< 1 Chronicles 19 >

1 Ní àkókò yí, Nahaṣi ọba àwọn ará Ammoni sì kú, ọmọ rẹ̀ sì rọ́pò rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ọba.
Și după aceasta s-a întâmplat, că Nahaș, împăratul copiilor lui Amon, a murit și fiul său a domnit în locul său.
2 Dafidi rò wí pé èmi yóò fi inú rere hàn sí Hanuni ọmọ Nahaṣi, nítorí baba a rẹ̀ fi inú rere hàn sí mi. Bẹ́ẹ̀ ni, Dafidi rán àwọn aṣojú lọ láti lọ fi ìbá kẹ́dùn rẹ̀ hàn sí Hanuni ní ti baba a rẹ̀. Nígbà tí àwọn ọkùnrin Dafidi wá sí ọ̀dọ̀ Hanuni ní ilẹ̀ àwọn ará Ammoni láti fi ìbá kẹ́dùn rẹ̀ hàn sí i.
Și David a spus: Voi arăta bunătate lui Hanun, fiul lui Nahaș, deoarece tatăl său mi-a arătat bunătate. Și David a trimis mesageri să îl mângâie referitor la tatăl său. Astfel servitorii lui David au intrat în țara copiilor lui Amon la Hanun, să îl mângâie.
3 Àwọn ọkùnrin ọlọ́lá ti Ammoni sọ fún Hanuni pé, “Ṣé ìwọ rò pé Dafidi ń bu ọlá fún baba rẹ nípa rírán àwọn olùtùnú sí ọ? Ṣé àwọn ọkùnrin rẹ̀ wá sí ọ̀dọ̀ rẹ láti rìn wò àti láti bì í ṣubú, àti láti ṣe ayọ́lẹ̀wò ilẹ̀ náà.”
Dar prinții copiilor lui Amon i-au spus lui Hanun: Crezi că David onorează pe tatăl tău, încât a trimis mângâietori la tine; nu au venit servitorii lui la tine să cerceteze și să dărâme și să spioneze țara?
4 Bẹ́ẹ̀ ni Hanuni fi ipá mú àwọn ọkùnrin Dafidi, fá irun wọn, wọ́n gé ẹ̀wù wọn kúrò ní àárín ìdí rẹ̀, ó sì rán wọn lọ.
De aceea Hanun a luat pe servitorii lui David și i-a ras și le-a retezat veșmintele la mijloc aproape până la fese și i-a trimis.
5 Nígbà tí ẹnìkan wá, tí ó sì sọ fún Dafidi nípa àwọn ọkùnrin rẹ̀, ó rán àwọn ìránṣẹ́ láti lọ bá wọn, nítorí wọ́n ti di rírẹ̀ sílẹ̀ gidigidi. Ọba wí pe, “Dúró ní Jeriko títí tí irùngbọ̀n yín yóò fi hù, nígbà náà ẹ padà wá”.
Atunci au mers câțiva și i-au spus lui David cum au fost oamenii lui tratați. Și a trimis după ei să îi întâlnească, pentru că oamenii erau foarte rușinați. Și împăratul a spus: Rămâneți la Ierihon până vă cresc bărbile și apoi întoarceți-vă.
6 Nígbà tí àwọn ará Ammoni sì ri pé wọ́n ti di ẹ̀ṣẹ̀ ní ihò imú Dafidi, Hanuni àti àwọn ará Ammoni rán ẹgbẹ̀rún tálẹ́ǹtì fàdákà láti gba iṣẹ́ àwọn kẹ̀kẹ́ àti àwọn agun-kẹ̀kẹ́ láti Aramu-Naharaimu, Siria Maaka àti Soba.
Și când copiii lui Amon au văzut că s-au împuțit înaintea lui David, Hanun și copiii lui Amon au trimis o mie de talanți de argint pentru a-și angaja care și călăreți din Mesopotamia și din Siria-Maaca și din Țoba.
7 Wọ́n gba iṣẹ́ ẹgbẹ̀rin méjìlélọ́gbọ̀n kẹ̀kẹ́ àti agun-kẹ̀kẹ́ àti ọba Maaka pẹ̀lú àwọn ọ̀wọ́ ọmọ-ogun rẹ̀ tí ó wá pàgọ́ ní ẹ̀bá Medeba, nígbà tí àwọn ará Ammoni kójọpọ̀ láti ìlú wọn, tí wọ́n sì jáde lọ fún ogun.
Astfel au angajat treizeci și două de mii de care și pe împăratul din Maaca și poporul său, care au venit și au așezat tabăra înaintea Medebei. Și copiii lui Amon s-au adunat din cetățile lor și au venit la bătălie.
8 Ní gbígbọ́ eléyìí, Dafidi rán Joabu jáde pẹ̀lú gbogbo àwọn ọmọ-ogun ọkùnrin tí ó le jà.
Și când David a auzit aceasta, a trimis pe Ioab și toată oștirea de războinici.
9 Àwọn ọmọ Ammoni sì jáde wá, wọ́n sì tẹ́ ogun ní ẹnu odi ìlú ńlá wọn, nígbà tí àwọn ọba tí ó wá, fún rara wọn wà ni orílẹ̀-èdè tí ó ṣí sílẹ̀.
Și copiii lui Amon au ieșit și s-au desfășurat de bătălie înaintea porții cetății; și împărații care veniseră erau deoparte în câmpie.
10 Joabu ri wí pé àwọn ìlà ogun wà níwájú àti ẹ̀yìn òun, bẹ́ẹ̀ ni o mu àwọn ọmọ-ogun tí ó dára ní Israẹli, o sì tẹ́ ogun wọn sí àwọn ará Siria.
Și când Ioab a văzut că bătălia era desfășurată împotriva lui înainte și înapoi, a ales dintre cei mai aleși din Israel și i-a desfășurat împotriva sirienilor.
11 Ó fi ìyókù àwọn ọkùnrin náà sí abẹ́ àkóso Abiṣai arákùnrin rẹ̀, a sì tẹ́ wọn kí wọn dojúkọ àwọn ará Ammoni.
Și restul poporului l-a dat în mâna lui Abișai, fratele său, și s-au desfășurat împotriva copiilor lui Amon.
12 Joabu wí pé tí àwọn ará Siria bá le jù fún mi, nígbà náà, ìwọ ni kí o gbà mí; ṣùgbọ́n tí àwọn ará Ammoni bá le jù fún ọ, nígbà náà èmi yóò gbà ọ́.
Și a spus: Dacă sirienii sunt prea tari pentru mine, atunci tu să mă ajuți, iar dacă fiii lui Amon sunt prea tari pentru tine, atunci eu te voi ajuta.
13 Jẹ́ alágbára kí ẹ sì jẹ́ kí a jà pẹ̀lú ìgboyà fún àwọn ènìyàn wa àti àwọn ìlú ńlá ti Ọlọ́run wa. Olúwa yóò ṣe ohun tí ó dára ní ojú rẹ̀.
Încurajează-te și să ne purtăm cu vitejie pentru poporul nostru și pentru cetățile Dumnezeului nostru și DOMNUL să facă ceea ce este bine în ochii lui.
14 Nígbà náà Joabu àti àwọn ọmọ-ogun pẹ̀lú rẹ̀ lọ síwájú láti lọ jà pẹ̀lú àwọn ará Siria. Wọ́n sì sálọ kúrò níwájú rẹ̀.
Astfel Ioab și poporul care era cu el a înaintat împotriva sirienilor pentru bătălie; iar ei au fugit din fața lui.
15 Nígbà ti àwọn ará Ammoni ri pé àwọn ará Siria ń sálọ, àwọn náà sálọ kúrò níwájú arákùnrin rẹ̀ Abiṣai. Wọ́n sì wọ inú ìlú ńlá lọ. Bẹ́ẹ̀ ni Joabu padà lọ sí Jerusalẹmu.
Și când copiii lui Amon au văzut că sirienii au fugit, au fugit la fel din fața lui Abișai fratele său și au intrat în cetate. Atunci Ioab a venit la Ierusalim.
16 Lẹ́yìn ìgbà tí àwọn ará Siria rí wí pé àwọn Israẹli ti lé wọn, wọ́n rán ìránṣẹ́. A sì mú àwọn ará Siria rékọjá odò Eufurate wá, pẹ̀lú Ṣofaki alákòóso ọmọ-ogun Hadadeseri, tí ó ń darí wọn.
Și când sirienii au văzut că au fost învinși înaintea lui Israel, au trimis mesageri și au scos pe sirienii care erau dincolo de râu; și Șofah, căpetenia oștirii lui Hadarezer, a mers înaintea lor.
17 Nígbà tí a sọ fún Dafidi nípa èyí, ó pe gbogbo Israẹli jọ wọ́n sì rékọjá Jordani; Ó lọ síwájú wọn, ó sì fa ìlà ogun dojúkọ wọ́n. Dafidi fa ìlà rẹ̀ láti bá àwọn ará Siria jagun wọ́n sì dojú ìjà kọ ọ́.
Și i s-a spus lui David; iar el a adunat tot Israelul și a trecut Iordanul și a venit asupra lor și s-a desfășurat pentru bătălie împotriva lor. Astfel când David a desfășurat bătălia împotriva sirienilor, ei au luptat cu el.
18 Ṣùgbọ́n àwọn ará Siria sálọ kúrò níwájú Israẹli, Dafidi sì pa ẹ̀ẹ́dẹ́gbàárin agun-kẹ̀kẹ́ wọn àti ọ̀kẹ́ méjì ọmọ-ogun ẹlẹ́ṣẹ̀. Ó pa Ṣofaki alákòóso ọmọ-ogun wọn pẹ̀lú.
Dar sirienii au fugit dinaintea lui Israel; și David a ucis dintre Sirieni șapte mii de bărbați care au luptat în care și patruzeci de mii de pedeștri, și a ucis pe Șofah, căpetenia oștirii.
19 Nígbà tí àwọn ẹrú Hadadeseri rí i wí pé Israẹli ti borí wọn, wọ́n ṣe àlàáfíà pẹ̀lú Dafidi, wọ́n sì ń sìn ní abẹ́ ẹ rẹ̀. Bẹ́ẹ̀ ni, àwọn ará Siria kò ní ìfẹ́ sí ríran àwọn ará Ammoni lọ́wọ́ mọ́.
Și când servitorii lui Hadarezer au văzut că au fost învinși în fața lui Israel, au făcut pace cu David și au devenit servitorii lui, iar sirienii nu au mai dorit să îi ajute pe copiii lui Amon vreodată.

< 1 Chronicles 19 >