< 1 Chronicles 19 >
1 Ní àkókò yí, Nahaṣi ọba àwọn ará Ammoni sì kú, ọmọ rẹ̀ sì rọ́pò rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ọba.
Történt ezután, hogy meghalt Náhás, az Ammon fiainak királya, és uralkodék az ő fia helyette.
2 Dafidi rò wí pé èmi yóò fi inú rere hàn sí Hanuni ọmọ Nahaṣi, nítorí baba a rẹ̀ fi inú rere hàn sí mi. Bẹ́ẹ̀ ni, Dafidi rán àwọn aṣojú lọ láti lọ fi ìbá kẹ́dùn rẹ̀ hàn sí Hanuni ní ti baba a rẹ̀. Nígbà tí àwọn ọkùnrin Dafidi wá sí ọ̀dọ̀ Hanuni ní ilẹ̀ àwọn ará Ammoni láti fi ìbá kẹ́dùn rẹ̀ hàn sí i.
És monda Dávid: Minden jóval leszek a Náhás fiához, Hánunhoz; mert az ő atyja is jól tett volt velem. Ezért Dávid követeket külde ő hozzá, a kik vigasztalnák őt az ő atyjának halála miatt; és elmenének a Dávid szolgái az Ammon fiainak földére Hánunhoz, hogy őt vigasztalnák.
3 Àwọn ọkùnrin ọlọ́lá ti Ammoni sọ fún Hanuni pé, “Ṣé ìwọ rò pé Dafidi ń bu ọlá fún baba rẹ nípa rírán àwọn olùtùnú sí ọ? Ṣé àwọn ọkùnrin rẹ̀ wá sí ọ̀dọ̀ rẹ láti rìn wò àti láti bì í ṣubú, àti láti ṣe ayọ́lẹ̀wò ilẹ̀ náà.”
Akkor mondának az Ammon fiainak főemberei Hánunnak: Azt hiszed-é, hogy Dávid atyád iránti tiszteletből küldött hozzád vigasztalókat? Avagy nem azért jöttek-é az ő szolgái hozzád, hogy a földet megvizsgálják, elpusztítsák és kikémleljék?
4 Bẹ́ẹ̀ ni Hanuni fi ipá mú àwọn ọkùnrin Dafidi, fá irun wọn, wọ́n gé ẹ̀wù wọn kúrò ní àárín ìdí rẹ̀, ó sì rán wọn lọ.
Megfogatá azért Hánun a Dávid szolgáit és azokat megnyiratá, és ruhájokat félig elmetszeté az ő derekukig, és úgy bocsátá el őket.
5 Nígbà tí ẹnìkan wá, tí ó sì sọ fún Dafidi nípa àwọn ọkùnrin rẹ̀, ó rán àwọn ìránṣẹ́ láti lọ bá wọn, nítorí wọ́n ti di rírẹ̀ sílẹ̀ gidigidi. Ọba wí pe, “Dúró ní Jeriko títí tí irùngbọ̀n yín yóò fi hù, nígbà náà ẹ padà wá”.
Elmenének pedig és értesíték Dávidot, hogy mi történt a férfiakkal. És külde eléjök (mert azok a férfiak felette nagy gyalázattal illettettek vala) és ezt izené a király: Maradjatok Jérikhóban, míg szakállatok megnövénd, akkor jőjjetek hozzám.
6 Nígbà tí àwọn ará Ammoni sì ri pé wọ́n ti di ẹ̀ṣẹ̀ ní ihò imú Dafidi, Hanuni àti àwọn ará Ammoni rán ẹgbẹ̀rún tálẹ́ǹtì fàdákà láti gba iṣẹ́ àwọn kẹ̀kẹ́ àti àwọn agun-kẹ̀kẹ́ láti Aramu-Naharaimu, Siria Maaka àti Soba.
Látván pedig az Ammon fiai, hogy tisztességtelen dolgot cselekedtek vala Dáviddal, küldének Hánun és az Ammon fiai ezer tálentom ezüstöt, hogy fogadjanak szekereket és lovagokat Mésopotámiából, siriai Maakából és Sóbából.
7 Wọ́n gba iṣẹ́ ẹgbẹ̀rin méjìlélọ́gbọ̀n kẹ̀kẹ́ àti agun-kẹ̀kẹ́ àti ọba Maaka pẹ̀lú àwọn ọ̀wọ́ ọmọ-ogun rẹ̀ tí ó wá pàgọ́ ní ẹ̀bá Medeba, nígbà tí àwọn ará Ammoni kójọpọ̀ láti ìlú wọn, tí wọ́n sì jáde lọ fún ogun.
Fogadának azért magoknak harminczkétezer szekeret, Maakának királyát is az ő népével együtt, a kik eljövének és tábort járának Medeba előtt. Az Ammon fiai is összegyűlének az ő városaikból és jövének az ütközetre.
8 Ní gbígbọ́ eléyìí, Dafidi rán Joabu jáde pẹ̀lú gbogbo àwọn ọmọ-ogun ọkùnrin tí ó le jà.
A mit mikor meghallott Dávid, elküldé Joábot és a vitézek egész seregét.
9 Àwọn ọmọ Ammoni sì jáde wá, wọ́n sì tẹ́ ogun ní ẹnu odi ìlú ńlá wọn, nígbà tí àwọn ọba tí ó wá, fún rara wọn wà ni orílẹ̀-èdè tí ó ṣí sílẹ̀.
És az Ammon fiai kimenvén, csatarendbe állának a város kapuja előtt; a mely királyok pedig segítségre jöttek vala, külön valának a mezőn.
10 Joabu ri wí pé àwọn ìlà ogun wà níwájú àti ẹ̀yìn òun, bẹ́ẹ̀ ni o mu àwọn ọmọ-ogun tí ó dára ní Israẹli, o sì tẹ́ ogun wọn sí àwọn ará Siria.
Látván pedig Joáb, hogy mind elől, mind hátul ellenség állana, kiválaszta az egész Izráel harczosai közül egynéhányat, és a Siriabeliek ellen rendelé.
11 Ó fi ìyókù àwọn ọkùnrin náà sí abẹ́ àkóso Abiṣai arákùnrin rẹ̀, a sì tẹ́ wọn kí wọn dojúkọ àwọn ará Ammoni.
A nép többi részét pedig testvérére, Abisaira bízá, és ezek az Ammon fiaival állának szembe.
12 Joabu wí pé tí àwọn ará Siria bá le jù fún mi, nígbà náà, ìwọ ni kí o gbà mí; ṣùgbọ́n tí àwọn ará Ammoni bá le jù fún ọ, nígbà náà èmi yóò gbà ọ́.
És monda: Ha a Siriabeliek rajtam erőt vennének, légy segítségemre; ha pedig az Ammon fiai rajtad vennének erőt, én is megsegéllek.
13 Jẹ́ alágbára kí ẹ sì jẹ́ kí a jà pẹ̀lú ìgboyà fún àwọn ènìyàn wa àti àwọn ìlú ńlá ti Ọlọ́run wa. Olúwa yóò ṣe ohun tí ó dára ní ojú rẹ̀.
Légy erős, sőt legyünk bátrak mindnyájan a mi népünkért és a mi Istenünk városaiért; az Úr pedig cselekedje azt, a mi néki tetszik.
14 Nígbà náà Joabu àti àwọn ọmọ-ogun pẹ̀lú rẹ̀ lọ síwájú láti lọ jà pẹ̀lú àwọn ará Siria. Wọ́n sì sálọ kúrò níwájú rẹ̀.
Harczra indula azért Joáb és az ő hada a Siriabeliek ellen, a kik ő előtte megfutamodának.
15 Nígbà ti àwọn ará Ammoni ri pé àwọn ará Siria ń sálọ, àwọn náà sálọ kúrò níwájú arákùnrin rẹ̀ Abiṣai. Wọ́n sì wọ inú ìlú ńlá lọ. Bẹ́ẹ̀ ni Joabu padà lọ sí Jerusalẹmu.
Az Ammon fiai pedig mikor látták, hogy megfutamodának a Siriabeliek: ők is megfutamodának Abisai elől az ő testvére elől, és a városba menekülének; Joáb pedig visszatért Jeruzsálembe.
16 Lẹ́yìn ìgbà tí àwọn ará Siria rí wí pé àwọn Israẹli ti lé wọn, wọ́n rán ìránṣẹ́. A sì mú àwọn ará Siria rékọjá odò Eufurate wá, pẹ̀lú Ṣofaki alákòóso ọmọ-ogun Hadadeseri, tí ó ń darí wọn.
Látván pedig a Siriabeliek, hogy az Izráel előtt megverettetének, követeket küldének és kihozatták a Siriabelieket, a kik a folyóvizen túl laknak vala, és Sófák, a Hadadézer seregeinek vezére volt az előljárójuk.
17 Nígbà tí a sọ fún Dafidi nípa èyí, ó pe gbogbo Israẹli jọ wọ́n sì rékọjá Jordani; Ó lọ síwájú wọn, ó sì fa ìlà ogun dojúkọ wọ́n. Dafidi fa ìlà rẹ̀ láti bá àwọn ará Siria jagun wọ́n sì dojú ìjà kọ ọ́.
Mikor pedig hírül adák Dávidnak, összegyűjté az egész Izráelt, és a Jordán vizén átmenvén, hozzájok érkezék és csatarendbe állott ellenök. És mikor csatarendbe állott Dávid a Siriabeliek ellen, ők is megütközének ő vele.
18 Ṣùgbọ́n àwọn ará Siria sálọ kúrò níwájú Israẹli, Dafidi sì pa ẹ̀ẹ́dẹ́gbàárin agun-kẹ̀kẹ́ wọn àti ọ̀kẹ́ méjì ọmọ-ogun ẹlẹ́ṣẹ̀. Ó pa Ṣofaki alákòóso ọmọ-ogun wọn pẹ̀lú.
De a Siriabeliek megfutamodának Izráel elől, és levága Dávid a Siriabeliek közül hétezer szekeret és negyvenezer gyalogot; annakfelette Sófákot, a sereg vezérét is megölé.
19 Nígbà tí àwọn ẹrú Hadadeseri rí i wí pé Israẹli ti borí wọn, wọ́n ṣe àlàáfíà pẹ̀lú Dafidi, wọ́n sì ń sìn ní abẹ́ ẹ rẹ̀. Bẹ́ẹ̀ ni, àwọn ará Siria kò ní ìfẹ́ sí ríran àwọn ará Ammoni lọ́wọ́ mọ́.
Mikor pedig látták a Hadadézer szolgái, hogy Izráel előtt legyőzetének: békét kötöttek Dáviddal és szolgálának néki, és nem akarák többször a Siriabeliek megsegélleni az Ammon fiait.