< 1 Chronicles 16 >

1 Wọ́n gbé àpótí ẹ̀rí Ọlọ́run, wá sínú àgọ́ ti Dafidi ti pèsè fún un, wọ́n sì gbé ẹbọ sísun àti ọrẹ ìdàpọ̀ kalẹ̀ níwájú Ọlọ́run.
PELA lakou i lawe mai ai i ka pahu o ke Akua, a hookau iho la ia ia iwaena konu o ka halelewa a Davida i kukulu ai nona: a mohai aku la lakou i na mohaikuni a me na mohai hoomalu imua o ke Akua.
2 Lẹ́yìn tí Dafidi parí ẹbọ sísun àti ọrẹ ìdàpọ̀, ó bùkún àwọn ènìyàn ní orúkọ Olúwa.
I ka wa i hoopau ai o Davida i ka mohai aku i na mohaikuni a me na mohaihoomalu, hoomaikai mai la ia i na kanaka ma ka inoa o Iehova.
3 Nígbà náà ó fún olúkúlùkù ọkùnrin àti obìnrin ọmọ Israẹli ní ìṣù àkàrà kan, àkàrà dídùn ti àkókò kan àti àkàrà dídùn ti èso àjàrà kan.
A haawi pakahi mai la ia i ka Iseraela a pau, i na kane a me na wahine, i kela mea i keia mea, i ka popoberena a me kauwahi ia, a me kekahi pai huawaina.
4 Ó yan díẹ̀ lára àwọn ará Lefi láti máa jọ́sìn níwájú àpótí ẹ̀rí Olúwa, àti láti ṣe ìrántí àti dúpẹ́ àti láti yin Olúwa, Ọlọ́run Israẹli.
A hoonoho iho la ia i kekahi poe o na Levi e lawelawe imua o ka pahu o Iehova e hoohiki, e hoomaikai, a e hoolea aku ia Iehova i ke Akua no ka Iseraela.
5 Asafu ni olóyè, àtẹ̀lé rẹ ni Sekariah, Jehieli, Ṣemiramotu, Asieli, Mattitiah, Eliabu, Benaiah, Obedi-Edomu àti Jeieli, àwọn ni yóò lu ohun èlò orin olókùn àti dùùrù haapu. Asafu ni yóò lu símbálì kíkan.
O Asapa ka luna, a malalo iho o Zekaria, o Ieiela, o Semiramota, o Iehiela, o Matitia, o Eliaba, o Benaia a o Obededoma: a o Ieiela me na pesaleteria a me na lira: aka, hookani ae la o Asapa me na kimebala:
6 Àti Benaiah àti Jahasieli àwọn àlùfáà ni yóò fọn ìpè nígbà gbogbo níwájú àpótí ẹ̀rí májẹ̀mú ti Ọlọ́run.
O Benaia hoi a o Iehaziela na kahuna, me na pu e mau ana imua o ka pahuberita o ke Akua.
7 Ní ọjọ́ náà Dafidi kọ́kọ́ fi lé Asafu àti àwọn ẹlẹgbẹ́ rẹ̀ lọ́wọ́ orin Dafidi ti ọpẹ́ sí Olúwa.
Ia la iho no, haawi mua mai la o Davida i ka mililani ia Iehova, maloko o ka lima o Asapa a o kona poe hoahanau.
8 Ẹ fi ọpẹ́ fún Olúwa, ẹ pe orúkọ rẹ̀, ẹ fi iṣẹ́ rẹ̀ hàn nínú àwọn ènìyàn fún ohun tí ó ṣe
E mililani aku ia Iehova, e kahea aku i kona inoa. E hoike aku i kana mau hana iwaena o kanaka.
9 Ẹ kọrin sí i, ẹ kọrin ìyìn, sí i, ẹ sọ ti gbogbo iṣẹ́ ìyanu rẹ̀.
E mele aku ia ia, e mele halelu aku ia ia, E kamailio oukou i na hana kupanaha ana a pau.
10 Ìyìn nínú orúkọ rẹ̀ mímọ́; jẹ kí ọkàn àwọn tí ó yin Olúwa kí ó yọ̀.
E kaena oukou no kona inoa hoano: E olioli ka naau o ka poe imi aku ia Iehova.
11 Ẹ wá Olúwa àti agbára rẹ̀; e wá ojú rẹ̀ nígbà gbogbo.
E imi aku oukou ia Iehova a me kona ikaika, E imi mau aku i kona maka.
12 Rántí àwọn ìyanu tí Ó ti ṣe, iṣẹ́ ìyanu rẹ̀ àti ìdájọ́ tí Ó ti sọ.
E hoomanao i na hana mana ana i hana'i, I na mea kupanaha ana, a me na olelo hoopono a kona waha;
13 A! ẹ̀yin ìran ọmọ Israẹli ìránṣẹ́ rẹ̀, àwọn ọmọ Jakọbu, ẹ̀yin tí ó ti yàn.
E na hua a Iseraela a kana kauwa, Na mamo hoi a Iakoba, o kona poe i waeia.
14 Òun ni Olúwa Ọlọ́run wa; ìdájọ́ rẹ̀ wà ní gbogbo ayé.
Oia o Iehova ko kakou Akua; Aia ma ka honua a pau kana mau olelo hoopono.
15 Ó rántí májẹ̀mú rẹ̀ láéláé, ọ̀rọ̀ tí ó pàṣẹ, fún ẹgbẹẹgbẹ̀rún ìran,
E malama mau oukou i kana berita, I ka olelo ana i kauoha mai ai i na hanauna he tausani;
16 májẹ̀mú tí ó dá pẹ̀lú Abrahamu, ìbúra tí ó ṣe pẹ̀lú fún Isaaki.
Ana i hana'i me Aberahama, A me kana hoohiki ana ia Isaaka:
17 Ó ṣe ìdánilójú u rẹ̀ fún Jakọbu, gẹ́gẹ́ bí àṣẹ sí Israẹli, gẹ́gẹ́ bi májẹ̀mú ayérayé:
Ua hookupaa oia ia mea hookahi i kanawai ia Iakoba, A i berita mau loa ia Iseraela,
18 “Sí ọ, ni èmi yóò fún ní ilẹ̀ Kenaani. Gẹ́gẹ́ bí ààyè tí ìwọ yóò jogún.”
E i mai ana, No oukou e haawi aku ai au i ka aina o Kanaana, I kuleana no ko oukou noho hooilina ana;
19 Nígbà tí wọn kéré ní iye, wọ́n kéré gidigidi, wọ́n sì jẹ́ àlejò níbẹ̀,
I ko oukou manawa i uuku ai, He uuku nae, a he poe malihini ilaila.
20 wọ́n rìn kiri láti orílẹ̀-èdè sí orílẹ̀-èdè láti ìjọba kan sí èkejì.
I ka manawa i hele ai lakou mai kekahi lahuikanaka a kekahi lahuikanaka, A mai kahi aupuni a hiki i kela aupuni;
21 Kò gba ọkùnrin kankan láyè láti pọ́n wọn lójú; nítorí tiwọn, ó bá àwọn ọba wí.
Aole ia i ae mai i kekahi kanaka e hana ino mai ia lakou, Oiaio no, ao mai la oia i na'lii no lakou,
22 “Má ṣe fọwọ́ kan àwọn ẹni àmì òróró mi; má ṣe pa àwọn wòlíì mi lára.”
Mai hoopa aku i kuu poe i poniia, Mai hoino hoi i kuu mau kaula.
23 Kọrin sí Olúwa gbogbo ayé; ẹ máa fi ìgbàlà rẹ̀ hàn láti ọjọ́ dé ọjọ́.
E mele aku ia Iehova, e ko ka honua a pau; E hoike aku i kona ola, ia la aku ia la aku.
24 Kéde ògo à rẹ̀ láàrín àwọn orílẹ̀-èdè, ohun ìyàlẹ́nu tí ó ṣe láàrín gbogbo ènìyàn.
E hai aku i kona nani i na lahuikanaka, I kana mau hana kupanaha i ko na aina a pau.
25 Nítorí títóbi ni Olúwa òun sì ni ìyìn yẹ jùlọ; òun ni kí a bẹ̀rù ju gbogbo àwọn Ọlọ́run lọ.
No ka mea, he nui no o Iehova, a e hoomaikai nui ia: E weliweliia hoi oia maluna o na akua a pau.
26 Nítorí gbogbo àwọn ọlọ́run orílẹ̀-èdè jẹ́ àwọn òrìṣà, ṣùgbọ́n Olúwa dá àwọn ọ̀run.
No ka mea, o na akua a pau o na kanaka, he poe kii lakou: Aka, na Iehova i hana na lani.
27 Dídán àti ọláńlá ni ó wà níwájú rẹ̀; agbára àti ayọ̀ ni ó wà ní ibi ibùgbé rẹ̀.
Ma kona alo ka nani a me ka mahalo; Ma kona wahi hoi ka ikaika a me ka olioli.
28 Fi fún Olúwa, ẹ̀yin ìdílé àwọn orílẹ̀-èdè, ẹ fi ògo àti ipá fún Olúwa.
E haawi aku no Iehova, e na hanauna kanaka, E haawi aku no Iehova i ka nani a me ka mana.
29 Fún Olúwa ní ìyìn nítorí orúkọ rẹ̀; gbé ọrẹ kí ẹ sì wá síwájú rẹ̀. Sìn Olúwa nínú inú dídùn ìwà mímọ́ rẹ̀.
E haawi aku ia Iehova i ka nani no kona inoa: E ho mai i ka mohai, a e hele mai imua ona: E hoomana ia Iehova ma ka nani o ka hemolele.
30 Wárìrì níwájú rẹ̀, gbogbo ayé! Ayé sì fi ìdí múlẹ̀; a kò sì le è ṣí i.
E weliweli imua ona, e ko ka honua a pau: E ku paa auanei hoi ke ao nei, i hoouaue ole ia'i.
31 Jẹ́ kí àwọn ọ̀run kí ó yọ̀, jẹ́ kí ayé kí ó ṣe inú dídùn; lẹ́ kí wọn kí ó sọ láàrín àwọn orílẹ̀-èdè, pé “Olúwa jẹ ọba!”
E hauoli ko na lani, e olioli ko ka honua: E oleloia hoi iwaena o na lahuikanaka, O Iehova e alii ana.
32 Jẹ́ kí ọ̀run kí ó tún dún padà, àti gbogbo ohun tí ó wà nínú rẹ̀; Jẹ́ kí àwọn pápá kí ó hó fún ayọ̀, àti gbogbo ohun tí ó wà nínú rẹ̀!
E halulu mai ke kai, a me na mea i piha ai: E olioli na mahinaai me na mea a pau oloko.
33 Nígbà náà ni igi igbó yóò kọrin, wọn yóò kọrin fún ayọ̀ níwájú Olúwa, nítorí tí ó wá láti ṣèdájọ́ ayé.
Alaila e kani aku ai na laau o ka nahele, I ka hiki ana mai o Iehova; No ka mea, ke hele mai la ia e hooponopono i ko ka honua.
34 Fi ọpẹ́ fún Olúwa, nítorí tí ó dára; ìfẹ́ ẹ rẹ̀ dúró títí láé.
E mililani aku ia Iehova, no ka mea, he maikai kona; A he mau loa kona aloha.
35 Ké lóhùn rara, “Gbà wá, Ọlọ́run olùgbàlà a wa; kó wa jọ kí o sì gbà wá kúrò lọ́wọ́ àwọn orílẹ̀-èdè, kí àwa kí ó lè fi ọpẹ́ fún orúkọ mímọ́ rẹ, kí àwa kí ó lè yọ̀ nínú ìyìn rẹ̀.”
E i aku hoi oukou, E hoola mai ia makou, E ke Akua nona ko kakou ola, E houluulu ia makou, a e hoopakele ia makou i ko na aina e, I aloha aku ai makou i kou inoa hoano, A e kaena aku ai i kou maikai.
36 Olùbùkún ni Olúwa, Ọlọ́run Israẹli, láé àti láéláé. Lẹ́yìn náà gbogbo àwọn ènìyàn wí pé, “Àmín,” wọ́n “Yin Olúwa.”
E hoomaikaiia ke Akua o ka Iseraela, a mau loa a mau loa aku. Olelo aku la na kanaka a pan, Amene, a hoomaikai aku la lakou ia Iehova.
37 Dafidi fi Asafu àti àwọn ẹlẹgbẹ́ rẹ̀ sílẹ̀ níwájú àpótí ẹ̀rí Olúwa láti jíṣẹ́ níbẹ̀ déédé, gẹ́gẹ́ bí ọjọ́ kọ̀ọ̀kan ṣe gbà.
A hoonoho aku la oia imua o ka pahuberita o Iehova ia Asapa a me kona poe hoahanau, e lawelawe mau imua o ka pahu, e like me ka mea pono e hanaia'i i kela la i keia la:
38 Ó fi Obedi-Edomu àti méjìdínláàádọ́rin ẹlẹgbẹ́ ẹ rẹ̀ láti ṣiṣẹ́ ìránṣẹ́ pẹ̀lú wọn. Obedi-Edomu mọ Jedutuni, àti Hosa pẹ̀lú jẹ́ olùtọ́jú ẹnu-ọ̀nà.
A me Obededoma, me ko lakou poe hoahanau, he kanaonokumamawalu; o Obededoma hoi he keiki a Iedutuna a o Hosa na kiaipuka:
39 Dafidi fi Sadoku àlùfáà àti àwọn àlùfáà ẹlẹgbẹ́ rẹ̀ níwájú Àgọ́ Olúwa ní ibi gíga ní Gibeoni.
A o Zadoka ke kahuna, a me kona poe hoahanau na kahuna, imua o ka halelewa o Iehova, ma ka wahi kiekie, aia ma Gibeona,
40 Láti gbé pẹpẹ ẹbọ sísun déédé, àárọ̀ àti ìrọ̀lẹ́ ní ìbámu pẹ̀lú gbogbo ohun tí a kọ sínú òfin Olúwa, tí ó ti fún Israẹli.
E mohai mau aku ai i na mohaikuni ia Iehova maluna o ke kuahu, i kakahiaka, a i ke ahiahi, e like me ka mea a pau i kakauia ma ke kanawai o Iehova, ana i kauoha mai ai i ka Iseraela:
41 Pẹ̀lú wọn ni Hemani àti Jedutuni àti ìyókù tí a mú àti yàn nípasẹ̀ orúkọ láti fi ọpẹ́ fún Olúwa, nítorí tí ìfẹ́ rẹ̀ dúró títí láéláé
Me lakou pu o Hemana, o Iedutuna, a o na mea i waeia e koe, o ka poe i kaheaia ma ka inoa, no ka mililani aku ia Iehova, no ka mea, he mau loa kona aloha:
42 Hemani àti Jedutuni ni wọ́n dúró fún fífọn ìpè àti Kimbali àti fún lílo ohun èlò yòókù fún orin Ọlọ́run. Àwọn ọmọ Jedutuni wà ní ipò dídúró ní ẹnu-ọ̀nà.
A me lakou pu o Hemana a o Iedutuna, me na pu kani a me na kimebala, no ka poe e pono ke hookani, me na mea kani a ke Akua A o na keikikane a Iedutuna na kiaipuka.
43 Nígbà náà gbogbo àwọn ènìyàn kúrò, olúkúlùkù sí ilé rẹ̀: Dafidi yípadà láti súre fún ìdílé rẹ̀.
A hele aku la na kanaka a pau o kela kanaka keia kanaka i kona hale iho: a hoi hou aku la o Davida e hoomaikai i ko ka hale ona.

< 1 Chronicles 16 >