< 1 Chronicles 2 >

1 Àwọn wọ̀nyí ni àwọn ọmọ Israẹli. Reubeni, Simeoni, Lefi, Juda, Isakari, Sebuluni,
filii autem Israhel Ruben Symeon Levi Iuda Isachar et Zabulon
2 Dani, Josẹfu, Benjamini; Naftali, Gadi: àti Aṣeri.
Dan Ioseph Beniamin Nepthali Gad Aser
3 Àwọn ọmọ Juda: Eri, Onani àti Ṣela, àwọn mẹ́tẹ̀ẹ̀ta wọ̀nyí ni wọ́n bí fún un láti ọ̀dọ̀ arábìnrin Kenaani, ọmọbìnrin Ṣua. Eri àkọ́bí Juda, ó sì burú ní ojú Olúwa, bẹ́ẹ̀ ni Olúwa sì pa á.
filii Iuda Her Aunan Sela tres nati sunt ei de filia Sue Chananitidis fuit autem Her primogenitus Iuda malus coram Domino et occidit eum
4 Tamari, aya ọmọbìnrin Juda, ó sì bí Peresi àti Sera sì ní ọmọ márùn-ún ní àpapọ̀.
Thamar autem nurus eius peperit ei Phares et Zara omnes ergo filii Iuda quinque
5 Àwọn ọmọ Peresi: Hesroni àti Hamulu.
filii autem Phares Esrom et Hamul
6 Àwọn ọmọ Sera: Simri, Etani, Hemani, Kalkoli àti Dara, gbogbo wọn jẹ́ márùn-ún.
filii quoque Zarae Zamri et Ethan et Eman Chalchal quoque et Darda simul quinque
7 Àwọn ọmọ Karmi: Akani, ẹni tí ó mú ìyọnu wá sórí Israẹli nípa ẹ̀ṣẹ̀ ìfibú lórí mímú ohun ìyàsọ́tọ̀.
filii Carmi Achar qui turbavit Israhel et peccavit in furto anathematis
8 Àwọn ọmọ Etani: Asariah.
filii Ethan Azarias
9 Àwọn ọmọ tí a bí fún Hesroni ni: Jerahmeeli, Ramu àti Kalebu.
filii autem Esrom qui nati sunt ei Ieremahel et Ram et Chalubi
10 Ramu sì ni baba Amminadabu, àti Amminadabu baba Nahiṣoni olórí àwọn ènìyàn Juda.
porro Ram genuit Aminadab Aminadab autem genuit Naasson principem filiorum Iuda
11 Nahiṣoni sì ni baba Salmoni, Salmoni ni baba Boasi,
Naasson quoque genuit Salma de quo ortus est Boez
12 Boasi baba Obedi àti Obedi baba Jese.
Boez vero genuit Obed qui et ipse genuit Isai
13 Jese sì ni baba Eliabu àkọ́bí rẹ̀; ọmọ ẹlẹ́ẹ̀kejì sì ni Abinadabu, ẹlẹ́ẹ̀kẹta ni Ṣimea,
Isai autem genuit primogenitum Heliab secundum Abinadab tertium Samaa
14 ẹlẹ́ẹ̀kẹrin Netaneli, ẹlẹ́ẹ̀karùnún Raddai,
quartum Nathanahel quintum Raddai
15 ẹlẹ́ẹ̀kẹfà Osemu àti ẹlẹ́ẹ̀keje Dafidi.
sextum Asom septimum David
16 Àwọn arábìnrin wọn ni Seruiah àti Abigaili. Àwọn ọmọ mẹ́ta Seruiah ni Abiṣai, Joabu àti Asaheli.
quorum sorores fuerunt Sarvia et Abigail filii Sarviae Abisai Ioab et Asahel tres
17 Abigaili ni ìyá Amasa, ẹni tí baba rẹ̀ sì jẹ́ Jeteri ará Iṣmaeli.
Abigail autem genuit Amasa cuius pater fuit Iether Ismahelites
18 Kalebu ọmọ Hesroni ní ọmọ láti ọ̀dọ̀ ìyàwó rẹ̀ Asuba (láti ọ̀dọ̀ Jerioti). Àwọn wọ̀nyí ni àwọn ọmọ rẹ̀: Jeṣeri, Ṣobabu àti Ardoni.
Chaleb vero filius Esrom accepit uxorem nomine Azuba de qua genuit Ierioth fueruntque filii eius Iesar et Sobab et Ardon
19 Nígbà tí Asuba sì kú, Kalebu sì fẹ́ Efrata ní aya, ẹni tí ó bí Huri fún un.
cumque mortua fuisset Azuba accepit uxorem Chaleb Ephrath quae peperit ei Ur
20 Huri ni baba Uri, Uri sì jẹ́ baba Besaleli.
porro Ur genuit Uri et Uri genuit Beselehel
21 Nígbà tí ó yá, Hesroni sì dùbúlẹ̀ pẹ̀lú ọmọbìnrin Makiri baba Gileadi (ó sì ti fẹ́ ní aya láti ìgbà tí ó ti wà ní ẹni ọgọ́ta ọdún) ó sì bí Segubu.
post haec ingressus est Esrom ad filiam Machir patris Galaad et accepit eam cum esset annorum sexaginta quae peperit ei Segub
22 Segubu sì jẹ́ baba Jairi, ẹni tí ó jẹ́ olùdarí ìlú mẹ́tàlélógún ní ilẹ̀ Gileadi.
sed et Segub genuit Iair et possedit viginti tres civitates in terra Galaad
23 (Ṣùgbọ́n Geṣuri àti Aramu sì fi agbára gba Hafoti-Jairi, àti Kenati pẹ̀lú gbogbo agbègbè rẹ̀ tí wọn tẹ̀dó sí jẹ́ ọgọ́ta ìlú.) Gbogbo wọ̀nyí ni àwọn ọmọ Makiri baba Gileadi.
cepitque Gessur et Aram oppida Iair et Canath et viculos eius sexaginta civitatum omnes isti filii Machir patris Galaad
24 Lẹ́yìn tí Hesroni sì kú ni Kalebu Efrata, Abijah ìyàwó rẹ̀ ti Hesroni sì bí Aṣihuri baba Tekoa fún un.
cum autem mortuus esset Esrom ingressus est Chaleb ad Ephrata habuit quoque Esrom uxorem Abia quae peperit ei Assur patrem Thecue
25 Ọmọ Jerahmeeli àkọ́bí Hesroni: Ramu ọmọ àkọ́bí rẹ̀ Buna, Oreni, Osemu àti Ahijah.
nati sunt autem filii Hieramehel primogeniti Esrom Ram primogenitus eius et Buna et Aran et Asom et Ahia
26 Jerahmeeli ní ìyàwó mìíràn, ẹni tí orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Atara; ó sì jẹ́ ìyá fún Onamu.
duxit quoque uxorem alteram Hieramehel nomine Atara quae fuit mater Onam
27 Àwọn ọmọ Ramu àkọ́bí Jerahmeeli: Maasi, Jamini àti Ekeri.
sed et filii Ram primogeniti Hieramehel fuerunt Moos et Iamin et Achar
28 Àwọn ọmọ Onamu: Ṣammai àti Jada. Àwọn ọmọ Ṣammai: Nadabu àti Abiṣuri.
Onam autem habuit filios Semmei et Iada filii autem Semmei Nadab et Abisur
29 Orúkọ ìyàwó Abiṣuri ni Abihaili ẹni tí ó bí Ahbani àti Molidi.
nomen vero uxoris Abisur Abiail quae peperit Ahobban et Molid
30 Àwọn ọmọ Nadabu Seledi àti Appaimu. Seledi sì kú láìsí ọmọ.
filii autem Nadab fuerunt Saled et Apphaim mortuus est autem Saled absque liberis
31 Àwọn ọmọ Appaimu: Iṣi, ẹni tí ó jẹ́ baba fún Ṣeṣani. Ṣeṣani sì jẹ́ baba fún Ahlai.
filius vero Apphaim Iesi qui Iesi genuit Sesan porro Sesan genuit Oholi
32 Àwọn ọmọ Jada, arákùnrin Ṣammai: Jeteri àti Jonatani. Jeteri sì kú láìní ọmọ.
filii autem Iada fratris Semmei Iether et Ionathan sed et Iether mortuus est absque liberis
33 Àwọn ọmọ Jonatani: Peleti àti Sasa. Àwọn wọ̀nyí ni ọmọ Jerahmeeli.
porro Ionathan genuit Phaleth et Ziza isti fuerunt filii Hieramehel
34 Ṣeṣani kò sì ní ọmọkùnrin àwọn ọmọbìnrin nìkan ni ó ní. Ó sì ní ìránṣẹ́ ará Ejibiti tí orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Jariha.
Sesan autem non habuit filios sed filias et servum aegyptium nomine Ieraa
35 Ṣeṣani sì fi ọmọ obìnrin rẹ̀ ní aya fún ìránṣẹ́ rẹ̀ Jariha, ó sì bí ọmọ fún tí orúkọ rẹ̀ jẹ́ Attai.
deditque ei filiam suam uxorem quae peperit ei Eththei
36 Attai sì jẹ́ baba fún Natani, Natani sì jẹ́ baba fún Sabadi,
Eththei autem genuit Nathan et Nathan genuit Zabad
37 Sabadi ni baba Eflali, Eflali jẹ́ baba Obedi,
Zabad quoque genuit Ophlal et Ophlal genuit Obed
38 Obedi sì ni baba Jehu, Jehu ni baba Asariah,
Obed genuit Ieu Ieu genuit Azariam
39 Asariah sì ni baba Helesi, Helesi ni baba Eleasa,
Azarias genuit Helles Helles genuit Elasa
40 Eleasa ni baba Sismai, Sismai ni baba Ṣallumu,
Elasa genuit Sisamoi Sisamoi genuit Sellum
41 Ṣallumu sì ni baba Jekamiah, Jekamiah sì ni baba Eliṣama.
Sellum genuit Icamian Icamian genuit Elisama
42 Àwọn ọmọ Kalebu arákùnrin Jerahmeeli: Meṣa àkọ́bí rẹ̀, ẹni tí ó jẹ́ baba fún Sifi, àti àwọn ọmọ rẹ̀ Meraṣa, ẹni tí ó jẹ́ baba fún Hebroni.
filii autem Chaleb fratris Hieramehel Mosa primogenitus eius ipse est pater Ziph et filii Maresa patris Hebron
43 Àwọn ọmọ Hebroni: Kora, Tapua, Rekemu, àti Ṣema.
porro filii Hebron Core et Thapphu et Recem et Samma
44 Ṣema ni baba Rahamu, Rahamu sì jẹ́ baba fún Jorkeamu. Rekemu sì ni baba Ṣammai.
Samma autem genuit Raam patrem Iercaam et Recem genuit Semmei
45 Àwọn ọmọ Ṣammai ni Maoni, Maoni sì ni baba Beti-Suri.
filius Semmei Maon et Maon pater Bethsur
46 Efani obìnrin Kalebu sì ni ìyá Harani, Mosa àti Gasesi, Harani sì ni baba Gasesi.
Epha autem concubina Chaleb peperit Arran et Musa et Gezez porro Arran genuit Gezez
47 Àwọn ọmọ Jahdai: Regemu, Jotamu, Geṣani, Peleti, Efani àti Ṣaafu.
filii Iadai Regom et Iotham et Gesum et Phaleth et Epha et Saaph
48 Maaka obìnrin Kalebu sì ni ìyá Seberi àti Tirhana.
concubina Chaleb Maacha peperit Saber et Tharana
49 Ó sì bí Ṣaafu baba Madmana, Ṣefa baba Makbena àti baba Gibeah, ọmọbìnrin Kalebu sì ni Aksa.
genuit autem Saaph pater Madmena Sue patrem Machbena et patrem Gabaa filia vero Chaleb fuit Achsa
50 Àwọn wọ̀nyí ni ọmọ Kalebu. Àwọn ọmọ Huri, àkọ́bí Efrata: Ṣobali baba Kiriati-Jearimu.
hii erant filii Chaleb filii Ur primogeniti Ephrata Sobal pater Cariathiarim
51 Salma baba Bẹtilẹhẹmu àti Harefu baba Beti-Gaderi.
Salma pater Bethleem Ariph pater Bethgader
52 Àwọn ọmọ Ṣobali baba Kiriati-Jearimu ni: Haroe, ìdajì àwọn ará Manaheti.
fuerunt autem filii Sobal patris Cariathiarim qui videbat dimidium requietionum
53 Àti ìdílé Kiriati-Jearimu: àti àwọn ara Itri, àti àwọn ará Puti, àti àwọn ará Ṣumati àti àwọn ará Miṣraiti: láti ọ̀dọ̀ wọn ni àwọn ọmọ ará Sorati àti àwọn ará Eṣtaoli ti wá.
et de cognatione Cariathiarim Iethrei et Apphutei et Semathei et Maserei ex his egressi sunt Saraitae et Esthaolitae
54 Àwọn ọmọ Salma: Bẹtilẹhẹmu, àti àwọn ará Netofa, Atrotu Beti-Joabu, ìdajì àwọn ará Manahati, àti ará Sori,
filii Salma Bethleem et Netophathi coronae domus Ioab et dimidium requietionis Sarai
55 àti àwọn ìdílé àwọn akọ̀wé, ẹni tí ń gbé ní Jabesi: àti àwọn ọmọ Tirati àti àwọn ará Ṣimeati àti àwọn ará Sukati. Àwọn wọ̀nyí ni àwọn ará Keni, ẹni tí ó wá láti ọ̀dọ̀ Hamati, baba ilé Rekabu.
cognationes quoque scribarum habitantium in Iabis canentes atque resonantes et in tabernaculis commorantes hii sunt Cinei qui venerunt de calore patris domus Rechab

< 1 Chronicles 2 >