< 1 Chronicles 2 >

1 Àwọn wọ̀nyí ni àwọn ọmọ Israẹli. Reubeni, Simeoni, Lefi, Juda, Isakari, Sebuluni,
Dies sind die Söhne Israels: Ruben, Simeon, Levi und Juda, Issachar und Sebulon,
2 Dani, Josẹfu, Benjamini; Naftali, Gadi: àti Aṣeri.
Dan Joseph und Benjamin, Naphthali, Gad und Asser.
3 Àwọn ọmọ Juda: Eri, Onani àti Ṣela, àwọn mẹ́tẹ̀ẹ̀ta wọ̀nyí ni wọ́n bí fún un láti ọ̀dọ̀ arábìnrin Kenaani, ọmọbìnrin Ṣua. Eri àkọ́bí Juda, ó sì burú ní ojú Olúwa, bẹ́ẹ̀ ni Olúwa sì pa á.
Die Söhne Judas waren: Ger, Onan und Sela, drei, die ihm von der Tochter Suas, der Kanaaniterin, geboren wurden. Es machte sich aber Ger, der Erstgeborene Judas, Jahwe mißfällig; daher ließ er ihn sterben.
4 Tamari, aya ọmọbìnrin Juda, ó sì bí Peresi àti Sera sì ní ọmọ márùn-ún ní àpapọ̀.
Seine Schwiegertochter Thamar gebar ihm Perez und Serah. Die Gesamtzahl der Söhne Judas war fünf.
5 Àwọn ọmọ Peresi: Hesroni àti Hamulu.
Die Söhne Perez waren: Hezron und Hamul.
6 Àwọn ọmọ Sera: Simri, Etani, Hemani, Kalkoli àti Dara, gbogbo wọn jẹ́ márùn-ún.
Und die Söhne Serahs: Simri, Ethan, Heman, Chalkol und Dara, zusammen fünf.
7 Àwọn ọmọ Karmi: Akani, ẹni tí ó mú ìyọnu wá sórí Israẹli nípa ẹ̀ṣẹ̀ ìfibú lórí mímú ohun ìyàsọ́tọ̀.
Und die Söhne Karmis: Achar, der Israel ins Unglück stürzte, indem er sich treulos am Geweihten vergriff.
8 Àwọn ọmọ Etani: Asariah.
Und die Söhne Ethans: Asarja.
9 Àwọn ọmọ tí a bí fún Hesroni ni: Jerahmeeli, Ramu àti Kalebu.
Und die Söhne Hezrons, die ihm geboren wurden: Jerahmeel, Ram und Kelubai.
10 Ramu sì ni baba Amminadabu, àti Amminadabu baba Nahiṣoni olórí àwọn ènìyàn Juda.
Ram aber erzeugte Amminadab, und Amminadab erzeugte Nahesson, den Fürsten der Judäer;
11 Nahiṣoni sì ni baba Salmoni, Salmoni ni baba Boasi,
Nahesson erzeugte Salma, Salma erzeugte Boas,
12 Boasi baba Obedi àti Obedi baba Jese.
Boas erzeugte Obed, Obed erzeugte Isai.
13 Jese sì ni baba Eliabu àkọ́bí rẹ̀; ọmọ ẹlẹ́ẹ̀kejì sì ni Abinadabu, ẹlẹ́ẹ̀kẹta ni Ṣimea,
Und Isai erzeugte Eliab, seinen Erstgeborenen, und Abinadab als zweiten, Simea als dritten,
14 ẹlẹ́ẹ̀kẹrin Netaneli, ẹlẹ́ẹ̀karùnún Raddai,
Nethaneel als vierten, Raddai als fünften,
15 ẹlẹ́ẹ̀kẹfà Osemu àti ẹlẹ́ẹ̀keje Dafidi.
Ozem als sechsten, David als siebenten.
16 Àwọn arábìnrin wọn ni Seruiah àti Abigaili. Àwọn ọmọ mẹ́ta Seruiah ni Abiṣai, Joabu àti Asaheli.
Und ihre Schwestern waren: Zeruja und Abigail; und die Söhne Zerujas waren Absai, Joab und Asahel, zusammen drei.
17 Abigaili ni ìyá Amasa, ẹni tí baba rẹ̀ sì jẹ́ Jeteri ará Iṣmaeli.
Abigail aber gebar Amasa, und der Vater Amasas war der Ismaelit Jether.
18 Kalebu ọmọ Hesroni ní ọmọ láti ọ̀dọ̀ ìyàwó rẹ̀ Asuba (láti ọ̀dọ̀ Jerioti). Àwọn wọ̀nyí ni àwọn ọmọ rẹ̀: Jeṣeri, Ṣobabu àti Ardoni.
Kaleb aber, der Sohn Hezrons, erzeugte Kinder mit Asuba und mit Jerioth; und dies sind deren Söhne: Jeser, Sobab und Ardon.
19 Nígbà tí Asuba sì kú, Kalebu sì fẹ́ Efrata ní aya, ẹni tí ó bí Huri fún un.
Und als Asuba gestorben war, heiratete Kaleb die Ephrath; die gebar ihm Hur.
20 Huri ni baba Uri, Uri sì jẹ́ baba Besaleli.
Hur aber erzeugte Uri und Uri erzeugte Bezaleel.
21 Nígbà tí ó yá, Hesroni sì dùbúlẹ̀ pẹ̀lú ọmọbìnrin Makiri baba Gileadi (ó sì ti fẹ́ ní aya láti ìgbà tí ó ti wà ní ẹni ọgọ́ta ọdún) ó sì bí Segubu.
Darnach verband sich Hezron mit der Tochter Machirs, des Vaters Gileads, und nahm sie zum Weibe, als er sechzig Jahre alt war; die gebar ihm Segub.
22 Segubu sì jẹ́ baba Jairi, ẹni tí ó jẹ́ olùdarí ìlú mẹ́tàlélógún ní ilẹ̀ Gileadi.
und Segub erzeugte Jair; der besaß dreiundzwanzig Städte im Lande Gilead.
23 (Ṣùgbọ́n Geṣuri àti Aramu sì fi agbára gba Hafoti-Jairi, àti Kenati pẹ̀lú gbogbo agbègbè rẹ̀ tí wọn tẹ̀dó sí jẹ́ ọgọ́ta ìlú.) Gbogbo wọ̀nyí ni àwọn ọmọ Makiri baba Gileadi.
Aber die Gesuriter und Aramäer nahmen ihnen die Zeltdörfer Jairs, Kenath und die zugehörigen Ortschaften, zusammen sechzig Städte. Diese alle waren Söhne Machirs, des Vaters Gileads.
24 Lẹ́yìn tí Hesroni sì kú ni Kalebu Efrata, Abijah ìyàwó rẹ̀ ti Hesroni sì bí Aṣihuri baba Tekoa fún un.
Und nach dem Tode Hezrons kam Kaleb nach Ephrath. Und das Weib Hezrons war Abia; die gebar ihm Ashur, den Vater Thekoas.
25 Ọmọ Jerahmeeli àkọ́bí Hesroni: Ramu ọmọ àkọ́bí rẹ̀ Buna, Oreni, Osemu àti Ahijah.
und die Söhne Jerahmeels, des Erstgeborenen Hezrons, waren: Ram, der Erstgeborene, und Buna, Oren, Ozem, Ahia.
26 Jerahmeeli ní ìyàwó mìíràn, ẹni tí orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Atara; ó sì jẹ́ ìyá fún Onamu.
Und Jerahmeel hatte noch ein anderes Weib, die hieß Atara; diese war die Mutter Onams.
27 Àwọn ọmọ Ramu àkọ́bí Jerahmeeli: Maasi, Jamini àti Ekeri.
Und die Söhne Rams, des Erstgeborenen Jerahmeels, waren: Maaz, Jamin und Eker.
28 Àwọn ọmọ Onamu: Ṣammai àti Jada. Àwọn ọmọ Ṣammai: Nadabu àti Abiṣuri.
Und die Söhne Onams waren: Sammai und Jada, und die Söhne Sammais: Nadab und Abisur.
29 Orúkọ ìyàwó Abiṣuri ni Abihaili ẹni tí ó bí Ahbani àti Molidi.
Das Weib Abisurs aber hieß Abihail; die gebar ihm Achban und Molid.
30 Àwọn ọmọ Nadabu Seledi àti Appaimu. Seledi sì kú láìsí ọmọ.
Und die Söhne Nadabs waren: Seled und Appaim; Seled aber starb kinderlos.
31 Àwọn ọmọ Appaimu: Iṣi, ẹni tí ó jẹ́ baba fún Ṣeṣani. Ṣeṣani sì jẹ́ baba fún Ahlai.
Und die Söhne Appaims waren: Jisei; und die Söhne Jiseis: Sesan; und die Söhne Sesans: Ahelai.
32 Àwọn ọmọ Jada, arákùnrin Ṣammai: Jeteri àti Jonatani. Jeteri sì kú láìní ọmọ.
Und die Söhne Jadas, des Bruders Sammais, waren: Jether und Jonathan; Jether aber starb kinderlos.
33 Àwọn ọmọ Jonatani: Peleti àti Sasa. Àwọn wọ̀nyí ni ọmọ Jerahmeeli.
Und die Söhne Jonathans waren: Peleth und Sasa. Das waren die Söhne Jerahmeels.
34 Ṣeṣani kò sì ní ọmọkùnrin àwọn ọmọbìnrin nìkan ni ó ní. Ó sì ní ìránṣẹ́ ará Ejibiti tí orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Jariha.
Und Sesan hatte keine Söhne, sondern nur Töchter. Es besaß aber Sesan einen ägyptischen Sklaven, der hieß Jarha.
35 Ṣeṣani sì fi ọmọ obìnrin rẹ̀ ní aya fún ìránṣẹ́ rẹ̀ Jariha, ó sì bí ọmọ fún tí orúkọ rẹ̀ jẹ́ Attai.
Und Sesan gab seinem Sklaven Jarha seine Tochter zum Weibe; die gebar ihm Attai.
36 Attai sì jẹ́ baba fún Natani, Natani sì jẹ́ baba fún Sabadi,
Attai erzeugte Nathan, Nathan erzeugte Sabad,
37 Sabadi ni baba Eflali, Eflali jẹ́ baba Obedi,
Sabad erzeugte Ephlal, Ephlal erzeugte Obed,
38 Obedi sì ni baba Jehu, Jehu ni baba Asariah,
Obed erzeugte Jehu, Jehu erzeugte Asarja,
39 Asariah sì ni baba Helesi, Helesi ni baba Eleasa,
Asarja erzeugte Helez, Helez erzeugte Eleasa,
40 Eleasa ni baba Sismai, Sismai ni baba Ṣallumu,
Eleasa erzeugte Sisemai, Sisemai erzeugte Sallum,
41 Ṣallumu sì ni baba Jekamiah, Jekamiah sì ni baba Eliṣama.
Sallum erzeugte Jekamja, Jekamja erzeugte Elisama.
42 Àwọn ọmọ Kalebu arákùnrin Jerahmeeli: Meṣa àkọ́bí rẹ̀, ẹni tí ó jẹ́ baba fún Sifi, àti àwọn ọmọ rẹ̀ Meraṣa, ẹni tí ó jẹ́ baba fún Hebroni.
Und die Söhne Kalebs, des Bruders Jerahmeels, waren: Mesa, sein Erstgeborener, das ist der Vater von Siph, und die Bewohner Maresas, des Vaters von Hebron.
43 Àwọn ọmọ Hebroni: Kora, Tapua, Rekemu, àti Ṣema.
Und die Söhne Hebrons waren: Korah, Thappuah, Rekem und Sema.
44 Ṣema ni baba Rahamu, Rahamu sì jẹ́ baba fún Jorkeamu. Rekemu sì ni baba Ṣammai.
Sema erzeugte Raham, den Vater Jorkeams, und Rekem erzeugte Sammai.
45 Àwọn ọmọ Ṣammai ni Maoni, Maoni sì ni baba Beti-Suri.
Der Sohn Sammais aber war Maon, und Maon war der Vater von Beth-Zur.
46 Efani obìnrin Kalebu sì ni ìyá Harani, Mosa àti Gasesi, Harani sì ni baba Gasesi.
Und Epha, das Kebsweib Kalebs, gebar Haran, Moza und Gases; Haran aber erzeugte Gases.
47 Àwọn ọmọ Jahdai: Regemu, Jotamu, Geṣani, Peleti, Efani àti Ṣaafu.
Und die Söhne Jehdais waren: Regem, Jotham, Gesan, Pelet, Epha und Saaph.
48 Maaka obìnrin Kalebu sì ni ìyá Seberi àti Tirhana.
Maacha, das Kebsweib Kalebs, gebar Seber und Thirhena.
49 Ó sì bí Ṣaafu baba Madmana, Ṣefa baba Makbena àti baba Gibeah, ọmọbìnrin Kalebu sì ni Aksa.
Und sie gebar auch Saaph, Saaph, den Vater Madmannas, Sewa, den Vater Machbenas und den Vater Gibeas; und die Tochter Kalebs war Achsa.
50 Àwọn wọ̀nyí ni ọmọ Kalebu. Àwọn ọmọ Huri, àkọ́bí Efrata: Ṣobali baba Kiriati-Jearimu.
Dies sind die Söhne Kalebs: die Söhne Hurs, des Erstgeborenen von Ephratha, waren: Sobal, der Vater von Kirjath-Jearim,
51 Salma baba Bẹtilẹhẹmu àti Harefu baba Beti-Gaderi.
Salma, der Vater von Bethlehem, Hareph, der Vater von Beth-Gader.
52 Àwọn ọmọ Ṣobali baba Kiriati-Jearimu ni: Haroe, ìdajì àwọn ará Manaheti.
Und Sobal, der Vater von Kirjath-Jearim, hatte zu Söhnen: Haroe, halb Menuhoth
53 Àti ìdílé Kiriati-Jearimu: àti àwọn ara Itri, àti àwọn ará Puti, àti àwọn ará Ṣumati àti àwọn ará Miṣraiti: láti ọ̀dọ̀ wọn ni àwọn ọmọ ará Sorati àti àwọn ará Eṣtaoli ti wá.
und die Geschlechter von Kirjath-Jearim, sowie die Jithriter, die Puthiter, die Sumathiter und die Misraiter. Von diesen gingen aus die Zoreathiter und die Esthaoliter.
54 Àwọn ọmọ Salma: Bẹtilẹhẹmu, àti àwọn ará Netofa, Atrotu Beti-Joabu, ìdajì àwọn ará Manahati, àti ará Sori,
Die Söhne Salmas sind: Bethlehem und Netophathiter, Ataroth, Beth-Joab und die Hälfte der Manahthiter, das ist der Zoreiter,
55 àti àwọn ìdílé àwọn akọ̀wé, ẹni tí ń gbé ní Jabesi: àti àwọn ọmọ Tirati àti àwọn ará Ṣimeati àti àwọn ará Sukati. Àwọn wọ̀nyí ni àwọn ará Keni, ẹni tí ó wá láti ọ̀dọ̀ Hamati, baba ilé Rekabu.
und die Geschlechter der Schriftgelehrten, die Jabez bewohnen, die Thireathiter, die Simeathiter und die Suchathiter. Das sind die Kiniter, die von Hammath, dem Stammvater des Hauses Rechabs, abstammen.

< 1 Chronicles 2 >