< 1 Chronicles 14 >
1 Nísinsin yìí Hiramu àti ọba Tire rán oníṣẹ́ sí Dafidi, àti pẹ̀lú igi kedari pẹ̀lú àwọn ọ̀mọ̀lé àti gbẹ́nàgbẹ́nà láti kọ́ ààfin fún un.
Potem Hiram, król Tyru, wysłał posłów do Dawida wraz z drewnem cedrowym, murarzami i cieślami, aby mu zbudowali dom.
2 Dafidi sì mọ Israẹli àti pé Olúwa ti fi òun ṣe ọba lórí Israẹli àti pé ìjọba rẹ̀ ga jùlọ nítorí ti àwọn ènìyàn rẹ̀.
I Dawid poznał, że PAN potwierdził jego królowanie nad Izraelem, gdyż wywyższył jego królestwo ze względu na swój lud Izraela.
3 Ní Jerusalẹmu Dafidi mú ọ̀pọ̀ ìyàwó ó sì di baba àwọn ọmọ ọkùnrin púpọ̀ àti ọmọbìnrin.
Dawid pojął więcej żon w Jerozolimie i spłodził więcej synów i córek.
4 Èyí ni orúkọ àwọn ọmọ náà tí wọ́n bí fún un níbẹ̀: Ṣammua, Ṣobabu, Natani, Solomoni,
A oto imiona tych, którzy mu się urodzili w Jerozolimie: Szammua, Szobab, Natan, Salomon;
5 Ibhari, Eliṣua, Elifeleti,
Jibchar, Eliszua, Elpalet;
7 Eliṣama, Beeliada, àti Elifeleti.
Eliszama, Beeliada i Elifelet.
8 Nígbà tí àwọn ará Filistini gbọ́ pé a ti fi àmì òróró yàn Dafidi ní ọba lórí gbogbo Israẹli, wọ́n sì lọ sókè pẹ̀lú ipá láti wá a rí, ṣùgbọ́n Dafidi gbọ́ nípa rẹ̀ ó sì jáde lọ láti pàdé wọn.
Kiedy Filistyni usłyszeli, że Dawid został namaszczony na króla nad całym Izraelem, wszyscy Filistyni wyruszyli, aby go szukać. Gdy Dawid usłyszał o tym, wyszedł naprzeciw nich.
9 Nísinsin yìí àwọn ará Filistini ti wá láti gbógun ti àfonífojì Refaimu;
Filistyni przybyli i rozciągnęli się w dolinie Refaim.
10 Dafidi sì béèrè lọ́dọ̀ Ọlọ́run wí pé, “Kí èmi kí ó gòkè tọ àwọn ará Filistini lọ bí? Ìwọ ó ha fi wọ́n lé mi lọ́wọ́?” Olúwa sì wí fún un pé, “Gòkè lọ èmi ó sì fi wọ́n lé ọ lọ́wọ́.”
I Dawid radził się Boga, mówiąc: Czy mam wyruszyć przeciw Filistynom i czy wydasz ich w moje ręce? PAN mu odpowiedział: Wyruszaj, a wydam ich w twoje ręce.
11 Bẹ́ẹ̀ ni Dafidi àti àwọn ènìyàn rẹ̀ gòkè lọ sí Baali-Perasimu, níbẹ̀ ó sì kọlù wọ́n. Ó sí wí pé, “Gẹ́gẹ́ bí omi tí ya jáde, Ọlọ́run ti ya Dafidi lórí àwọn ọ̀tá mi pẹ̀lú ọwọ́ mi.” Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n sì ń pè ibẹ̀ ní Baali-Perasimu.
A gdy przybyli do Baal-Perasim, tam Dawid ich pobił. Wtedy Dawid powiedział: Bóg rozerwał moich wrogów przez moją rękę, jak rozrywają się wody. Dlatego nazwał to miejsce Baal-Perasim.
12 Àwọn ará Filistini sì ti fi àwọn òrìṣà wọn sílẹ̀ níbẹ̀. Dafidi sì pa á láṣẹ láti jó wọn nínú iná.
I porzucili tam swoje bożki, a Dawid rozkazał spalić je ogniem.
13 Lẹ́ẹ̀kan sí i àwọn ará Filistini gbógun wọ́n sì fọ́nká àfonífojì,
Lecz Filistyni znowu rozciągnęli się w dolinie.
14 Bẹ́ẹ̀ ni Dafidi sì tún béèrè lọ́wọ́ Ọlọ́run, Ọlọ́run sì dalóhùn pé, “Má ṣe gòkè tààrà, ṣùgbọ́n ẹ yí wọn ká, kí ẹ sì mú wọn níwájú igi muliberi.
Dawid więc ponownie radził się Boga, a Bóg mu odpowiedział: Nie ruszaj na nich, ale odwróć się od nich, abyś natarł na nich od strony drzew morwowych.
15 Tí ó bá sì ṣe, tí ẹ̀yin bá ti gbọ́ ìró ẹsẹ̀ ní orí òkè igi muliberi, ẹ jáde fún ogun, nítorí èyí yóò fihàn pé Ọlọ́run ti jáde níwájú rẹ láti kọlu àwọn ọmọ-ogun Filistini.”
A gdy usłyszysz odgłos kroków wśród wierzchołków drzew morwowych, wtedy wyruszysz do bitwy, gdyż Bóg wyruszył przed tobą, aby pobić wojska Filistynów.
16 Bẹ́ẹ̀ ni Dafidi ṣe ohun tí Ọlọ́run ti pàṣẹ fún wọn, wọ́n sì kọlu àwọn ọmọ-ogun Filistini láti gbogbo ọ̀nà Gibeoni lọ sí Geseri.
I Dawid uczynił tak, jak mu rozkazał Bóg, i pobili wojska Filistynów od Gibeonu aż do Gezer.
17 Bẹ́ẹ̀ ni òkìkí Dafidi tàn ká gbogbo ilẹ̀ káàkiri, Olúwa sì mú kí gbogbo orílẹ̀-èdè bẹ̀rù rẹ̀.
I w ten sposób rozsławiło się imię Dawida na wszystkich ziemiach, a PAN sprawił, że bały się go wszystkie narody.