< 1 Chronicles 14 >

1 Nísinsin yìí Hiramu àti ọba Tire rán oníṣẹ́ sí Dafidi, àti pẹ̀lú igi kedari pẹ̀lú àwọn ọ̀mọ̀lé àti gbẹ́nàgbẹ́nà láti kọ́ ààfin fún un.
UHiramu inkosi yeTire wasethuma izithunywa kuDavida, lezigodo zemisedari lababazi bamatshe lababazi bezigodo ukumakhela indlu.
2 Dafidi sì mọ Israẹli àti pé Olúwa ti fi òun ṣe ọba lórí Israẹli àti pé ìjọba rẹ̀ ga jùlọ nítorí ti àwọn ènìyàn rẹ̀.
UDavida wasesazi ukuthi iNkosi yayimmisile ukuthi abe yinkosi phezu kukaIsrayeli, ngoba umbuso wakhe wawuphakanyiselwe phezulu ngenxa yabantu bayo uIsrayeli.
3 Ní Jerusalẹmu Dafidi mú ọ̀pọ̀ ìyàwó ó sì di baba àwọn ọmọ ọkùnrin púpọ̀ àti ọmọbìnrin.
UDavida wasethatha abanye abafazi eJerusalema; uDavida wasezala amanye amadodana lamadodakazi.
4 Èyí ni orúkọ àwọn ọmọ náà tí wọ́n bí fún un níbẹ̀: Ṣammua, Ṣobabu, Natani, Solomoni,
Lala ngamabizo abantwana aba labo eJerusalema: OShamuwa, loShobabi, uNathani, loSolomoni,
5 Ibhari, Eliṣua, Elifeleti,
loIbihari, loElishuwa, loEliphaleti,
6 Noga, Nefegi, Jafia,
loNoga, loNefegi, loJafiya,
7 Eliṣama, Beeliada, àti Elifeleti.
loElishama, loBeyeliyada, loElifaleti.
8 Nígbà tí àwọn ará Filistini gbọ́ pé a ti fi àmì òróró yàn Dafidi ní ọba lórí gbogbo Israẹli, wọ́n sì lọ sókè pẹ̀lú ipá láti wá a rí, ṣùgbọ́n Dafidi gbọ́ nípa rẹ̀ ó sì jáde lọ láti pàdé wọn.
AmaFilisti esezwile ukuthi uDavida ugcotshiwe ukuthi abe yinkosi phezu kukaIsrayeli wonke, wonke amaFilisti enyuka ukudinga uDavida; uDavida ekuzwa waphuma ukuyamelana lawo.
9 Nísinsin yìí àwọn ará Filistini ti wá láti gbógun ti àfonífojì Refaimu;
AmaFilisti asefika azisabalalisa esihotsheni seRefayimi.
10 Dafidi sì béèrè lọ́dọ̀ Ọlọ́run wí pé, “Kí èmi kí ó gòkè tọ àwọn ará Filistini lọ bí? Ìwọ ó ha fi wọ́n lé mi lọ́wọ́?” Olúwa sì wí fún un pé, “Gòkè lọ èmi ó sì fi wọ́n lé ọ lọ́wọ́.”
UDavida wasebuza kuNkulunkulu esithi: Ngenyukele yini kumaFilisti? Uzawanikela esandleni sami yini? INkosi yasisithi kuye: Yenyuka, ngoba ngizawanikela esandleni sakho.
11 Bẹ́ẹ̀ ni Dafidi àti àwọn ènìyàn rẹ̀ gòkè lọ sí Baali-Perasimu, níbẹ̀ ó sì kọlù wọ́n. Ó sí wí pé, “Gẹ́gẹ́ bí omi tí ya jáde, Ọlọ́run ti ya Dafidi lórí àwọn ọ̀tá mi pẹ̀lú ọwọ́ mi.” Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n sì ń pè ibẹ̀ ní Baali-Perasimu.
Basebesenyukela eBhali-Perazimi, uDavida wawatshaya lapho; uDavida wasesithi: UNkulunkulu ufohlele ezitheni zami ngesandla sami njengokufohla kwamanzi. Ngenxa yalokhu babiza leyondawo ngokuthi yiBhali-Perazimi.
12 Àwọn ará Filistini sì ti fi àwọn òrìṣà wọn sílẹ̀ níbẹ̀. Dafidi sì pa á láṣẹ láti jó wọn nínú iná.
Asetshiya onkulunkulu bawo lapho, uDavida wasesithi kabatshiswe ngomlilo.
13 Lẹ́ẹ̀kan sí i àwọn ará Filistini gbógun wọ́n sì fọ́nká àfonífojì,
AmaFilisti asebuya ezisabalalisa esihotsheni futhi.
14 Bẹ́ẹ̀ ni Dafidi sì tún béèrè lọ́wọ́ Ọlọ́run, Ọlọ́run sì dalóhùn pé, “Má ṣe gòkè tààrà, ṣùgbọ́n ẹ yí wọn ká, kí ẹ sì mú wọn níwájú igi muliberi.
Lapho uDavida ebuza futhi kuNkulunkulu, uNkulunkulu wathi kuye: Ungenyukeli ngemva kwawo, agombolozele usuka kiwo, uze kuwo maqondana lezihlahla zebhalisamu.
15 Tí ó bá sì ṣe, tí ẹ̀yin bá ti gbọ́ ìró ẹsẹ̀ ní orí òkè igi muliberi, ẹ jáde fún ogun, nítorí èyí yóò fihàn pé Ọlọ́run ti jáde níwájú rẹ láti kọlu àwọn ọmọ-ogun Filistini.”
Kuzakuthi-ke lapho usizwa umsindo wokuhamba ezihlokweni zezihlahla zebhalisamu, ubusuphumela empini, ngoba uNkulunkulu uzabe esephume phambi kwakho ukutshaya ibutho lamaFilisti.
16 Bẹ́ẹ̀ ni Dafidi ṣe ohun tí Ọlọ́run ti pàṣẹ fún wọn, wọ́n sì kọlu àwọn ọmọ-ogun Filistini láti gbogbo ọ̀nà Gibeoni lọ sí Geseri.
Ngakho uDavida wenza njengoba uNkulunkulu emlayile; basebetshaya ibutho lamaFilisti kusukela eGibeyoni kwaze kwaba seGezeri.
17 Bẹ́ẹ̀ ni òkìkí Dafidi tàn ká gbogbo ilẹ̀ káàkiri, Olúwa sì mú kí gbogbo orílẹ̀-èdè bẹ̀rù rẹ̀.
Njalo ibizo likaDavida laphumela kuwo wonke amazwe; iNkosi yasibeka ukwesabeka kwakhe phezu kwazo zonke izizwe.

< 1 Chronicles 14 >