< 1 Chronicles 14 >
1 Nísinsin yìí Hiramu àti ọba Tire rán oníṣẹ́ sí Dafidi, àti pẹ̀lú igi kedari pẹ̀lú àwọn ọ̀mọ̀lé àti gbẹ́nàgbẹ́nà láti kọ́ ààfin fún un.
And Iram, the kyng of Tyre, sente messageris to Dauid, and `he sente trees of cedre, and werk men of wallis and of trees, that thei schulden bilde to hym an hows.
2 Dafidi sì mọ Israẹli àti pé Olúwa ti fi òun ṣe ọba lórí Israẹli àti pé ìjọba rẹ̀ ga jùlọ nítorí ti àwọn ènìyàn rẹ̀.
And Dauid knewe that the Lord hadde confermyd hym in to kyng on Israel; and that his rewme was reisid on his puple Israel.
3 Ní Jerusalẹmu Dafidi mú ọ̀pọ̀ ìyàwó ó sì di baba àwọn ọmọ ọkùnrin púpọ̀ àti ọmọbìnrin.
And Dauid took othere wyues in Jerusalem, and gendride sones and douytris.
4 Èyí ni orúkọ àwọn ọmọ náà tí wọ́n bí fún un níbẹ̀: Ṣammua, Ṣobabu, Natani, Solomoni,
And these ben the names of hem that weren borun to hym in Jerusalem; Sammu, and Sobab, Nathan, and Salomon,
5 Ibhari, Eliṣua, Elifeleti,
Jeber, and Elisu, and Heli, and Eliphalech,
and Noga, and Napheg, and Japhie,
7 Eliṣama, Beeliada, àti Elifeleti.
and Elisama, and Baliada, and Eliphelech.
8 Nígbà tí àwọn ará Filistini gbọ́ pé a ti fi àmì òróró yàn Dafidi ní ọba lórí gbogbo Israẹli, wọ́n sì lọ sókè pẹ̀lú ipá láti wá a rí, ṣùgbọ́n Dafidi gbọ́ nípa rẹ̀ ó sì jáde lọ láti pàdé wọn.
Forsothe the Filisteis herden that Dauid was anoyntid `in to kyng on al Israel, and alle stieden to seke Dauid. And whanne Dauid hadde herd this thing, he yede out ayens hem.
9 Nísinsin yìí àwọn ará Filistini ti wá láti gbógun ti àfonífojì Refaimu;
Forsothe Filisteis camen, and weren spred abrood in the valey of Raphaym;
10 Dafidi sì béèrè lọ́dọ̀ Ọlọ́run wí pé, “Kí èmi kí ó gòkè tọ àwọn ará Filistini lọ bí? Ìwọ ó ha fi wọ́n lé mi lọ́wọ́?” Olúwa sì wí fún un pé, “Gòkè lọ èmi ó sì fi wọ́n lé ọ lọ́wọ́.”
and Dauid counselide the Lord, and seide, Whether Y schal stie to Filisteis? and whether thou schalt bitake hem in to myn hondis? And the Lord seide to hym, Stie thou, and Y schal bitake hem in thin hond.
11 Bẹ́ẹ̀ ni Dafidi àti àwọn ènìyàn rẹ̀ gòkè lọ sí Baali-Perasimu, níbẹ̀ ó sì kọlù wọ́n. Ó sí wí pé, “Gẹ́gẹ́ bí omi tí ya jáde, Ọlọ́run ti ya Dafidi lórí àwọn ọ̀tá mi pẹ̀lú ọwọ́ mi.” Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n sì ń pè ibẹ̀ ní Baali-Perasimu.
And whanne thei hadden styed in to Baal Pharasym, Dauid smoot hem there, and seide, God hath departid myn enemyes bi myn hond, as watris ben departid. And therfor the name of that place was clepid Baal Pharasym; and thei leften there her goddis,
12 Àwọn ará Filistini sì ti fi àwọn òrìṣà wọn sílẹ̀ níbẹ̀. Dafidi sì pa á láṣẹ láti jó wọn nínú iná.
which Dauid comaundide to be brent.
13 Lẹ́ẹ̀kan sí i àwọn ará Filistini gbógun wọ́n sì fọ́nká àfonífojì,
Forsothe another tyme Filisteis felden in, and weren spred abrood in the valei;
14 Bẹ́ẹ̀ ni Dafidi sì tún béèrè lọ́wọ́ Ọlọ́run, Ọlọ́run sì dalóhùn pé, “Má ṣe gòkè tààrà, ṣùgbọ́n ẹ yí wọn ká, kí ẹ sì mú wọn níwájú igi muliberi.
and eft Dauid counseilide the Lord, and the Lord seide to hym, Thou schalt not stie aftir hem; go awei fro hem, and thou schalt come ayens hem euen ayens the pere trees.
15 Tí ó bá sì ṣe, tí ẹ̀yin bá ti gbọ́ ìró ẹsẹ̀ ní orí òkè igi muliberi, ẹ jáde fún ogun, nítorí èyí yóò fihàn pé Ọlọ́run ti jáde níwájú rẹ láti kọlu àwọn ọmọ-ogun Filistini.”
And whanne thou schalt here the sowun of a goere in the cop of the pere trees, thanne thou schalt go out to batel; for the Lord is go out byfor thee, to smyte the castels of Filisteis.
16 Bẹ́ẹ̀ ni Dafidi ṣe ohun tí Ọlọ́run ti pàṣẹ fún wọn, wọ́n sì kọlu àwọn ọmọ-ogun Filistini láti gbogbo ọ̀nà Gibeoni lọ sí Geseri.
Therfor Dauid dide as God comaundide to hym, and he smoot the castels of Filisteis fro Gabaon `til to Gazara.
17 Bẹ́ẹ̀ ni òkìkí Dafidi tàn ká gbogbo ilẹ̀ káàkiri, Olúwa sì mú kí gbogbo orílẹ̀-èdè bẹ̀rù rẹ̀.
And the name of Dauid was puplischid in alle cuntreis, and the Lord yaf his drede on alle folkis.