< 1 Chronicles 14 >
1 Nísinsin yìí Hiramu àti ọba Tire rán oníṣẹ́ sí Dafidi, àti pẹ̀lú igi kedari pẹ̀lú àwọn ọ̀mọ̀lé àti gbẹ́nàgbẹ́nà láti kọ́ ààfin fún un.
Hiram, roi de Tyr, envoya des messagers à David, avec du bois de cèdre, ainsi que des tailleurs de pierres et des charpentiers, pour lui bâtir une maison.
2 Dafidi sì mọ Israẹli àti pé Olúwa ti fi òun ṣe ọba lórí Israẹli àti pé ìjọba rẹ̀ ga jùlọ nítorí ti àwọn ènìyàn rẹ̀.
Et David reconnut que Yahweh l’affermissait comme roi sur Israël, car son royaume était haut élevé, à cause de son peuple d’Israël.
3 Ní Jerusalẹmu Dafidi mú ọ̀pọ̀ ìyàwó ó sì di baba àwọn ọmọ ọkùnrin púpọ̀ àti ọmọbìnrin.
David prit encore des femmes à Jérusalem et il engendra encore des fils et des filles.
4 Èyí ni orúkọ àwọn ọmọ náà tí wọ́n bí fún un níbẹ̀: Ṣammua, Ṣobabu, Natani, Solomoni,
Voici les noms des enfants qu’il eut à Jérusalem: Samua, Sobad, Nathan, Salomon,
5 Ibhari, Eliṣua, Elifeleti,
Jébahar, Elisua, Eliphalet,
7 Eliṣama, Beeliada, àti Elifeleti.
Elisama, Baaiada et Eliphalet.
8 Nígbà tí àwọn ará Filistini gbọ́ pé a ti fi àmì òróró yàn Dafidi ní ọba lórí gbogbo Israẹli, wọ́n sì lọ sókè pẹ̀lú ipá láti wá a rí, ṣùgbọ́n Dafidi gbọ́ nípa rẹ̀ ó sì jáde lọ láti pàdé wọn.
Les Philistins apprirent que David avait été oint pour roi sur tout Israël; alors tous les Philistins montèrent pour rechercher David. David l’apprit, et il sortit au-devant d’eux.
9 Nísinsin yìí àwọn ará Filistini ti wá láti gbógun ti àfonífojì Refaimu;
Les Philistins, étant venus, se précipitèrent dans la vallée des Rephaïm.
10 Dafidi sì béèrè lọ́dọ̀ Ọlọ́run wí pé, “Kí èmi kí ó gòkè tọ àwọn ará Filistini lọ bí? Ìwọ ó ha fi wọ́n lé mi lọ́wọ́?” Olúwa sì wí fún un pé, “Gòkè lọ èmi ó sì fi wọ́n lé ọ lọ́wọ́.”
David consulta Dieu, en disant: « Monterai-je contre les Philistins? Les livrerez-vous entre mes mains? « Et Yahweh lui dit: « Monte, et je les livrerai entre tes mains. »
11 Bẹ́ẹ̀ ni Dafidi àti àwọn ènìyàn rẹ̀ gòkè lọ sí Baali-Perasimu, níbẹ̀ ó sì kọlù wọ́n. Ó sí wí pé, “Gẹ́gẹ́ bí omi tí ya jáde, Ọlọ́run ti ya Dafidi lórí àwọn ọ̀tá mi pẹ̀lú ọwọ́ mi.” Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n sì ń pè ibẹ̀ ní Baali-Perasimu.
Ils montèrent à Baal-Pharasim, et là David les battit. Et David dit: « Dieu a brisé mes ennemis par ma main, comme les eaux brisent les digues. « C’est pourquoi on a donné à ce lieu le nom de Baal-Pharasim.
12 Àwọn ará Filistini sì ti fi àwọn òrìṣà wọn sílẹ̀ níbẹ̀. Dafidi sì pa á láṣẹ láti jó wọn nínú iná.
Ils laissèrent là leurs dieux. Et David dit qu’on les livre au feu.
13 Lẹ́ẹ̀kan sí i àwọn ará Filistini gbógun wọ́n sì fọ́nká àfonífojì,
Les Philistins se précipitèrent de nouveau dans la vallée.
14 Bẹ́ẹ̀ ni Dafidi sì tún béèrè lọ́wọ́ Ọlọ́run, Ọlọ́run sì dalóhùn pé, “Má ṣe gòkè tààrà, ṣùgbọ́n ẹ yí wọn ká, kí ẹ sì mú wọn níwájú igi muliberi.
David consulta encore Dieu, et Dieu lui dit: « Ne monte pas après eux; détourne-toi d’eux, et tu arriveras sur eux du côté des balsamiers.
15 Tí ó bá sì ṣe, tí ẹ̀yin bá ti gbọ́ ìró ẹsẹ̀ ní orí òkè igi muliberi, ẹ jáde fún ogun, nítorí èyí yóò fihàn pé Ọlọ́run ti jáde níwájú rẹ láti kọlu àwọn ọmọ-ogun Filistini.”
Quand tu entendras un bruit de pas dans les cimes des balsamiers, alors tu sortiras pour combattre, car Dieu sortira devant toi pour battre l’armée des Philistins. »
16 Bẹ́ẹ̀ ni Dafidi ṣe ohun tí Ọlọ́run ti pàṣẹ fún wọn, wọ́n sì kọlu àwọn ọmọ-ogun Filistini láti gbogbo ọ̀nà Gibeoni lọ sí Geseri.
David fit comme Dieu le lui ordonnait, et ils battirent l’armée des Philistins depuis Gabaon jusqu’à Gazer.
17 Bẹ́ẹ̀ ni òkìkí Dafidi tàn ká gbogbo ilẹ̀ káàkiri, Olúwa sì mú kí gbogbo orílẹ̀-èdè bẹ̀rù rẹ̀.
La renommée de David se répandit dans tous les pays, et Yahweh le fit craindre à toutes les nations.