< 1 Chronicles 19 >
1 Ní àkókò yí, Nahaṣi ọba àwọn ará Ammoni sì kú, ọmọ rẹ̀ sì rọ́pò rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ọba.
Un notikās pēc tam, ka Nahas, Amona bērnu ķēniņš, nomira, un viņa dēls palika par ķēniņu viņa vietā.
2 Dafidi rò wí pé èmi yóò fi inú rere hàn sí Hanuni ọmọ Nahaṣi, nítorí baba a rẹ̀ fi inú rere hàn sí mi. Bẹ́ẹ̀ ni, Dafidi rán àwọn aṣojú lọ láti lọ fi ìbá kẹ́dùn rẹ̀ hàn sí Hanuni ní ti baba a rẹ̀. Nígbà tí àwọn ọkùnrin Dafidi wá sí ọ̀dọ̀ Hanuni ní ilẹ̀ àwọn ará Ammoni láti fi ìbá kẹ́dùn rẹ̀ hàn sí i.
Tad Dāvids sacīja: es darīšu žēlastību pie Anona, Nahasa dēla, jo viņa tēvs žēlastību darījis pie manis. Un Dāvids sūtīja vēstnešus, viņu iepriecināt par viņa tēvu. Tad Dāvida kalpi nāca uz Amona bērnu zemi pie Anona, viņu iepriecināt.
3 Àwọn ọkùnrin ọlọ́lá ti Ammoni sọ fún Hanuni pé, “Ṣé ìwọ rò pé Dafidi ń bu ọlá fún baba rẹ nípa rírán àwọn olùtùnú sí ọ? Ṣé àwọn ọkùnrin rẹ̀ wá sí ọ̀dọ̀ rẹ láti rìn wò àti láti bì í ṣubú, àti láti ṣe ayọ́lẹ̀wò ilẹ̀ náà.”
Bet Amona bērnu lielkungi sacīja uz Anonu: vai Dāvids godina tavu tēvu tavās acīs, ka tas sūtījis pie tevis iepriecētājus? Vai viņa kalpi nav tāpēc pie tevis nākuši, ka zemi izklausa un izposta un izlūko?
4 Bẹ́ẹ̀ ni Hanuni fi ipá mú àwọn ọkùnrin Dafidi, fá irun wọn, wọ́n gé ẹ̀wù wọn kúrò ní àárín ìdí rẹ̀, ó sì rán wọn lọ.
Tad Anons ņēma Dāvida kalpus un tiem nodzina bārdu un viņiem nogrieza vienu drēbju pusi līdz gurniem un tos atlaida.
5 Nígbà tí ẹnìkan wá, tí ó sì sọ fún Dafidi nípa àwọn ọkùnrin rẹ̀, ó rán àwọn ìránṣẹ́ láti lọ bá wọn, nítorí wọ́n ti di rírẹ̀ sílẹ̀ gidigidi. Ọba wí pe, “Dúró ní Jeriko títí tí irùngbọ̀n yín yóò fi hù, nígbà náà ẹ padà wá”.
Un tie aizgāja. Un kad nu Dāvidam ziņu deva par tiem vīriem, tad viņš tiem sūtīja pretī, (jo tie vīri bija ļoti apsmieti, ) un ķēniņš tiem lika sacīt: paliekat Jērikū, tiekams jūsu bārda atkal būs ataugusi, tad nāciet atpakaļ.
6 Nígbà tí àwọn ará Ammoni sì ri pé wọ́n ti di ẹ̀ṣẹ̀ ní ihò imú Dafidi, Hanuni àti àwọn ará Ammoni rán ẹgbẹ̀rún tálẹ́ǹtì fàdákà láti gba iṣẹ́ àwọn kẹ̀kẹ́ àti àwọn agun-kẹ̀kẹ́ láti Aramu-Naharaimu, Siria Maaka àti Soba.
Kad nu Amona bērni redzēja, ka bija palikuši smirdoši Dāvida priekšā, tad Anons un Amona bērni sūtīja tūkstoš sudraba talentus, saderēt ratus un jātniekus no Mezopotamijas, no Maēkas un no Cobas.
7 Wọ́n gba iṣẹ́ ẹgbẹ̀rin méjìlélọ́gbọ̀n kẹ̀kẹ́ àti agun-kẹ̀kẹ́ àti ọba Maaka pẹ̀lú àwọn ọ̀wọ́ ọmọ-ogun rẹ̀ tí ó wá pàgọ́ ní ẹ̀bá Medeba, nígbà tí àwọn ará Ammoni kójọpọ̀ láti ìlú wọn, tí wọ́n sì jáde lọ fún ogun.
Un tie sev saderēja trīsdesmit un divi tūkstoš ratus un to ķēniņu no Maēkas un viņa ļaudis, un tie nāca un apmeta lēģeri pret Medbu. Un Amona bērni arīdzan sapulcējās no savām pilsētām un nāca karā.
8 Ní gbígbọ́ eléyìí, Dafidi rán Joabu jáde pẹ̀lú gbogbo àwọn ọmọ-ogun ọkùnrin tí ó le jà.
Kad nu Dāvids to dzirdēja, tad viņš sūtīja Joabu un visu spēku ar tiem vareniem.
9 Àwọn ọmọ Ammoni sì jáde wá, wọ́n sì tẹ́ ogun ní ẹnu odi ìlú ńlá wọn, nígbà tí àwọn ọba tí ó wá, fún rara wọn wà ni orílẹ̀-èdè tí ó ṣí sílẹ̀.
Un Amona bērni izgāja un nostājās uz kauju priekš pilsētas vārtiem. Bet tie ķēniņi, kas bija nākuši, turējās savrup laukā.
10 Joabu ri wí pé àwọn ìlà ogun wà níwájú àti ẹ̀yìn òun, bẹ́ẹ̀ ni o mu àwọn ọmọ-ogun tí ó dára ní Israẹli, o sì tẹ́ ogun wọn sí àwọn ará Siria.
Kad nu Joabs redzēja, ka karš pret viņu taisījās no priekšas un no aizmugures, tad viņš izlasīja kādus no Israēla jauniem vīriem un nostājās Sīriešiem pretī.
11 Ó fi ìyókù àwọn ọkùnrin náà sí abẹ́ àkóso Abiṣai arákùnrin rẹ̀, a sì tẹ́ wọn kí wọn dojúkọ àwọn ará Ammoni.
Bet tos citus ļaudis viņš deva Abizajam, savam brālim, rokā, un tie nostājās pret Amona bērniem.
12 Joabu wí pé tí àwọn ará Siria bá le jù fún mi, nígbà náà, ìwọ ni kí o gbà mí; ṣùgbọ́n tí àwọn ará Ammoni bá le jù fún ọ, nígbà náà èmi yóò gbà ọ́.
Un viņš sacīja: ja Sīrieši būs stiprāki nekā es, tad nāc tu man palīgā, bet ja Amona bērni būs stiprāki nekā tu, tad es nākušu tev palīgā.
13 Jẹ́ alágbára kí ẹ sì jẹ́ kí a jà pẹ̀lú ìgboyà fún àwọn ènìyàn wa àti àwọn ìlú ńlá ti Ọlọ́run wa. Olúwa yóò ṣe ohun tí ó dára ní ojú rẹ̀.
Turies droši un lai stipri cīnāmies priekš saviem ļaudīm un priekš sava Dieva pilsētām, un Tas Kungs lai dara, kā tam patīk.
14 Nígbà náà Joabu àti àwọn ọmọ-ogun pẹ̀lú rẹ̀ lọ síwájú láti lọ jà pẹ̀lú àwọn ará Siria. Wọ́n sì sálọ kúrò níwájú rẹ̀.
Un Joabs nāca tuvāki ar saviem ļaudīm, kas pie viņa bija, kauties ar Sīriešiem, bet tie bēga viņa priekšā.
15 Nígbà ti àwọn ará Ammoni ri pé àwọn ará Siria ń sálọ, àwọn náà sálọ kúrò níwájú arákùnrin rẹ̀ Abiṣai. Wọ́n sì wọ inú ìlú ńlá lọ. Bẹ́ẹ̀ ni Joabu padà lọ sí Jerusalẹmu.
Un kad Amona bērni redzēja, kā Sīrieši bēga, tad tie arīdzan bēga priekš Abizajus, viņa brāļa, un tie nāca pilsētā, un Joabs nāca uz Jeruzālemi.
16 Lẹ́yìn ìgbà tí àwọn ará Siria rí wí pé àwọn Israẹli ti lé wọn, wọ́n rán ìránṣẹ́. A sì mú àwọn ará Siria rékọjá odò Eufurate wá, pẹ̀lú Ṣofaki alákòóso ọmọ-ogun Hadadeseri, tí ó ń darí wọn.
Kad nu Sīrieši redzēja, ka Israēla priekšā bija sakauti, tad tie sūtīja vēstnešus un lika nākt tiem Sīriešiem, kas viņpus upes dzīvoja, un Šofahs, HadadEzera kara lielskungs, gāja viņu priekšā.
17 Nígbà tí a sọ fún Dafidi nípa èyí, ó pe gbogbo Israẹli jọ wọ́n sì rékọjá Jordani; Ó lọ síwájú wọn, ó sì fa ìlà ogun dojúkọ wọ́n. Dafidi fa ìlà rẹ̀ láti bá àwọn ará Siria jagun wọ́n sì dojú ìjà kọ ọ́.
Kad to Dāvidam teica, tad viņš sapulcēja visu Israēli un pārgāja pār Jardāni, un nāca pie tiem un nostājās tiem pretī. Un Dāvids nostājās Sīriešiem pretī uz kauju, un tie ar viņu kāvās.
18 Ṣùgbọ́n àwọn ará Siria sálọ kúrò níwájú Israẹli, Dafidi sì pa ẹ̀ẹ́dẹ́gbàárin agun-kẹ̀kẹ́ wọn àti ọ̀kẹ́ méjì ọmọ-ogun ẹlẹ́ṣẹ̀. Ó pa Ṣofaki alákòóso ọmọ-ogun wọn pẹ̀lú.
Bet Sīrieši bēga Israēla priekšā, un Dāvids nokāva no Sīriešiem septiņ tūkstoš ratus un četrdesmit tūkstoš kājniekus; viņš nokāva arī Šofahu, to kara lielkungu.
19 Nígbà tí àwọn ẹrú Hadadeseri rí i wí pé Israẹli ti borí wọn, wọ́n ṣe àlàáfíà pẹ̀lú Dafidi, wọ́n sì ń sìn ní abẹ́ ẹ rẹ̀. Bẹ́ẹ̀ ni, àwọn ará Siria kò ní ìfẹ́ sí ríran àwọn ará Ammoni lọ́wọ́ mọ́.
Kad nu HadadEzera kalpi redzēja, ka Israēla priekšā bija sakauti, tad tie derēja mieru ar Dāvidu un viņam kalpoja. Un Sīrieši negribēja vairs Amona bērniem palīdzēt.