< 1 Chronicles 16 >

1 Wọ́n gbé àpótí ẹ̀rí Ọlọ́run, wá sínú àgọ́ ti Dafidi ti pèsè fún un, wọ́n sì gbé ẹbọ sísun àti ọrẹ ìdàpọ̀ kalẹ̀ níwájú Ọlọ́run.
A gdy przynieśli arkę Boga i umieścili ją pośrodku namiotu wzniesionego przez Dawida, złożyli całopalenia i ofiary pojednawcze przed Bogiem.
2 Lẹ́yìn tí Dafidi parí ẹbọ sísun àti ọrẹ ìdàpọ̀, ó bùkún àwọn ènìyàn ní orúkọ Olúwa.
A gdy Dawid skończył składanie całopaleń i ofiar pojednawczych, błogosławił lud w imię PANA.
3 Nígbà náà ó fún olúkúlùkù ọkùnrin àti obìnrin ọmọ Israẹli ní ìṣù àkàrà kan, àkàrà dídùn ti àkókò kan àti àkàrà dídùn ti èso àjàrà kan.
I rozdał wszystkim Izraelitom, tak mężczyźnie, jak i kobiecie, po bochenku chleba i po kawałku mięsa oraz po bukłaku [wina].
4 Ó yan díẹ̀ lára àwọn ará Lefi láti máa jọ́sìn níwájú àpótí ẹ̀rí Olúwa, àti láti ṣe ìrántí àti dúpẹ́ àti láti yin Olúwa, Ọlọ́run Israẹli.
Ustanowił też niektórych Lewitów sługami przed arką PANA, aby wspominali i chwalili [go], i dziękowali PANU, Bogu Izraela:
5 Asafu ni olóyè, àtẹ̀lé rẹ ni Sekariah, Jehieli, Ṣemiramotu, Asieli, Mattitiah, Eliabu, Benaiah, Obedi-Edomu àti Jeieli, àwọn ni yóò lu ohun èlò orin olókùn àti dùùrù haapu. Asafu ni yóò lu símbálì kíkan.
Asafa, naczelnika, a po nim Zachariasza, Jejela, Szemiramota, Jechiela, Mattitiasza, Eliaba, Benajasza i Obed-Edoma: Jejela [do gry] na instrumentach: cytrach i harfach, a Asafa – na cymbałach;
6 Àti Benaiah àti Jahasieli àwọn àlùfáà ni yóò fọn ìpè nígbà gbogbo níwájú àpótí ẹ̀rí májẹ̀mú ti Ọlọ́run.
A kapłanów Benajasza i Jachaziela, aby [stali] nieustannie z trąbami przed arką przymierza Boga.
7 Ní ọjọ́ náà Dafidi kọ́kọ́ fi lé Asafu àti àwọn ẹlẹgbẹ́ rẹ̀ lọ́wọ́ orin Dafidi ti ọpẹ́ sí Olúwa.
Wtedy w tym dniu Dawid postanowił po raz pierwszy, aby Asaf i jego bracia chwalili PANA [tym psalmem]:
8 Ẹ fi ọpẹ́ fún Olúwa, ẹ pe orúkọ rẹ̀, ẹ fi iṣẹ́ rẹ̀ hàn nínú àwọn ènìyàn fún ohun tí ó ṣe
Wysławiajcie PANA, wzywajcie jego imienia, opowiadajcie między narodami sprawy jego.
9 Ẹ kọrin sí i, ẹ kọrin ìyìn, sí i, ẹ sọ ti gbogbo iṣẹ́ ìyanu rẹ̀.
Śpiewajcie mu, śpiewajcie mu psalmy, rozmawiajcie o wszystkich jego cudach.
10 Ìyìn nínú orúkọ rẹ̀ mímọ́; jẹ kí ọkàn àwọn tí ó yin Olúwa kí ó yọ̀.
Chlubcie się jego świętym imieniem, niech się raduje serce szukających PANA.
11 Ẹ wá Olúwa àti agbára rẹ̀; e wá ojú rẹ̀ nígbà gbogbo.
Szukajcie PANA i jego mocy, szukajcie zawsze jego oblicza.
12 Rántí àwọn ìyanu tí Ó ti ṣe, iṣẹ́ ìyanu rẹ̀ àti ìdájọ́ tí Ó ti sọ.
Przypominajcie sobie dzieła, które czynił, jego cuda i wyroki jego ust.
13 A! ẹ̀yin ìran ọmọ Israẹli ìránṣẹ́ rẹ̀, àwọn ọmọ Jakọbu, ẹ̀yin tí ó ti yàn.
Wy, potomkowie Izraela, jego sługi; wy, synowie Jakuba, jego wybrańcy!
14 Òun ni Olúwa Ọlọ́run wa; ìdájọ́ rẹ̀ wà ní gbogbo ayé.
On [jest] PANEM, naszym Bogiem, jego sądy na całej ziemi.
15 Ó rántí májẹ̀mú rẹ̀ láéláé, ọ̀rọ̀ tí ó pàṣẹ, fún ẹgbẹẹgbẹ̀rún ìran,
Pamiętajcie zawsze o jego przymierzu, o słowie, które nakazał po tysiąc pokoleń;
16 májẹ̀mú tí ó dá pẹ̀lú Abrahamu, ìbúra tí ó ṣe pẹ̀lú fún Isaaki.
[O przymierzu], które zawarł z Abrahamem, i o przysiędze złożonej Izaakowi.
17 Ó ṣe ìdánilójú u rẹ̀ fún Jakọbu, gẹ́gẹ́ bí àṣẹ sí Israẹli, gẹ́gẹ́ bi májẹ̀mú ayérayé:
Ustanowił je jako prawo dla Jakuba, jako wieczne przymierze dla Izraela;
18 “Sí ọ, ni èmi yóò fún ní ilẹ̀ Kenaani. Gẹ́gẹ́ bí ààyè tí ìwọ yóò jogún.”
Mówiąc: Tobie dam ziemię Kanaan jako dział waszego dziedzictwa;
19 Nígbà tí wọn kéré ní iye, wọ́n kéré gidigidi, wọ́n sì jẹ́ àlejò níbẹ̀,
Kiedy było was niewielu, [byliście] nieliczni i obcy w niej.
20 wọ́n rìn kiri láti orílẹ̀-èdè sí orílẹ̀-èdè láti ìjọba kan sí èkejì.
I wędrowali od narodu do narodu, z jednego królestwa do innego ludu;
21 Kò gba ọkùnrin kankan láyè láti pọ́n wọn lójú; nítorí tiwọn, ó bá àwọn ọba wí.
Nikomu nie pozwolił ich krzywdzić, nawet karcił królów z ich powodu, [mówiąc];
22 “Má ṣe fọwọ́ kan àwọn ẹni àmì òróró mi; má ṣe pa àwọn wòlíì mi lára.”
Nie dotykajcie moich pomazańców, a moim prorokom nie czyńcie [nic] złego.
23 Kọrin sí Olúwa gbogbo ayé; ẹ máa fi ìgbàlà rẹ̀ hàn láti ọjọ́ dé ọjọ́.
Śpiewaj PANU, cała ziemio, opowiadajcie dzień po dniu o jego zbawieniu.
24 Kéde ògo à rẹ̀ láàrín àwọn orílẹ̀-èdè, ohun ìyàlẹ́nu tí ó ṣe láàrín gbogbo ènìyàn.
Głoście wśród narodów jego chwałę, pośród wszystkich ludów – jego cudowne dzieła;
25 Nítorí títóbi ni Olúwa òun sì ni ìyìn yẹ jùlọ; òun ni kí a bẹ̀rù ju gbogbo àwọn Ọlọ́run lọ.
Wielki bowiem [jest] PAN i godny wszelkiej chwały, straszliwszy nad wszystkich bogów;
26 Nítorí gbogbo àwọn ọlọ́run orílẹ̀-èdè jẹ́ àwọn òrìṣà, ṣùgbọ́n Olúwa dá àwọn ọ̀run.
Gdyż wszyscy bogowie narodów [są] bożkami, a PAN uczynił niebiosa.
27 Dídán àti ọláńlá ni ó wà níwájú rẹ̀; agbára àti ayọ̀ ni ó wà ní ibi ibùgbé rẹ̀.
Chwała i cześć przed nim, moc i radość w jego przybytku.
28 Fi fún Olúwa, ẹ̀yin ìdílé àwọn orílẹ̀-èdè, ẹ fi ògo àti ipá fún Olúwa.
Oddajcie PANU, rodziny narodów, oddajcie PANU chwałę i moc.
29 Fún Olúwa ní ìyìn nítorí orúkọ rẹ̀; gbé ọrẹ kí ẹ sì wá síwájú rẹ̀. Sìn Olúwa nínú inú dídùn ìwà mímọ́ rẹ̀.
Oddajcie PANU chwałę jego imienia. Przynoście dary i przychodźcie przed jego oblicze. Oddajcie PANU pokłon w ozdobie świętości.
30 Wárìrì níwájú rẹ̀, gbogbo ayé! Ayé sì fi ìdí múlẹ̀; a kò sì le è ṣí i.
Zadrżyj przed nim, cała ziemio. Świat będzie utwierdzony, aby się nie poruszył.
31 Jẹ́ kí àwọn ọ̀run kí ó yọ̀, jẹ́ kí ayé kí ó ṣe inú dídùn; lẹ́ kí wọn kí ó sọ láàrín àwọn orílẹ̀-èdè, pé “Olúwa jẹ ọba!”
Niech się weselą niebiosa i niech się raduje ziemia, niech mówią wśród narodów: PAN króluje!
32 Jẹ́ kí ọ̀run kí ó tún dún padà, àti gbogbo ohun tí ó wà nínú rẹ̀; Jẹ́ kí àwọn pápá kí ó hó fún ayọ̀, àti gbogbo ohun tí ó wà nínú rẹ̀!
Niech zaszumi morze i to, co je napełnia, niech radują się pola i wszystko, co [jest] na nich.
33 Nígbà náà ni igi igbó yóò kọrin, wọn yóò kọrin fún ayọ̀ níwájú Olúwa, nítorí tí ó wá láti ṣèdájọ́ ayé.
Wtedy radośnie wykrzykną leśne drzewa przed PANEM, bo idzie, aby sądzić ziemię.
34 Fi ọpẹ́ fún Olúwa, nítorí tí ó dára; ìfẹ́ ẹ rẹ̀ dúró títí láé.
Wysławiajcie PANA, bo jest dobry, bo jego miłosierdzie [trwa] na wieki.
35 Ké lóhùn rara, “Gbà wá, Ọlọ́run olùgbàlà a wa; kó wa jọ kí o sì gbà wá kúrò lọ́wọ́ àwọn orílẹ̀-èdè, kí àwa kí ó lè fi ọpẹ́ fún orúkọ mímọ́ rẹ, kí àwa kí ó lè yọ̀ nínú ìyìn rẹ̀.”
I mówcie: Zbaw nas, BOŻE naszego zbawienia, i zgromadź nas, i wybaw nas od pogan, abyśmy wielbili twoje święte imię i chlubili się twoją chwałą.
36 Olùbùkún ni Olúwa, Ọlọ́run Israẹli, láé àti láéláé. Lẹ́yìn náà gbogbo àwọn ènìyàn wí pé, “Àmín,” wọ́n “Yin Olúwa.”
Błogosławiony PAN, Bóg Izraela, na wieki wieków. I cały lud powiedział: Amen i chwalił PANA.
37 Dafidi fi Asafu àti àwọn ẹlẹgbẹ́ rẹ̀ sílẹ̀ níwájú àpótí ẹ̀rí Olúwa láti jíṣẹ́ níbẹ̀ déédé, gẹ́gẹ́ bí ọjọ́ kọ̀ọ̀kan ṣe gbà.
I [Dawid] zostawił tam przed arką przymierza PANA Asafa i jego braci, aby nieustannie pełnili służbę przed arką, według potrzeby każdego dnia;
38 Ó fi Obedi-Edomu àti méjìdínláàádọ́rin ẹlẹgbẹ́ ẹ rẹ̀ láti ṣiṣẹ́ ìránṣẹ́ pẹ̀lú wọn. Obedi-Edomu mọ Jedutuni, àti Hosa pẹ̀lú jẹ́ olùtọ́jú ẹnu-ọ̀nà.
Także Obed-Edoma i ich braci, sześćdziesięciu ośmiu; a Obed-Edoma, syna Jedutuna, i Chosę [uczynił] odźwiernymi.
39 Dafidi fi Sadoku àlùfáà àti àwọn àlùfáà ẹlẹgbẹ́ rẹ̀ níwájú Àgọ́ Olúwa ní ibi gíga ní Gibeoni.
Kapłana Sadoka i jego braci kapłanów [pozostawił] przed przybytkiem PANA na wyżynie w Gibeonie;
40 Láti gbé pẹpẹ ẹbọ sísun déédé, àárọ̀ àti ìrọ̀lẹ́ ní ìbámu pẹ̀lú gbogbo ohun tí a kọ sínú òfin Olúwa, tí ó ti fún Israẹli.
Aby składali PANU nieustannie, rano i wieczorem, całopalenia na ołtarzu całopaleń, zgodnie ze wszystkim, co jest napisane w Prawie PANA, które nadał on Izraelowi;
41 Pẹ̀lú wọn ni Hemani àti Jedutuni àti ìyókù tí a mú àti yàn nípasẹ̀ orúkọ láti fi ọpẹ́ fún Olúwa, nítorí tí ìfẹ́ rẹ̀ dúró títí láéláé
A z nimi [pozostawił] Hemana i Jedutuna oraz resztę wybranych, imiennie wyznaczonych, aby chwalili PANA, bo jego miłosierdzie [trwa] na wieki.
42 Hemani àti Jedutuni ni wọ́n dúró fún fífọn ìpè àti Kimbali àti fún lílo ohun èlò yòókù fún orin Ọlọ́run. Àwọn ọmọ Jedutuni wà ní ipò dídúró ní ẹnu-ọ̀nà.
I u nich, u Hemana i Jedutuna, [pozostawił] trąby i cymbały dla grających na tych i na [innych] instrumentach muzycznych dla Boga. Synowie zaś Jedutuna [byli] odźwiernymi.
43 Nígbà náà gbogbo àwọn ènìyàn kúrò, olúkúlùkù sí ilé rẹ̀: Dafidi yípadà láti súre fún ìdílé rẹ̀.
Potem cały lud się rozszedł, każdy do swego domu. Dawid też wrócił, aby błogosławić swojemu domowi.

< 1 Chronicles 16 >