< 1 Chronicles 19 >

1 Ní àkókò yí, Nahaṣi ọba àwọn ará Ammoni sì kú, ọmọ rẹ̀ sì rọ́pò rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ọba.
Phat chomkhat jou a Ammon mite Lengpa Nahash ahung thi chun achapa Hanun chu leng in ahung pang tai.
2 Dafidi rò wí pé èmi yóò fi inú rere hàn sí Hanuni ọmọ Nahaṣi, nítorí baba a rẹ̀ fi inú rere hàn sí mi. Bẹ́ẹ̀ ni, Dafidi rán àwọn aṣojú lọ láti lọ fi ìbá kẹ́dùn rẹ̀ hàn sí Hanuni ní ti baba a rẹ̀. Nígbà tí àwọn ọkùnrin Dafidi wá sí ọ̀dọ̀ Hanuni ní ilẹ̀ àwọn ará Ammoni láti fi ìbá kẹ́dùn rẹ̀ hàn sí i.
David in, “Keiman Hanun chung a hi kakitah na kapoh doh ding ahi, ajeh chu apa Nahash hi keima chung a akitah jing in ahi,” tin asei e. Hiti chun David in Hanun pa thina jeh a lunghem na akon lungmon sah nading in asottol le ho asol in ahivang in David sottolle ho Ammon gam ahung lhun phat in,
3 Àwọn ọkùnrin ọlọ́lá ti Ammoni sọ fún Hanuni pé, “Ṣé ìwọ rò pé Dafidi ń bu ọlá fún baba rẹ nípa rírán àwọn olùtùnú sí ọ? Ṣé àwọn ọkùnrin rẹ̀ wá sí ọ̀dọ̀ rẹ láti rìn wò àti láti bì í ṣubú, àti láti ṣe ayọ́lẹ̀wò ilẹ̀ náà.”
Ammon mite lamkai pa chun Hanun kom ah chun, “Nangman hiche mipite hohi napa jabolna jal'a hung a nagel mong ham? Hichu hilou a David in amaho hi agam umdan ho vetoh le a chujouteng le hung kon uva agamsung mite jouse hi nokhum ding lung agot joh ahi,” tin asei e.
4 Bẹ́ẹ̀ ni Hanuni fi ipá mú àwọn ọkùnrin Dafidi, fá irun wọn, wọ́n gé ẹ̀wù wọn kúrò ní àárín ìdí rẹ̀, ó sì rán wọn lọ.
Chuin Hanun in David sottolle ho chu aman in asam u avo peh un chule aponsil hou jong akongjang atobuh dung uva achetan peh in abon chaovin David heng a anung sol tauve.
5 Nígbà tí ẹnìkan wá, tí ó sì sọ fún Dafidi nípa àwọn ọkùnrin rẹ̀, ó rán àwọn ìránṣẹ́ láti lọ bá wọn, nítorí wọ́n ti di rírẹ̀ sílẹ̀ gidigidi. Ọba wí pe, “Dúró ní Jeriko títí tí irùngbọ̀n yín yóò fi hù, nígbà náà ẹ padà wá”.
David in amite chunga hitobng thilsoh umchan le asottolle ho ajachat naho thu ajah jeh chun Jericho khopi ah chun akhamul u ahung khandoh kah uva tham den uva chujouteng hung kile ding in asei e.
6 Nígbà tí àwọn ará Ammoni sì ri pé wọ́n ti di ẹ̀ṣẹ̀ ní ihò imú Dafidi, Hanuni àti àwọn ará Ammoni rán ẹgbẹ̀rún tálẹ́ǹtì fàdákà láti gba iṣẹ́ àwọn kẹ̀kẹ́ àti àwọn agun-kẹ̀kẹ́ láti Aramu-Naharaimu, Siria Maaka àti Soba.
Ammon mite chun, David lungdou na athilbol u ahetdoh phat u chun Hanun le Ammon mite chun Zoab le Aramaacah chule Ram-naharaim gam a kon sakol touthem sepai le kangtalai tampi thalah nadin dangka talent sangsom sagi le sang nga jen ana thot in ahi.
7 Wọ́n gba iṣẹ́ ẹgbẹ̀rin méjìlélọ́gbọ̀n kẹ̀kẹ́ àti agun-kẹ̀kẹ́ àti ọba Maaka pẹ̀lú àwọn ọ̀wọ́ ọmọ-ogun rẹ̀ tí ó wá pàgọ́ ní ẹ̀bá Medeba, nígbà tí àwọn ará Ammoni kójọpọ̀ láti ìlú wọn, tí wọ́n sì jáde lọ fún ogun.
Chujongle amahon kangtalai sang somthum le ni jong athalah uvin, Maacah le asepai te jong ana kitho piu ve. Chule hiche sepai ho chu Medaba mun a Hanun in amakhopi tah a anapan sah sepai ho toh chun ana umkhom uvin ahi.
8 Ní gbígbọ́ eléyìí, Dafidi rán Joabu jáde pẹ̀lú gbogbo àwọn ọmọ-ogun ọkùnrin tí ó le jà.
David in hichu ajah phat in Joab le asepai gal hang ho chu ama kisat pi din ana sol pai in ahi.
9 Àwọn ọmọ Ammoni sì jáde wá, wọ́n sì tẹ́ ogun ní ẹnu odi ìlú ńlá wọn, nígbà tí àwọn ọba tí ó wá, fún rara wọn wà ni orílẹ̀-èdè tí ó ṣí sílẹ̀.
Hichun Ammon mite jong ahung kon doh un khopi kelkot phung ah chun galsat ding in ahung kigol doh tauve, chule galsat dia hung kon leng ho jong chun ama hinathei cheh in galsat dia kigot na panmun akisem uvin ahi.
10 Joabu ri wí pé àwọn ìlà ogun wà níwájú àti ẹ̀yìn òun, bẹ́ẹ̀ ni o mu àwọn ọmọ-ogun tí ó dára ní Israẹli, o sì tẹ́ ogun wọn sí àwọn ará Siria.
Joab in amelmaten anung ama a ahin nokhum amu doh phat in Israel te sepai hatlai ho chu Aramean sepai te kisat pi ding in alhengdoh in ahi.
11 Ó fi ìyókù àwọn ọkùnrin náà sí abẹ́ àkóso Abiṣai arákùnrin rẹ̀, a sì tẹ́ wọn kí wọn dojúkọ àwọn ará Ammoni.
Chule aman sepai dang adalhah chengse chu asopipa Abishai lamkai nanoi a Ammon mite kisat pi ding in apan sah e.
12 Joabu wí pé tí àwọn ará Siria bá le jù fún mi, nígbà náà, ìwọ ni kí o gbà mí; ṣùgbọ́n tí àwọn ará Ammoni bá le jù fún ọ, nígbà náà èmi yóò gbà ọ́.
Joab in asopipa jah a chun, “Aramean mite chu kahin jolal le neihung kithopi ding chule nang in jong Ammon mite nanjolal le kahung kithopi ding nahi,” ati.
13 Jẹ́ alágbára kí ẹ sì jẹ́ kí a jà pẹ̀lú ìgboyà fún àwọn ènìyàn wa àti àwọn ìlú ńlá ti Ọlọ́run wa. Olúwa yóò ṣe ohun tí ó dára ní ojú rẹ̀.
Hat unlang hangsan tahin pang un e Pathen khopi ule emiteu va ding in gal isat diu ahi. Pakai in ama deilam in hinbol jeng tahen.
14 Nígbà náà Joabu àti àwọn ọmọ-ogun pẹ̀lú rẹ̀ lọ síwájú láti lọ jà pẹ̀lú àwọn ará Siria. Wọ́n sì sálọ kúrò níwájú rẹ̀.
Joab le asepaiten Aramean mite àsat un anadel jam tauve.
15 Nígbà ti àwọn ará Ammoni ri pé àwọn ará Siria ń sálọ, àwọn náà sálọ kúrò níwájú arákùnrin rẹ̀ Abiṣai. Wọ́n sì wọ inú ìlú ńlá lọ. Bẹ́ẹ̀ ni Joabu padà lọ sí Jerusalẹmu.
Chule Ammon miten Aramean mite jam amu doh phat u chun Abishai a kon in anajam un akhopiuva ana kile tauve.
16 Lẹ́yìn ìgbà tí àwọn ará Siria rí wí pé àwọn Israẹli ti lé wọn, wọ́n rán ìránṣẹ́. A sì mú àwọn ará Siria rékọjá odò Eufurate wá, pẹ̀lú Ṣofaki alákòóso ọmọ-ogun Hadadeseri, tí ó ń darí wọn.
Aramean miten Israel te ajolel u ahetdoh phat uchun Euphrates luipang le avel dung a kon in Aramean sepaite akoukhom in amaho chu abon'un Hadadezer sepai jalamkai pa thunoi in ana um sah uvin ahi.
17 Nígbà tí a sọ fún Dafidi nípa èyí, ó pe gbogbo Israẹli jọ wọ́n sì rékọjá Jordani; Ó lọ síwájú wọn, ó sì fa ìlà ogun dojúkọ wọ́n. Dafidi fa ìlà rẹ̀ láti bá àwọn ará Siria jagun wọ́n sì dojú ìjà kọ ọ́.
David in hitobng thilumchan ho ahet doh phat in jordan vadung vel dung a kon jousea Israel sepaite chu galsat din ana kou khom in Aramean mite toh ana kisat tauvin ahi.
18 Ṣùgbọ́n àwọn ará Siria sálọ kúrò níwájú Israẹli, Dafidi sì pa ẹ̀ẹ́dẹ́gbàárin agun-kẹ̀kẹ́ wọn àti ọ̀kẹ́ méjì ọmọ-ogun ẹlẹ́ṣẹ̀. Ó pa Ṣofaki alákòóso ọmọ-ogun wọn pẹ̀lú.
Chule Aramean mite chu Israel te a kon in anagal lel un, anajam kit tauvin ahi. Hichea chun David sepai ten Aramean sepai lamkai pipu Shobah pum in sepai kangtalai tol mi sang sagi le kenglam sepai mi sang somli jen ana that uvin ahi.
19 Nígbà tí àwọn ẹrú Hadadeseri rí i wí pé Israẹli ti borí wọn, wọ́n ṣe àlàáfíà pẹ̀lú Dafidi, wọ́n sì ń sìn ní abẹ́ ẹ rẹ̀. Bẹ́ẹ̀ ni, àwọn ará Siria kò ní ìfẹ́ sí ríran àwọn ará Ammoni lọ́wọ́ mọ́.
Hadadezer thunoi a leng umhon jong Israelten gal ajo amudoh phat uvin, David angsung a akipelut uvin ama thunoi in aum tauve, chule Aramean miten aitih a jong Ammon mite akitho pi kit diu anom tapouve.

< 1 Chronicles 19 >