ́n run, Olúwa sì wò. Ó sì káàánú nítorí ibi náà, ó sì wí fún angẹli tí ó pa àwọn ènìyàn náà run pé, “Ó ti tó! Dá ọwọ́ rẹ dúró.” Angẹli Olúwa náà sì dúró níbi ilẹ̀ ìpakà Arauna ará Jebusi.
Hahoi Jerusalem raphoe hanelah, Cathut ni kalvantami a patoun teh, raphoe hane a kâcai navah, BAWIPA ni a khet teh, hawihoehnae sak han a noe e hah bout a kâhno. Ka raphoe e kalvantami koevah, a khout toe na kut dâw hanh lawi telah atipouh teh, BAWIPA e kalvantami teh Jebusit tami Ornan e cangkatinnae teng vah a kangdue.
16 Dafidi sì wòkè ó sì rí angẹli Olúwa dúró láàrín ọ̀run àti ayé pẹ̀lú idà fífàyọ ní ọwọ́ rẹ̀ tí ó sì nà án sórí Jerusalẹmu. Nígbà náà Dafidi àti àwọn àgbàgbà, sì wọ aṣọ ọ̀fọ̀, wọ́n sì da ojú wọn bolẹ̀.
Devit ni kho a radoung teh, BAWIPA kalvantami tahloi a rayu nalaihoi Jerusalem koelah a nue teh, talai hoi kalvan a rahak dawk a kangdue e hah a hmu. Hatdawkvah, Devit hoi kacuenaw ni buri a kâramuk awh teh, talai dawk a tabo awh.
17 Dafidi sì wí fún Ọlọ́run pé, “Èmi ha kọ́ ni mo pàṣẹ àti ka àwọn jagunjagun ènìyàn? Èmi ni ẹni náà tí ó dẹ́ṣẹ̀ tí ó sì ṣe ohun búburú pàápàá, ṣùgbọ́n bí ó ṣe ti àgùntàn wọ̀nyí, kí ni wọ́n ṣe? Èmí bẹ̀ ọ́ Olúwa Ọlọ́run mi, jẹ́ kí ọwọ́ rẹ kí ó wà lára mi àti àwọn ìdílé baba mi, ṣùgbọ́n má ṣe jẹ́ kí àjàkálẹ̀-ààrùn yìí kí ó dúró lórí àwọn ènìyàn rẹ.”
Devit ni Cathut koe taminaw touk hane kâ kapoekung teh kai nahoehmaw. Kai heh yonnae ka sak e, kahawihoehe poung lah hno ka sak e teh kai doeh. Hetnaw ni bangmaw a sak awh. Oe BAWIPA ka Cathut, kai hoi ka imthungnaw dawk na kut pho nateh, na taminaw ni lacik hah khang awh hanh naseh, telah ati.
18 Nígbà náà angẹli Olúwa náà pàṣẹ fún Gadi láti sọ fún Dafidi pé, kí Dafidi kí ó gòkè lọ, kí ó sì tẹ́ pẹpẹ kan fún Olúwa lórí ilẹ̀ ìpakà Arauna ará Jebusi.
Hatdawkvah, BAWIPA kalvantami ni Jebusit tami Ornan e cangkatinnae koevah Devit a cei vaiteh, BAWIPA hanelah thuengnae khoungroe kangdue sak hanelah, Devit koe dei pouh hanelah Gad koe kâ a poe.
19 Bẹ́ẹ̀ ni Dafidi sì gòkè lọ pẹ̀lú ìgbọ́ràn sí ọ̀rọ̀ tí Gadi ti sọ ní orúkọ Olúwa.
A dei e patetlah Gad ni BAWIPA min lahoi a dei pouh e patetlah Devit teh a cei.
20 Nígbà tí Arauna sì ń pakà lọ́wọ́, ó sì yípadà ó sì rí angẹli; àwọn ọmọ rẹ̀ mẹ́rẹ̀ẹ̀rin tí ó wà pẹ̀lú rẹ̀ pa ará wọn mọ́.
Ornan ni a kamlang teh kalvantami hah a hmu. Ahni koe kaawm e a capa 4 touh a kâhro. Ornan ma teh cang a katin.
21 Bí Dafidi sì ti dé ọ̀dọ̀ Arauna, Arauna sì wò, ó sì rí Dafidi, ó sì ti ibi ilẹ̀ ìpakà rẹ̀ jáde, ó sì wólẹ̀, ó dojúbolẹ̀ níwájú Dafidi.
Hottelah Devit ni Ornan koe a pha teh, Ornan ni a khet navah, Devit hah a hmu. Cang a katin e pak a tha teh, Devit e hmalah talai dawk a tabo.
22 Dafidi sì wí fún Arauna pé, “Jẹ́ kí èmi kí ó ni ibi ìpakà rẹ kí èmi kí ó sì lè tẹ́ pẹpẹ kan níbẹ̀ fún Olúwa, ìwọ ó sì fi fún mi ni iye owó rẹ̀ pípé, kí a lè dá àjàkálẹ̀-ààrùn dúró lọ́dọ̀ àwọn ènìyàn.”
Devit ni BAWIPA hanelah thuengnae khoungroe ka sak thai nahanelah cangkatinnae hmuen hah na poe haw. Taminaw koehoi lacik a kâkayaw thai nahanelah, ka kuepcalah a phu na poe han telah atipouh.
23 Arauna sì wí fún Dafidi pé, “Mú un fún ara rẹ, sì jẹ́ kí olúwa mi ọba kí ó ṣe ohun tí ó dára lójú rẹ̀. Wò ó, èmí yóò fún ọ ní àwọn màlúù fún ẹbọ sísun, àti ohun èlò ìpakà fún igi, àti ọkà fún ọrẹ oúnjẹ. Èmi yóò fun ọ ní gbogbo èyí.”
Ornan ni Devit koe lat yawkaw, siangpahrang ka bawipa ni ahawi na tie patetlah sak yawkaw, khenhaw! hmaisawi thuengnae sak nahanelah maitotan hoi thueng hanelah cakong, tavai hoi thueng nahanelah cakang hai na poe han. Abuemlahoi koung na poe telah atipouh.
24 Ṣùgbọ́n ọba Dafidi dá Arauna lóhùn pé, “Bẹ́ẹ̀ kọ́, ṣùgbọ́n èmi yóò rà á ní iye owó rẹ̀ ní pípé, nítorí èmi kì yóò èyí tí ó jẹ́ tìrẹ fún Olúwa, tàbí láti rú ẹbọ sísun tí kò ná mi ní ohun kan.”
Siangpahrang Devit ni Ornan koevah, telah nahoeh. Aphu hoi kâran han. Bangkongtetpawiteh, BAWIPA hanlah nange ka lat mahoeh. Banghai baw laipalah thuengnae sathei hah ka poe mahoeh atipouh.
25 Bẹ́ẹ̀ ni Dafidi san ẹgbẹ̀ta ṣékélì wúrà fún Arauna nípa ìwọ̀n fún ibẹ̀ náà.
Hatdawkvah, Devit ni hote hmuen teh Ornan koe sui shekel 600 touh hoi a ran.
26 Dafidi sì tẹ́ pẹpẹ fún Olúwa níbẹ̀ ó sì rú ẹbọ sísun àti ẹbọ ọpẹ́. Ó sì ké pe Olúwa, Olúwa sì fi iná dá a lóhùn láti òkè ọ̀run wá lórí pẹpẹ fún ẹbọ ọrẹ sísun.
Devit ni hote hmuen koe BAWIPA hanlah khoungroe a sak teh, sathei thuengnae hoi roum thuengnae sathei poenae a sak. BAWIPA a kaw teh khoungroe dawkvah kalvan lahoi hmai hoi a pato.
27 Nígbà náà Olúwa sọ̀rọ̀ sí angẹli, ó sì gbé idà padà bọ̀ sínú àkọ̀ rẹ̀.
BAWIPA ni kalvantaminaw hah kâ a poe teh, tahloi teh a tabu dawk bout a pâseng.
28 Ní àkókò náà nígbà tí Dafidi sì rí wí pé Olúwa ti dá a lóhùn lórí ilẹ̀ ìpakà ti Arauna ará Jebusi, ó sì rú ẹbọ sísun níbẹ̀.
Devit ni Jebusit tami Ornan e cangkatinnae koehoi BAWIPA ni na pato tie hah a panue torei teh, hawvah thueng a sak.
29 Àgọ́ Olúwa tí Mose ti ṣe ní aginjù, àti pẹpẹ ẹbọ sísun wà lórí ibi gíga ní Gibeoni ní àkókò náà.
Hatnae tueng dawkvah, Mosi ni kahrawngum BAWIPA e lukkareiim hoi hmaisawinae khoungroe a sak e hah, Gibeon kho e hmuenrasang doeh ao rah.
30 Ṣùgbọ́n Dafidi kò lè lọ síwájú rẹ̀ láti béèrè lọ́wọ́ Ọlọ́run, nítorí tí ó bẹ̀rù nípa idà ọwọ́ angẹli Olúwa.
Hateiteh, Cathut koe pouknae hei hanelah Devit ni a hmalah cet thai hoeh. Bangkongtetpawiteh, BAWIPA e kalvantami e tahloi hah a taki.