< 1 Chronicles 2 >

1 Àwọn wọ̀nyí ni àwọn ọmọ Israẹli. Reubeni, Simeoni, Lefi, Juda, Isakari, Sebuluni,
These [are] sons of Israel: Reuben, Simeon, Levi, and Judah, Issachar, and Zebulun,
2 Dani, Josẹfu, Benjamini; Naftali, Gadi: àti Aṣeri.
Dan, Joseph, and Benjamin, Naphtali, Gad, and Asher.
3 Àwọn ọmọ Juda: Eri, Onani àti Ṣela, àwọn mẹ́tẹ̀ẹ̀ta wọ̀nyí ni wọ́n bí fún un láti ọ̀dọ̀ arábìnrin Kenaani, ọmọbìnrin Ṣua. Eri àkọ́bí Juda, ó sì burú ní ojú Olúwa, bẹ́ẹ̀ ni Olúwa sì pa á.
Sons of Judah: Er, and Onan, and Shelah, three have been born to him of a daughter of Shua the Canaanitess. And Er, firstborn of Judah, is evil in the eyes of YHWH, and He puts him to death.
4 Tamari, aya ọmọbìnrin Juda, ó sì bí Peresi àti Sera sì ní ọmọ márùn-ún ní àpapọ̀.
And his daughter-in-law Tamar has borne Perez and Zerah to him. All the sons of Judah [are] five.
5 Àwọn ọmọ Peresi: Hesroni àti Hamulu.
Sons of Perez: Hezron, and Hamul.
6 Àwọn ọmọ Sera: Simri, Etani, Hemani, Kalkoli àti Dara, gbogbo wọn jẹ́ márùn-ún.
And sons of Zerah: Zimri, and Ethan, and Heman, and Calcol, and Dara; all of them five.
7 Àwọn ọmọ Karmi: Akani, ẹni tí ó mú ìyọnu wá sórí Israẹli nípa ẹ̀ṣẹ̀ ìfibú lórí mímú ohun ìyàsọ́tọ̀.
And sons of Carmi: Achar, troubler of Israel, who trespassed in the devoted thing.
8 Àwọn ọmọ Etani: Asariah.
And sons of Ethan: Azariah.
9 Àwọn ọmọ tí a bí fún Hesroni ni: Jerahmeeli, Ramu àti Kalebu.
And sons of Hezron who were born to him: Jerahmeel, and Ram, and Chelubai.
10 Ramu sì ni baba Amminadabu, àti Amminadabu baba Nahiṣoni olórí àwọn ènìyàn Juda.
And Ram begot Amminadab, and Amminadab begot Nahshon, prince of the sons of Judah;
11 Nahiṣoni sì ni baba Salmoni, Salmoni ni baba Boasi,
and Nahshon begot Salma, and Salma begot Boaz,
12 Boasi baba Obedi àti Obedi baba Jese.
and Boaz begot Obed, and Obed begot Jesse;
13 Jese sì ni baba Eliabu àkọ́bí rẹ̀; ọmọ ẹlẹ́ẹ̀kejì sì ni Abinadabu, ẹlẹ́ẹ̀kẹta ni Ṣimea,
and Jesse begot his firstborn Eliab, and Abinadab the second, and Shimea the third,
14 ẹlẹ́ẹ̀kẹrin Netaneli, ẹlẹ́ẹ̀karùnún Raddai,
Nethaneel the fourth, Raddai the fifth,
15 ẹlẹ́ẹ̀kẹfà Osemu àti ẹlẹ́ẹ̀keje Dafidi.
Ozem the sixth, David the seventh,
16 Àwọn arábìnrin wọn ni Seruiah àti Abigaili. Àwọn ọmọ mẹ́ta Seruiah ni Abiṣai, Joabu àti Asaheli.
and their sisters Zeruiah and Abigail. And sons of Zeruiah: Abishai, and Joab, and Asah-El—three.
17 Abigaili ni ìyá Amasa, ẹni tí baba rẹ̀ sì jẹ́ Jeteri ará Iṣmaeli.
And Abigail has borne Amasa, and the father of Amasa [is] Jether the Ishmaelite.
18 Kalebu ọmọ Hesroni ní ọmọ láti ọ̀dọ̀ ìyàwó rẹ̀ Asuba (láti ọ̀dọ̀ Jerioti). Àwọn wọ̀nyí ni àwọn ọmọ rẹ̀: Jeṣeri, Ṣobabu àti Ardoni.
And Caleb son of Hezron has begotten Azubah, Isshah, and Jerioth; and these [are] her sons: Jesher, and Shobab, and Ardon.
19 Nígbà tí Asuba sì kú, Kalebu sì fẹ́ Efrata ní aya, ẹni tí ó bí Huri fún un.
And Azubah dies, and Caleb takes Ephrath to himself, and she bears Hur to him.
20 Huri ni baba Uri, Uri sì jẹ́ baba Besaleli.
And Hur begot Uri, and Uri begot Bezaleel.
21 Nígbà tí ó yá, Hesroni sì dùbúlẹ̀ pẹ̀lú ọmọbìnrin Makiri baba Gileadi (ó sì ti fẹ́ ní aya láti ìgbà tí ó ti wà ní ẹni ọgọ́ta ọdún) ó sì bí Segubu.
And afterward Hezron has gone in to a daughter of Machir father of Gilead, and he has taken her, and he [is] a son of sixty years, and she bears Segub to him.
22 Segubu sì jẹ́ baba Jairi, ẹni tí ó jẹ́ olùdarí ìlú mẹ́tàlélógún ní ilẹ̀ Gileadi.
And Segub begot Jair, and he has twenty-three cities in the land of Gilead,
23 (Ṣùgbọ́n Geṣuri àti Aramu sì fi agbára gba Hafoti-Jairi, àti Kenati pẹ̀lú gbogbo agbègbè rẹ̀ tí wọn tẹ̀dó sí jẹ́ ọgọ́ta ìlú.) Gbogbo wọ̀nyí ni àwọn ọmọ Makiri baba Gileadi.
and he takes Geshur and Aram, the small villages of Jair, from them, with Kenath and its small towns, sixty cities—all these [belonged to] the sons of Machir father of Gilead.
24 Lẹ́yìn tí Hesroni sì kú ni Kalebu Efrata, Abijah ìyàwó rẹ̀ ti Hesroni sì bí Aṣihuri baba Tekoa fún un.
And after the death of Hezron in Caleb-Ephratah, then the wife of Hezron, Abijah, even bears to him Asshur, father of Tekoa.
25 Ọmọ Jerahmeeli àkọ́bí Hesroni: Ramu ọmọ àkọ́bí rẹ̀ Buna, Oreni, Osemu àti Ahijah.
And sons of Jerahmeel, firstborn of Hezron, are: the firstborn Ram, and Bunah, and Oren, and Ozem, Ahijah.
26 Jerahmeeli ní ìyàwó mìíràn, ẹni tí orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Atara; ó sì jẹ́ ìyá fún Onamu.
And Jerahmeel has another wife, and her name [is] Atarah, she [is] mother of Onam.
27 Àwọn ọmọ Ramu àkọ́bí Jerahmeeli: Maasi, Jamini àti Ekeri.
And sons of Ram, firstborn of Jerahmeel, are Maaz, and Jamin, and Eker.
28 Àwọn ọmọ Onamu: Ṣammai àti Jada. Àwọn ọmọ Ṣammai: Nadabu àti Abiṣuri.
And sons of Onam are Shammai and Jada. And sons of Shammai: Nadab and Abishur.
29 Orúkọ ìyàwó Abiṣuri ni Abihaili ẹni tí ó bí Ahbani àti Molidi.
And the name of the wife of Abishur [is] Abihail, and she bears Ahban and Molid to him.
30 Àwọn ọmọ Nadabu Seledi àti Appaimu. Seledi sì kú láìsí ọmọ.
And sons of Nadab: Seled and Appaim; and Seled dies without sons.
31 Àwọn ọmọ Appaimu: Iṣi, ẹni tí ó jẹ́ baba fún Ṣeṣani. Ṣeṣani sì jẹ́ baba fún Ahlai.
And sons of Appaim: Ishi. And sons of Ishi: Sheshan. And sons of Sheshan: Ahlai.
32 Àwọn ọmọ Jada, arákùnrin Ṣammai: Jeteri àti Jonatani. Jeteri sì kú láìní ọmọ.
And sons of Jada, brother of Shammai: Jether and Jonathan; and Jether dies without sons.
33 Àwọn ọmọ Jonatani: Peleti àti Sasa. Àwọn wọ̀nyí ni ọmọ Jerahmeeli.
And sons of Jonathan: Peleth and Zaza. These were sons of Jerahmeel.
34 Ṣeṣani kò sì ní ọmọkùnrin àwọn ọmọbìnrin nìkan ni ó ní. Ó sì ní ìránṣẹ́ ará Ejibiti tí orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Jariha.
And Sheshan had no sons, but daughters, and Sheshan has a servant, an Egyptian, and his name [is] Jarha,
35 Ṣeṣani sì fi ọmọ obìnrin rẹ̀ ní aya fún ìránṣẹ́ rẹ̀ Jariha, ó sì bí ọmọ fún tí orúkọ rẹ̀ jẹ́ Attai.
and Sheshan gives his daughter to his servant Jarha for a wife, and she bears Attai to him;
36 Attai sì jẹ́ baba fún Natani, Natani sì jẹ́ baba fún Sabadi,
and Attai begot Nathan, and Nathan begot Zabad,
37 Sabadi ni baba Eflali, Eflali jẹ́ baba Obedi,
and Zabad begot Ephlal, and Ephlal begot Obed,
38 Obedi sì ni baba Jehu, Jehu ni baba Asariah,
and Obed begot Jehu,
39 Asariah sì ni baba Helesi, Helesi ni baba Eleasa,
and Jehu begot Azariah, and Azariah begot Helez, and Helez begot Eleasah,
40 Eleasa ni baba Sismai, Sismai ni baba Ṣallumu,
and Eleasah begot Sismai, and Sismai begot Shallum,
41 Ṣallumu sì ni baba Jekamiah, Jekamiah sì ni baba Eliṣama.
and Shallum begot Jekamiah, and Jekamiah begot Elishama.
42 Àwọn ọmọ Kalebu arákùnrin Jerahmeeli: Meṣa àkọ́bí rẹ̀, ẹni tí ó jẹ́ baba fún Sifi, àti àwọn ọmọ rẹ̀ Meraṣa, ẹni tí ó jẹ́ baba fún Hebroni.
And sons of Caleb brother of Jerahmeel: Mesha his firstborn, he [is] father of Ziph; and sons of Mareshah: Abi-Hebron.
43 Àwọn ọmọ Hebroni: Kora, Tapua, Rekemu, àti Ṣema.
And sons of Hebron: Korah, and Tappuah, and Rekem, and Shema.
44 Ṣema ni baba Rahamu, Rahamu sì jẹ́ baba fún Jorkeamu. Rekemu sì ni baba Ṣammai.
And Shema begot Raham father of Jorkoam, and Rekem begot Shammai.
45 Àwọn ọmọ Ṣammai ni Maoni, Maoni sì ni baba Beti-Suri.
And a son of Shammai [is] Maon, and Maon [is] father of Beth-Zur.
46 Efani obìnrin Kalebu sì ni ìyá Harani, Mosa àti Gasesi, Harani sì ni baba Gasesi.
And Ephah concubine of Caleb bore Haran, and Moza, and Gazez; and Haran begot Gazez.
47 Àwọn ọmọ Jahdai: Regemu, Jotamu, Geṣani, Peleti, Efani àti Ṣaafu.
And sons of Jahdai: Regem, and Jotham, and Geshem, and Pelet, and Ephah, and Shaaph.
48 Maaka obìnrin Kalebu sì ni ìyá Seberi àti Tirhana.
The concubine of Caleb, Maachah, bore Sheber and Tirhanah;
49 Ó sì bí Ṣaafu baba Madmana, Ṣefa baba Makbena àti baba Gibeah, ọmọbìnrin Kalebu sì ni Aksa.
and she bears Shaaph father of Madmannah, Sheva father of Machbenah, and father of Gibea; and a daughter of Caleb [is] Achsa.
50 Àwọn wọ̀nyí ni ọmọ Kalebu. Àwọn ọmọ Huri, àkọ́bí Efrata: Ṣobali baba Kiriati-Jearimu.
These were sons of Caleb son of Hur, firstborn of Ephrathah: Shobal father of Kirjath-Jearim,
51 Salma baba Bẹtilẹhẹmu àti Harefu baba Beti-Gaderi.
Salma father of Beth-Lehem, Hareph father of Beth-Gader.
52 Àwọn ọmọ Ṣobali baba Kiriati-Jearimu ni: Haroe, ìdajì àwọn ará Manaheti.
And there are sons to Shobal father of Kirjath-Jearim: Haroeh, half of the Menuhothite;
53 Àti ìdílé Kiriati-Jearimu: àti àwọn ara Itri, àti àwọn ará Puti, àti àwọn ará Ṣumati àti àwọn ará Miṣraiti: láti ọ̀dọ̀ wọn ni àwọn ọmọ ará Sorati àti àwọn ará Eṣtaoli ti wá.
and the families of Kirjath-Jearim: the Ithrite, and the Puhite, and the Shumathite, and the Mishraite. The Zorathite and the Eshtaolite went out from these.
54 Àwọn ọmọ Salma: Bẹtilẹhẹmu, àti àwọn ará Netofa, Atrotu Beti-Joabu, ìdajì àwọn ará Manahati, àti ará Sori,
Sons of Salma: Beth-Lehem, and the Netophathite, Atroth, Beth-Joab, and half of the Menuhothite, the Zorite;
55 àti àwọn ìdílé àwọn akọ̀wé, ẹni tí ń gbé ní Jabesi: àti àwọn ọmọ Tirati àti àwọn ará Ṣimeati àti àwọn ará Sukati. Àwọn wọ̀nyí ni àwọn ará Keni, ẹni tí ó wá láti ọ̀dọ̀ Hamati, baba ilé Rekabu.
and the families of the scribes, the inhabitants of Jabez: Tirathites, Shimeathites, Suchathites. They [are] the Kenites, those coming of Hammath father of the house of Rechab.

< 1 Chronicles 2 >