< 1 Chronicles 17 >

1 Lẹ́yìn ìgbà tí Dafidi ti fi ìdí kalẹ̀ sínú ààfin rẹ̀, ó sọ fún Natani wòlíì pé, “Èmi nìyí, tí ń gbé inú ààfin kedari nígbà tí àpótí ẹ̀rí Olúwa wà lábẹ́ àgọ́.”
I stalo se, když bydlil David v domě svém, že řekl Nátanovi proroku: Aj, já přebývám v domě cedrovém, truhla pak smlouvy Hospodinovy jest pod kortýnami.
2 Natani dá Dafidi lóhùn pé, “Ohunkóhun tí o bá ní lọ́kàn, ṣe é nítorí tí Ọlọ́run wà pẹ̀lú rẹ.”
I řekl Nátan Davidovi: Cožkoli jest v srdci tvém, učiň; nebo Bůh s tebou jest.
3 Ní àṣálẹ́ ọjọ́ náà, ọ̀rọ̀ Ọlọ́run tọ Natani wá, wí pé:
Potom té noci stalo se slovo Boží k Nátanovi, řkoucí:
4 “Lọ sọ fún ìránṣẹ́ mi Dafidi, ‘Èyí ni ohun tí Olúwa wí: Ìwọ kò gbọdọ̀ kọ́ ilé fún mi láti máa gbé.
Jdi a rci Davidovi služebníku mému: Toto dí Hospodin: Ne ty stavěti mi budeš dům k bydlení,
5 Èmi kò tí ì gbé nínú ilé láti ọjọ́ tí mo ti mú Israẹli jáde wá láti Ejibiti títí di òní yìí. Èmi ń lọ láti àgọ́ dé àgọ́ àti láti ibùgbé dé ibùgbé.
Poněvadž jsem nebydlil v žádném domě od toho dne, jakž jsem vyvedl syny Izraelské, až do dne tohoto, ale procházel jsem se z stánku do stánku, také i vně kromě příbytku.
6 Ni ibi gbogbo tí mo ti bá gbogbo Israẹli rìn dé, ǹjẹ́ mo wí nǹkan kan sí ọ̀kan nínú àwọn adarí Israẹli, tí èmí pàṣẹ fún láti máa jẹ́ olùṣọ́-àgùntàn àwọn ènìyàn mi, wí pé, “Kí ní ṣe tí ẹ̀yin kò fi kọ́ ilé tí a fi igi kedari kọ́ fún mi?”’
Nadto kudyž jsem koli chodil se vším Izraelem, zdali jsem slovo řekl kterému z soudců Izraelských, (jimž jsem přikázal, aby pásli lid můj), řka: Proč jste mi neustavěli domu cedrového?
7 “Nígbà náà, sọ fún ìránṣẹ́ mi Dafidi pé, ‘Èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí: Èmi mú ọ kúrò ní pápá oko tútù wá, àní kúrò lẹ́yìn agbo àgùntàn, kí ìwọ kí ó lè máa ṣe olórí àwọn ènìyàn mi Israẹli.
Protož nyní toto díš služebníku mému Davidovi: Takto praví Hospodin zástupů: Já jsem tě vzal z ovčince, když jsi chodil za stádem, abys byl vývodou lidu mého Izraelského.
8 Èmi ti wà pẹ̀lú rẹ ní, ibikíbi tí ìwọ bá lọ, èmí sì ti gé gbogbo àwọn ọ̀tá rẹ kúrò níwájú rẹ. Nísinsin yìí Èmi yóò mú kí orúkọ rẹ kí ó dàbí orúkọ àwọn ènìyàn ńlá jùlọ tí ó wà ní ayé.
A býval jsem s tebou všudy, kamž jsi koli se obrátil, všecky také nepřátely tvé vyhladil jsem před tváří tvou, a učinilť jsem jméno veliké, jako jméno vznešených na zemi.
9 Èmi yóò sì pèsè ààyè kan fún àwọn ènìyàn mi Israẹli, kí wọn kí ó lè ní ilé tiwọn, kí a má sì ṣe dààmú wọn mọ́. Àwọn ènìyàn búburú kì yóò ni wọ́n lára mọ́, gẹ́gẹ́ bí wọ́n ti ṣe ní ìbẹ̀rẹ̀.
Ano i lidu svému Izraelskému způsobil jsem místo, a vštípil jej tu. I bude bydliti na místě svém, a nepohne se více, aniž na něj dotírati budou lidé nešlechetní, jako prvé,
10 Bí wọ́n sì ti ṣe láti ìgbà tí mo ti yan àwọn aṣáájú lórí àwọn ènìyàn mi Israẹli. Èmi pẹ̀lú yóò ṣẹ́gun gbogbo àwọn ọ̀tá yín. “‘Èmi sọ fún yín pé Olúwa yóò kọ́ ilé kan fún yín,
Hned od toho času, jakž jsem ustanovil soudce nad lidem svým Izraelským, až jsem ponížil všech nepřátel tvých; nýbrž oznamujiť, že Hospodin sám vystaví tobě dům.
11 nígbà ti ọjọ́ rẹ bá kọjá, tí ìwọ bá lọ láti lọ bá àwọn baba à rẹ, Èmi yóò gbé àwọn ọmọ rẹ sókè láti rọ́pò rẹ, ọ̀kan lára àwọn ọmọ tìrẹ, Èmi yóò sì fìdí ìjọba rẹ̀ kalẹ̀.
Nebo když se vyplní dnové tvoji, abys šel za otci svými, vzbudím símě tvé po tobě, kteréž bude z synů tvých, a utvrdím království jeho.
12 Òun ni ẹni tí yóò kọ́ ilé fún mi, èmi yóò sí fi ìdí ìtẹ́ rẹ̀ kalẹ̀ títí láé.
Onť mi ustaví dům, a já utvrdím trůn jeho až na věky.
13 Èmi yóò jẹ́ baba rẹ̀, Òun yóò sì jẹ́ ọmọ mi. Èmi kì yóò mú ìfẹ́ mi kúrò lọ́dọ̀ rẹ̀ láéláé gẹ́gẹ́ bí mo ṣe mú un kúrò lọ́dọ̀ àwọn aṣáájú rẹ̀.
Já budu jemu otcem, a on mi bude synem, a milosrdenství svého neodejmu od něho, jako jsem je odjal od toho, kterýž byl před tebou.
14 Èmi yóò gbé e ka orí ilé mi àti ìjọba mi títí láé; ìtẹ́ rẹ̀ ni a ó fi ìdí rẹ̀ múlẹ̀ títí láé.’”
Ale postavím jej v domě svém a v království svém až na věky, a trůn jeho bude nepohnutelný až na věky.
15 Natani ròyìn fún Dafidi gbogbo àwọn ọ̀rọ̀ ti ìfihàn yí.
Podlé všech slov těchto, a podlé všeho vidění tohoto, tak mluvil Nátan Davidovi.
16 Nígbà náà, ọba Dafidi wọlé lọ, ó sì jókòó níwájú Olúwa ó sì wí pé, “Ta ni èmi, Olúwa Ọlọ́run, àti ki ni ìdílé mi, tí ìwọ mú mi dé ibí?
Tedy všed král David, posadil se před Hospodinem, a řekl: Kdož jsem já, ó Hospodine Bože, a jaký jest dům můj, že jsi mne tak zvýšil?
17 Pẹ̀lú bí ẹni pé èyí kò tó lójú rẹ, Ọlọ́run, ìwọ ti sọ̀rọ̀ nípa ọjọ́ iwájú ilé ìránṣẹ́ rẹ. Ìwọ ti wò mí bí ẹni pé èmi ni ẹni gbígbéga jù láàrín àwọn ọkùnrin Olúwa Ọlọ́run.
Anobrž i to jsi za málo u sebe položil, ó Bože, pročež jsi zamluvil se o domu služebníka svého i na dlouhé časy, a popatřil jsi na mne, jako na osobu člověka vzácného, Hospodine Bože.
18 “Kí ni ohun tí Dafidi tún lè sọ nítorí ọlá tí o bù fún ìránṣẹ́ rẹ? Nítorí tí ìwọ mọ ìránṣẹ́ rẹ,
Což ještě více mluviti má David před tebou o zvelebení služebníka tvého? Ty zajisté znáš služebníka svého.
19 Olúwa. Nítorí ti ìránṣẹ́ rẹ àti gẹ́gẹ́ bí àṣẹ rẹ, ìwọ ti ṣe ohun ńlá yìí àti láti fi gbogbo ìlérí ńlá yìí hàn.
Hospodine, pro služebníka svého a podlé srdce svého činíš velikou věc tuto, abys v známost uvedl všecky převeliké věci.
20 “Kò sí ẹnìkan bí rẹ Olúwa, kò sì sí Ọlọ́run kan àfi ìwọ, gẹ́gẹ́ bí à ti gbọ́ pẹ̀lú etí ara wa.
Hospodine, neníť tobě rovného, anobrž není žádného Boha kromě tebe, podlé toho všeho, jakž jsme slýchali ušima svýma.
21 Pẹ̀lú ta ni ó dàbí àwọn ènìyàn rẹ Israẹli—orílẹ̀-èdè kan ní ayé, tí Ọlọ́run jáde lọ láti ra àwọn ènìyàn kan padà fún ara rẹ̀, àti láti lè ṣe orúkọ fún ara à rẹ, àti láti ṣe ohun ńlá àti ọwọ́ ìyanu nípa lílé àwọn orílẹ̀-èdè kúrò níwájú àwọn ènìyàn rẹ̀, ẹni tí ó gbàlà láti Ejibiti?
Nebo kde jest který národ na zemi, jako lid tvůj Izraelský, jehož by Bůh šel, aby vykoupil sobě lid a dobyl sobě jména, čině veliké a hrozné věci, vyháněje před tváří lidu svého, kterýž jsi vykoupil z Egypta, pohany?
22 Ìwọ ṣe àwọn ènìyàn rẹ Israẹli ní tìrẹ láéláé ìwọ Olúwa sì ti di Ọlọ́run wọn.
Zvolil jsi zajisté lid svůj Izraelský sobě za lid až na věky, a ty, Hospodine, sám jsi jejich Bohem.
23 “Nísinsin yìí, Olúwa, jẹ́ kí ìlérí tí ìwọ ti ṣe fún ìránṣẹ́ rẹ àti ilé rẹ̀ di fífi ìdí múlẹ̀ títí láé. Ṣe gẹ́gẹ́ bí o ti ṣe ìlérí.
Nyní tedy, Hospodine, slovo to, jímž jsi zamluvil se služebníku svému a domu jeho, budiž jisté až na věky, a učiň tak, jakž jsi mluvil.
24 Kí ó lè di fífi ìdí múlẹ̀ àti kí orúkọ rẹ di gbígbéga títí láé. Nígbà náà ni àwọn ọkùnrin yóò wí pé, ‘Olúwa àwọn ọmọ-ogun, ni Ọlọ́run Israẹli.’ Ilé ìránṣẹ́ rẹ Dafidi sì ni a ó fi ìdí rẹ̀ múlẹ̀ níwájú rẹ.
Budiž, pravím, jisté, tak aby velebeno bylo jméno tvé až na věky, a říkáno: Hospodin zástupů, Bůh Izraelský, jest Bůh nad Izraelem, a dům Davida služebníka tvého ať jest nepohnutelný před oblíčejem tvým.
25 “Ìwọ, Ọlọ́run mi, ti fihan ìránṣẹ́ rẹ pé, ìwọ yóò kọ́ ilé fún un. Bẹ́ẹ̀ ni ìránṣẹ́ rẹ ti ní ìgboyà láti gbàdúrà sí ọ.
Nebo ty, Bože můj, zjevil jsi služebníku svému, že mu ustavíš dům, a protož směl služebník tvůj modliti se před tebou.
26 Olúwa, ìwọ ni Ọlọ́run. Ìwọ ti fi ìlérí dídára yìí fún ìránṣẹ́ rẹ.
A tak, ó Hospodine, ty jsi sám Bůh, a mluvil jsi o služebníku svém dobré věci tyto.
27 Nísinsin yìí ó ti tẹ́ ọ lọ́rùn láti bùkún ilé ìránṣẹ́ rẹ kí ó lè tẹ̀síwájú ní ojú rẹ; nítorí ìwọ, Olúwa, ti bùkún un, a ó sì bùkún un títí láéláé.”
Nyní tedy ráčil jsi požehnati domu služebníka svého, aby trval na věky před oblíčejem tvým; nebo jsi ty, Hospodine, požehnal, i budeť požehnaný na věky.

< 1 Chronicles 17 >