< 1 Chronicles 19 >

1 Ní àkókò yí, Nahaṣi ọba àwọn ará Ammoni sì kú, ọmọ rẹ̀ sì rọ́pò rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ọba.
MAHOPE mai o ia mea, make iho la o Nahasa ke alii o na mamo a Amona, a nohoalii iho la o Hanuna ma kona wahi.
2 Dafidi rò wí pé èmi yóò fi inú rere hàn sí Hanuni ọmọ Nahaṣi, nítorí baba a rẹ̀ fi inú rere hàn sí mi. Bẹ́ẹ̀ ni, Dafidi rán àwọn aṣojú lọ láti lọ fi ìbá kẹ́dùn rẹ̀ hàn sí Hanuni ní ti baba a rẹ̀. Nígbà tí àwọn ọkùnrin Dafidi wá sí ọ̀dọ̀ Hanuni ní ilẹ̀ àwọn ará Ammoni láti fi ìbá kẹ́dùn rẹ̀ hàn sí i.
Olelo iho la o Davida, E lokomaikai no wau ia Hanuna ke keiki a Nahasa; no ka mea, i lokomaikai mai kona makuakane ia'u. Hoouna aku la o Davida i na elele e hooluolu aku ia ia no kona makuakane. A hiki aku la na elele o Davida i ka aina o na mamo a Amona, io Hanuna la, e hooluolu ia ia.
3 Àwọn ọkùnrin ọlọ́lá ti Ammoni sọ fún Hanuni pé, “Ṣé ìwọ rò pé Dafidi ń bu ọlá fún baba rẹ nípa rírán àwọn olùtùnú sí ọ? Ṣé àwọn ọkùnrin rẹ̀ wá sí ọ̀dọ̀ rẹ láti rìn wò àti láti bì í ṣubú, àti láti ṣe ayọ́lẹ̀wò ilẹ̀ náà.”
Aka, o na alii o na mamo a Amona, i aku la lakou ia Hanuna, Ke manao nei anei oe, e hoomaikai mai o Davida i kou makuakane i kona hoouna ana mai iou la i na mea hooluolu? Aole anei i hele mai kana mau kauwa iou nei e makaikai, a e hookahuli, a e hoomakakiu mai i ka aina?
4 Bẹ́ẹ̀ ni Hanuni fi ipá mú àwọn ọkùnrin Dafidi, fá irun wọn, wọ́n gé ẹ̀wù wọn kúrò ní àárín ìdí rẹ̀, ó sì rán wọn lọ.
Nolaila, lalau mai la o Hanuna i na kauwa a Davida, a kahi ae la i ko lakou umiumi, a okioki iho la i ko lakou mau aahu mawaena, ma ko lakou kikala, a kipaku mai la ia lakou.
5 Nígbà tí ẹnìkan wá, tí ó sì sọ fún Dafidi nípa àwọn ọkùnrin rẹ̀, ó rán àwọn ìránṣẹ́ láti lọ bá wọn, nítorí wọ́n ti di rírẹ̀ sílẹ̀ gidigidi. Ọba wí pe, “Dúró ní Jeriko títí tí irùngbọ̀n yín yóò fi hù, nígbà náà ẹ padà wá”.
Hele mai la kekahi, a hai aku la ia Davida i ka mea i hanaia mai i ua mau kanaka la. Hoouna aku ia ia e halawai me lakou: no ka mea, ua hilahila loa lakou. I aku la ke alii, E noho oukou ma Ieriko, a ulu ae ko oukou umiumi, alaila e hoi mai
6 Nígbà tí àwọn ará Ammoni sì ri pé wọ́n ti di ẹ̀ṣẹ̀ ní ihò imú Dafidi, Hanuni àti àwọn ará Ammoni rán ẹgbẹ̀rún tálẹ́ǹtì fàdákà láti gba iṣẹ́ àwọn kẹ̀kẹ́ àti àwọn agun-kẹ̀kẹ́ láti Aramu-Naharaimu, Siria Maaka àti Soba.
A ike iho la na mamo a Amona, ua pilau lakou imua o Davida, hoouka aku la o Hanuna me na mamo a Amona i na talena kala he tausani e hoolimalima no lakou i na halekaa a me na hoohololio mai Mesopotamia, a mai Suria-maaka, a mai Zoba mai.
7 Wọ́n gba iṣẹ́ ẹgbẹ̀rin méjìlélọ́gbọ̀n kẹ̀kẹ́ àti agun-kẹ̀kẹ́ àti ọba Maaka pẹ̀lú àwọn ọ̀wọ́ ọmọ-ogun rẹ̀ tí ó wá pàgọ́ ní ẹ̀bá Medeba, nígbà tí àwọn ará Ammoni kójọpọ̀ láti ìlú wọn, tí wọ́n sì jáde lọ fún ogun.
Hoolimalima ae la lakou i na kaa he kanakolukumamalua tausani, a me ke alii o Maaka, a me kona poe kanaka; a hele mai lakou a hoomoana imua o Medeba. Akoakoa mai la na mamo a Amona mailoko mai o ko lakou mau kulanakauhale, a hele mai i ke kaua.
8 Ní gbígbọ́ eléyìí, Dafidi rán Joabu jáde pẹ̀lú gbogbo àwọn ọmọ-ogun ọkùnrin tí ó le jà.
A lohe ae la o Davida, hoouna aku la oia ia Ioaba, me ka puali a pau o ka poe ikaika.
9 Àwọn ọmọ Ammoni sì jáde wá, wọ́n sì tẹ́ ogun ní ẹnu odi ìlú ńlá wọn, nígbà tí àwọn ọba tí ó wá, fún rara wọn wà ni orílẹ̀-èdè tí ó ṣí sílẹ̀.
Hele mai la ka poe mamo a Amona iwaho, a hoonohonoho i ke kaua ma ke alo o ka puka e komo ai iloko o ke kulanakauhale: a ku okoa ae la na alii i hiki mai ma ke kola.
10 Joabu ri wí pé àwọn ìlà ogun wà níwájú àti ẹ̀yìn òun, bẹ́ẹ̀ ni o mu àwọn ọmọ-ogun tí ó dára ní Israẹli, o sì tẹ́ ogun wọn sí àwọn ará Siria.
A ike aku la o Ioaba i ke alo o na kaua, mamua kekahi, a mahope kekahi, wae aku la oia i ka poe ui a pau o ka Iseraela, a hoonohonoho aku la ia lakou e ku e i ko Suria
11 Ó fi ìyókù àwọn ọkùnrin náà sí abẹ́ àkóso Abiṣai arákùnrin rẹ̀, a sì tẹ́ wọn kí wọn dojúkọ àwọn ará Ammoni.
A haawi aku la ia i ka poe i koe ma ka lima o Abisai kona kaikaina, a hoonohonoho aku oia ia lakou e ku e i na mamo a Amona.
12 Joabu wí pé tí àwọn ará Siria bá le jù fún mi, nígbà náà, ìwọ ni kí o gbà mí; ṣùgbọ́n tí àwọn ará Ammoni bá le jù fún ọ, nígbà náà èmi yóò gbà ọ́.
I aku la oia, Ina e oi aku ka ikaika o ko Suria i ko'u, alaila e kokua mai oe ia'u: aka, ina e oi aku ka ikaika o na mamo a Amona i kou, alaila au e kokua aku ia oe.
13 Jẹ́ alágbára kí ẹ sì jẹ́ kí a jà pẹ̀lú ìgboyà fún àwọn ènìyàn wa àti àwọn ìlú ńlá ti Ọlọ́run wa. Olúwa yóò ṣe ohun tí ó dára ní ojú rẹ̀.
I nui ka ikaika, a e koa hoi kakou no ko kakou lahuikanaka, a me na kulanakauhale no ko kakou Akua: a e hana mai o Iehova i ka mea pono imua o kona maka.
14 Nígbà náà Joabu àti àwọn ọmọ-ogun pẹ̀lú rẹ̀ lọ síwájú láti lọ jà pẹ̀lú àwọn ará Siria. Wọ́n sì sálọ kúrò níwájú rẹ̀.
Neenee aku la o Ioaba me na kanaka me ia imua o ko Suria, i ke kaua ana; a hee aku la lakou imua ona.
15 Nígbà ti àwọn ará Ammoni ri pé àwọn ará Siria ń sálọ, àwọn náà sálọ kúrò níwájú arákùnrin rẹ̀ Abiṣai. Wọ́n sì wọ inú ìlú ńlá lọ. Bẹ́ẹ̀ ni Joabu padà lọ sí Jerusalẹmu.
A ike aku la na mamo a Amona, ua hee aku la ko Suria, alaila hee aku la hoi lakou imua o Abisai kona kaikaina, a komo aku la iloko o ke kulanakauhale. Alaila hele mai la o Ioaba i Ierusalema.
16 Lẹ́yìn ìgbà tí àwọn ará Siria rí wí pé àwọn Israẹli ti lé wọn, wọ́n rán ìránṣẹ́. A sì mú àwọn ará Siria rékọjá odò Eufurate wá, pẹ̀lú Ṣofaki alákòóso ọmọ-ogun Hadadeseri, tí ó ń darí wọn.
A ike ae la ko Suria, ua pepehiia lakou imua o ka Iseraela, hoouna aku la lakou i na elele, a kai mai la lakou i ko Suria e noho ana ma kela aoao o ka muliwai: a imua o lakou o Sopaka ka lunakoa no Hadarezera.
17 Nígbà tí a sọ fún Dafidi nípa èyí, ó pe gbogbo Israẹli jọ wọ́n sì rékọjá Jordani; Ó lọ síwájú wọn, ó sì fa ìlà ogun dojúkọ wọ́n. Dafidi fa ìlà rẹ̀ láti bá àwọn ará Siria jagun wọ́n sì dojú ìjà kọ ọ́.
A hai aku la kekahi ia Davida: a hoakoakoa ae la oia i ka Iseraela a pau, a hele aku la ma kela aoao o Ioredane, a hiki aku la io lakou la, a hoonohonoho aku la i ke kaua ku e ia lakou. Aia hoonohonoho aku ai o Davida i ke kaua ku e ia lakou, alaila lakou i kaua mai me ia.
18 Ṣùgbọ́n àwọn ará Siria sálọ kúrò níwájú Israẹli, Dafidi sì pa ẹ̀ẹ́dẹ́gbàárin agun-kẹ̀kẹ́ wọn àti ọ̀kẹ́ méjì ọmọ-ogun ẹlẹ́ṣẹ̀. Ó pa Ṣofaki alákòóso ọmọ-ogun wọn pẹ̀lú.
A hee aku la ko Suria imua o ka Iseraela; a pepehi aku la o Davida i na kanaka o na halekaa ehiku tausani, a me na kanaka kaniwawae he kanaha tausani, a make iho la o Sopaka ka lunakaua.
19 Nígbà tí àwọn ẹrú Hadadeseri rí i wí pé Israẹli ti borí wọn, wọ́n ṣe àlàáfíà pẹ̀lú Dafidi, wọ́n sì ń sìn ní abẹ́ ẹ rẹ̀. Bẹ́ẹ̀ ni, àwọn ará Siria kò ní ìfẹ́ sí ríran àwọn ará Ammoni lọ́wọ́ mọ́.
A ike iho la na kauwa a Hadarezera, ua pepehiia lakou imua o ka Iseraela, hookuikahi mai la lakou me Davida, a lilo iho la i poe kauwa nana Aole hoi i manao ko Suria e kokua hou aku i na mamo a Amona.

< 1 Chronicles 19 >