< 1 Chronicles 16 >

1 Wọ́n gbé àpótí ẹ̀rí Ọlọ́run, wá sínú àgọ́ ti Dafidi ti pèsè fún un, wọ́n sì gbé ẹbọ sísun àti ọrẹ ìdàpọ̀ kalẹ̀ níwájú Ọlọ́run.
Ils firent entrer l'arche de Dieu et la placèrent au milieu de la tente que David avait dressée pour elle, et ils offrirent devant Dieu des holocaustes et des sacrifices de prospérité.
2 Lẹ́yìn tí Dafidi parí ẹbọ sísun àti ọrẹ ìdàpọ̀, ó bùkún àwọn ènìyàn ní orúkọ Olúwa.
Lorsque David eut achevé d'offrir les holocaustes et les sacrifices de prospérité, il bénit le peuple au nom de l'Éternel.
3 Nígbà náà ó fún olúkúlùkù ọkùnrin àti obìnrin ọmọ Israẹli ní ìṣù àkàrà kan, àkàrà dídùn ti àkókò kan àti àkàrà dídùn ti èso àjàrà kan.
Il donna à tous ceux d'Israël, hommes et femmes, un pain, une portion de viande et un gâteau de raisins secs.
4 Ó yan díẹ̀ lára àwọn ará Lefi láti máa jọ́sìn níwájú àpótí ẹ̀rí Olúwa, àti láti ṣe ìrántí àti dúpẹ́ àti láti yin Olúwa, Ọlọ́run Israẹli.
Il désigna quelques-uns des Lévites pour faire le service devant l'arche de l'Éternel, pour commémorer, remercier et louer l'Éternel, le Dieu d'Israël:
5 Asafu ni olóyè, àtẹ̀lé rẹ ni Sekariah, Jehieli, Ṣemiramotu, Asieli, Mattitiah, Eliabu, Benaiah, Obedi-Edomu àti Jeieli, àwọn ni yóò lu ohun èlò orin olókùn àti dùùrù haapu. Asafu ni yóò lu símbálì kíkan.
Asaph, le chef, et après lui Zacharie, puis Jeïel, Schemiramoth, Jehiel, Mattithia, Éliab, Benaja, Obed-Édom et Jeïel, avec des instruments à cordes et des harpes; Asaph, avec des cymbales, en sonnant à haute voix;
6 Àti Benaiah àti Jahasieli àwọn àlùfáà ni yóò fọn ìpè nígbà gbogbo níwájú àpótí ẹ̀rí májẹ̀mú ti Ọlọ́run.
et les sacrificateurs Benaja et Jahaziel, avec des trompettes, toujours devant l'arche de l'alliance de Dieu.
7 Ní ọjọ́ náà Dafidi kọ́kọ́ fi lé Asafu àti àwọn ẹlẹgbẹ́ rẹ̀ lọ́wọ́ orin Dafidi ti ọpẹ́ sí Olúwa.
Et en ce jour-là, David ordonna pour la première fois de rendre grâce à Yahvé par l'intermédiaire d'Asaph et de ses frères.
8 Ẹ fi ọpẹ́ fún Olúwa, ẹ pe orúkọ rẹ̀, ẹ fi iṣẹ́ rẹ̀ hàn nínú àwọn ènìyàn fún ohun tí ó ṣe
Oh! Rendez grâce à Yahvé. Invoquez son nom. Faites connaître ce qu'il a fait parmi les peuples.
9 Ẹ kọrin sí i, ẹ kọrin ìyìn, sí i, ẹ sọ ti gbogbo iṣẹ́ ìyanu rẹ̀.
Chantez pour lui. Chantez-lui des louanges. Racontez toutes ses œuvres merveilleuses.
10 Ìyìn nínú orúkọ rẹ̀ mímọ́; jẹ kí ọkàn àwọn tí ó yin Olúwa kí ó yọ̀.
Gloire à son saint nom. Que le cœur de ceux qui cherchent Yahvé se réjouisse.
11 Ẹ wá Olúwa àti agbára rẹ̀; e wá ojú rẹ̀ nígbà gbogbo.
Cherchez Yahvé et sa force. Cherchez son visage pour toujours.
12 Rántí àwọn ìyanu tí Ó ti ṣe, iṣẹ́ ìyanu rẹ̀ àti ìdájọ́ tí Ó ti sọ.
Souvenez-vous des merveilles qu'il a faites, ses merveilles, et les jugements de sa bouche,
13 A! ẹ̀yin ìran ọmọ Israẹli ìránṣẹ́ rẹ̀, àwọn ọmọ Jakọbu, ẹ̀yin tí ó ti yàn.
vous, progéniture d'Israël, son serviteur, vous, enfants de Jacob, ses élus.
14 Òun ni Olúwa Ọlọ́run wa; ìdájọ́ rẹ̀ wà ní gbogbo ayé.
Il est Yahvé, notre Dieu. Ses jugements sont dans toute la terre.
15 Ó rántí májẹ̀mú rẹ̀ láéláé, ọ̀rọ̀ tí ó pàṣẹ, fún ẹgbẹẹgbẹ̀rún ìran,
Souviens-toi de son alliance pour toujours, la parole qu'il a commandée à mille générations,
16 májẹ̀mú tí ó dá pẹ̀lú Abrahamu, ìbúra tí ó ṣe pẹ̀lú fún Isaaki.
l'alliance qu'il a conclue avec Abraham, son serment à Isaac.
17 Ó ṣe ìdánilójú u rẹ̀ fún Jakọbu, gẹ́gẹ́ bí àṣẹ sí Israẹli, gẹ́gẹ́ bi májẹ̀mú ayérayé:
Il le confirma à Jacob comme une loi, et à Israël pour une alliance éternelle,
18 “Sí ọ, ni èmi yóò fún ní ilẹ̀ Kenaani. Gẹ́gẹ́ bí ààyè tí ìwọ yóò jogún.”
en disant: « Je te donnerai le pays de Canaan, Le lot de votre héritage, »
19 Nígbà tí wọn kéré ní iye, wọ́n kéré gidigidi, wọ́n sì jẹ́ àlejò níbẹ̀,
quand vous n'étiez qu'un petit nombre d'hommes, oui, très peu, et des étrangers en son sein.
20 wọ́n rìn kiri láti orílẹ̀-èdè sí orílẹ̀-èdè láti ìjọba kan sí èkejì.
Ils allaient de nation en nation, d'un royaume à un autre peuple.
21 Kò gba ọkùnrin kankan láyè láti pọ́n wọn lójú; nítorí tiwọn, ó bá àwọn ọba wí.
Il n'a permis à personne de leur faire du tort. Oui, il a réprimandé les rois pour leur bien,
22 “Má ṣe fọwọ́ kan àwọn ẹni àmì òróró mi; má ṣe pa àwọn wòlíì mi lára.”
« Ne touchez pas à mes oints! Ne faites pas de mal à mes prophètes! »
23 Kọrin sí Olúwa gbogbo ayé; ẹ máa fi ìgbàlà rẹ̀ hàn láti ọjọ́ dé ọjọ́.
Chantez à Yahvé, toute la terre! Afficher son salut au jour le jour.
24 Kéde ògo à rẹ̀ láàrín àwọn orílẹ̀-èdè, ohun ìyàlẹ́nu tí ó ṣe láàrín gbogbo ènìyàn.
Déclarez sa gloire parmi les nations, et ses merveilles parmi tous les peuples.
25 Nítorí títóbi ni Olúwa òun sì ni ìyìn yẹ jùlọ; òun ni kí a bẹ̀rù ju gbogbo àwọn Ọlọ́run lọ.
Car Yahvé est grand et digne de louange. Il doit également être craint par-dessus tous les dieux.
26 Nítorí gbogbo àwọn ọlọ́run orílẹ̀-èdè jẹ́ àwọn òrìṣà, ṣùgbọ́n Olúwa dá àwọn ọ̀run.
Car tous les dieux des peuples sont des idoles, mais Yahvé a fait les cieux.
27 Dídán àti ọláńlá ni ó wà níwájú rẹ̀; agbára àti ayọ̀ ni ó wà ní ibi ibùgbé rẹ̀.
L'honneur et la majesté sont devant lui. La force et la joie sont à sa place.
28 Fi fún Olúwa, ẹ̀yin ìdílé àwọn orílẹ̀-èdè, ẹ fi ògo àti ipá fún Olúwa.
Rendez hommage à Yahvé, vous, familles des peuples, attribue à Yahvé la gloire et la force!
29 Fún Olúwa ní ìyìn nítorí orúkọ rẹ̀; gbé ọrẹ kí ẹ sì wá síwájú rẹ̀. Sìn Olúwa nínú inú dídùn ìwà mímọ́ rẹ̀.
Rendez à Yahvé la gloire due à son nom. Apportez une offrande, et venez devant lui. Adorez Yahvé dans une tenue sacrée.
30 Wárìrì níwájú rẹ̀, gbogbo ayé! Ayé sì fi ìdí múlẹ̀; a kò sì le è ṣí i.
Tremblez devant lui, toute la terre! Le monde est également établi qu'il ne peut pas être déplacé.
31 Jẹ́ kí àwọn ọ̀run kí ó yọ̀, jẹ́ kí ayé kí ó ṣe inú dídùn; lẹ́ kí wọn kí ó sọ láàrín àwọn orílẹ̀-èdè, pé “Olúwa jẹ ọba!”
Que les cieux se réjouissent! et que la terre se réjouisse! Qu'ils disent parmi les nations: « Yahvé règne! »
32 Jẹ́ kí ọ̀run kí ó tún dún padà, àti gbogbo ohun tí ó wà nínú rẹ̀; Jẹ́ kí àwọn pápá kí ó hó fún ayọ̀, àti gbogbo ohun tí ó wà nínú rẹ̀!
Que la mer rugisse, et sa plénitude! Que le champ exulte, et tout ce qu'il contient!
33 Nígbà náà ni igi igbó yóò kọrin, wọn yóò kọrin fún ayọ̀ níwájú Olúwa, nítorí tí ó wá láti ṣèdájọ́ ayé.
Alors les arbres de la forêt chanteront de joie devant Yahvé, car il vient pour juger la terre.
34 Fi ọpẹ́ fún Olúwa, nítorí tí ó dára; ìfẹ́ ẹ rẹ̀ dúró títí láé.
Oh! Rendez grâce à Yahvé, car il est bon, car sa bonté est éternelle.
35 Ké lóhùn rara, “Gbà wá, Ọlọ́run olùgbàlà a wa; kó wa jọ kí o sì gbà wá kúrò lọ́wọ́ àwọn orílẹ̀-èdè, kí àwa kí ó lè fi ọpẹ́ fún orúkọ mímọ́ rẹ, kí àwa kí ó lè yọ̀ nínú ìyìn rẹ̀.”
Dis: « Sauve-nous, Dieu de notre salut! Rassemblez-nous et délivrez-nous des nations, pour rendre grâce à ton saint nom, pour triompher dans ta louange. »
36 Olùbùkún ni Olúwa, Ọlọ́run Israẹli, láé àti láéláé. Lẹ́yìn náà gbogbo àwọn ènìyàn wí pé, “Àmín,” wọ́n “Yin Olúwa.”
Béni soit Yahvé, le Dieu d'Israël, de l'éternité à l'éternité. Tout le peuple dit: « Amen » et loua Yahvé.
37 Dafidi fi Asafu àti àwọn ẹlẹgbẹ́ rẹ̀ sílẹ̀ níwájú àpótí ẹ̀rí Olúwa láti jíṣẹ́ níbẹ̀ déédé, gẹ́gẹ́ bí ọjọ́ kọ̀ọ̀kan ṣe gbà.
Il laissa là Asaph et ses frères devant l'arche de l'alliance de Yahvé, pour qu'ils fassent le service devant l'arche continuellement, selon le travail de chaque jour;
38 Ó fi Obedi-Edomu àti méjìdínláàádọ́rin ẹlẹgbẹ́ ẹ rẹ̀ láti ṣiṣẹ́ ìránṣẹ́ pẹ̀lú wọn. Obedi-Edomu mọ Jedutuni, àti Hosa pẹ̀lú jẹ́ olùtọ́jú ẹnu-ọ̀nà.
et Obed-Edom avec leurs soixante-huit parents; Obed-Edom aussi, fils de Jeduthun, et Hosah pour être portiers;
39 Dafidi fi Sadoku àlùfáà àti àwọn àlùfáà ẹlẹgbẹ́ rẹ̀ níwájú Àgọ́ Olúwa ní ibi gíga ní Gibeoni.
et le sacrificateur Zadok et ses frères les sacrificateurs, devant la tente de Yahvé, dans le haut lieu qui était à Gabaon,
40 Láti gbé pẹpẹ ẹbọ sísun déédé, àárọ̀ àti ìrọ̀lẹ́ ní ìbámu pẹ̀lú gbogbo ohun tí a kọ sínú òfin Olúwa, tí ó ti fún Israẹli.
pour offrir des holocaustes à Yahvé sur l'autel des holocaustes, continuellement, matin et soir, selon tout ce qui est écrit dans la loi de Yahvé, qu'il a prescrite à Israël;
41 Pẹ̀lú wọn ni Hemani àti Jedutuni àti ìyókù tí a mú àti yàn nípasẹ̀ orúkọ láti fi ọpẹ́ fún Olúwa, nítorí tí ìfẹ́ rẹ̀ dúró títí láéláé
Avec eux, Héman et Jeduthun, et les autres élus nommément désignés, pour rendre grâces à l'Éternel, parce que sa miséricorde dure à toujours.
42 Hemani àti Jedutuni ni wọ́n dúró fún fífọn ìpè àti Kimbali àti fún lílo ohun èlò yòókù fún orin Ọlọ́run. Àwọn ọmọ Jedutuni wà ní ipò dídúró ní ẹnu-ọ̀nà.
Avec eux, Héman et Jeduthun, avec des trompettes et des cymbales pour ceux qui doivent sonner à haute voix, et avec des instruments pour les chants de Dieu, et les fils de Jeduthun pour être à la porte.
43 Nígbà náà gbogbo àwọn ènìyàn kúrò, olúkúlùkù sí ilé rẹ̀: Dafidi yípadà láti súre fún ìdílé rẹ̀.
Tout le peuple partit, chacun dans sa maison, et David s'en retourna pour bénir sa maison.

< 1 Chronicles 16 >