< 1 Chronicles 19 >

1 Ní àkókò yí, Nahaṣi ọba àwọn ará Ammoni sì kú, ọmọ rẹ̀ sì rọ́pò rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ọba.
Keyinki waⱪitlarda xundaⱪ boldiki, Ammonlarning padixaⱨi Naⱨax ɵldi; oƣli Ⱨanun orniƣa padixaⱨ boldi.
2 Dafidi rò wí pé èmi yóò fi inú rere hàn sí Hanuni ọmọ Nahaṣi, nítorí baba a rẹ̀ fi inú rere hàn sí mi. Bẹ́ẹ̀ ni, Dafidi rán àwọn aṣojú lọ láti lọ fi ìbá kẹ́dùn rẹ̀ hàn sí Hanuni ní ti baba a rẹ̀. Nígbà tí àwọn ọkùnrin Dafidi wá sí ọ̀dọ̀ Hanuni ní ilẹ̀ àwọn ará Ammoni láti fi ìbá kẹ́dùn rẹ̀ hàn sí i.
Dawut: «Naⱨax manga iltipat kɵrsǝtkini üqün, uning oƣli Ⱨanunƣa iltipat kɵrsitimǝn» dǝp, atisining pǝtisigǝ uning kɵnglini soraxⱪa Ⱨanunning yeniƣa ǝlqilǝrni ǝwǝtti. Dawutning ǝlqiliri Ammonlarning zeminƣa yetip kelip, kɵnglini soriƣili Ⱨanun bilǝn kɵrüxmǝkqi boldi.
3 Àwọn ọkùnrin ọlọ́lá ti Ammoni sọ fún Hanuni pé, “Ṣé ìwọ rò pé Dafidi ń bu ọlá fún baba rẹ nípa rírán àwọn olùtùnú sí ọ? Ṣé àwọn ọkùnrin rẹ̀ wá sí ọ̀dọ̀ rẹ láti rìn wò àti láti bì í ṣubú, àti láti ṣe ayọ́lẹ̀wò ilẹ̀ náà.”
Lekin Ammonlarning ǝmǝldarliri Ⱨanunƣa: «Dawutni rastla atilirining izzǝt-ⱨɵrmitini ⱪilip siligǝ kɵngül soriƣili adǝm ǝwǝtiptu, dǝp ⱪaramla? Uning hizmǝtkarlirining ɵzlirining aldiliriƣa kelixi bu yǝrni küzitix, aƣdurmiqiliⱪ ⱪilix, qarlax üqün ǝmǝsmidu?» — dedi.
4 Bẹ́ẹ̀ ni Hanuni fi ipá mú àwọn ọkùnrin Dafidi, fá irun wọn, wọ́n gé ẹ̀wù wọn kúrò ní àárín ìdí rẹ̀, ó sì rán wọn lọ.
Xuning bilǝn Ⱨanun Dawutning hizmǝtkarlirini tutup, ularning saⱪal-burutlirini qüxürgüziwetip ⱨǝm kiyimlirining bǝldin tɵwinini kǝstürüwetip andin ularni ⱪoyuwǝtti.
5 Nígbà tí ẹnìkan wá, tí ó sì sọ fún Dafidi nípa àwọn ọkùnrin rẹ̀, ó rán àwọn ìránṣẹ́ láti lọ bá wọn, nítorí wọ́n ti di rírẹ̀ sílẹ̀ gidigidi. Ọba wí pe, “Dúró ní Jeriko títí tí irùngbọ̀n yín yóò fi hù, nígbà náà ẹ padà wá”.
Bǝzilǝr kelip Dawutⱪa ǝlqilǝrning ǝⱨwalini uⱪturdi; u ularni kütüwelixⱪa aldiƣa adǝm ǝwǝtti, qünki ular tolimu iza-aⱨanǝttǝ ⱪalƣanidi. Xunga padixaⱨ ularƣa: «Saⱪal-burutinglar ɵskiqilik Yeriho xǝⱨiridǝ turup andin yenip kelinglar» dedi.
6 Nígbà tí àwọn ará Ammoni sì ri pé wọ́n ti di ẹ̀ṣẹ̀ ní ihò imú Dafidi, Hanuni àti àwọn ará Ammoni rán ẹgbẹ̀rún tálẹ́ǹtì fàdákà láti gba iṣẹ́ àwọn kẹ̀kẹ́ àti àwọn agun-kẹ̀kẹ́ láti Aramu-Naharaimu, Siria Maaka àti Soba.
Ammonlar ɵzlirining Dawutning nǝpritigǝ uqriƣanliⱪini bildi, Ⱨanun wǝ Ammonlar Aram-Naⱨaraim, Aram-Maakaⱨ wǝ Zobaⱨdin jǝng ⱨarwisi wǝ atliⱪ lǝxkǝr yallaxⱪa adǝm ǝwǝtip ming talant kümüx bǝrdi.
7 Wọ́n gba iṣẹ́ ẹgbẹ̀rin méjìlélọ́gbọ̀n kẹ̀kẹ́ àti agun-kẹ̀kẹ́ àti ọba Maaka pẹ̀lú àwọn ọ̀wọ́ ọmọ-ogun rẹ̀ tí ó wá pàgọ́ ní ẹ̀bá Medeba, nígbà tí àwọn ará Ammoni kójọpọ̀ láti ìlú wọn, tí wọ́n sì jáde lọ fún ogun.
Ular ottuz ikki ming jǝng ⱨarwisi, xundaⱪla Maakaⱨ padixaⱨi bilǝn uning ⱪoxunini yalliwaldi; ular Mǝdǝbaning aldiƣa kelip bargaⱨ ⱪurdi. Ammonlarmu jǝng ⱪilix üqün ⱨǝrⱪaysi xǝⱨǝrliridin kelip jǝm boluxti.
8 Ní gbígbọ́ eléyìí, Dafidi rán Joabu jáde pẹ̀lú gbogbo àwọn ọmọ-ogun ọkùnrin tí ó le jà.
Dawut buni anglap Yoab bilǝn barliⱪ ǝskǝr ⱪoxunini [ularning aldiƣa] qiⱪardi.
9 Àwọn ọmọ Ammoni sì jáde wá, wọ́n sì tẹ́ ogun ní ẹnu odi ìlú ńlá wọn, nígbà tí àwọn ọba tí ó wá, fún rara wọn wà ni orílẹ̀-èdè tí ó ṣí sílẹ̀.
Ammonlar qiⱪip xǝⱨǝr dǝrwazisining aldida sǝp tüzüp turdi; jǝnggǝ atlinip qiⱪⱪan padixaⱨlarmu dalada ayrim sǝp tüzüp turuxti.
10 Joabu ri wí pé àwọn ìlà ogun wà níwájú àti ẹ̀yìn òun, bẹ́ẹ̀ ni o mu àwọn ọmọ-ogun tí ó dára ní Israẹli, o sì tẹ́ ogun wọn sí àwọn ará Siria.
Yoab ɵzining aldi-kǝynidin ⱨujumƣa uqraydiƣanliⱪini kɵrüp, pütün Israildin bir ⱪisim sǝrhil adǝmlǝrni tallap, Suriylǝr bilǝn jǝng ⱪilixⱪa ularni sǝptǝ turƣuzdi;
11 Ó fi ìyókù àwọn ọkùnrin náà sí abẹ́ àkóso Abiṣai arákùnrin rẹ̀, a sì tẹ́ wọn kí wọn dojúkọ àwọn ará Ammoni.
u ⱪalƣan adǝmlirini inisi Abixayƣa tapxurdi, xuningdǝk ular ɵzlirini Ammonlar bilǝn jǝng ⱪilixⱪa sǝp ⱪilip tǝyyarlidi.
12 Joabu wí pé tí àwọn ará Siria bá le jù fún mi, nígbà náà, ìwọ ni kí o gbà mí; ṣùgbọ́n tí àwọn ará Ammoni bá le jù fún ọ, nígbà náà èmi yóò gbà ọ́.
Yoab Abixayƣa: «Əgǝr Suriylǝr manga küqlük kǝlsǝ, sǝn manga yardǝm bǝrgǝysǝn; ǝmma Ammonlar sanga küqlük kǝlsǝ, mǝn berip sanga yardǝm berǝy.
13 Jẹ́ alágbára kí ẹ sì jẹ́ kí a jà pẹ̀lú ìgboyà fún àwọn ènìyàn wa àti àwọn ìlú ńlá ti Ọlọ́run wa. Olúwa yóò ṣe ohun tí ó dára ní ojú rẹ̀.
Jür’ǝtlik bolƣin! Ɵz hǝlⱪimiz üqün wǝ Hudayimizning xǝⱨǝrliri üqün baturluⱪ ⱪilayli. Pǝrwǝrdigar Ɵzigǝ layiⱪ kɵrünginini ⱪilƣay! — dedi.
14 Nígbà náà Joabu àti àwọn ọmọ-ogun pẹ̀lú rẹ̀ lọ síwájú láti lọ jà pẹ̀lú àwọn ará Siria. Wọ́n sì sálọ kúrò níwájú rẹ̀.
Əmdi Yoab wǝ uning bilǝn bolƣan adǝmlǝr Suriylǝrgǝ ⱨujum ⱪilƣili qiⱪti; Suriylǝr uning aldidin ⱪaqti.
15 Nígbà ti àwọn ará Ammoni ri pé àwọn ará Siria ń sálọ, àwọn náà sálọ kúrò níwájú arákùnrin rẹ̀ Abiṣai. Wọ́n sì wọ inú ìlú ńlá lọ. Bẹ́ẹ̀ ni Joabu padà lọ sí Jerusalẹmu.
Suriylǝrning ⱪaqⱪanliⱪini kɵrgǝn Ammonlarmu Yoabning inisi Abixayning aldidin ⱪeqip, xǝⱨǝrgǝ kiriwaldi. Andin Yoab Yerusalemƣa ⱪaytip kǝldi.
16 Lẹ́yìn ìgbà tí àwọn ará Siria rí wí pé àwọn Israẹli ti lé wọn, wọ́n rán ìránṣẹ́. A sì mú àwọn ará Siria rékọjá odò Eufurate wá, pẹ̀lú Ṣofaki alákòóso ọmọ-ogun Hadadeseri, tí ó ń darí wọn.
Suriylǝr bolsa ɵzlirining Israillarning aldida mǝƣlup bolƣinini kɵrgǝndǝ, ǝlqi ǝwǝtip, [Əfrat] dǝryasining u tǝripidiki Suriylǝrni qaⱪirtip kǝldi. Ⱨadad’ezǝrning ⱪoxunining sǝrdari bolƣan Xofaⱪ ularƣa yetǝkqi idi.
17 Nígbà tí a sọ fún Dafidi nípa èyí, ó pe gbogbo Israẹli jọ wọ́n sì rékọjá Jordani; Ó lọ síwájú wọn, ó sì fa ìlà ogun dojúkọ wọ́n. Dafidi fa ìlà rẹ̀ láti bá àwọn ará Siria jagun wọ́n sì dojú ìjà kọ ọ́.
Buningdin hǝwǝr tapⱪan Dawut pütkül Israil hǝlⱪini yiƣip Iordan dǝryasidin ɵtüp, Suriylǝrning yeniƣa kelip ularƣa ⱪarxi sǝp tüzüp turdi. Dawutning sǝp tüzgǝnlikini kɵrgǝn Suriylǝr jǝnggǝ atlandi.
18 Ṣùgbọ́n àwọn ará Siria sálọ kúrò níwájú Israẹli, Dafidi sì pa ẹ̀ẹ́dẹ́gbàárin agun-kẹ̀kẹ́ wọn àti ọ̀kẹ́ méjì ọmọ-ogun ẹlẹ́ṣẹ̀. Ó pa Ṣofaki alákòóso ọmọ-ogun wọn pẹ̀lú.
Suriylǝr Israillarning aldidin ⱪaqti; Dawut Suriylǝrdin yǝttǝ ming jǝng ⱨarwiliⱪni wǝ ⱪiriⱪ ming piyadǝ lǝxkǝrni ɵltürdi wǝ yǝnǝ Suriylǝrning sǝrdari Xofaⱪni ɵltürdi.
19 Nígbà tí àwọn ẹrú Hadadeseri rí i wí pé Israẹli ti borí wọn, wọ́n ṣe àlàáfíà pẹ̀lú Dafidi, wọ́n sì ń sìn ní abẹ́ ẹ rẹ̀. Bẹ́ẹ̀ ni, àwọn ará Siria kò ní ìfẹ́ sí ríran àwọn ará Ammoni lọ́wọ́ mọ́.
Ⱨadad’ezǝrning ǝmǝldarliri Israil aldida yengilginini kɵrgǝndǝ, Dawut bilǝn sülⱨ ⱪilip uningƣa beⱪindi; xuningdin keyin Suriylǝr ikkinqi Ammoniylarƣa yardǝm berixni halimaydiƣan boldi.

< 1 Chronicles 19 >