< 1 Chronicles 15 >
1 Lẹ́yìn ìgbà tí Dafidi ti kọ́ ilé fún ara rẹ̀ ní ìlú Dafidi. Ó sì fi ààyè sílẹ̀ fún àpótí ẹ̀rí Ọlọ́run ó sì pàgọ́ fún un.
Et il se bâtit des demeures en la ville de David, et il prépara un lieu pour l'arche du Seigneur, et il fit un tabernacle.
2 Nígbà náà Dafidi wí pé, kò sí ẹnìkan àyàfi àwọn ọmọ Lefi ni ó lè gbé àpótí ẹ̀rí Ọlọ́run, nítorí Olúwa yàn wọ́n láti gbé àpótí ẹ̀rí Olúwa àti láti máa ṣe ìránṣẹ́ níwájú rẹ̀ títí láé.
Alors David dit: Nul ne peut transporter l'arche de Dieu, sinon les lévites; car le Seigneur les a choisis pour porter l'arche du Seigneur et le servir éternellement.
3 Dafidi kó gbogbo àwọn ọmọ Israẹli jọ ní Jerusalẹmu láti gbé àpótí ẹ̀rí Olúwa wá sí ibi tí ó ti pèsè sílẹ̀ fún un.
Et David réunit tout le peuple de Jérusalem, pour transporter l'arche au lieu qu'il avait préparé.
4 Wọ̀nyí ni àwọn ọmọ Aaroni àti àwọn ọmọ Lefi tí Dafidi péjọ papọ̀.
David convoqua aussi les lévites, fils d'Aaron.
5 Ọgọ́fà nínú àwọn ọmọ Kohati; Urieli olórí àti àwọn ẹbí rẹ̀.
Des fils de Caath: Uriel leur chef, et ses frères: cent vingt hommes.
6 Igba ó lé ogún nínú àwọn ọmọ Merari; Asaiah olórí àti àwọn ẹbí rẹ̀.
Des fils de Mérari: Asaie leur chef, et ses frères: deux cent vingt.
7 Àádóje nínú àwọn ọmọ Gerṣoni; Joẹli olórí àti àwọn ẹbí rẹ̀.
Des fils de Gerson: Johel leur chef, et ses frères: cent trente.
8 Igba nínú àwọn ọmọ Elisafani; Ṣemaiah olórí àti àwọn ẹbí rẹ̀.
Des fils d'Elisaphat: Sémeï leur chef, et ses frères: deux cents.
9 Ọgọ́rin nínú àwọn ọmọ Hebroni; Elieli olórí àti àwọn ẹbí rẹ̀.
Des fils d'Hébron: Elihel leur chef, et ses frères: quatre-vingts.
10 Méjìléláàádọ́fà nínú àwọn ọmọ Usieli; Amminadabu olórí àti àwọn ẹbí rẹ̀.
Des fils d'Oziel: Aminadab leur chef, et ses frères: cent douze.
11 Dafidi sì ránṣẹ́ pe Sadoku, Abiatari tí wọ́n jẹ́ àlùfáà, àti Urieli, Asaiah. Joẹli, Ṣemaiah, Elieli àti Amminadabu tí wọ́n jẹ́ Lefi.
Et David appela les prêtres Sadoc et Abiathar avec les lévites: Uriel, et Asaïe, et Johel, et Sémeï, et Elihel, et Aminadab,
12 Ó sì fi fún wọn pé, “Ẹ̀yin ni olórí àwọn ìdílé Lefi; ẹ̀yin àti àwọn Lefi ènìyàn yín, ẹ ya ara yín sí mímọ́ kí ẹ lè gbé àpótí ẹ̀rí Olúwa, Ọlọ́run Israẹli, lọ sí ibi tí mó ti pèsè sílẹ̀ fún un.
Et il leur dit: Vous êtes chefs de familles des lévites: purifiez-vous donc, et purifiez vos frères, et vous transporterez l'arche du Dieu d'Israël, au lieu que je lui ai préparé.
13 Nítorí tí ẹ̀yin ọmọ Lefi kò gbe gòkè wá ní ìgbà àkọ́kọ́ ti Olúwa Ọlọ́run fi ìbínú rẹ̀ ko lù wá. Àwa kò sì ṣe ìwádìí lọ́wọ́ rẹ̀ nípa bí a ti ń ṣe é gẹ́gẹ́ bí ọ́nà tí a là sílẹ̀.”
Car, d'abord, parce que vous n'étiez point là; le Seigneur Dieu nous a châtiés, pour ne l'avoir point cherché, selon la loi.
14 Bẹ́ẹ̀ ni àwọn àlùfáà àti àwọn Lefi ya ara wọn sí mímọ́ láti gbé àpótí ẹ̀rí Olúwa gòkè wá, Ọlọ́run Israẹli.
Et les prêtres et les lévites se purifièrent, pour transporter l'arche du Dieu d'Israël.
15 Nígbà náà ni àwọn Lefi gbé àpótí ẹ̀rí Ọlọ́run pẹ̀lú ọ̀pá ní èjìká wọn gẹ́gẹ́ bí Mose ti pa á láṣẹ gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ Olúwa.
Et les fils des lévites prirent l'arche de Dieu de la manière prescrite par Moïse, d'après la parole de Dieu et selon l'Écriture; puis, ils posèrent les leviers sur leurs épaules.
16 Dafidi sọ fún àwọn olórí àwọn Lefi láti yan àwọn arákùnrin wọn gẹ́gẹ́ bí akọrin láti kọ orin ayọ̀, pẹ̀lú àwọn ohun èlò orin olókùn, dùùrù, àti símbálì.
Et David dit aux chefs des lévites: Choisissez parmi vos frères des chantres, s'accompagnant d'instruments: de lyres, de harpes et de cymbales, pour chanter bien haut des cantiques d'allégresse,
17 Bẹ́ẹ̀ ni àwọn Lefi yan Hemani ọmọ Joẹli; àti nínú àwọn arákùnrin rẹ̀, Asafu ọmọ Berekiah, àti nínú àwọn ọmọ Merari arákùnrin wọn, Etani ọmọ Kuṣaiah;
Et les lévites désignèrent Hêman, fils de Johel; puis, Asaph, fils de Barachia, un de leurs frères; puis, Ethan, fils de Cisaïe, un des fils de Mérari, un de leurs frères.
18 àti pẹ̀lú wọn àwọn arákùnrin wọn tí a yàn bí olùrànlọ́wọ́ wọn: Sekariah, Jaasieli, Ṣemiramotu, Jehieli, Unni, Eliabu, Benaiah, Maaseiah, Mattitiah, Elifelehu, Mikimeiah, àti Obedi-Edomu àti Jeieli, àwọn aṣọ́bodè.
Et, avec eux, au second rang, leurs frères Zacharie, Oziel, Semiramoth, Jehiel, Eliohel, Eliab, Banaias, Maasaïe, Matthathias, Eliphena, Macélia, Abdedom, Jehiel et Ozias, qui étaient les portiers.
19 Àwọn akọrin sì ni Hemani, Asafu, àti Etani ti àwọn ti kimbali idẹ tí ń dún kíkan;
Les chantres harpistes: Hêman, Asaph et Ethan, avaient des cymbales d'airain pour les faire retentir.
20 Sekariah, Asieli, Ṣemiramotu, Jehieli, àti Unni, Eliabu, Maaseiah àti Benaiah àwọn tí ó gbọdọ̀ ta ohun èlò orin olókùn gẹ́gẹ́ bí alamoti,
Zacharie et Oziel, Semiramoth, Jéhiel, Oni, Eliab, Maasaïe, Banaïas, avaient des lyres sur l'alcimoth.
21 àti Mattitiah, Elifelehu, Mikneiah, Obedi-Edomu, Jeieli àti Asasiah ni ó ní láti ta ohun èlò olóhùn gooro, láti darí gẹ́gẹ́ bí ṣeminiti.
Et Matthathias, et Eliphalu, et Macélia, et Abdedom, et Jehiel, et Ozias, avaient des harpes pour renforcer l'amasenith.
22 Kenaniah olórí àwọn ará Lefi ni ó wà ní ìkáwọ́ orin èyí sì ni ojúṣe nítorí ó mòye nípa rẹ̀.
Honénias, chef des lévites, était maître du chant, à cause de son intelligence.
23 Berekiah àti Elkana ni kí ó wà gẹ́gẹ́ bí olùṣọ́nà fún àpótí ẹ̀rí.
Barachias et Elcana étaient portiers de l'arche.
24 Ṣebaniah, Jehoṣafati, Netaneli, Amasai, Sekariah, Benaiah àti Elieseri ní àwọn àlùfáà, tí o ń fún ìpè níwájú àpótí ẹ̀rí Ọlọ́run. Obedi-Edomu àti Jehiah ni ó sì gbọdọ̀ jẹ́ olùṣọ́nà fún àpótí ẹ̀rí.
Somnia, Josaphat, Nathanaël Amasaï, Zacharie, Banaïas et Eliézer, les prêtres, sonnaient de la trompette devant l'arche de Dieu. Abdedom et Jehia étaient portiers de l'arche de Dieu.
25 Bẹ́ẹ̀ ni Dafidi àti àwọn àgbàgbà Israẹli àti àwọn olórí ẹgbẹẹgbẹ̀rún lọ láti gbé àpótí ẹ̀rí ti májẹ̀mú Olúwa láti ilé Obedi-Edomu, pẹ̀lú inú dídùn.
David, et les anciens d'Israël et les chefs de mille hommes, partirent ainsi pour transférer l'arche de l'alliance de la maison d'Abdedom, avec allégresse.
26 Nítorí Ọlọ́run tì ràn wọ́n lọ́wọ́ àwọn ará Lefi ẹni tí ó gbé àpótí ẹ̀rí ti májẹ̀mú Olúwa, akọ màlúù méje pẹ̀lú àgbò méje láti fi ṣé ìrúbọ.
Et comme Dieu fortifiait les lévites qui portaient l'arche de l'alliance du Seigneur, on sacrifia devant le cortège sept bœufs et sept béliers.
27 Dafidi sì wọ efodu; aṣọ ìgúnwà ọ̀gbọ̀ dáradára, àti gbogbo àwọn ọmọ Lefi tí ń ru àpótí ẹ̀rí náà, àti àwọn akọrin, àti Kenaniah olórí pẹ̀lú àwọn akọrin. Dafidi sì wọ aṣọ ìgúnwà funfun.
Or, David était revêtu d'une robe de lin, ainsi que tous les lévites qui portaient l'arche de l'alliance du Seigneur, et les chantres-harpistes, et Honénias, maître du chant; David avait comme eux une robe de lin.
28 Bẹ́ẹ̀ ni gbogbo Israẹli gbé àpótí ẹ̀rí àti májẹ̀mú Olúwa gòkè wá pẹ̀lú ariwo, pẹ̀lú àyíká ìhó ayọ̀ àti láti fọn fèrè ti ìpè, àti kimbali, àti láti ta ohun èlò orin olókùn àti dùùrù olóhùn gooro.
Et tout Israël conduisait l'arche de l'alliance du Seigneur, jetant des cris de joie et chantant: les uns au son des trompettes et des cymbales, les autres avec accompagnement de lyres et de harpes.
29 Bí àpótí ẹ̀rí Olúwa ti ń wọ ìlú ńlá Dafidi, Mikali ọmọbìnrin Saulu ń wò láti ojú fèrèsé nígbà tí ó sì rí ọba Dafidi ń jó, ó sì ń ṣe àjọyọ̀, ó sì kẹ́gàn rẹ̀ ní ọkàn rẹ̀.
Lorsque l'arche de l'alliance du Seigneur entra dans la ville de David, Michol, fille de Sain, se penchant à sa fenêtre, vit le roi David danser et toucher de la harpe; et, en son âme, elle le méprisa.