< 1 Chronicles 2 >

1 Àwọn wọ̀nyí ni àwọn ọmọ Israẹli. Reubeni, Simeoni, Lefi, Juda, Isakari, Sebuluni,
These are the sons of Israel; Reuben, Simeon, Levi, and Judah, Issachar, and Zebulun,
2 Dani, Josẹfu, Benjamini; Naftali, Gadi: àti Aṣeri.
Dan, Joseph, and Benjamin, Naphtali, Gad, and Asher.
3 Àwọn ọmọ Juda: Eri, Onani àti Ṣela, àwọn mẹ́tẹ̀ẹ̀ta wọ̀nyí ni wọ́n bí fún un láti ọ̀dọ̀ arábìnrin Kenaani, ọmọbìnrin Ṣua. Eri àkọ́bí Juda, ó sì burú ní ojú Olúwa, bẹ́ẹ̀ ni Olúwa sì pa á.
The sons of Judah; Er, and Onan, and Shelah: which three were born unto him of the daughter of Shua the Canaanitess. And Er, the firstborn of Judah, was evil in the sight of Yhwh; and he slew him.
4 Tamari, aya ọmọbìnrin Juda, ó sì bí Peresi àti Sera sì ní ọmọ márùn-ún ní àpapọ̀.
And Tamar his daughter in law bare him Pharez and Zerah. All the sons of Judah were five.
5 Àwọn ọmọ Peresi: Hesroni àti Hamulu.
The sons of Pharez; Hezron, and Hamul.
6 Àwọn ọmọ Sera: Simri, Etani, Hemani, Kalkoli àti Dara, gbogbo wọn jẹ́ márùn-ún.
And the sons of Zerah; Zimri, and Ethan, and Heman, and Calcol, and Dara: five of them in all.
7 Àwọn ọmọ Karmi: Akani, ẹni tí ó mú ìyọnu wá sórí Israẹli nípa ẹ̀ṣẹ̀ ìfibú lórí mímú ohun ìyàsọ́tọ̀.
And the sons of Carmi; Achar, the troubler of Israel, who transgressed in the thing accursed.
8 Àwọn ọmọ Etani: Asariah.
And the sons of Ethan; Azariah.
9 Àwọn ọmọ tí a bí fún Hesroni ni: Jerahmeeli, Ramu àti Kalebu.
The sons also of Hezron, that were born unto him; Jerahmeel, and Ram, and Chelubai.
10 Ramu sì ni baba Amminadabu, àti Amminadabu baba Nahiṣoni olórí àwọn ènìyàn Juda.
And Ram begat Amminadab; and Amminadab begat Nahshon, prince of the children of Judah;
11 Nahiṣoni sì ni baba Salmoni, Salmoni ni baba Boasi,
And Nahshon begat Salma, and Salma begat Boaz,
12 Boasi baba Obedi àti Obedi baba Jese.
And Boaz begat Obed, and Obed begat Jesse,
13 Jese sì ni baba Eliabu àkọ́bí rẹ̀; ọmọ ẹlẹ́ẹ̀kejì sì ni Abinadabu, ẹlẹ́ẹ̀kẹta ni Ṣimea,
And Jesse begat his firstborn Eliab, and Abinadab the second, and Shimma the third,
14 ẹlẹ́ẹ̀kẹrin Netaneli, ẹlẹ́ẹ̀karùnún Raddai,
Nethaneel the fourth, Raddai the fifth,
15 ẹlẹ́ẹ̀kẹfà Osemu àti ẹlẹ́ẹ̀keje Dafidi.
Ozem the sixth, David the seventh:
16 Àwọn arábìnrin wọn ni Seruiah àti Abigaili. Àwọn ọmọ mẹ́ta Seruiah ni Abiṣai, Joabu àti Asaheli.
Whose sisters were Zeruiah, and Abigail. And the sons of Zeruiah; Abishai, and Joab, and Asahel, three.
17 Abigaili ni ìyá Amasa, ẹni tí baba rẹ̀ sì jẹ́ Jeteri ará Iṣmaeli.
And Abigail bare Amasa: and the father of Amasa was Jether the Ishmeelite.
18 Kalebu ọmọ Hesroni ní ọmọ láti ọ̀dọ̀ ìyàwó rẹ̀ Asuba (láti ọ̀dọ̀ Jerioti). Àwọn wọ̀nyí ni àwọn ọmọ rẹ̀: Jeṣeri, Ṣobabu àti Ardoni.
And Caleb the son of Hezron begat children of Azubah his wife, and of Jerioth: her sons are these; Jesher, and Shobab, and Ardon.
19 Nígbà tí Asuba sì kú, Kalebu sì fẹ́ Efrata ní aya, ẹni tí ó bí Huri fún un.
And when Azubah was dead, Caleb took unto him Ephrath, which bare him Hur.
20 Huri ni baba Uri, Uri sì jẹ́ baba Besaleli.
And Hur begat Uri, and Uri begat Bezaleel.
21 Nígbà tí ó yá, Hesroni sì dùbúlẹ̀ pẹ̀lú ọmọbìnrin Makiri baba Gileadi (ó sì ti fẹ́ ní aya láti ìgbà tí ó ti wà ní ẹni ọgọ́ta ọdún) ó sì bí Segubu.
And afterward Hezron went in to the daughter of Machir the father of Gilead, whom he married when he was threescore years old; and she bare him Segub.
22 Segubu sì jẹ́ baba Jairi, ẹni tí ó jẹ́ olùdarí ìlú mẹ́tàlélógún ní ilẹ̀ Gileadi.
And Segub begat Jair, who had three and twenty cities in the land of Gilead.
23 (Ṣùgbọ́n Geṣuri àti Aramu sì fi agbára gba Hafoti-Jairi, àti Kenati pẹ̀lú gbogbo agbègbè rẹ̀ tí wọn tẹ̀dó sí jẹ́ ọgọ́ta ìlú.) Gbogbo wọ̀nyí ni àwọn ọmọ Makiri baba Gileadi.
And he took Geshur, and Aram, with the towns of Jair, from them, with Kenath, and the towns thereof, even threescore cities. All these belonged to the sons of Machir the father of Gilead.
24 Lẹ́yìn tí Hesroni sì kú ni Kalebu Efrata, Abijah ìyàwó rẹ̀ ti Hesroni sì bí Aṣihuri baba Tekoa fún un.
And after that Hezron was dead in Caleb–ephratah, then Abiah Hezron’s wife bare him Ashur the father of Tekoa.
25 Ọmọ Jerahmeeli àkọ́bí Hesroni: Ramu ọmọ àkọ́bí rẹ̀ Buna, Oreni, Osemu àti Ahijah.
And the sons of Jerahmeel the firstborn of Hezron were, Ram the firstborn, and Bunah, and Oren, and Ozem, and Ahijah.
26 Jerahmeeli ní ìyàwó mìíràn, ẹni tí orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Atara; ó sì jẹ́ ìyá fún Onamu.
Jerahmeel had also another wife, whose name was Atarah; she was the mother of Onam.
27 Àwọn ọmọ Ramu àkọ́bí Jerahmeeli: Maasi, Jamini àti Ekeri.
And the sons of Ram the firstborn of Jerahmeel were, Maaz, and Jamin, and Eker.
28 Àwọn ọmọ Onamu: Ṣammai àti Jada. Àwọn ọmọ Ṣammai: Nadabu àti Abiṣuri.
And the sons of Onam were, Shammai, and Jada. And the sons of Shammai; Nadab, and Abishur.
29 Orúkọ ìyàwó Abiṣuri ni Abihaili ẹni tí ó bí Ahbani àti Molidi.
And the name of the wife of Abishur was Abihail, and she bare him Ahban, and Molid.
30 Àwọn ọmọ Nadabu Seledi àti Appaimu. Seledi sì kú láìsí ọmọ.
And the sons of Nadab; Seled, and Appaim: but Seled died without children.
31 Àwọn ọmọ Appaimu: Iṣi, ẹni tí ó jẹ́ baba fún Ṣeṣani. Ṣeṣani sì jẹ́ baba fún Ahlai.
And the sons of Appaim; Ishi. And the sons of Ishi; Sheshan. And the children of Sheshan; Ahlai.
32 Àwọn ọmọ Jada, arákùnrin Ṣammai: Jeteri àti Jonatani. Jeteri sì kú láìní ọmọ.
And the sons of Jada the brother of Shammai; Jether, and Jonathan: and Jether died without children.
33 Àwọn ọmọ Jonatani: Peleti àti Sasa. Àwọn wọ̀nyí ni ọmọ Jerahmeeli.
And the sons of Jonathan; Peleth, and Zaza. These were the sons of Jerahmeel.
34 Ṣeṣani kò sì ní ọmọkùnrin àwọn ọmọbìnrin nìkan ni ó ní. Ó sì ní ìránṣẹ́ ará Ejibiti tí orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Jariha.
Now Sheshan had no sons, but daughters. And Sheshan had a servant, an Egyptian, whose name was Jarha.
35 Ṣeṣani sì fi ọmọ obìnrin rẹ̀ ní aya fún ìránṣẹ́ rẹ̀ Jariha, ó sì bí ọmọ fún tí orúkọ rẹ̀ jẹ́ Attai.
And Sheshan gave his daughter to Jarha his servant to wife; and she bare him Attai.
36 Attai sì jẹ́ baba fún Natani, Natani sì jẹ́ baba fún Sabadi,
And Attai begat Nathan, and Nathan begat Zabad,
37 Sabadi ni baba Eflali, Eflali jẹ́ baba Obedi,
And Zabad begat Ephlal, and Ephlal begat Obed,
38 Obedi sì ni baba Jehu, Jehu ni baba Asariah,
And Obed begat Jehu, and Jehu begat Azariah,
39 Asariah sì ni baba Helesi, Helesi ni baba Eleasa,
And Azariah begat Helez, and Helez begat Eleasah,
40 Eleasa ni baba Sismai, Sismai ni baba Ṣallumu,
And Eleasah begat Sisamai, and Sisamai begat Shallum,
41 Ṣallumu sì ni baba Jekamiah, Jekamiah sì ni baba Eliṣama.
And Shallum begat Jekamiah, and Jekamiah begat Elishama.
42 Àwọn ọmọ Kalebu arákùnrin Jerahmeeli: Meṣa àkọ́bí rẹ̀, ẹni tí ó jẹ́ baba fún Sifi, àti àwọn ọmọ rẹ̀ Meraṣa, ẹni tí ó jẹ́ baba fún Hebroni.
Now the sons of Caleb the brother of Jerahmeel were, Mesha his firstborn, which was the father of Ziph; and the sons of Mareshah the father of Hebron.
43 Àwọn ọmọ Hebroni: Kora, Tapua, Rekemu, àti Ṣema.
And the sons of Hebron; Korah, and Tappuah, and Rekem, and Shema.
44 Ṣema ni baba Rahamu, Rahamu sì jẹ́ baba fún Jorkeamu. Rekemu sì ni baba Ṣammai.
And Shema begat Raham, the father of Jorkoam: and Rekem begat Shammai.
45 Àwọn ọmọ Ṣammai ni Maoni, Maoni sì ni baba Beti-Suri.
And the son of Shammai was Maon: and Maon was the father of Beth–zur.
46 Efani obìnrin Kalebu sì ni ìyá Harani, Mosa àti Gasesi, Harani sì ni baba Gasesi.
And Ephah, Caleb’s concubine, bare Haran, and Moza, and Gazez: and Haran begat Gazez.
47 Àwọn ọmọ Jahdai: Regemu, Jotamu, Geṣani, Peleti, Efani àti Ṣaafu.
And the sons of Jahdai; Regem, and Jotham, and Geshan, and Pelet, and Ephah, and Shaaph.
48 Maaka obìnrin Kalebu sì ni ìyá Seberi àti Tirhana.
Maachah, Caleb’s concubine, bare Sheber, and Tirhanah.
49 Ó sì bí Ṣaafu baba Madmana, Ṣefa baba Makbena àti baba Gibeah, ọmọbìnrin Kalebu sì ni Aksa.
She bare also Shaaph the father of Madmannah, Sheva the father of Machbenah, and the father of Gibea: and the daughter of Caleb was Achsah.
50 Àwọn wọ̀nyí ni ọmọ Kalebu. Àwọn ọmọ Huri, àkọ́bí Efrata: Ṣobali baba Kiriati-Jearimu.
These were the sons of Caleb the son of Hur, the firstborn of Ephratah; Shobal the father of Kirjath–jearim,
51 Salma baba Bẹtilẹhẹmu àti Harefu baba Beti-Gaderi.
Salma the father of Beth–lehem, Hareph the father of Beth–gader.
52 Àwọn ọmọ Ṣobali baba Kiriati-Jearimu ni: Haroe, ìdajì àwọn ará Manaheti.
And Shobal the father of Kirjath–jearim had sons; Haroeh, and half of the Manahethites.
53 Àti ìdílé Kiriati-Jearimu: àti àwọn ara Itri, àti àwọn ará Puti, àti àwọn ará Ṣumati àti àwọn ará Miṣraiti: láti ọ̀dọ̀ wọn ni àwọn ọmọ ará Sorati àti àwọn ará Eṣtaoli ti wá.
And the families of Kirjath–jearim; the Ithrites, and the Puhites, and the Shumathites, and the Mishraites; of them came the Zareathites, and the Eshtaulites.
54 Àwọn ọmọ Salma: Bẹtilẹhẹmu, àti àwọn ará Netofa, Atrotu Beti-Joabu, ìdajì àwọn ará Manahati, àti ará Sori,
The sons of Salma; Beth–lehem, and the Netophathites, Ataroth, the house of Joab, and half of the Manahethites, the Zorites.
55 àti àwọn ìdílé àwọn akọ̀wé, ẹni tí ń gbé ní Jabesi: àti àwọn ọmọ Tirati àti àwọn ará Ṣimeati àti àwọn ará Sukati. Àwọn wọ̀nyí ni àwọn ará Keni, ẹni tí ó wá láti ọ̀dọ̀ Hamati, baba ilé Rekabu.
And the families of the scribes which dwelt at Jabez; the Tirathites, the Shimeathites, and Suchathites. These are the Kenites that came of Hemath, the father of the house of Rechab.

< 1 Chronicles 2 >