< 1 Chronicles 15 >
1 Lẹ́yìn ìgbà tí Dafidi ti kọ́ ilé fún ara rẹ̀ ní ìlú Dafidi. Ó sì fi ààyè sílẹ̀ fún àpótí ẹ̀rí Ọlọ́run ó sì pàgọ́ fún un.
Et il bâtit pour lui des maisons dans la Cité de David, et prépara une place à l'Arche de Dieu et dressa une tente pour la recevoir.
2 Nígbà náà Dafidi wí pé, kò sí ẹnìkan àyàfi àwọn ọmọ Lefi ni ó lè gbé àpótí ẹ̀rí Ọlọ́run, nítorí Olúwa yàn wọ́n láti gbé àpótí ẹ̀rí Olúwa àti láti máa ṣe ìránṣẹ́ níwájú rẹ̀ títí láé.
Alors David dit: L'Arche de Dieu ne doit être portée que par les Lévites, car c'est eux que l'Éternel a choisis pour porter l'Arche de Dieu et en faire le service à perpétuité.
3 Dafidi kó gbogbo àwọn ọmọ Israẹli jọ ní Jerusalẹmu láti gbé àpótí ẹ̀rí Olúwa wá sí ibi tí ó ti pèsè sílẹ̀ fún un.
Et David assembla tout Israël à Jérusalem pour transporter l'Arche de l'Éternel à sa place, qu'il lui avait préparée.
4 Wọ̀nyí ni àwọn ọmọ Aaroni àti àwọn ọmọ Lefi tí Dafidi péjọ papọ̀.
Et David réunit les fils d'Aaron et les Lévites;
5 Ọgọ́fà nínú àwọn ọmọ Kohati; Urieli olórí àti àwọn ẹbí rẹ̀.
des fils de Cahath: Uriel, le chef, et ses frères, cent vingt;
6 Igba ó lé ogún nínú àwọn ọmọ Merari; Asaiah olórí àti àwọn ẹbí rẹ̀.
des fils de Merari: Asaïa, le chef, et ses frères, deux cent vingt;
7 Àádóje nínú àwọn ọmọ Gerṣoni; Joẹli olórí àti àwọn ẹbí rẹ̀.
des fils de Gersom: Joël, le chef, et ses frères, cent trente;
8 Igba nínú àwọn ọmọ Elisafani; Ṣemaiah olórí àti àwọn ẹbí rẹ̀.
des fils d'Elitsaphan: Semaïa, le chef, et ses frères, deux cents;
9 Ọgọ́rin nínú àwọn ọmọ Hebroni; Elieli olórí àti àwọn ẹbí rẹ̀.
des fils de Hébron: Eliel, le chef, et ses frères, quatre-vingts;
10 Méjìléláàádọ́fà nínú àwọn ọmọ Usieli; Amminadabu olórí àti àwọn ẹbí rẹ̀.
des fils de Uzziel: Amminadab, le chef, et ses frères, cent-douze.
11 Dafidi sì ránṣẹ́ pe Sadoku, Abiatari tí wọ́n jẹ́ àlùfáà, àti Urieli, Asaiah. Joẹli, Ṣemaiah, Elieli àti Amminadabu tí wọ́n jẹ́ Lefi.
Et David manda Tsadoc et Abiathar, Prêtres; et les Lévites Uriel, Asaïa et Joël; Semaïa, Eliel, et Amminadab,
12 Ó sì fi fún wọn pé, “Ẹ̀yin ni olórí àwọn ìdílé Lefi; ẹ̀yin àti àwọn Lefi ènìyàn yín, ẹ ya ara yín sí mímọ́ kí ẹ lè gbé àpótí ẹ̀rí Olúwa, Ọlọ́run Israẹli, lọ sí ibi tí mó ti pèsè sílẹ̀ fún un.
et leur dit: Vous êtes les patriarches des Lévites; mettez-vous en état de sainteté, vous et vos frères, et transportez l'Arche de l'Éternel, Dieu d'Israël, au lieu que je lui ai préparé.
13 Nítorí tí ẹ̀yin ọmọ Lefi kò gbe gòkè wá ní ìgbà àkọ́kọ́ ti Olúwa Ọlọ́run fi ìbínú rẹ̀ ko lù wá. Àwa kò sì ṣe ìwádìí lọ́wọ́ rẹ̀ nípa bí a ti ń ṣe é gẹ́gẹ́ bí ọ́nà tí a là sílẹ̀.”
C'est parce que la première fois vous ne l'avez pas fait, que l'Éternel, notre Dieu, a frappé un coup sur nous, parce que nous ne l'avions pas consulté selon le droit.
14 Bẹ́ẹ̀ ni àwọn àlùfáà àti àwọn Lefi ya ara wọn sí mímọ́ láti gbé àpótí ẹ̀rí Olúwa gòkè wá, Ọlọ́run Israẹli.
Et les Prêtres et les Lévites se mirent en état de sainteté pour faire la translation de l'Arche de l'Éternel, Dieu d'Israël.
15 Nígbà náà ni àwọn Lefi gbé àpótí ẹ̀rí Ọlọ́run pẹ̀lú ọ̀pá ní èjìká wọn gẹ́gẹ́ bí Mose ti pa á láṣẹ gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ Olúwa.
Et les fils des Lévites portèrent l'Arche de Dieu, comme Moïse l'avait prescrit d'après la parole de l'Éternel, sur leurs épaules où posaient les barres.
16 Dafidi sọ fún àwọn olórí àwọn Lefi láti yan àwọn arákùnrin wọn gẹ́gẹ́ bí akọrin láti kọ orin ayọ̀, pẹ̀lú àwọn ohun èlò orin olókùn, dùùrù, àti símbálì.
Et David dit aux chefs des Lévites de mettre de service leurs frères les chantres, avec des instruments de musique, harpes et luths et cymbales, retentissants, pour prendre un ton éclatant en signe de joie.
17 Bẹ́ẹ̀ ni àwọn Lefi yan Hemani ọmọ Joẹli; àti nínú àwọn arákùnrin rẹ̀, Asafu ọmọ Berekiah, àti nínú àwọn ọmọ Merari arákùnrin wọn, Etani ọmọ Kuṣaiah;
Et les Lévites mirent de service: Heiman, fils de Joël, et, de ses frères, Asaph, fils de Béréchia, et, des fils de Merari, leurs frères: Eithan, fils de Cusaïa,
18 àti pẹ̀lú wọn àwọn arákùnrin wọn tí a yàn bí olùrànlọ́wọ́ wọn: Sekariah, Jaasieli, Ṣemiramotu, Jehieli, Unni, Eliabu, Benaiah, Maaseiah, Mattitiah, Elifelehu, Mikimeiah, àti Obedi-Edomu àti Jeieli, àwọn aṣọ́bodè.
et avec eux leurs frères puînés Zacharie, Ben et Jaëziel et Semiramoth et Jehiel et Unni, Eliab et Benaïa et Maëséia et Matthithia et Eliphéléhou et Micnéihu et Obed-Edom et Jeïel, portiers;
19 Àwọn akọrin sì ni Hemani, Asafu, àti Etani ti àwọn ti kimbali idẹ tí ń dún kíkan;
et les chantres Heiman, Asaph et Eithan pour faire résonner les cymbales d'airain, et
20 Sekariah, Asieli, Ṣemiramotu, Jehieli, àti Unni, Eliabu, Maaseiah àti Benaiah àwọn tí ó gbọdọ̀ ta ohun èlò orin olókùn gẹ́gẹ́ bí alamoti,
Zacharie et Aziel et Semiramoth et Jehiel et Unni et Eliab et Maëséia et Benaïa avec des harpes en mode virginal
21 àti Mattitiah, Elifelehu, Mikneiah, Obedi-Edomu, Jeieli àti Asasiah ni ó ní láti ta ohun èlò olóhùn gooro, láti darí gẹ́gẹ́ bí ṣeminiti.
et Matthithia et Eliphéléhou et Micnéihu et Obed-Edom et Jeïel et Azazia avec des luths en octave de basse pour conduire le chant.
22 Kenaniah olórí àwọn ará Lefi ni ó wà ní ìkáwọ́ orin èyí sì ni ojúṣe nítorí ó mòye nípa rẹ̀.
Et Chenania, Maître chantre des Lévites, enseignait le chant, car il était entendu.
23 Berekiah àti Elkana ni kí ó wà gẹ́gẹ́ bí olùṣọ́nà fún àpótí ẹ̀rí.
Et Béréchia et Elcana étaient portiers de l'Arche.
24 Ṣebaniah, Jehoṣafati, Netaneli, Amasai, Sekariah, Benaiah àti Elieseri ní àwọn àlùfáà, tí o ń fún ìpè níwájú àpótí ẹ̀rí Ọlọ́run. Obedi-Edomu àti Jehiah ni ó sì gbọdọ̀ jẹ́ olùṣọ́nà fún àpótí ẹ̀rí.
Et Sebania et Josaphat et Nethaneël et Amasaï et Zacharie et Benaïa et Eliézer, Prêtres, sonnaient des trompettes devant l'Arche de Dieu. Et Obed-Edom et Jehia étaient portiers de l'Arche.
25 Bẹ́ẹ̀ ni Dafidi àti àwọn àgbàgbà Israẹli àti àwọn olórí ẹgbẹẹgbẹ̀rún lọ láti gbé àpótí ẹ̀rí ti májẹ̀mú Olúwa láti ilé Obedi-Edomu, pẹ̀lú inú dídùn.
Ainsi David et les Anciens d'Israël et les chefs de mille partirent pour transporter l'Arche de l'alliance de l'Éternel de la maison d'Obed-Edom, dans l'allégresse.
26 Nítorí Ọlọ́run tì ràn wọ́n lọ́wọ́ àwọn ará Lefi ẹni tí ó gbé àpótí ẹ̀rí ti májẹ̀mú Olúwa, akọ màlúù méje pẹ̀lú àgbò méje láti fi ṣé ìrúbọ.
Et comme Dieu fut en aide aux Lévites qui portaient l'Arche d'alliance de l'Éternel, ils sacrifièrent sept taureaux et sept béliers.
27 Dafidi sì wọ efodu; aṣọ ìgúnwà ọ̀gbọ̀ dáradára, àti gbogbo àwọn ọmọ Lefi tí ń ru àpótí ẹ̀rí náà, àti àwọn akọrin, àti Kenaniah olórí pẹ̀lú àwọn akọrin. Dafidi sì wọ aṣọ ìgúnwà funfun.
Et David était revêtu d'un manteau de byssus, de même que tous les Lévites, porteurs de l'Arche, et les chantres et Chenania, Maître chantre parmi les chantres; et David portait un éphod de lin.
28 Bẹ́ẹ̀ ni gbogbo Israẹli gbé àpótí ẹ̀rí àti májẹ̀mú Olúwa gòkè wá pẹ̀lú ariwo, pẹ̀lú àyíká ìhó ayọ̀ àti láti fọn fèrè ti ìpè, àti kimbali, àti láti ta ohun èlò orin olókùn àti dùùrù olóhùn gooro.
Et tout Israël opéra la translation de l'Arche de l'alliance de l'Éternel avec des acclamations et au son des clairons et des trompettes et des cymbales, faisant résonner les harpes et les luths.
29 Bí àpótí ẹ̀rí Olúwa ti ń wọ ìlú ńlá Dafidi, Mikali ọmọbìnrin Saulu ń wò láti ojú fèrèsé nígbà tí ó sì rí ọba Dafidi ń jó, ó sì ń ṣe àjọyọ̀, ó sì kẹ́gàn rẹ̀ ní ọkàn rẹ̀.
Et lorsque l'Arche d'alliance de l'Éternel atteignait la cité de David, Michal, fille de Saül, regardait par la fenêtre, et elle vit le roi David dansant et sautant, et elle conçut pour lui du mépris en son cœur.