< 1 Chronicles 16 >

1 Wọ́n gbé àpótí ẹ̀rí Ọlọ́run, wá sínú àgọ́ ti Dafidi ti pèsè fún un, wọ́n sì gbé ẹbọ sísun àti ọrẹ ìdàpọ̀ kalẹ̀ níwájú Ọlọ́run.
Alawii makĩrehe ithandũkũ rĩa Ngai, makĩrĩtoonyia thĩinĩ wa hema ĩrĩa yaambĩtwo nĩ Daudi nĩ ũndũ warĩo, na makĩrutĩra Ngai maruta ma njino na maruta ma ũiguano.
2 Lẹ́yìn tí Dafidi parí ẹbọ sísun àti ọrẹ ìdàpọ̀, ó bùkún àwọn ènìyàn ní orúkọ Olúwa.
Daudi aarĩkia kũruta maruta ma njino na maruta ma ũiguano-rĩ, akĩrathima andũ acio thĩinĩ wa rĩĩtwa rĩa Jehova.
3 Nígbà náà ó fún olúkúlùkù ọkùnrin àti obìnrin ọmọ Israẹli ní ìṣù àkàrà kan, àkàrà dídùn ti àkókò kan àti àkàrà dídùn ti èso àjàrà kan.
Ningĩ akĩhe andũ a Isiraeli othe, arũme na andũ-a-nja o mũndũ mũgate, na gĩcunjĩ kĩa nyama, na ngũmba ya thabibũ nyũmũ.
4 Ó yan díẹ̀ lára àwọn ará Lefi láti máa jọ́sìn níwájú àpótí ẹ̀rí Olúwa, àti láti ṣe ìrántí àti dúpẹ́ àti láti yin Olúwa, Ọlọ́run Israẹli.
Nĩathuurire Alawii amwe matungatage mbere ya ithandũkũ rĩa Jehova, na mathaithanagĩre andũ, na macookagie ngaatho, na magoocage Jehova, Ngai wa Isiraeli, nao nĩo:
5 Asafu ni olóyè, àtẹ̀lé rẹ ni Sekariah, Jehieli, Ṣemiramotu, Asieli, Mattitiah, Eliabu, Benaiah, Obedi-Edomu àti Jeieli, àwọn ni yóò lu ohun èlò orin olókùn àti dùùrù haapu. Asafu ni yóò lu símbálì kíkan.
Asafu ũrĩa warĩ mũnene wao, na mũnini wake aarĩ Zekaria, agacookwo nĩ Jeieli, na Shemiramothu, na Jehieli, na Matithia, na Eliabu, na Benaia, na Obedi-Edomu, na Jeieli. Acio maarĩ a kũhũũraga inanda cia kĩnũbi na inanda cia mũgeeto, nake Asafu agambagie thaani iria ihũũrithanagio ikagamba,
6 Àti Benaiah àti Jahasieli àwọn àlùfáà ni yóò fọn ìpè nígbà gbogbo níwájú àpótí ẹ̀rí májẹ̀mú ti Ọlọ́run.
nao athĩnjĩri-Ngai, Benaia na Jahazieli, maarĩ a kũhuha tũrumbeta hĩndĩ ciothe marĩ mbere ya ithandũkũ rĩa kĩrĩkanĩro kĩa Ngai.
7 Ní ọjọ́ náà Dafidi kọ́kọ́ fi lé Asafu àti àwọn ẹlẹgbẹ́ rẹ̀ lọ́wọ́ orin Dafidi ti ọpẹ́ sí Olúwa.
Mũthenya ũcio ũndũ wa mbere, ũrĩa Daudi eekire nĩ kũnengera Asafu na athiritũ ake thaburi ĩno ya gũcookeria Jehova ngaatho:
8 Ẹ fi ọpẹ́ fún Olúwa, ẹ pe orúkọ rẹ̀, ẹ fi iṣẹ́ rẹ̀ hàn nínú àwọn ènìyàn fún ohun tí ó ṣe
Cookeriai Jehova ngaatho, kaĩrai rĩĩtwa rĩake; menyithaniai ndũrĩrĩ-inĩ ũrĩa ekĩte.
9 Ẹ kọrin sí i, ẹ kọrin ìyìn, sí i, ẹ sọ ti gbogbo iṣẹ́ ìyanu rẹ̀.
Mũinĩrei, mũmũinĩre mũkĩmũgoocaga, mũheane ũhoro wa ciĩko ciake ciothe cia magegania.
10 Ìyìn nínú orúkọ rẹ̀ mímọ́; jẹ kí ọkàn àwọn tí ó yin Olúwa kí ó yọ̀.
Mwĩrahei nĩ ũndũ wa rĩĩtwa rĩake itheru; ngoro cia arĩa marongoragia Jehova nĩ ikene.
11 Ẹ wá Olúwa àti agbára rẹ̀; e wá ojú rẹ̀ nígbà gbogbo.
Mathaai Jehova o na hinya wake; mũmaathage ũthiũ wake hĩndĩ ciothe.
12 Rántí àwọn ìyanu tí Ó ti ṣe, iṣẹ́ ìyanu rẹ̀ àti ìdájọ́ tí Ó ti sọ.
Ririkanai magegania marĩa ekĩte, na ciama ciake, na matuĩro ma ciira marĩa atuĩte,
13 A! ẹ̀yin ìran ọmọ Israẹli ìránṣẹ́ rẹ̀, àwọn ọmọ Jakọbu, ẹ̀yin tí ó ti yàn.
inyuĩ njiaro cia Isiraeli ndungata yake, o inyuĩ ciana cia Jakubu, inyuĩ andũ ake arĩa athuurĩte.
14 Òun ni Olúwa Ọlọ́run wa; ìdájọ́ rẹ̀ wà ní gbogbo ayé.
Jehova nĩwe Ngai witũ; matuĩro make ma ciira marĩ thĩ yothe.
15 Ó rántí májẹ̀mú rẹ̀ láéláé, ọ̀rọ̀ tí ó pàṣẹ, fún ẹgbẹẹgbẹ̀rún ìran,
Nĩaririkanaga kĩrĩkanĩro gĩake nginya tene, nĩkĩo kiugo kĩrĩa aathanire, kĩrũmagĩrĩrwo nĩ njiarwa ngiri,
16 májẹ̀mú tí ó dá pẹ̀lú Abrahamu, ìbúra tí ó ṣe pẹ̀lú fún Isaaki.
kĩrĩkanĩro kĩrĩa aarĩkanĩire na Iburahĩmu, na noguo mwĩhĩtwa ũrĩa eehĩtire harĩ Isaaka.
17 Ó ṣe ìdánilójú u rẹ̀ fún Jakọbu, gẹ́gẹ́ bí àṣẹ sí Israẹli, gẹ́gẹ́ bi májẹ̀mú ayérayé:
Nĩagĩĩkĩrire hinya harĩ Jakubu kĩrĩ kĩrĩra gĩake kĩa watho wa kũrũmagĩrĩrwo, agĩgĩĩkĩra hinya kũrĩ Isiraeli kĩrĩ kĩrĩkanĩro gĩa gũtũũra tene na tene, akiuga atĩrĩ:
18 “Sí ọ, ni èmi yóò fún ní ilẹ̀ Kenaani. Gẹ́gẹ́ bí ààyè tí ìwọ yóò jogún.”
“Wee nĩwe ngaahe bũrũri wa Kaanani, ũtuĩke igai rĩrĩa ũkaagaya.”
19 Nígbà tí wọn kéré ní iye, wọ́n kéré gidigidi, wọ́n sì jẹ́ àlejò níbẹ̀,
Hĩndĩ ĩrĩa maarĩ o anini magĩtarwo, o anini biũ, na maarĩ ageni kuo-rĩ,
20 wọ́n rìn kiri láti orílẹ̀-èdè sí orílẹ̀-èdè láti ìjọba kan sí èkejì.
moorũũraga kuuma rũrĩrĩ rũmwe nginya rũrĩa rũngĩ, na kuuma ũthamaki-inĩ ũmwe nginya ũrĩa ũngĩ.
21 Kò gba ọkùnrin kankan láyè láti pọ́n wọn lójú; nítorí tiwọn, ó bá àwọn ọba wí.
Ndarĩ mũndũ o na ũmwe etĩkĩririe amanyariire; nĩarũithirie athamaki nĩ ũndũ wao, akĩmeera atĩrĩ:
22 “Má ṣe fọwọ́ kan àwọn ẹni àmì òróró mi; má ṣe pa àwọn wòlíì mi lára.”
“Mũtikanahutie andũ arĩa akwa aitĩrĩrie maguta; mũtikaneke anabii akwa ũũru.”
23 Kọrin sí Olúwa gbogbo ayé; ẹ máa fi ìgbàlà rẹ̀ hàn láti ọjọ́ dé ọjọ́.
Inĩrai Jehova, inyuĩ andũ a thĩ yothe; mũhunjagie ũhonokio wake mũthenya o mũthenya.
24 Kéde ògo à rẹ̀ láàrín àwọn orílẹ̀-èdè, ohun ìyàlẹ́nu tí ó ṣe láàrín gbogbo ènìyàn.
Umbũrai riiri wake kũrĩ ndũrĩrĩ, mumbũre mawĩko make ma magegania kũrĩ andũ othe.
25 Nítorí títóbi ni Olúwa òun sì ni ìyìn yẹ jùlọ; òun ni kí a bẹ̀rù ju gbogbo àwọn Ọlọ́run lọ.
Nĩgũkorwo Jehova nĩ mũnene, na nĩ wa kũgoocwo mũno; nĩwe wa gwĩtigĩrwo gũkĩra ngai ciothe.
26 Nítorí gbogbo àwọn ọlọ́run orílẹ̀-èdè jẹ́ àwọn òrìṣà, ṣùgbọ́n Olúwa dá àwọn ọ̀run.
Nĩgũkorwo ngai ciothe cia ndũrĩrĩ nĩ mĩhianano, no Jehova nĩwe wombire igũrũ.
27 Dídán àti ọláńlá ni ó wà níwájú rẹ̀; agbára àti ayọ̀ ni ó wà ní ibi ibùgbé rẹ̀.
Riiri na ũnene irĩ mbere yake; hinya na gĩkeno itũũraga gwake.
28 Fi fún Olúwa, ẹ̀yin ìdílé àwọn orílẹ̀-èdè, ẹ fi ògo àti ipá fún Olúwa.
Tũũgĩriai Jehova, inyuĩ mĩhĩrĩga ya ndũrĩrĩ, mũtũũgĩrie Jehova nĩ ũndũ wa riiri na hinya wake,
29 Fún Olúwa ní ìyìn nítorí orúkọ rẹ̀; gbé ọrẹ kí ẹ sì wá síwájú rẹ̀. Sìn Olúwa nínú inú dídùn ìwà mímọ́ rẹ̀.
Tũũgĩriai Jehova, nĩ ũndũ wa riiri ũrĩa wagĩrĩire rĩĩtwa rĩake. Mũreherei maruta na mũũke mbere yake; mũhooe Jehova thĩinĩ wa riiri wa ũtheru wake.
30 Wárìrì níwájú rẹ̀, gbogbo ayé! Ayé sì fi ìdí múlẹ̀; a kò sì le è ṣí i.
Inainai mũrĩ mbere yake, inyuĩ andũ a thĩ yothe! Thĩ ĩhaandĩtwo ĩkarũma; ndĩngĩenyenyeka.
31 Jẹ́ kí àwọn ọ̀run kí ó yọ̀, jẹ́ kí ayé kí ó ṣe inú dídùn; lẹ́ kí wọn kí ó sọ láàrín àwọn orílẹ̀-èdè, pé “Olúwa jẹ ọba!”
Igũrũ nĩ rĩkene, thĩ nĩĩcanjamũke; nakuo ndũrĩrĩ-inĩ nĩ kuugwo atĩrĩ, “Jehova nĩwe ũthamakaga!”
32 Jẹ́ kí ọ̀run kí ó tún dún padà, àti gbogbo ohun tí ó wà nínú rẹ̀; Jẹ́ kí àwọn pápá kí ó hó fún ayọ̀, àti gbogbo ohun tí ó wà nínú rẹ̀!
Iria nĩ rĩrurume, na indo iria ciothe irĩ thĩinĩ warĩo; mĩgũnda nĩĩkenerũrũke na indo iria ciothe irĩ thĩinĩ wayo!
33 Nígbà náà ni igi igbó yóò kọrin, wọn yóò kọrin fún ayọ̀ níwájú Olúwa, nítorí tí ó wá láti ṣèdájọ́ ayé.
Hĩndĩ ĩyo mĩtĩ ya mĩtitũ nĩĩkaina; ĩine nĩ gũkena ĩrĩ mbere ya Jehova, nĩgũkorwo nĩarooka gũciirithia thĩ.
34 Fi ọpẹ́ fún Olúwa, nítorí tí ó dára; ìfẹ́ ẹ rẹ̀ dúró títí láé.
Cookeriai Jehova ngaatho, nĩgũkorwo nĩ mwega; wendo wake ũtũũraga nginya tene.
35 Ké lóhùn rara, “Gbà wá, Ọlọ́run olùgbàlà a wa; kó wa jọ kí o sì gbà wá kúrò lọ́wọ́ àwọn orílẹ̀-èdè, kí àwa kí ó lè fi ọpẹ́ fún orúkọ mímọ́ rẹ, kí àwa kí ó lè yọ̀ nínú ìyìn rẹ̀.”
Anĩrĩrai muuge atĩrĩ, “Tũhonokie, Wee Ngai Mũhonokia witũ; tũcookanĩrĩrie na ũtũkũũre kuuma kũrĩ ndũrĩrĩ, nĩguo tũcookagĩrie rĩĩtwa rĩaku itheru ngaatho, nĩgeetha twĩrahage nĩ ũndũ wa ũgooci waku.”
36 Olùbùkún ni Olúwa, Ọlọ́run Israẹli, láé àti láéláé. Lẹ́yìn náà gbogbo àwọn ènìyàn wí pé, “Àmín,” wọ́n “Yin Olúwa.”
Jehova arogoocwo, o we Ngai wa Isiraeli, kuuma tene na tene, nginya tene na tene. Nao andũ othe makiuga atĩrĩ, “Ameni” na “Goocai Jehova.”
37 Dafidi fi Asafu àti àwọn ẹlẹgbẹ́ rẹ̀ sílẹ̀ níwájú àpótí ẹ̀rí Olúwa láti jíṣẹ́ níbẹ̀ déédé, gẹ́gẹ́ bí ọjọ́ kọ̀ọ̀kan ṣe gbà.
Daudi agĩtiga Asafu na athiritũ ake hau mbere ya ithandũkũ rĩa kĩrĩkanĩro kĩa Jehova nĩguo matungatage kuo hĩndĩ ciothe, kũringana na mabata ma o mũthenya.
38 Ó fi Obedi-Edomu àti méjìdínláàádọ́rin ẹlẹgbẹ́ ẹ rẹ̀ láti ṣiṣẹ́ ìránṣẹ́ pẹ̀lú wọn. Obedi-Edomu mọ Jedutuni, àti Hosa pẹ̀lú jẹ́ olùtọ́jú ẹnu-ọ̀nà.
O na ningĩ agĩtiga Obedi-Edomu na athiritũ ake mĩrongo ĩtandatũ na anana matungatage hamwe nao. Obedi-Edomu mũrũ wa Jeduthuni marĩ na Hosa maarĩ arangĩri a kĩhingo.
39 Dafidi fi Sadoku àlùfáà àti àwọn àlùfáà ẹlẹgbẹ́ rẹ̀ níwájú Àgọ́ Olúwa ní ibi gíga ní Gibeoni.
Daudi agĩtiga Zadoku ũrĩa mũthĩnjĩri-Ngai hamwe na athĩnjĩri-Ngai arĩa angĩ hau mbere ya hema ĩrĩa nyamũre, kũndũ kũrĩa gũtũũgĩru kũu Gibeoni,
40 Láti gbé pẹpẹ ẹbọ sísun déédé, àárọ̀ àti ìrọ̀lẹ́ ní ìbámu pẹ̀lú gbogbo ohun tí a kọ sínú òfin Olúwa, tí ó ti fún Israẹli.
nĩguo marutagĩre Jehova maruta ma njino kĩgongona-inĩ kĩa maruta ma njino hĩndĩ ciothe, rũciinĩ na hwaĩ-inĩ, kũringana na ũrĩa kwandĩkĩtwo watho-inĩ wa Jehova ũrĩa aaheete andũ a Isiraeli.
41 Pẹ̀lú wọn ni Hemani àti Jedutuni àti ìyókù tí a mú àti yàn nípasẹ̀ orúkọ láti fi ọpẹ́ fún Olúwa, nítorí tí ìfẹ́ rẹ̀ dúró títí láéláé
Arĩa maarĩ hamwe nao nĩ Hemani na Jeduthuni, na arĩa angĩ maarĩ athuure na makagwetwo na marĩĩtwa nĩgeetha macookagĩrie Jehova ngaatho, makiugaga atĩrĩ, “Tondũ wendo wake ũtũũraga nginya tene.”
42 Hemani àti Jedutuni ni wọ́n dúró fún fífọn ìpè àti Kimbali àti fún lílo ohun èlò yòókù fún orin Ọlọ́run. Àwọn ọmọ Jedutuni wà ní ipò dídúró ní ẹnu-ọ̀nà.
Hemani na Jeduthuni nĩo meehokeirwo kũhuha tũrumbeta, na kũhũũrithania thaani iria ihũũrithanagio ikagamba, o na kũhũũraga inanda iria ingĩ cia kũina rwĩmbo rwamũre. Ariũ a Jeduthuni nĩo maaheirwo wĩra wa kũrangĩra kĩhingo.
43 Nígbà náà gbogbo àwọn ènìyàn kúrò, olúkúlùkù sí ilé rẹ̀: Dafidi yípadà láti súre fún ìdílé rẹ̀.
Hĩndĩ ĩyo andũ othe magĩthiĩ o mũndũ gwake mũciĩ, nake Daudi agĩcooka mũciĩ akarathime andũ a nyũmba yake.

< 1 Chronicles 16 >