< 1 Chronicles 17 >

1 Lẹ́yìn ìgbà tí Dafidi ti fi ìdí kalẹ̀ sínú ààfin rẹ̀, ó sọ fún Natani wòlíì pé, “Èmi nìyí, tí ń gbé inú ààfin kedari nígbà tí àpótí ẹ̀rí Olúwa wà lábẹ́ àgọ́.”
Thuutha wa Daudi gũikara nyũmba yake ya ũthamaki kwa ihinda, akĩĩra mũnabii Nathani atĩrĩ, “Niĩ njikaraga nyũmba ya ũthamaki yakĩtwo na mĩtarakwa, o rĩrĩa ithandũkũ rĩa kĩrĩkanĩro kĩa Jehova rĩigĩtwo hema-inĩ.”
2 Natani dá Dafidi lóhùn pé, “Ohunkóhun tí o bá ní lọ́kàn, ṣe é nítorí tí Ọlọ́run wà pẹ̀lú rẹ.”
Nathani agĩcookeria Daudi atĩrĩ, “Ũndũ ũrĩa ũreciiria gwĩka-rĩ, wĩke, nĩgũkorwo Ngai arĩ hamwe nawe.”
3 Ní àṣálẹ́ ọjọ́ náà, ọ̀rọ̀ Ọlọ́run tọ Natani wá, wí pé:
Ũtukũ ũcio kiugo kĩa Ngai gĩgĩkinyĩra Nathani, akĩĩrwo atĩrĩ:
4 “Lọ sọ fún ìránṣẹ́ mi Dafidi, ‘Èyí ni ohun tí Olúwa wí: Ìwọ kò gbọdọ̀ kọ́ ilé fún mi láti máa gbé.
“Thiĩ ũkeere ndungata yakwa Daudi atĩrĩ, ‘Jehova ekuuga ũũ: Wee tiwe wa kũnjakĩra nyũmba ya gũtũũra.
5 Èmi kò tí ì gbé nínú ilé láti ọjọ́ tí mo ti mú Israẹli jáde wá láti Ejibiti títí di òní yìí. Èmi ń lọ láti àgọ́ dé àgọ́ àti láti ibùgbé dé ibùgbé.
Niĩ ndirĩ ndatũũra nyũmba kuuma mũthenya ũrĩa ndaarutire andũ a Isiraeli kuuma bũrũri wa Misiri nginya ũmũthĩ. Ndũũraga hema-inĩ, thaamaga kuuma handũ hamwe ngathiĩ harĩa hangĩ, ngoima gĩikaro kĩmwe ngathiĩ kĩrĩa kĩngĩ.
6 Ni ibi gbogbo tí mo ti bá gbogbo Israẹli rìn dé, ǹjẹ́ mo wí nǹkan kan sí ọ̀kan nínú àwọn adarí Israẹli, tí èmí pàṣẹ fún láti máa jẹ́ olùṣọ́-àgùntàn àwọn ènìyàn mi, wí pé, “Kí ní ṣe tí ẹ̀yin kò fi kọ́ ilé tí a fi igi kedari kọ́ fún mi?”’
Kũrĩa guothe ndaanathiĩ na andũ a Isiraeli othe-rĩ, ndĩ ndooria mũtongoria o na ũmwe wa arĩa ndaathire marĩithagie andũ akwa atĩrĩ, “Mwagĩte kũnjakĩra nyũmba ya mĩtarakwa nĩkĩ?”’
7 “Nígbà náà, sọ fún ìránṣẹ́ mi Dafidi pé, ‘Èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí: Èmi mú ọ kúrò ní pápá oko tútù wá, àní kúrò lẹ́yìn agbo àgùntàn, kí ìwọ kí ó lè máa ṣe olórí àwọn ènìyàn mi Israẹli.
“Na rĩrĩ, ĩra ndungata yakwa Daudi atĩrĩ, ‘Jehova Mwene-Hinya-Wothe ekuuga ũũ: Ndaakũrutire rũũru-inĩ, ngĩgũtigithia kũrũmĩrĩra mahiũ nĩguo ũtuĩke mwathi wa andũ akwa a Isiraeli.
8 Èmi ti wà pẹ̀lú rẹ ní, ibikíbi tí ìwọ bá lọ, èmí sì ti gé gbogbo àwọn ọ̀tá rẹ kúrò níwájú rẹ. Nísinsin yìí Èmi yóò mú kí orúkọ rẹ kí ó dàbí orúkọ àwọn ènìyàn ńlá jùlọ tí ó wà ní ayé.
Nĩngoretwo nawe kũrĩa guothe wanathiĩ, na ngakwehereria thũ ciaku ciothe ikehera mbere yaku. Rĩu nĩngũtũma rĩĩtwa rĩaku rĩtuĩke inene o ta marĩĩtwa ma andũ arĩa anene mũno a thĩ.
9 Èmi yóò sì pèsè ààyè kan fún àwọn ènìyàn mi Israẹli, kí wọn kí ó lè ní ilé tiwọn, kí a má sì ṣe dààmú wọn mọ́. Àwọn ènìyàn búburú kì yóò ni wọ́n lára mọ́, gẹ́gẹ́ bí wọ́n ti ṣe ní ìbẹ̀rẹ̀.
Na nĩngaahe andũ akwa a Isiraeli handũ na ndĩmahaande wega nĩgeetha magĩe na mũciĩ wao kĩũmbe, na matigacooka gũthĩĩnĩka. Andũ aaganu matigacooka kũmahinyĩrĩria rĩngĩ, ta ũrĩa meekaga kĩambĩrĩria-inĩ
10 Bí wọ́n sì ti ṣe láti ìgbà tí mo ti yan àwọn aṣáájú lórí àwọn ènìyàn mi Israẹli. Èmi pẹ̀lú yóò ṣẹ́gun gbogbo àwọn ọ̀tá yín. “‘Èmi sọ fún yín pé Olúwa yóò kọ́ ilé kan fún yín,
na matũire meekaga kuuma rĩrĩa ndathuurire atongoria a gũtongoragia andũ akwa a Isiraeli. O na nĩngatooria thũ cianyu ciothe. “‘Na ningĩ ngũkwĩra atĩ Jehova we mwene nĩwe ũgũgwakĩra nyũmba:
11 nígbà ti ọjọ́ rẹ bá kọjá, tí ìwọ bá lọ láti lọ bá àwọn baba à rẹ, Èmi yóò gbé àwọn ọmọ rẹ sókè láti rọ́pò rẹ, ọ̀kan lára àwọn ọmọ tìrẹ, Èmi yóò sì fìdí ìjọba rẹ̀ kalẹ̀.
Hĩndĩ ĩrĩa matukũ maku magaathira nawe ũthiĩ ũgatũũranie na maithe manyu, nĩngarũgamia mũndũ wa rũciaro rwaku athamake ithenya rĩaku, agaakorwo arĩ ũmwe wa ariũ aku, na nĩngahaanda ũthamaki wake.
12 Òun ni ẹni tí yóò kọ́ ilé fún mi, èmi yóò sí fi ìdí ìtẹ́ rẹ̀ kalẹ̀ títí láé.
Ũcio nĩwe ũkaanjakĩra nyũmba, na nĩngahaanda gĩtĩ gĩake kĩa ũnene nginya tene.
13 Èmi yóò jẹ́ baba rẹ̀, Òun yóò sì jẹ́ ọmọ mi. Èmi kì yóò mú ìfẹ́ mi kúrò lọ́dọ̀ rẹ̀ láéláé gẹ́gẹ́ bí mo ṣe mú un kúrò lọ́dọ̀ àwọn aṣáájú rẹ̀.
Nĩngatuĩka ithe, nake nĩagatuĩka mũrũ wakwa. Ndikeheria wendo wakwa harĩ we, ta ũrĩa ndehereirie ũrĩa warĩ mbere yaku.
14 Èmi yóò gbé e ka orí ilé mi àti ìjọba mi títí láé; ìtẹ́ rẹ̀ ni a ó fi ìdí rẹ̀ múlẹ̀ títí láé.’”
Nĩngamũtua mwathi wa nyũmba yakwa na ũthamaki wakwa nginya tene; gĩtĩ gĩake kĩa ũnene gĩkehaanda nginya tene.’”
15 Natani ròyìn fún Dafidi gbogbo àwọn ọ̀rọ̀ ti ìfihàn yí.
Nathani akĩmenyithia Daudi ũhoro wa ũguũrio ũcio wothe.
16 Nígbà náà, ọba Dafidi wọlé lọ, ó sì jókòó níwájú Olúwa ó sì wí pé, “Ta ni èmi, Olúwa Ọlọ́run, àti ki ni ìdílé mi, tí ìwọ mú mi dé ibí?
Nake Mũthamaki Daudi agĩtoonya, agĩikara thĩ mbere ya Jehova, akiuga atĩrĩ: “Niĩ ndĩkĩrĩ ũ, Wee Jehova Ngai, nayo nyũmba yakwa-rĩ, ĩkĩrĩ kĩ, atĩ nĩkĩo ũnginyĩtie nginya haha?
17 Pẹ̀lú bí ẹni pé èyí kò tó lójú rẹ, Ọlọ́run, ìwọ ti sọ̀rọ̀ nípa ọjọ́ iwájú ilé ìránṣẹ́ rẹ. Ìwọ ti wò mí bí ẹni pé èmi ni ẹni gbígbéga jù láàrín àwọn ọkùnrin Olúwa Ọlọ́run.
Na ta ũndũ ũcio ũrĩ o mũnini maitho-inĩ maku, Wee Ngai-rĩ, nĩwarĩtie ũhoro wa matukũ marĩa magooka makoniĩ nyũmba ya ndungata yaku. Na rĩu Wee Jehova Ngai, ũnyonete ta ndĩ mũndũ ũmwe wa arĩa atũũgĩrie mũno.
18 “Kí ni ohun tí Dafidi tún lè sọ nítorí ọlá tí o bù fún ìránṣẹ́ rẹ? Nítorí tí ìwọ mọ ìránṣẹ́ rẹ,
“Nĩ atĩa ũngĩ Daudi angĩkwĩra nĩ ũndũ wa gũtĩĩa ndungata yaku? Nĩgũkorwo nĩũũĩ ndungata yaku, Wee Jehova.
19 Olúwa. Nítorí ti ìránṣẹ́ rẹ àti gẹ́gẹ́ bí àṣẹ rẹ, ìwọ ti ṣe ohun ńlá yìí àti láti fi gbogbo ìlérí ńlá yìí hàn.
Nĩ ũndũ wa ndungata yaku na kũringana na wendo waku-rĩ, nĩwĩkĩte ũndũ ũyũ mũnene na ũgatũma ciĩranĩro ici nene imenyeke.
20 “Kò sí ẹnìkan bí rẹ Olúwa, kò sì sí Ọlọ́run kan àfi ìwọ, gẹ́gẹ́ bí à ti gbọ́ pẹ̀lú etí ara wa.
“Gũtirĩ ũngĩ ũhaana tawe, Wee Jehova, na gũtirĩ Ngai ũngĩ tiga Wee, o ta ũrĩa tũiguĩte na matũ maitũ.
21 Pẹ̀lú ta ni ó dàbí àwọn ènìyàn rẹ Israẹli—orílẹ̀-èdè kan ní ayé, tí Ọlọ́run jáde lọ láti ra àwọn ènìyàn kan padà fún ara rẹ̀, àti láti lè ṣe orúkọ fún ara à rẹ, àti láti ṣe ohun ńlá àti ọwọ́ ìyanu nípa lílé àwọn orílẹ̀-èdè kúrò níwájú àwọn ènìyàn rẹ̀, ẹni tí ó gbàlà láti Ejibiti?
Na nũũ ũhaana ta andũ aku a Isiraeli, rũrĩrĩ rũmwe gũkũ thĩ rũrĩa Ngai waruo aakũũrire rũtuĩke andũ ake, nĩgeetha wĩgĩĩre igweta, na wĩke maũndũ manene na ma magegania ma gwĩtigĩrwo, nĩ ũndũ wa kũingata ndũrĩrĩ ciehere mbere ya andũ aku arĩa wakũũrire kuuma bũrũri wa Misiri?
22 Ìwọ ṣe àwọn ènìyàn rẹ Israẹli ní tìrẹ láéláé ìwọ Olúwa sì ti di Ọlọ́run wọn.
Watũmire andũ aku a Isiraeli matuĩke andũ aku mwene nginya tene, nawe, Wee Jehova, nĩũtuĩkĩte Ngai wao.
23 “Nísinsin yìí, Olúwa, jẹ́ kí ìlérí tí ìwọ ti ṣe fún ìránṣẹ́ rẹ àti ilé rẹ̀ di fífi ìdí múlẹ̀ títí láé. Ṣe gẹ́gẹ́ bí o ti ṣe ìlérí.
“Na rĩrĩ, Jehova, tũma kĩĩranĩro kĩrĩa weranĩire gĩkoniĩ ndungata yaku na nyũmba yake kĩrũme nginya tene. Na wĩke o ta ũguo wĩranĩire,
24 Kí ó lè di fífi ìdí múlẹ̀ àti kí orúkọ rẹ di gbígbéga títí láé. Nígbà náà ni àwọn ọkùnrin yóò wí pé, ‘Olúwa àwọn ọmọ-ogun, ni Ọlọ́run Israẹli.’ Ilé ìránṣẹ́ rẹ Dafidi sì ni a ó fi ìdí rẹ̀ múlẹ̀ níwájú rẹ.
nĩgeetha kĩĩranĩro kĩu kĩĩhaande, narĩo rĩĩtwa rĩaku rĩnenehe nginya tene. Ningĩ andũ nĩmakoiga atĩrĩ, ‘Jehova Mwene-Hinya-Wothe, Ngai wa Isiraeli, nĩwe Ngai wa andũ a Isiraeli!’ Na nyũmba ya ndungata yaku Daudi nĩĩkehaanda mbere yaku.”
25 “Ìwọ, Ọlọ́run mi, ti fihan ìránṣẹ́ rẹ pé, ìwọ yóò kọ́ ilé fún un. Bẹ́ẹ̀ ni ìránṣẹ́ rẹ ti ní ìgboyà láti gbàdúrà sí ọ.
“Wee Ngai wakwa, nĩũguũrĩirie ndungata yaku atĩ nĩũkamĩakĩra nyũmba. Nĩ ũndũ ũcio ndungata yaku nĩĩgĩĩte na ũmĩrĩru wa gũkũhooya.
26 Olúwa, ìwọ ni Ọlọ́run. Ìwọ ti fi ìlérí dídára yìí fún ìránṣẹ́ rẹ.
Wee Jehova, nĩwe Ngai! Nĩwĩrĩire ndungata yaku maũndũ maya mega.
27 Nísinsin yìí ó ti tẹ́ ọ lọ́rùn láti bùkún ilé ìránṣẹ́ rẹ kí ó lè tẹ̀síwájú ní ojú rẹ; nítorí ìwọ, Olúwa, ti bùkún un, a ó sì bùkún un títí láéláé.”
Rĩu nĩwonete kwagĩrĩire ũrathime nyũmba ya ndungata yaku, nĩgeetha ĩtũũre nginya tene maitho-inĩ maku; nĩgũkorwo, Wee Jehova nĩũmĩrathimĩte, na ĩgũtũũra ĩrĩ ndaathime nginya tene.”

< 1 Chronicles 17 >