< 1 Chronicles 19 >

1 Ní àkókò yí, Nahaṣi ọba àwọn ará Ammoni sì kú, ọmọ rẹ̀ sì rọ́pò rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ọba.
Te phoeiah tah Ammon koca rhoek kah manghai Nahash te duek tih a capa te anih yueng la manghai.
2 Dafidi rò wí pé èmi yóò fi inú rere hàn sí Hanuni ọmọ Nahaṣi, nítorí baba a rẹ̀ fi inú rere hàn sí mi. Bẹ́ẹ̀ ni, Dafidi rán àwọn aṣojú lọ láti lọ fi ìbá kẹ́dùn rẹ̀ hàn sí Hanuni ní ti baba a rẹ̀. Nígbà tí àwọn ọkùnrin Dafidi wá sí ọ̀dọ̀ Hanuni ní ilẹ̀ àwọn ará Ammoni láti fi ìbá kẹ́dùn rẹ̀ hàn sí i.
Te vaengah David loh, “A napa loh kai taengah sitlohnah a tueng sak dongah Nahash capa Hanun te sitlohnah ka tueng sak van eh,” a ti. Te dongah a napa kongah anih suem ham te David loh puencawn a tueih tih David kah sal rhoek khaw Hanun suem hamla Ammon koca rhoek kah khohmuen la pawk uh.
3 Àwọn ọkùnrin ọlọ́lá ti Ammoni sọ fún Hanuni pé, “Ṣé ìwọ rò pé Dafidi ń bu ọlá fún baba rẹ nípa rírán àwọn olùtùnú sí ọ? Ṣé àwọn ọkùnrin rẹ̀ wá sí ọ̀dọ̀ rẹ láti rìn wò àti láti bì í ṣubú, àti láti ṣe ayọ́lẹ̀wò ilẹ̀ náà.”
Tedae Ammon koca rhoek kah mangpa rhoek loh Hanun taengah, “Nang suem ham han tueih dongah na mikhmuh ah David loh na pa a thangpom nama? Khohmuen he hip ham neh maelh ham, khe ham pawt nim a sal rhoek te nang taengla ha pawk uh?” a ti nah.
4 Bẹ́ẹ̀ ni Hanuni fi ipá mú àwọn ọkùnrin Dafidi, fá irun wọn, wọ́n gé ẹ̀wù wọn kúrò ní àárín ìdí rẹ̀, ó sì rán wọn lọ.
Te dongah Hanun loh David kah sal rhoek te a tuuk. Amih te sam a vok pah, a himbai te a ael ah rhakhuem a hlueng pah phoeiah a tueih.
5 Nígbà tí ẹnìkan wá, tí ó sì sọ fún Dafidi nípa àwọn ọkùnrin rẹ̀, ó rán àwọn ìránṣẹ́ láti lọ bá wọn, nítorí wọ́n ti di rírẹ̀ sílẹ̀ gidigidi. Ọba wí pe, “Dúró ní Jeriko títí tí irùngbọ̀n yín yóò fi hù, nígbà náà ẹ padà wá”.
A caeh uh vaengah tah a hlang rhoek kawng te David ham a puen pauh. Hlang rhoek khaw hmaithae la mat a om uh coeng dongah amih aka doe te a tueih. Te vaengah manghai loh, “Na hmuimul a cawn hil Jerikho ah om uh lamtah ha mael uh,” a ti nah.
6 Nígbà tí àwọn ará Ammoni sì ri pé wọ́n ti di ẹ̀ṣẹ̀ ní ihò imú Dafidi, Hanuni àti àwọn ará Ammoni rán ẹgbẹ̀rún tálẹ́ǹtì fàdákà láti gba iṣẹ́ àwọn kẹ̀kẹ́ àti àwọn agun-kẹ̀kẹ́ láti Aramu-Naharaimu, Siria Maaka àti Soba.
David taengah bo a rhim uh te Ammon koca rhoek loh a hmuh uh. Te dongah Hanun neh Ammon koca rhoek loh Aramnaharaim, Arammaakah, Zobah lamkah leng neh marhang caem te paang hamla cak talent thawng khat neh a tah.
7 Wọ́n gba iṣẹ́ ẹgbẹ̀rin méjìlélọ́gbọ̀n kẹ̀kẹ́ àti agun-kẹ̀kẹ́ àti ọba Maaka pẹ̀lú àwọn ọ̀wọ́ ọmọ-ogun rẹ̀ tí ó wá pàgọ́ ní ẹ̀bá Medeba, nígbà tí àwọn ará Ammoni kójọpọ̀ láti ìlú wọn, tí wọ́n sì jáde lọ fún ogun.
Te dongah amamih ham te leng thawng sawmthum thawng hnih te a paang uh. Manghai Maakah neh a pilnam te khaw cet uh tih Medeba rhaldan ah rhaeh uh. Ammon koca rhoek khaw amamih khopuei lamloh coi uh thae tih caemtloek la pawk uh.
8 Ní gbígbọ́ eléyìí, Dafidi rán Joabu jáde pẹ̀lú gbogbo àwọn ọmọ-ogun ọkùnrin tí ó le jà.
David loh a yaak vaengah Joab neh hlangrhalh caempuei te boeih a tueih.
9 Àwọn ọmọ Ammoni sì jáde wá, wọ́n sì tẹ́ ogun ní ẹnu odi ìlú ńlá wọn, nígbà tí àwọn ọba tí ó wá, fún rara wọn wà ni orílẹ̀-èdè tí ó ṣí sílẹ̀.
Ammon koca rhoek te cet uh tih khopuei thohka ah caemtloek rhong a pai uh. Te vaengah manghai aka pawk rhoek te lohma ah amamih bueng omuh.
10 Joabu ri wí pé àwọn ìlà ogun wà níwájú àti ẹ̀yìn òun, bẹ́ẹ̀ ni o mu àwọn ọmọ-ogun tí ó dára ní Israẹli, o sì tẹ́ ogun wọn sí àwọn ará Siria.
Joab loh caemtloek hmai ah a hnuk a hmai la a om te a hmuh. Te dongah Israel khuikah a coelh boeih te koep a coelh tih Aram te mah hamla rhong a pai.
11 Ó fi ìyókù àwọn ọkùnrin náà sí abẹ́ àkóso Abiṣai arákùnrin rẹ̀, a sì tẹ́ wọn kí wọn dojúkọ àwọn ará Ammoni.
Pilnam kah a coihpaih te a mana Abishai kut ah a khueh tih Ammon koca rhoek te mah hamla rhong a pai uh.
12 Joabu wí pé tí àwọn ará Siria bá le jù fún mi, nígbà náà, ìwọ ni kí o gbà mí; ṣùgbọ́n tí àwọn ará Ammoni bá le jù fún ọ, nígbà náà èmi yóò gbà ọ́.
Te vaengah, “Aram te kai lakah a tlung atah loeihnah hamla kai taengah om. Tedae Ammon koca rhoek te nang lakah a tlung oeh atah nang kang khang van eh.
13 Jẹ́ alágbára kí ẹ sì jẹ́ kí a jà pẹ̀lú ìgboyà fún àwọn ènìyàn wa àti àwọn ìlú ńlá ti Ọlọ́run wa. Olúwa yóò ṣe ohun tí ó dára ní ojú rẹ̀.
Thaahuel uh lamtah mah pilnam ham neh mamih kah Pathen khopuei rhoek ham khaw thaahuel uh sih. BOEIPA loh a mikhmuh ah a then a saii bitni,” a ti nah.
14 Nígbà náà Joabu àti àwọn ọmọ-ogun pẹ̀lú rẹ̀ lọ síwájú láti lọ jà pẹ̀lú àwọn ará Siria. Wọ́n sì sálọ kúrò níwájú rẹ̀.
Te phoeiah Joab neh a taengkah pilnam loh Aram te caemtloek la a thoeih hatah a mikhmuh lamloh rhaelrham uh.
15 Nígbà ti àwọn ará Ammoni ri pé àwọn ará Siria ń sálọ, àwọn náà sálọ kúrò níwájú arákùnrin rẹ̀ Abiṣai. Wọ́n sì wọ inú ìlú ńlá lọ. Bẹ́ẹ̀ ni Joabu padà lọ sí Jerusalẹmu.
Ammon koca rhoek loh Aram a rhaelrham te a hmuh vaengah amamih khaw Joab mana Abishai mikhmuh lamloh rhaelrham uh tih khopuei khuila a kun coeng dongah Joab khaw Jerusalem la mael.
16 Lẹ́yìn ìgbà tí àwọn ará Siria rí wí pé àwọn Israẹli ti lé wọn, wọ́n rán ìránṣẹ́. A sì mú àwọn ará Siria rékọjá odò Eufurate wá, pẹ̀lú Ṣofaki alákòóso ọmọ-ogun Hadadeseri, tí ó ń darí wọn.
Aram loh Israel mikhmuh ah a yawk te a hmuh vaengah puencawn rhoek te a tueih uh. Te vaengah Aram loh tuiva rhalvangan lamkah te a khuen uh tih Hadadezer kah caempuei mangpa Shophate teamih hmai ah a lamhma sak.
17 Nígbà tí a sọ fún Dafidi nípa èyí, ó pe gbogbo Israẹli jọ wọ́n sì rékọjá Jordani; Ó lọ síwájú wọn, ó sì fa ìlà ogun dojúkọ wọ́n. Dafidi fa ìlà rẹ̀ láti bá àwọn ará Siria jagun wọ́n sì dojú ìjà kọ ọ́.
Tedae David taengla a puen pah dongah Israel pum te a coi tih Jordan te kat. Amih te a paan tih a rhaldan ah rhong a pai. David loh Aram te caemtloek neh doe hamla rhong a pai tih a vathoh thil uh.
18 Ṣùgbọ́n àwọn ará Siria sálọ kúrò níwájú Israẹli, Dafidi sì pa ẹ̀ẹ́dẹ́gbàárin agun-kẹ̀kẹ́ wọn àti ọ̀kẹ́ méjì ọmọ-ogun ẹlẹ́ṣẹ̀. Ó pa Ṣofaki alákòóso ọmọ-ogun wọn pẹ̀lú.
Aram te Israel mikhmuh lamloh a rhaelrham coeng dongah David loh Aram kah leng caem thawng rhih, rhalkap te hlang thawng sawmli a ngawn pah tih caempuei mangpa Shophate te a duek sak.
19 Nígbà tí àwọn ẹrú Hadadeseri rí i wí pé Israẹli ti borí wọn, wọ́n ṣe àlàáfíà pẹ̀lú Dafidi, wọ́n sì ń sìn ní abẹ́ ẹ rẹ̀. Bẹ́ẹ̀ ni, àwọn ará Siria kò ní ìfẹ́ sí ríran àwọn ará Ammoni lọ́wọ́ mọ́.
Israel mikhmuh ah a yawk uh te Hadadezer kah sal rhoek loh a hmuh. Te dongah David te a sah tih a taengah thotat uh. Te phoeiah Aram loh Ammon koca te rhun ham ngaih voel pawh.

< 1 Chronicles 19 >