< 1 Chronicles 17 >

1 Lẹ́yìn ìgbà tí Dafidi ti fi ìdí kalẹ̀ sínú ààfin rẹ̀, ó sọ fún Natani wòlíì pé, “Èmi nìyí, tí ń gbé inú ààfin kedari nígbà tí àpótí ẹ̀rí Olúwa wà lábẹ́ àgọ́.”
David chu ama inpia ana umlai in Themgao Nathan chu akou in akom a hitin asei e, “Keimala Cedar thing a kisa innom tah a kacheng in, ahivang in Pakai kitepna thingkong vang chu ponbuh a kisa mai mai noi a ana kikoi in ahi.”
2 Natani dá Dafidi lóhùn pé, “Ohunkóhun tí o bá ní lọ́kàn, ṣe é nítorí tí Ọlọ́run wà pẹ̀lú rẹ.”
Nathan in adonbut in, “Nalung a um nagel chan chu bollin ajeh chu Pathen in naumpi nai.”
3 Ní àṣálẹ́ ọjọ́ náà, ọ̀rọ̀ Ọlọ́run tọ Natani wá, wí pé:
Ahivang in, hicheni jantah chun Pathen in Nathan kom a anasei e,
4 “Lọ sọ fún ìránṣẹ́ mi Dafidi, ‘Èyí ni ohun tí Olúwa wí: Ìwọ kò gbọdọ̀ kọ́ ilé fún mi láti máa gbé.
“Chenlang kasohpa David kom a gahiltan nangma hi keima umna ding munsem ding chu nahipoi’tin ana sei e.”
5 Èmi kò tí ì gbé nínú ilé láti ọjọ́ tí mo ti mú Israẹli jáde wá láti Ejibiti títí di òní yìí. Èmi ń lọ láti àgọ́ dé àgọ́ àti láti ibùgbé dé ibùgbé.
Keiman Egypt gam a kon Israel te kahin pui doh nikho apat tunigei in ka insung a kacheng kha hih laiye, Hiti chun ponbuh a kisong houbuh munkhat a kon mun chom chom a kana ki chon le jin ahi.
6 Ni ibi gbogbo tí mo ti bá gbogbo Israẹli rìn dé, ǹjẹ́ mo wí nǹkan kan sí ọ̀kan nínú àwọn adarí Israẹli, tí èmí pàṣẹ fún láti máa jẹ́ olùṣọ́-àgùntàn àwọn ènìyàn mi, wí pé, “Kí ní ṣe tí ẹ̀yin kò fi kọ́ ilé tí a fi igi kedari kọ́ fún mi?”’
Keiman Israel mite toh kilhon khom ding le kamite kelngoi ching a pang lamkai ho kom a jong Cedar thing a kisa in eisah pih diu in jong kana sei kha hyh e.
7 “Nígbà náà, sọ fún ìránṣẹ́ mi Dafidi pé, ‘Èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí: Èmi mú ọ kúrò ní pápá oko tútù wá, àní kúrò lẹ́yìn agbo àgùntàn, kí ìwọ kí ó lè máa ṣe olórí àwọn ènìyàn mi Israẹli.
Tun nangma chen lang kalhachapa David kom a hitin gasei tan, “Van Pakai thanei chungnung in hitin aphong doh e, keiman nangma hi hamhing lah a kelngoi ching a napan na’a kon kapuidoh a kami Israel te chung a lamkai dia kapan sah ding nahi, ati.
8 Èmi ti wà pẹ̀lú rẹ ní, ibikíbi tí ìwọ bá lọ, èmí sì ti gé gbogbo àwọn ọ̀tá rẹ kúrò níwájú rẹ. Nísinsin yìí Èmi yóò mú kí orúkọ rẹ kí ó dàbí orúkọ àwọn ènìyàn ńlá jùlọ tí ó wà ní ayé.
Chule keiman nangma nache namun jousea kalhonpi jing a, nangma masang a namelmate jouse jong kasuh gam jeng ding leiset chung a mi minthang ho bang a namin kakithan sah ding ahi.
9 Èmi yóò sì pèsè ààyè kan fún àwọn ènìyàn mi Israẹli, kí wọn kí ó lè ní ilé tiwọn, kí a má sì ṣe dààmú wọn mọ́. Àwọn ènìyàn búburú kì yóò ni wọ́n lára mọ́, gẹ́gẹ́ bí wọ́n ti ṣe ní ìbẹ̀rẹ̀.
Chule kamite Israel te ding a achen nadiu munjong kapeh ding dettah a lungmongsel a cheng uva koiman jong asuh ling thei loudiu ahi. Namdang ten jong masang a banga asuh mang kit loudiu ahi.
10 Bí wọ́n sì ti ṣe láti ìgbà tí mo ti yan àwọn aṣáájú lórí àwọn ènìyàn mi Israẹli. Èmi pẹ̀lú yóò ṣẹ́gun gbogbo àwọn ọ̀tá yín. “‘Èmi sọ fún yín pé Olúwa yóò kọ́ ilé kan fún yín,
Keiman aphat dungjui a kamite Israel te chung a Lamkai vaihom ding kapan sah jing ding chule namel mateu aboncha kasuh gam ding chuche kal a jong Pakai in naleng gam sung u phatthei aboh ding ahi.
11 nígbà ti ọjọ́ rẹ bá kọjá, tí ìwọ bá lọ láti lọ bá àwọn baba à rẹ, Èmi yóò gbé àwọn ọmọ rẹ sókè láti rọ́pò rẹ, ọ̀kan lára àwọn ọmọ tìrẹ, Èmi yóò sì fìdí ìjọba rẹ̀ kalẹ̀.
Nahinkho abei nung a napu napate kom a dia nache nungteng jong le keiman nadalhah nason nachilhah te lah a nachapate khat pen kadopsang ding ahi chule aleng gam jong lentah a kaphudoh peh ding ahi.
12 Òun ni ẹni tí yóò kọ́ ilé fún mi, èmi yóò sí fi ìdí ìtẹ́ rẹ̀ kalẹ̀ títí láé.
Amapa chun keima ding a houin khat eisah peh ding chule keiman alenggam laltouna chu aitih chan a kaphudet jing ding ahi.
13 Èmi yóò jẹ́ baba rẹ̀, Òun yóò sì jẹ́ ọmọ mi. Èmi kì yóò mú ìfẹ́ mi kúrò lọ́dọ̀ rẹ̀ láéláé gẹ́gẹ́ bí mo ṣe mú un kúrò lọ́dọ̀ àwọn aṣáájú rẹ̀.
Hiche mipa ding a chu keima hi apa kahi a ama chu kachapa hiding ahi. Nangma masang a mipa chung a kangailutna kana lahdoh bang a, ama chung a hi kanung lah doh lou ding ahi.
14 Èmi yóò gbé e ka orí ilé mi àti ìjọba mi títí láé; ìtẹ́ rẹ̀ ni a ó fi ìdí rẹ̀ múlẹ̀ títí láé.’”
Keiman ama kainsung a le kagamsung a leng a kapan sah ding chule alenggam laltou na chu atonsot geiya kaphudet pih a longlouva umjing ding ahi,” ati.
15 Natani ròyìn fún Dafidi gbogbo àwọn ọ̀rọ̀ ti ìfihàn yí.
Hiti chun Nathan ahung kile in Pakai in amusah thil hojouse chu David kom a ahung seipeh tan ahi.
16 Nígbà náà, ọba Dafidi wọlé lọ, ó sì jókòó níwájú Olúwa ó sì wí pé, “Ta ni èmi, Olúwa Ọlọ́run, àti ki ni ìdílé mi, tí ìwọ mú mi dé ibí?
Chuin David alut in Pakai angsung a atao vin hitin asei e, “O Pakai Pathen keima hi koi kahi a chule kainsung mite hi ipi hija hichan gei a neihin pui peh jing u ham?
17 Pẹ̀lú bí ẹni pé èyí kò tó lójú rẹ, Ọlọ́run, ìwọ ti sọ̀rọ̀ nípa ọjọ́ iwájú ilé ìránṣẹ́ rẹ. Ìwọ ti wò mí bí ẹni pé èmi ni ẹni gbígbéga jù láàrín àwọn ọkùnrin Olúwa Ọlọ́run.
Tun thil hicheng jouse kal val in jong O Pathen, nalhachapa keima khunung a insung thudol khanggui sotpi hunglhung ding jong neisei doh pih in ahi.
18 “Kí ni ohun tí Dafidi tún lè sọ nítorí ọlá tí o bù fún ìránṣẹ́ rẹ? Nítorí tí ìwọ mọ ìránṣẹ́ rẹ,
Hitabang a nalhachapa neijabol na hi nangma kom a ipi kasei be nahlai ding ham, nalhachapa keima itobang kahi la neihet soh kei ahitai.
19 Olúwa. Nítorí ti ìránṣẹ́ rẹ àti gẹ́gẹ́ bí àṣẹ rẹ, ìwọ ti ṣe ohun ńlá yìí àti láti fi gbogbo ìlérí ńlá yìí hàn.
Nalhachapa keima neigel khoh najal le nalungel lam tah bang in kachung a thil loupi tampi mite muthei jin nabol doh in ahi,
20 “Kò sí ẹnìkan bí rẹ Olúwa, kò sì sí Ọlọ́run kan àfi ìwọ, gẹ́gẹ́ bí à ti gbọ́ pẹ̀lú etí ara wa.
O Pakai, nang tabang koima dang aumpoi, nangma tabang Pathen dang jong kanei pouve,
21 Pẹ̀lú ta ni ó dàbí àwọn ènìyàn rẹ Israẹli—orílẹ̀-èdè kan ní ayé, tí Ọlọ́run jáde lọ láti ra àwọn ènìyàn kan padà fún ara rẹ̀, àti láti lè ṣe orúkọ fún ara à rẹ, àti láti ṣe ohun ńlá àti ọwọ́ ìyanu nípa lílé àwọn orílẹ̀-èdè kúrò níwájú àwọn ènìyàn rẹ̀, ẹni tí ó gbàlà láti Ejibiti?
Nami Israel nam mite tabang leisetna koidang um am? O Pathen, nangma tah in namite asoh chan nagam a kon in nana huhdoh jeh in namin akithang in ahi, nangman thil kidang tah nabol in namite masang a ding ho jong nana del jam in ahi.
22 Ìwọ ṣe àwọn ènìyàn rẹ Israẹli ní tìrẹ láéláé ìwọ Olúwa sì ti di Ọlọ́run wọn.
Nangman Israel mite chu nangma mite dih tah mong in nana lheng doh in Pakai nangma chu a Pathen u nahitan ahi,
23 “Nísinsin yìí, Olúwa, jẹ́ kí ìlérí tí ìwọ ti ṣe fún ìránṣẹ́ rẹ àti ilé rẹ̀ di fífi ìdí múlẹ̀ títí láé. Ṣe gẹ́gẹ́ bí o ti ṣe ìlérí.
O Pakai tunvang keima nalhacha kahitai, keima le ka insungmi chung chang thua nakitepna bang in bol jeng tan chule hiche kitepna hi aitih chan a ding hita hen.
24 Kí ó lè di fífi ìdí múlẹ̀ àti kí orúkọ rẹ di gbígbéga títí láé. Nígbà náà ni àwọn ọkùnrin yóò wí pé, ‘Olúwa àwọn ọmọ-ogun, ni Ọlọ́run Israẹli.’ Ilé ìránṣẹ́ rẹ Dafidi sì ni a ó fi ìdí rẹ̀ múlẹ̀ níwájú rẹ.
Nangma min kiphut doh henlang mijousen tonsot'in jana pecheh hen chule Pakai thanei chungnung pen Israel Pathen chu Israel Pathen ahi mong e tia kisei ding, nalhachapa David insung jeng jong nangma angsung a phudet a um ding ahi.
25 “Ìwọ, Ọlọ́run mi, ti fihan ìránṣẹ́ rẹ pé, ìwọ yóò kọ́ ilé fún un. Bẹ́ẹ̀ ni ìránṣẹ́ rẹ ti ní ìgboyà láti gbàdúrà sí ọ.
O ka Pathen keima hi nangma ang a ngamtah a hungtao a kahi, ajeh chu nalhachapa keima hi ka in ding neisah peh a lenggam khat neitundoh peh ding chu kicheh tah in neimu sah tai.
26 Olúwa, ìwọ ni Ọlọ́run. Ìwọ ti fi ìlérí dídára yìí fún ìránṣẹ́ rẹ.
O Pakai nangma bou Pathen nahi chule hitabang thilpha tampihi nalhachapa kei ding in kitepna nanei e.
27 Nísinsin yìí ó ti tẹ́ ọ lọ́rùn láti bùkún ilé ìránṣẹ́ rẹ kí ó lè tẹ̀síwájú ní ojú rẹ; nítorí ìwọ, Olúwa, ti bùkún un, a ó sì bùkún un títí láéláé.”
Tunjong nalhachapa insung phatthei naboh a hichu nalhachapa a ding a aitih gei a nangma masang a umjing ding ahi. Ajeh chu O Pakai nangma phathei boh chu ipi hijong le phattheiboh chang jing ding ahi.

< 1 Chronicles 17 >