< 1 Chronicles 18 >
1 Ní àkókò kan, Dafidi kọlu àwọn ará Filistini, ó sì ṣẹ́gun wọn. Ó sì mú Gati àti àwọn ìletò agbègbè rẹ̀ kúrò lábẹ́ ìdarí àwọn ará Filistini.
David défit ensuite les Philistins, abattit leur puissance et leur enleva Gath et ses dépendances.
2 Dafidi borí àwọn ará Moabu, wọ́n sì di ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀, wọ́n sì mú owó òde wá.
Puis il vainquit les Moabites, qui furent assujettis à David et devinrent ses tributaires.
3 Síbẹ̀, Dafidi sì kọlu Hadadeseri ọba Soba ní Hamati, bí ó ti ń lọ láti fi ìdí ìjọba rẹ̀ múlẹ̀ létí odò Eufurate.
Puis David battit Hadarézer, roi de Çoba, du côté de Hamath, tandis qu’il marchait vers l’Euphrate pour étendre sa domination.
4 Dafidi fi agbára gba ẹgbẹ̀rún kẹ̀kẹ́ rẹ̀, ẹ̀ẹ́dẹ́gbàárin agun-kẹ̀kẹ́ àti ogún ẹgbẹ̀rún ológun ilẹ̀. Ó sì já gbogbo ọgọ́rùn-ún iṣan ẹsẹ̀ àwọn kẹ̀kẹ́-ẹṣin náà.
David lui captura mille chars, sept mille cavaliers et vingt mille hommes de pied, fit mutiler tous les attelages, et n’en conserva que cent.
5 Nígbà ti àwọn ará Siria ti Damasku wá láti ran Hadadeseri ọba Soba lọ́wọ́, Dafidi lu ẹgbẹ̀rún méjìlélógún wọn bọ lẹ̀.
La Syrie de Damas vint au secours de Hadarézer, roi de Çoba; David tua aux Syriens vingt-deux mille hommes.
6 Ó sì fi àwọn ọ̀wọ́ ọmọ-ogun rẹ sínú ìjọba Siria ti Damasku, àwọn ará Siria sì ń sìn ní abẹ́ rẹ̀, wọ́n sì mú owó ìṣákọ́lẹ̀ wá. Olúwa sì ń fún Dafidi ní ìṣẹ́gun ní ibi gbogbo tí ó bá lọ.
Il mit ensuite des garnisons dans la Syrie de Damas, qui devint sujette et tributaire de David. Ainsi le Seigneur protégeait David dans toutes ses campagnes.
7 Dafidi mú àpáta wúrà tí àwọn ìjòyè Hadadeseri gbé, ó sì gbé wọn wá sí Jerusalẹmu.
David s’empara des boucliers d’or, que portaient les serviteurs de Hadarézer, et les transporta à Jérusalem.
8 Láti Tibhati àti Kuni, àwọn ìlú Hadadeseri, Dafidi kó ọ̀pọ̀lọpọ̀ idẹ tí Solomoni lò láti fi ṣe okùn idẹ, àwọn òpó àti oríṣìí ohun èlò idẹ.
Egalement de Thibat et de Koun, villes de Hadarézer, le roi David emporta du cuivre en grande quantité, qui servit à Salomon pour faire la Mer de cuivre, les colonnes et les objets en cuivre.
9 Nígbà tí Tou ọba Hamati gbọ́ pé Dafidi ti borí gbogbo ọmọ-ogun Hadadeseri ọba Soba.
Toou, roi de Hamath, ayant appris que David avait défait toute l’armée de Hadarézer, roi de Çoba,
10 Ó rán ọmọ rẹ̀ Hadoramu sí ọba Dafidi láti kí i àti láti lọ bá a yọ̀ lórí ìṣẹ́gun rẹ̀ nínú ogun lórí Hadadeseri, tí ó wà lójú ogun pẹ̀lú Tou. Hadoramu mú oríṣìíríṣìí ohun èlò ti wúrà àti fàdákà àti idẹ wá.
envoya son fils Hadoram au roi David pour le saluer et le féliciter d’avoir combattu et vaincu Hadarézer, car celui-ci était en guerre avec Toou. Il lui envoyait en même temps toute sorte de vases d’or, d’argent et de cuivre.
11 Ọba Dafidi ya ohun èlò wọ́n yí sí mímọ́ fún Olúwa, gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣe pẹ̀lú fàdákà àti wúrà tí ó ti mú láti gbogbo àwọn orílẹ̀-èdè wọ̀nyí: Edomu àti Moabu, ará Ammoni àti àwọn ará Filistini àti Amaleki.
Ceux-là aussi, le roi David les consacra à l’Eternel, comme il avait fait de l’argent et de l’or qu’il avait enlevés à tous les peuples, aux Iduméens, aux Moabites, aux Ammonites, aux Philistins et aux Amalécites.
12 Abiṣai ọmọ Seruiah lu ẹgbàá mẹ́sàn ará Edomu bolẹ̀ ní àfonífojì Iyọ̀.
Abchaï, fils de Cerouya, avait battu dix-huit mille Iduméens dans la vallée du Sel.
13 Ó fi ẹgbẹ́ ogun sí Edomu, gbogbo àwọn ará Edomu sì ń sìn ní abẹ́ Dafidi. Olúwa fún Dafidi ní ìṣẹ́gun ní gbogbo ibí tí ó bá lọ.
Il mit des garnisons dans l’Idumée, de sorte que toute l’Idumée devint tributaire de David. Et le Seigneur protégea David dans toutes ses voies.
14 Dafidi jẹ ọba lórí gbogbo Israẹli, ó sì ṣe òdodo àti ohun tí ó yẹ fún gbogbo àwọn ènìyàn rẹ̀.
David régna sur tout Israël, et il gouverna tout son peuple avec justice et équité.
15 Joabu ọmọ Seruiah jẹ́ olórí ẹgbẹ́ ọmọ-ogun; Jehoṣafati ọmọ Ahiludi jẹ́ akọ̀wé ìrántí;
Joab, fils de Cerouya, était chef de l’armée; Josaphat, fils d’Ahiloud, archiviste;
16 Sadoku ọmọ Ahitubu àti Abimeleki ọmọ Abiatari jẹ́ àwọn àlùfáà; Ṣafṣa jẹ́ akọ̀wé;
Çadok, fils d’Ahitoub, et Abimélec, fils d’Ebiatar, prêtres; Chavcha, secrétaire;
17 Benaiah ọmọ Jehoiada jẹ́ olórí àwọn Kereti àti Peleti; àwọn ọmọ Dafidi sì ni àwọn olóyè oníṣẹ́ ní ọ̀dọ̀ ọba.
Benaïahou, fils de Joïada, était à la tête des Krêthi et Pelêthi; et les fils de David étaient les premiers ministres du roi.