< 1 Chronicles 15 >

1 Lẹ́yìn ìgbà tí Dafidi ti kọ́ ilé fún ara rẹ̀ ní ìlú Dafidi. Ó sì fi ààyè sílẹ̀ fún àpótí ẹ̀rí Ọlọ́run ó sì pàgọ́ fún un.
Or [David] bâtit pour lui des maisons dans la Cité de David, et prépara un lieu pour l'Arche de Dieu; et lui tendit un tabernacle.
2 Nígbà náà Dafidi wí pé, kò sí ẹnìkan àyàfi àwọn ọmọ Lefi ni ó lè gbé àpótí ẹ̀rí Ọlọ́run, nítorí Olúwa yàn wọ́n láti gbé àpótí ẹ̀rí Olúwa àti láti máa ṣe ìránṣẹ́ níwájú rẹ̀ títí láé.
Et David dit: L'Arche de Dieu ne doit être portée que par les Lévites; car l'Eternel les a choisis pour porter l'Arche de Dieu, et pour faire le service à toujours.
3 Dafidi kó gbogbo àwọn ọmọ Israẹli jọ ní Jerusalẹmu láti gbé àpótí ẹ̀rí Olúwa wá sí ibi tí ó ti pèsè sílẹ̀ fún un.
David donc assembla tous ceux d'Israël à Jérusalem, pour amener l'Arche de l'Eternel dans le lieu qu'il lui avait préparé.
4 Wọ̀nyí ni àwọn ọmọ Aaroni àti àwọn ọmọ Lefi tí Dafidi péjọ papọ̀.
David assembla aussi les enfants d'Aaron, et les Lévites.
5 Ọgọ́fà nínú àwọn ọmọ Kohati; Urieli olórí àti àwọn ẹbí rẹ̀.
Des enfants de Kéhath, Uriël le Chef, et ses frères, six vingts.
6 Igba ó lé ogún nínú àwọn ọmọ Merari; Asaiah olórí àti àwọn ẹbí rẹ̀.
Des enfants de Mérari, Hasaïa le Chef, et ses frères, deux cent et vingt.
7 Àádóje nínú àwọn ọmọ Gerṣoni; Joẹli olórí àti àwọn ẹbí rẹ̀.
Des enfants de Guersom, Joël le Chef, et ses frères, cent trente.
8 Igba nínú àwọn ọmọ Elisafani; Ṣemaiah olórí àti àwọn ẹbí rẹ̀.
Des enfants d'Elitsaphan, Sémahja le chef, et ses frères, deux cents.
9 Ọgọ́rin nínú àwọn ọmọ Hebroni; Elieli olórí àti àwọn ẹbí rẹ̀.
Des enfants de Hébron, Eliël le Chef, et ses frères, quatre-vingts.
10 Méjìléláàádọ́fà nínú àwọn ọmọ Usieli; Amminadabu olórí àti àwọn ẹbí rẹ̀.
Des enfants de Huziël, Hamminadab le Chef et ses frères, cent et douze.
11 Dafidi sì ránṣẹ́ pe Sadoku, Abiatari tí wọ́n jẹ́ àlùfáà, àti Urieli, Asaiah. Joẹli, Ṣemaiah, Elieli àti Amminadabu tí wọ́n jẹ́ Lefi.
David donc appela Tsadoc et Abiathar les Sacrificateurs, et ces Lévites-là, [savoir], Uriël, Hasaïa, Joël, Sémahja, Eliël, et Hamminadab;
12 Ó sì fi fún wọn pé, “Ẹ̀yin ni olórí àwọn ìdílé Lefi; ẹ̀yin àti àwọn Lefi ènìyàn yín, ẹ ya ara yín sí mímọ́ kí ẹ lè gbé àpótí ẹ̀rí Olúwa, Ọlọ́run Israẹli, lọ sí ibi tí mó ti pèsè sílẹ̀ fún un.
Et il leur dit: Vous qui êtes les Chefs des pères des Lévites, sanctifiez-vous, vous et vos frères; et transportez l'Arche de l'Eternel le Dieu d'Israël, au lieu que je lui ai préparé.
13 Nítorí tí ẹ̀yin ọmọ Lefi kò gbe gòkè wá ní ìgbà àkọ́kọ́ ti Olúwa Ọlọ́run fi ìbínú rẹ̀ ko lù wá. Àwa kò sì ṣe ìwádìí lọ́wọ́ rẹ̀ nípa bí a ti ń ṣe é gẹ́gẹ́ bí ọ́nà tí a là sílẹ̀.”
Parce que vous n'y avez pas été la première fois, l'Eternel notre Dieu a fait une brèche entre nous; car nous ne l'avons pas recherché comme il est ordonné.
14 Bẹ́ẹ̀ ni àwọn àlùfáà àti àwọn Lefi ya ara wọn sí mímọ́ láti gbé àpótí ẹ̀rí Olúwa gòkè wá, Ọlọ́run Israẹli.
Les Sacrificateurs donc et les Lévites se sanctifièrent pour amener l'Arche de l'Eternel, le Dieu d'Israël.
15 Nígbà náà ni àwọn Lefi gbé àpótí ẹ̀rí Ọlọ́run pẹ̀lú ọ̀pá ní èjìká wọn gẹ́gẹ́ bí Mose ti pa á láṣẹ gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ Olúwa.
Et les enfants des Lévites portèrent l'Arche de Dieu sur leurs épaules, avec les barres qu'ils avaient sur eux, comme Moïse l'avait commandé suivant la parole de l'Eternel.
16 Dafidi sọ fún àwọn olórí àwọn Lefi láti yan àwọn arákùnrin wọn gẹ́gẹ́ bí akọrin láti kọ orin ayọ̀, pẹ̀lú àwọn ohun èlò orin olókùn, dùùrù, àti símbálì.
Et David dit aux Chefs des Lévites, d'établir quelques-uns de leurs frères qui chantassent avec des instruments de musique, [savoir] des musettes, des violons, et des cymbales, [et] qui fissent retentir leur voix avec joie.
17 Bẹ́ẹ̀ ni àwọn Lefi yan Hemani ọmọ Joẹli; àti nínú àwọn arákùnrin rẹ̀, Asafu ọmọ Berekiah, àti nínú àwọn ọmọ Merari arákùnrin wọn, Etani ọmọ Kuṣaiah;
Les Lévites donc établirent Héman fils de Joël, et d'entre ses frères, Asaph fils de Bérécia; et des enfants de Mérari, qui étaient leurs frères, Ethan fils de Kusaïa;
18 àti pẹ̀lú wọn àwọn arákùnrin wọn tí a yàn bí olùrànlọ́wọ́ wọn: Sekariah, Jaasieli, Ṣemiramotu, Jehieli, Unni, Eliabu, Benaiah, Maaseiah, Mattitiah, Elifelehu, Mikimeiah, àti Obedi-Edomu àti Jeieli, àwọn aṣọ́bodè.
Et avec eux leurs frères pour être au second rang, Zacharie, Ben, Jahaziël, Sémiramoth, Jéhiël, Hunni, Eliab, Bénéja, Mahaséïa, Mattitia, et Eliphaléhu, Miknéïa, Hobed-Edom, et Jéhiël, portiers.
19 Àwọn akọrin sì ni Hemani, Asafu, àti Etani ti àwọn ti kimbali idẹ tí ń dún kíkan;
Et quant à Héman, Asaph, et Ethan chantres, [ils sonnaient] des cymbales d'airain, en faisant retentir [leur voix].
20 Sekariah, Asieli, Ṣemiramotu, Jehieli, àti Unni, Eliabu, Maaseiah àti Benaiah àwọn tí ó gbọdọ̀ ta ohun èlò orin olókùn gẹ́gẹ́ bí alamoti,
Et Zacharie, Haziël, Sémiramoth, Jéhiël, Hunni, Eliab, Mahaséïa, et Bénéja jouaient de la musette, sur Halamoth.
21 àti Mattitiah, Elifelehu, Mikneiah, Obedi-Edomu, Jeieli àti Asasiah ni ó ní láti ta ohun èlò olóhùn gooro, láti darí gẹ́gẹ́ bí ṣeminiti.
Et Mattitia, Eliphaléhu, Miknéja, Hobed-Edom, Jéhiël, [et] Hazaria jouaient des violons sur l'octave, pour renforcer le ton.
22 Kenaniah olórí àwọn ará Lefi ni ó wà ní ìkáwọ́ orin èyí sì ni ojúṣe nítorí ó mòye nípa rẹ̀.
Mais Kénaïa, le principal des Lévites avait la charge de faire porter l'Arche, enseignant comment il la fallait porter; car il était homme fort intelligent.
23 Berekiah àti Elkana ni kí ó wà gẹ́gẹ́ bí olùṣọ́nà fún àpótí ẹ̀rí.
Et Bérécia et Elkana, étaient portiers pour l'Arche.
24 Ṣebaniah, Jehoṣafati, Netaneli, Amasai, Sekariah, Benaiah àti Elieseri ní àwọn àlùfáà, tí o ń fún ìpè níwájú àpótí ẹ̀rí Ọlọ́run. Obedi-Edomu àti Jehiah ni ó sì gbọdọ̀ jẹ́ olùṣọ́nà fún àpótí ẹ̀rí.
Et Sébania, Jéhosaphat, Nathanaël, Hamasaï, Zacharie, Bénéja, Elihézer, Sacrificateurs, sonnaient des trompettes devant l'Arche de Dieu, et Hobed-Edom et Jéhïa étaient portiers pour l'Arche.
25 Bẹ́ẹ̀ ni Dafidi àti àwọn àgbàgbà Israẹli àti àwọn olórí ẹgbẹẹgbẹ̀rún lọ láti gbé àpótí ẹ̀rí ti májẹ̀mú Olúwa láti ilé Obedi-Edomu, pẹ̀lú inú dídùn.
David donc et les Anciens d'Israël, avec les Gouverneurs de milliers, marchaient, amenant avec joie l'Arche de l'alliance de l'Eternel, de la maison d'Hobed-Edom.
26 Nítorí Ọlọ́run tì ràn wọ́n lọ́wọ́ àwọn ará Lefi ẹni tí ó gbé àpótí ẹ̀rí ti májẹ̀mú Olúwa, akọ màlúù méje pẹ̀lú àgbò méje láti fi ṣé ìrúbọ.
Et selon que Dieu soulageait les Lévites qui portaient l'Arche de l'alliance de l'Eternel, on sacrifiait sept veaux et sept béliers.
27 Dafidi sì wọ efodu; aṣọ ìgúnwà ọ̀gbọ̀ dáradára, àti gbogbo àwọn ọmọ Lefi tí ń ru àpótí ẹ̀rí náà, àti àwọn akọrin, àti Kenaniah olórí pẹ̀lú àwọn akọrin. Dafidi sì wọ aṣọ ìgúnwà funfun.
Et David était vêtu d'un éphod de fin lin; et tous les Lévites aussi qui portaient l'Arche, et les chantres; et Kénaïa, qui avait la principale charge de faire porter l'Arche, était avec les chantres; et David avait un éphod de lin.
28 Bẹ́ẹ̀ ni gbogbo Israẹli gbé àpótí ẹ̀rí àti májẹ̀mú Olúwa gòkè wá pẹ̀lú ariwo, pẹ̀lú àyíká ìhó ayọ̀ àti láti fọn fèrè ti ìpè, àti kimbali, àti láti ta ohun èlò orin olókùn àti dùùrù olóhùn gooro.
Ainsi tout Israël amena l'Arche de l'alliance de l'Eternel, avec de grands cris de joie, et au son du cor, des trompettes et des cymbales, faisant retentir [leur voix] avec des musettes et des violons.
29 Bí àpótí ẹ̀rí Olúwa ti ń wọ ìlú ńlá Dafidi, Mikali ọmọbìnrin Saulu ń wò láti ojú fèrèsé nígbà tí ó sì rí ọba Dafidi ń jó, ó sì ń ṣe àjọyọ̀, ó sì kẹ́gàn rẹ̀ ní ọkàn rẹ̀.
Mais il arriva, comme l'Arche de l'alliance de l'Eternel entrait dans la Cité de David, que Mical fille de Saül, regardant par la fenêtre, vit le Roi David sautant et jouant, et elle le méprisa dans son cœur.

< 1 Chronicles 15 >