< 1 Chronicles 15 >

1 Lẹ́yìn ìgbà tí Dafidi ti kọ́ ilé fún ara rẹ̀ ní ìlú Dafidi. Ó sì fi ààyè sílẹ̀ fún àpótí ẹ̀rí Ọlọ́run ó sì pàgọ́ fún un.
Il se construisit des maisons dans la Cité de David, appropria un emplacement pour l’arche de Dieu et lui dressa une tente.
2 Nígbà náà Dafidi wí pé, kò sí ẹnìkan àyàfi àwọn ọmọ Lefi ni ó lè gbé àpótí ẹ̀rí Ọlọ́run, nítorí Olúwa yàn wọ́n láti gbé àpótí ẹ̀rí Olúwa àti láti máa ṣe ìránṣẹ́ níwájú rẹ̀ títí láé.
Alors David décida que l’arche de Dieu ne serait portée que par les Lévites, car c’étaient eux que l’Eternel avait choisis pour le transport de l’arche de Dieu et pour son culte à tout jamais.
3 Dafidi kó gbogbo àwọn ọmọ Israẹli jọ ní Jerusalẹmu láti gbé àpótí ẹ̀rí Olúwa wá sí ibi tí ó ti pèsè sílẹ̀ fún un.
Ensuite David convoqua tout Israël à Jérusalem pour transférer l’arche de l’Eternel sur l’emplacement qu’il lui avait préparé.
4 Wọ̀nyí ni àwọn ọmọ Aaroni àti àwọn ọmọ Lefi tí Dafidi péjọ papọ̀.
Il assembla les Aaronides et les Lévites, à savoir:
5 Ọgọ́fà nínú àwọn ọmọ Kohati; Urieli olórí àti àwọn ẹbí rẹ̀.
Des Kehâtites: Ouriël, le chef, et ses frères, au nombre de cent vingt.
6 Igba ó lé ogún nínú àwọn ọmọ Merari; Asaiah olórí àti àwọn ẹbí rẹ̀.
Des Merarites: Assaïa, le chef et ses frères, au nombre de deux cent vingt.
7 Àádóje nínú àwọn ọmọ Gerṣoni; Joẹli olórí àti àwọn ẹbí rẹ̀.
Des Gherchomites: Joël, le chef; et ses frères, au nombre de cent trente.
8 Igba nínú àwọn ọmọ Elisafani; Ṣemaiah olórí àti àwọn ẹbí rẹ̀.
Des Eliçafanites: Chemaïa, le chef, et ses frères, au nombre de deux cents.
9 Ọgọ́rin nínú àwọn ọmọ Hebroni; Elieli olórí àti àwọn ẹbí rẹ̀.
Des Hébronites: Eliël, le chef, et ses frères, au nombre de quatre-vingts.
10 Méjìléláàádọ́fà nínú àwọn ọmọ Usieli; Amminadabu olórí àti àwọn ẹbí rẹ̀.
Des Ouzziélites: Amminadab, le chef, et ses frères au nombre de cent douze.
11 Dafidi sì ránṣẹ́ pe Sadoku, Abiatari tí wọ́n jẹ́ àlùfáà, àti Urieli, Asaiah. Joẹli, Ṣemaiah, Elieli àti Amminadabu tí wọ́n jẹ́ Lefi.
Puis David manda les prêtres Çadok et Ebiatar, et les Lévites Ouriël, Assaïa, Joël, Chemaïa, Eliël et Amminadab,
12 Ó sì fi fún wọn pé, “Ẹ̀yin ni olórí àwọn ìdílé Lefi; ẹ̀yin àti àwọn Lefi ènìyàn yín, ẹ ya ara yín sí mímọ́ kí ẹ lè gbé àpótí ẹ̀rí Olúwa, Ọlọ́run Israẹli, lọ sí ibi tí mó ti pèsè sílẹ̀ fún un.
et il leur dit: "Comme vous êtes les chefs des familles lévitiques, sanctifiez-vous, vous et vos frères, et transportez l’arche de l’Eternel, Dieu d’Israël, à l’endroit que j’ai aménagé pour elle.
13 Nítorí tí ẹ̀yin ọmọ Lefi kò gbe gòkè wá ní ìgbà àkọ́kọ́ ti Olúwa Ọlọ́run fi ìbínú rẹ̀ ko lù wá. Àwa kò sì ṣe ìwádìí lọ́wọ́ rẹ̀ nípa bí a ti ń ṣe é gẹ́gẹ́ bí ọ́nà tí a là sílẹ̀.”
Car c’est à cause de votre absence, la première fois, que l’Eternel, notre Dieu, a opéré des brèches parmi nous, qui ne nous étions pas enquis de lui selon les règles."
14 Bẹ́ẹ̀ ni àwọn àlùfáà àti àwọn Lefi ya ara wọn sí mímọ́ láti gbé àpótí ẹ̀rí Olúwa gòkè wá, Ọlọ́run Israẹli.
Les prêtres et les Lévites se sanctifièrent pour le transfert de l’arche de l’Eternel, Dieu d’Israël.
15 Nígbà náà ni àwọn Lefi gbé àpótí ẹ̀rí Ọlọ́run pẹ̀lú ọ̀pá ní èjìká wọn gẹ́gẹ́ bí Mose ti pa á láṣẹ gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ Olúwa.
Les Lévites portèrent l’arche de Dieu, comme l’avait prescrit Moïse sur l’ordre de l’Eternel, à savoir sur l’épaule, au moyen de barres.
16 Dafidi sọ fún àwọn olórí àwọn Lefi láti yan àwọn arákùnrin wọn gẹ́gẹ́ bí akọrin láti kọ orin ayọ̀, pẹ̀lú àwọn ohun èlò orin olókùn, dùùrù, àti símbálì.
David dit aux chefs des Lévites de mettre en place leurs frères les chantres, muni d’instruments de musique, luths, harpes et cymbales, pour entonner des cantiques, en donnant de toute leur voix en signe de réjouissance.
17 Bẹ́ẹ̀ ni àwọn Lefi yan Hemani ọmọ Joẹli; àti nínú àwọn arákùnrin rẹ̀, Asafu ọmọ Berekiah, àti nínú àwọn ọmọ Merari arákùnrin wọn, Etani ọmọ Kuṣaiah;
En conséquence, les Lévites mirent en place Hêmân, fils de Joël, et, parmi ses parents, Assaph, fils de Bérékhiahou; des Merarites, leurs frères, Etân, fils de Kouchayahou;
18 àti pẹ̀lú wọn àwọn arákùnrin wọn tí a yàn bí olùrànlọ́wọ́ wọn: Sekariah, Jaasieli, Ṣemiramotu, Jehieli, Unni, Eliabu, Benaiah, Maaseiah, Mattitiah, Elifelehu, Mikimeiah, àti Obedi-Edomu àti Jeieli, àwọn aṣọ́bodè.
avec eux, au second rang, leurs frères: Zekhariahou, Bên, Yaaziêl, Chemiramot, Yehiël, Ounni, Elïab, Benaïahou, Maasêyahou, Mattitiahou, Eliflêhou, Miknêyahou, Obed-Edom et Yeïêl, portiers.
19 Àwọn akọrin sì ni Hemani, Asafu, àti Etani ti àwọn ti kimbali idẹ tí ń dún kíkan;
Les chantres Hêmân, Assaph et Etân s’accompagnaient de cymbales de cuivre,
20 Sekariah, Asieli, Ṣemiramotu, Jehieli, àti Unni, Eliabu, Maaseiah àti Benaiah àwọn tí ó gbọdọ̀ ta ohun èlò orin olókùn gẹ́gẹ́ bí alamoti,
Zekhariahou, Aziël, Chemiramot, Yehiël, Ounni, Elïab, Maasêyahou et Benaïahou, de luths à la manière d’Alamoth,
21 àti Mattitiah, Elifelehu, Mikneiah, Obedi-Edomu, Jeieli àti Asasiah ni ó ní láti ta ohun èlò olóhùn gooro, láti darí gẹ́gẹ́ bí ṣeminiti.
Mattitiahou, Eliflêhou, Miknêyahou, Obed-Edom, Yeïêl et Azaziahou de harpes à huit cordes pour conduire le chœur.
22 Kenaniah olórí àwọn ará Lefi ni ó wà ní ìkáwọ́ orin èyí sì ni ojúṣe nítorí ó mòye nípa rẹ̀.
Kenaniahou, chef lévitique, préposé aux transports, commandait le transport, car il s’y entendait.
23 Berekiah àti Elkana ni kí ó wà gẹ́gẹ́ bí olùṣọ́nà fún àpótí ẹ̀rí.
Bérékhia et Elkana étaient portiers pour garder l’arche.
24 Ṣebaniah, Jehoṣafati, Netaneli, Amasai, Sekariah, Benaiah àti Elieseri ní àwọn àlùfáà, tí o ń fún ìpè níwájú àpótí ẹ̀rí Ọlọ́run. Obedi-Edomu àti Jehiah ni ó sì gbọdọ̀ jẹ́ olùṣọ́nà fún àpótí ẹ̀rí.
Les prêtres Chebaniahou, Yochafat, Nethanêl, Amassaï, Zekhariahou, Benaïahou et Eliézer jouaient de la trompette devant l’arche de Dieu. Obed-Edom et Yehiya étaient portiers pour garder l’arche.
25 Bẹ́ẹ̀ ni Dafidi àti àwọn àgbàgbà Israẹli àti àwọn olórí ẹgbẹẹgbẹ̀rún lọ láti gbé àpótí ẹ̀rí ti májẹ̀mú Olúwa láti ilé Obedi-Edomu, pẹ̀lú inú dídùn.
David, les anciens d’Israël et les chefs de mille, qui marchaient en cortège pour transporter l’arche de l’alliance de l’Eternel depuis la maison d’Obed-Edom, étaient dans la joie.
26 Nítorí Ọlọ́run tì ràn wọ́n lọ́wọ́ àwọn ará Lefi ẹni tí ó gbé àpótí ẹ̀rí ti májẹ̀mú Olúwa, akọ màlúù méje pẹ̀lú àgbò méje láti fi ṣé ìrúbọ.
Comme Dieu assistait les Lévites porteurs de l’arche d’alliance de l’Eternel, on immola sept taureaux et sept béliers.
27 Dafidi sì wọ efodu; aṣọ ìgúnwà ọ̀gbọ̀ dáradára, àti gbogbo àwọn ọmọ Lefi tí ń ru àpótí ẹ̀rí náà, àti àwọn akọrin, àti Kenaniah olórí pẹ̀lú àwọn akọrin. Dafidi sì wọ aṣọ ìgúnwà funfun.
David était revêtu d’un surplis de byssus, ainsi que tous les Lévites qui portaient l’arche, les chantres et Kenania, chef des transports (les chantres). David était paré, en outre, d’un éphod de lin.
28 Bẹ́ẹ̀ ni gbogbo Israẹli gbé àpótí ẹ̀rí àti májẹ̀mú Olúwa gòkè wá pẹ̀lú ariwo, pẹ̀lú àyíká ìhó ayọ̀ àti láti fọn fèrè ti ìpè, àti kimbali, àti láti ta ohun èlò orin olókùn àti dùùrù olóhùn gooro.
Tout Israël faisait cortège au transfert de l’arche d’alliance de l’Eternel, avec des cris de joie, au son du Chofar, des trompettes et des cymbales, ou jouant de la lyre et de la harpe.
29 Bí àpótí ẹ̀rí Olúwa ti ń wọ ìlú ńlá Dafidi, Mikali ọmọbìnrin Saulu ń wò láti ojú fèrèsé nígbà tí ó sì rí ọba Dafidi ń jó, ó sì ń ṣe àjọyọ̀, ó sì kẹ́gàn rẹ̀ ní ọkàn rẹ̀.
C’Est ainsi que l’arche d’alliance de l’Eternel arriva à la Cité de David. Mikhal, fille de Saül, regardait alors par la fenêtre. Voyant le roi David sautant et dansant, elle en conçut du dédain pour lui.

< 1 Chronicles 15 >