< 1 Chronicles 16 >

1 Wọ́n gbé àpótí ẹ̀rí Ọlọ́run, wá sínú àgọ́ ti Dafidi ti pèsè fún un, wọ́n sì gbé ẹbọ sísun àti ọrẹ ìdàpọ̀ kalẹ̀ níwájú Ọlọ́run.
Therfor thei brouyten the arke of God, and settiden it in the myddis of the tabernacle, that Dauid hadde araied therto; and thei offriden brent sacrifices and pesible sacrifices bifor the Lord.
2 Lẹ́yìn tí Dafidi parí ẹbọ sísun àti ọrẹ ìdàpọ̀, ó bùkún àwọn ènìyàn ní orúkọ Olúwa.
And whanne Dauid offrynge brent sacrifices and pesible sacrifices hadde fillid, he blesside the puple in the name of the Lord;
3 Nígbà náà ó fún olúkúlùkù ọkùnrin àti obìnrin ọmọ Israẹli ní ìṣù àkàrà kan, àkàrà dídùn ti àkókò kan àti àkàrà dídùn ti èso àjàrà kan.
and departide to alle to ech bi hym silf fro a man til to a womman o cake of breed, and a part of rostid fleisch of a bugle, and flour fried in oile.
4 Ó yan díẹ̀ lára àwọn ará Lefi láti máa jọ́sìn níwájú àpótí ẹ̀rí Olúwa, àti láti ṣe ìrántí àti dúpẹ́ àti láti yin Olúwa, Ọlọ́run Israẹli.
And he ordeynede bifor the arke of the Lord, of the Leuytis, that schulden mynystre, and haue mynde of the werkis of the Lord, and glorifie and preyse the Lord God of Israel;
5 Asafu ni olóyè, àtẹ̀lé rẹ ni Sekariah, Jehieli, Ṣemiramotu, Asieli, Mattitiah, Eliabu, Benaiah, Obedi-Edomu àti Jeieli, àwọn ni yóò lu ohun èlò orin olókùn àti dùùrù haapu. Asafu ni yóò lu símbálì kíkan.
`he ordeynede Asaph the prince, and Zacharie his secounde; forsothe `he ordeynede Jahiel, and Semiramoth, and Jahel, and Mathathie, and Eliab, and Banaye, and Obededom, and Jehiel, on the orguns, on the sautrie, and on the harpis; but he ordeynede Asaph to sowne with cymbalis;
6 Àti Benaiah àti Jahasieli àwọn àlùfáà ni yóò fọn ìpè nígbà gbogbo níwájú àpótí ẹ̀rí májẹ̀mú ti Ọlọ́run.
sotheli he ordeynede Banaye and Aziel, preestis, bifor the arke of the boond of pees of the Lord, for to trumpe contynueli.
7 Ní ọjọ́ náà Dafidi kọ́kọ́ fi lé Asafu àti àwọn ẹlẹgbẹ́ rẹ̀ lọ́wọ́ orin Dafidi ti ọpẹ́ sí Olúwa.
In that dai Dauid made Asaph prince, and hise britheren, for to knowleche `to the Lord.
8 Ẹ fi ọpẹ́ fún Olúwa, ẹ pe orúkọ rẹ̀, ẹ fi iṣẹ́ rẹ̀ hàn nínú àwọn ènìyàn fún ohun tí ó ṣe
Knowleche ye to the Lord, and inwardli clepe ye his name; make ye hise fyndyngis knowun among puplis.
9 Ẹ kọrin sí i, ẹ kọrin ìyìn, sí i, ẹ sọ ti gbogbo iṣẹ́ ìyanu rẹ̀.
Synge ye to hym, and seie ye salm to hym, and telle ye alle his merueylis.
10 Ìyìn nínú orúkọ rẹ̀ mímọ́; jẹ kí ọkàn àwọn tí ó yin Olúwa kí ó yọ̀.
Preise ye his hooli name; the herte of men sekynge the Lord be glad.
11 Ẹ wá Olúwa àti agbára rẹ̀; e wá ojú rẹ̀ nígbà gbogbo.
Seke ye the Lord and his vertu; seke ye euere his face.
12 Rántí àwọn ìyanu tí Ó ti ṣe, iṣẹ́ ìyanu rẹ̀ àti ìdájọ́ tí Ó ti sọ.
Haue ye mynde of hise merueilis whiche he dide; of hise signes, and of the domes of his mouth.
13 A! ẹ̀yin ìran ọmọ Israẹli ìránṣẹ́ rẹ̀, àwọn ọmọ Jakọbu, ẹ̀yin tí ó ti yàn.
The seed of Israel, his seruaunt, preise thou God; the sones of Jacob, his chosun, preise ye God.
14 Òun ni Olúwa Ọlọ́run wa; ìdájọ́ rẹ̀ wà ní gbogbo ayé.
He is `oure Lord God; hise domes ben in ech lond.
15 Ó rántí májẹ̀mú rẹ̀ láéláé, ọ̀rọ̀ tí ó pàṣẹ, fún ẹgbẹẹgbẹ̀rún ìran,
Haue ye mynde with outen ende of his couenaunt; of the word whiche he couenauntide `in to a thousynde generaciouns.
16 májẹ̀mú tí ó dá pẹ̀lú Abrahamu, ìbúra tí ó ṣe pẹ̀lú fún Isaaki.
Which word he couenauntide with Abraham; and of his ooth to Ysaac.
17 Ó ṣe ìdánilójú u rẹ̀ fún Jakọbu, gẹ́gẹ́ bí àṣẹ sí Israẹli, gẹ́gẹ́ bi májẹ̀mú ayérayé:
And he ordeynede that to Jacob in to a comaundement; and to Israel in to euerlastynge couenaunt.
18 “Sí ọ, ni èmi yóò fún ní ilẹ̀ Kenaani. Gẹ́gẹ́ bí ààyè tí ìwọ yóò jogún.”
And seide, To thee Y schal yyue the lond of Canaan; the part of youre erytage.
19 Nígbà tí wọn kéré ní iye, wọ́n kéré gidigidi, wọ́n sì jẹ́ àlejò níbẹ̀,
Whanne thei weren fewe in noumbre; litle, and pilgrims therof.
20 wọ́n rìn kiri láti orílẹ̀-èdè sí orílẹ̀-èdè láti ìjọba kan sí èkejì.
And thei passiden fro folk in to the folk; and fro a rewme to another puple.
21 Kò gba ọkùnrin kankan láyè láti pọ́n wọn lójú; nítorí tiwọn, ó bá àwọn ọba wí.
He suffride not ony man falseli chalenge hem; but he blamyde kyngis for hem.
22 “Má ṣe fọwọ́ kan àwọn ẹni àmì òróró mi; má ṣe pa àwọn wòlíì mi lára.”
Nyle ye touche my cristis; and nyle ye do wickidli ayens my prophetis.
23 Kọrin sí Olúwa gbogbo ayé; ẹ máa fi ìgbàlà rẹ̀ hàn láti ọjọ́ dé ọjọ́.
Al erthe, singe ye to the Lord; telle ye fro dai into dai his helthe.
24 Kéde ògo à rẹ̀ láàrín àwọn orílẹ̀-èdè, ohun ìyàlẹ́nu tí ó ṣe láàrín gbogbo ènìyàn.
Telle ye among hethen men his glorie; hise merueylis among alle puplis.
25 Nítorí títóbi ni Olúwa òun sì ni ìyìn yẹ jùlọ; òun ni kí a bẹ̀rù ju gbogbo àwọn Ọlọ́run lọ.
For the Lord is greet, and worthi to be preisid ful myche; and he is orible, `ethir griseful, ouer alle goddis.
26 Nítorí gbogbo àwọn ọlọ́run orílẹ̀-èdè jẹ́ àwọn òrìṣà, ṣùgbọ́n Olúwa dá àwọn ọ̀run.
For alle the goddis of puplis ben idols; but the Lord made heuenes.
27 Dídán àti ọláńlá ni ó wà níwájú rẹ̀; agbára àti ayọ̀ ni ó wà ní ibi ibùgbé rẹ̀.
Knoulechyng and greet doyng ben bifor hym; strengthe and ioy ben in the place of hym.
28 Fi fún Olúwa, ẹ̀yin ìdílé àwọn orílẹ̀-èdè, ẹ fi ògo àti ipá fún Olúwa.
Ye meynees of puplis, `bringe ye to the Lord; brynge ye to the Lord glorie and empire.
29 Fún Olúwa ní ìyìn nítorí orúkọ rẹ̀; gbé ọrẹ kí ẹ sì wá síwájú rẹ̀. Sìn Olúwa nínú inú dídùn ìwà mímọ́ rẹ̀.
Yyue ye glorie to his name, reise ye sacrifice, and come ye in his siyt; and worschipe ye the Lord in hooli fairnesse.
30 Wárìrì níwájú rẹ̀, gbogbo ayé! Ayé sì fi ìdí múlẹ̀; a kò sì le è ṣí i.
Al erthe be mouyd fro his face; for he foundide the world vnmouable.
31 Jẹ́ kí àwọn ọ̀run kí ó yọ̀, jẹ́ kí ayé kí ó ṣe inú dídùn; lẹ́ kí wọn kí ó sọ láàrín àwọn orílẹ̀-èdè, pé “Olúwa jẹ ọba!”
Heuenes be glad, and the erthe `ioy fulli; and seie thei among naciouns, The Lord schal regne.
32 Jẹ́ kí ọ̀run kí ó tún dún padà, àti gbogbo ohun tí ó wà nínú rẹ̀; Jẹ́ kí àwọn pápá kí ó hó fún ayọ̀, àti gbogbo ohun tí ó wà nínú rẹ̀!
The see thundre, and his fulnesse; the feeldis fulli ioye, and alle thingis that ben in tho.
33 Nígbà náà ni igi igbó yóò kọrin, wọn yóò kọrin fún ayọ̀ níwájú Olúwa, nítorí tí ó wá láti ṣèdájọ́ ayé.
Thanne the trees of the forest schulen preyse bifor the Lord; for he cometh to deme the erthe.
34 Fi ọpẹ́ fún Olúwa, nítorí tí ó dára; ìfẹ́ ẹ rẹ̀ dúró títí láé.
Knouleche ye to the Lord, for he is good; for his mersi is withouten ende.
35 Ké lóhùn rara, “Gbà wá, Ọlọ́run olùgbàlà a wa; kó wa jọ kí o sì gbà wá kúrò lọ́wọ́ àwọn orílẹ̀-èdè, kí àwa kí ó lè fi ọpẹ́ fún orúkọ mímọ́ rẹ, kí àwa kí ó lè yọ̀ nínú ìyìn rẹ̀.”
And seie ye, Thou God oure sauyour, saue vs, and gadere vs, and delyuere vs fro hethen men; that we knowleche to thin hooli name, and be fulli glade in thi songis.
36 Olùbùkún ni Olúwa, Ọlọ́run Israẹli, láé àti láéláé. Lẹ́yìn náà gbogbo àwọn ènìyàn wí pé, “Àmín,” wọ́n “Yin Olúwa.”
Blessid be the Lord God of Israel fro with oute bigynnyng and til `in to with outen ende; and al the puple seie, Amen, and seie heriyng to God.
37 Dafidi fi Asafu àti àwọn ẹlẹgbẹ́ rẹ̀ sílẹ̀ níwájú àpótí ẹ̀rí Olúwa láti jíṣẹ́ níbẹ̀ déédé, gẹ́gẹ́ bí ọjọ́ kọ̀ọ̀kan ṣe gbà.
Therfor Dauid lefte there, bifor the arke of boond of pees of the Lord, Asaph and hise britheren, for to mynystre in the siyt of the arke contynueli bi alle daies and her whilis.
38 Ó fi Obedi-Edomu àti méjìdínláàádọ́rin ẹlẹgbẹ́ ẹ rẹ̀ láti ṣiṣẹ́ ìránṣẹ́ pẹ̀lú wọn. Obedi-Edomu mọ Jedutuni, àti Hosa pẹ̀lú jẹ́ olùtọ́jú ẹnu-ọ̀nà.
Forsothe he ordeynede porteris, Obededom and hise britheren, eiyte and sixti, and Obededom, the sone of Idithum, and Oza.
39 Dafidi fi Sadoku àlùfáà àti àwọn àlùfáà ẹlẹgbẹ́ rẹ̀ níwájú Àgọ́ Olúwa ní ibi gíga ní Gibeoni.
Sotheli `he ordeynede Sadoch preest, and hise britheren, preestis bifor the tabernacle of the Lord, in the hiy place that was in Gabaon,
40 Láti gbé pẹpẹ ẹbọ sísun déédé, àárọ̀ àti ìrọ̀lẹ́ ní ìbámu pẹ̀lú gbogbo ohun tí a kọ sínú òfin Olúwa, tí ó ti fún Israẹli.
for to offre brent sacrifices to the Lord on the auter of brent sacrifice contynueli, in the morwetid and euentid, bi alle thingis that ben writun in the lawe of the Lord, which he comaundide to Israel.
41 Pẹ̀lú wọn ni Hemani àti Jedutuni àti ìyókù tí a mú àti yàn nípasẹ̀ orúkọ láti fi ọpẹ́ fún Olúwa, nítorí tí ìfẹ́ rẹ̀ dúró títí láéláé
And aftir hym Dauyd ordeynede Eman, and Idithum, and other chosene, ech man bi his name, for to knowleche to the Lord; for his mercy is withouten ende.
42 Hemani àti Jedutuni ni wọ́n dúró fún fífọn ìpè àti Kimbali àti fún lílo ohun èlò yòókù fún orin Ọlọ́run. Àwọn ọmọ Jedutuni wà ní ipò dídúró ní ẹnu-ọ̀nà.
Also he ordeynede Eman, and Idithum, trumpynge, and schakynge cymbalis, and alle orguns of musikis, for to synge to God; forsothe he made the sones of Idithum to be portours, `ether bereris.
43 Nígbà náà gbogbo àwọn ènìyàn kúrò, olúkúlùkù sí ilé rẹ̀: Dafidi yípadà láti súre fún ìdílé rẹ̀.
And al the puple turnede ayen in to her hows, and Dauid turnede ayen, to blesse also his hows.

< 1 Chronicles 16 >