< 1 Chronicles 19 >

1 Ní àkókò yí, Nahaṣi ọba àwọn ará Ammoni sì kú, ọmọ rẹ̀ sì rọ́pò rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ọba.
Thuutha wa mahinda macio-rĩ, Nahashu mũthamaki wa Aamoni agĩkua, nake mũriũ agĩtuĩka mũthamaki ithenya rĩake.
2 Dafidi rò wí pé èmi yóò fi inú rere hàn sí Hanuni ọmọ Nahaṣi, nítorí baba a rẹ̀ fi inú rere hàn sí mi. Bẹ́ẹ̀ ni, Dafidi rán àwọn aṣojú lọ láti lọ fi ìbá kẹ́dùn rẹ̀ hàn sí Hanuni ní ti baba a rẹ̀. Nígbà tí àwọn ọkùnrin Dafidi wá sí ọ̀dọ̀ Hanuni ní ilẹ̀ àwọn ará Ammoni láti fi ìbá kẹ́dùn rẹ̀ hàn sí i.
Nake Daudi agĩĩciiria atĩrĩ, “Nĩngwĩka Hanuni mũrũ wa Nahashu maũndũ mega ma ũtugi tondũ ithe nĩanjĩkire maũndũ mega ma ũtugi.” Nĩ ũndũ ũcio Daudi agĩtũma andũ kũrĩ Hanuni makamũcakaithie nĩ ũndũ wa gũkuĩrwo nĩ ithe. Rĩrĩa andũ acio maatũmĩtwo nĩ Daudi maakinyire kũrĩ Hanuni o kũu bũrũri wa Amoni nĩguo mamũcakaithie-rĩ,
3 Àwọn ọkùnrin ọlọ́lá ti Ammoni sọ fún Hanuni pé, “Ṣé ìwọ rò pé Dafidi ń bu ọlá fún baba rẹ nípa rírán àwọn olùtùnú sí ọ? Ṣé àwọn ọkùnrin rẹ̀ wá sí ọ̀dọ̀ rẹ láti rìn wò àti láti bì í ṣubú, àti láti ṣe ayọ́lẹ̀wò ilẹ̀ náà.”
andũ arĩa maarĩ igweta a Amoni makĩũria Hanuni atĩrĩ, “Ũreciiria Daudi nĩ thoguo aratĩĩa nĩ ũndũ wa gũgũtũmĩra andũ magũcakaithie? Githĩ andũ ake matiũkĩte kũrĩ we matuĩrie na mathigaane bũrũri nĩguo macooke maũtunyane?”
4 Bẹ́ẹ̀ ni Hanuni fi ipá mú àwọn ọkùnrin Dafidi, fá irun wọn, wọ́n gé ẹ̀wù wọn kúrò ní àárín ìdí rẹ̀, ó sì rán wọn lọ.
Nĩ ũndũ ũcio Hanuni akĩnyiitithia andũ acio a Daudi, akĩmenjithia nderu, nacio nguo ciao igĩtinio irima gatagatĩ ka njikarĩro, na akĩmaingata.
5 Nígbà tí ẹnìkan wá, tí ó sì sọ fún Dafidi nípa àwọn ọkùnrin rẹ̀, ó rán àwọn ìránṣẹ́ láti lọ bá wọn, nítorí wọ́n ti di rírẹ̀ sílẹ̀ gidigidi. Ọba wí pe, “Dúró ní Jeriko títí tí irùngbọ̀n yín yóò fi hù, nígbà náà ẹ padà wá”.
Rĩrĩa mũndũ ũmwe aakinyĩirie Daudi ũhoro wa andũ acio-rĩ, Daudi agĩtũma andũ makamatũnge, tondũ andũ acio nĩmaconorithĩtio mũno. Mũthamaki akiuga atĩrĩ, “Ikarai kũu Jeriko nginya nderu cianyu ikũre, mũcooke mũũke.”
6 Nígbà tí àwọn ará Ammoni sì ri pé wọ́n ti di ẹ̀ṣẹ̀ ní ihò imú Dafidi, Hanuni àti àwọn ará Ammoni rán ẹgbẹ̀rún tálẹ́ǹtì fàdákà láti gba iṣẹ́ àwọn kẹ̀kẹ́ àti àwọn agun-kẹ̀kẹ́ láti Aramu-Naharaimu, Siria Maaka àti Soba.
Rĩrĩa andũ a Amoni maamenyire atĩ nĩmatuĩkĩte kĩndũ kĩnungu harĩ Daudi-rĩ, Hanuni na andũ a Amoni makĩneana betha taranda ngiri ĩmwe cia gũkombora ngaari cia ita na atwarithia a cio kuuma Mesopotamia, na Aramu-Maaka, na Zoba.
7 Wọ́n gba iṣẹ́ ẹgbẹ̀rin méjìlélọ́gbọ̀n kẹ̀kẹ́ àti agun-kẹ̀kẹ́ àti ọba Maaka pẹ̀lú àwọn ọ̀wọ́ ọmọ-ogun rẹ̀ tí ó wá pàgọ́ ní ẹ̀bá Medeba, nígbà tí àwọn ará Ammoni kójọpọ̀ láti ìlú wọn, tí wọ́n sì jáde lọ fún ogun.
Magĩkombora ngaari cia ita ngiri mĩrongo ĩtatũ na igĩrĩ na atwarithia a cio, hamwe na mũthamaki wa Maaka na mbũtũ ciake, arĩa mookire makĩamba hema hakuhĩ na Medeba; hĩndĩ ĩyo andũ a Amoni nao magĩcookanĩrĩrio kuuma matũũra-inĩ mao, magĩthiĩ kũrũa mbaara.
8 Ní gbígbọ́ eléyìí, Dafidi rán Joabu jáde pẹ̀lú gbogbo àwọn ọmọ-ogun ọkùnrin tí ó le jà.
Nake Daudi aigua ũhoro ũcio-rĩ, agĩtũma Joabu na ita rĩothe rĩa mbaara.
9 Àwọn ọmọ Ammoni sì jáde wá, wọ́n sì tẹ́ ogun ní ẹnu odi ìlú ńlá wọn, nígbà tí àwọn ọba tí ó wá, fún rara wọn wà ni orílẹ̀-èdè tí ó ṣí sílẹ̀.
Nao andũ a Amoni makiumagara, makĩarania mbũtũ cia mbaara kĩhingo-inĩ gĩa itũũra rĩao inene, nao athamaki arĩa mookĩte mbaara, magĩkorwo maarĩ oiki kũu werũ-inĩ.
10 Joabu ri wí pé àwọn ìlà ogun wà níwájú àti ẹ̀yìn òun, bẹ́ẹ̀ ni o mu àwọn ọmọ-ogun tí ó dára ní Israẹli, o sì tẹ́ ogun wọn sí àwọn ará Siria.
Joabu nĩonire atĩ thigari nĩciaranĩtio mbere yake o na thuutha wake; nĩ ũndũ ũcio agĩthuura mbũtũ imwe iria njega mũno kũu Isiraeli, agĩcitũma ikarũe na Asuriata.
11 Ó fi ìyókù àwọn ọkùnrin náà sí abẹ́ àkóso Abiṣai arákùnrin rẹ̀, a sì tẹ́ wọn kí wọn dojúkọ àwọn ará Ammoni.
Andũ acio angĩ akĩmaiga watho-inĩ wa Abishai mũrũ wa nyina. Nao akĩmatũma makarũe na andũ a Amoni.
12 Joabu wí pé tí àwọn ará Siria bá le jù fún mi, nígbà náà, ìwọ ni kí o gbà mí; ṣùgbọ́n tí àwọn ará Ammoni bá le jù fún ọ, nígbà náà èmi yóò gbà ọ́.
Joabu akiuga atĩrĩ, “Asuriata mangĩngĩria hinya-rĩ, wee ũũke ũndeithie; no Aamoni mangĩgũkĩria hinya, nĩngagũteithia.
13 Jẹ́ alágbára kí ẹ sì jẹ́ kí a jà pẹ̀lú ìgboyà fún àwọn ènìyàn wa àti àwọn ìlú ńlá ti Ọlọ́run wa. Olúwa yóò ṣe ohun tí ó dára ní ojú rẹ̀.
Wĩyũmĩrĩrie nĩgeetha tũrũe na ũcamba nĩ ũndũ wa andũ aitũ, na nĩ ũndũ wa matũũra manene ma Ngai witũ. Jehova nĩegwĩka ũrĩa ekuona kwagĩrĩire maitho-inĩ make.”
14 Nígbà náà Joabu àti àwọn ọmọ-ogun pẹ̀lú rẹ̀ lọ síwájú láti lọ jà pẹ̀lú àwọn ará Siria. Wọ́n sì sálọ kúrò níwájú rẹ̀.
Nake Joabu arĩ na mbũtũ ciake agĩtharĩkĩra Asuriata, nao makĩmũũrĩra.
15 Nígbà ti àwọn ará Ammoni ri pé àwọn ará Siria ń sálọ, àwọn náà sálọ kúrò níwájú arákùnrin rẹ̀ Abiṣai. Wọ́n sì wọ inú ìlú ńlá lọ. Bẹ́ẹ̀ ni Joabu padà lọ sí Jerusalẹmu.
Rĩrĩa Aamoni moonire atĩ Asuriata nĩmaroora-rĩ, o nao makĩũrĩra Abishai mũrũ wa nyina magĩtoonya itũũra thĩinĩ. Nĩ ũndũ ũcio Joabu agĩcooka Jerusalemu.
16 Lẹ́yìn ìgbà tí àwọn ará Siria rí wí pé àwọn Israẹli ti lé wọn, wọ́n rán ìránṣẹ́. A sì mú àwọn ará Siria rékọjá odò Eufurate wá, pẹ̀lú Ṣofaki alákòóso ọmọ-ogun Hadadeseri, tí ó ń darí wọn.
Thuutha wa Asuriata kuona atĩ nĩmatoorio nĩ andũ a Isiraeli, magĩtũma andũ makarehithie Asuriata a kuuma mũrĩmo wa Rũũĩ rwa Farati matongoretio nĩ Shofaku ũrĩa warĩ mũnene wa mbũtũ cia ita cia Hadadezeri.
17 Nígbà tí a sọ fún Dafidi nípa èyí, ó pe gbogbo Israẹli jọ wọ́n sì rékọjá Jordani; Ó lọ síwájú wọn, ó sì fa ìlà ogun dojúkọ wọ́n. Dafidi fa ìlà rẹ̀ láti bá àwọn ará Siria jagun wọ́n sì dojú ìjà kọ ọ́.
Rĩrĩa Daudi eerirwo ũhoro ũcio, agĩcookanĩrĩria ita rĩa Isiraeli rĩothe, makĩringa Rũũĩ rwa Jorodani, nake akĩmakinyĩra na akĩiga mbũtũ ciake imangʼetheire. Daudi akĩhaarĩria mbũtũ ciake nĩguo itũngane na Asuriata acio mbaara-inĩ, nao Asuriata makĩrũa nake.
18 Ṣùgbọ́n àwọn ará Siria sálọ kúrò níwájú Israẹli, Dafidi sì pa ẹ̀ẹ́dẹ́gbàárin agun-kẹ̀kẹ́ wọn àti ọ̀kẹ́ méjì ọmọ-ogun ẹlẹ́ṣẹ̀. Ó pa Ṣofaki alákòóso ọmọ-ogun wọn pẹ̀lú.
No rĩrĩ, Asuriata makĩũrĩra Isiraeli, nake Daudi akĩũraga atwarithia a ngaari ciao cia ita ngiri mũgwanja, na thigari ciao cia magũrũ ngiri mĩrongo ĩna. Ningĩ akĩũraga Shofaku, mũnene wa mbũtũ ciao.
19 Nígbà tí àwọn ẹrú Hadadeseri rí i wí pé Israẹli ti borí wọn, wọ́n ṣe àlàáfíà pẹ̀lú Dafidi, wọ́n sì ń sìn ní abẹ́ ẹ rẹ̀. Bẹ́ẹ̀ ni, àwọn ará Siria kò ní ìfẹ́ sí ríran àwọn ará Ammoni lọ́wọ́ mọ́.
Hĩndĩ ĩrĩa ndungata cia Hadadezeri cionire atĩ nĩmahootwo nĩ Isiraeli-rĩ, magĩthondeka thayũ na Daudi, nao magĩtuĩka a gwathagwo nĩwe. Nĩ ũndũ ũcio Asuriata matiacookire gwĩtĩkĩra gũteithia Aamoni rĩngĩ.

< 1 Chronicles 19 >