< 1 Chronicles 12 >
1 Àwọn wọ̀nyí ni ọkùnrin tí ó wá sí ọ̀dọ̀ Dafidi ní Siklagi, nígbà tí ó sá kúrò níwájú Saulu ọmọ Kiṣi (wọ́n wà lára àwọn jagunjagun ẹni tí ó ràn án lọ́wọ́ láti ibi ìjà.
Aya nĩo andũ arĩa mookire kũrĩ Daudi arĩ kũu Zikilagi, hĩndĩ ĩrĩa aaingatĩtwo akehera maitho-inĩ ma Saũlũ mũrũ wa Kishu (maarĩ amwe a njamba cia ita iria ciamũteithirie mbaara-inĩ;
2 Wọ́n sì mú wọn pẹ̀lú ìtẹríba wọ́n sì lágbára láti ta ọfà tàbí láti ta kànnàkànnà òkúta ní ọwọ́ òsì tàbí ní ọwọ́ ọ̀tún, wọ́n sì jẹ́ ìbátan ọkùnrin Saulu láti ẹ̀yà Benjamini):
Nao maakuuaga mota na nĩmooĩ gũikia mĩguĩ, na gũikia mahiga na kĩgũtha, na guoko kwa ũrĩo kana kwa ũmotho; maarĩ a mbarĩ ĩmwe na Saũlũ kuuma mũhĩrĩga wa Benjamini), nao maarĩ:
3 Ahieseri olórí wọn àti Joaṣi àwọn ọmọ Ṣemaah ará Gibeah: Jeṣieli àti Peleti ọmọ Asmafeti, Beraka, Jehu ará Anatoti.
Ahiezeri ũrĩa warĩ mũnene wao na Joashu, ariũ a Shemaa ũrĩa Mũgibea; na Jezieli, na Peleti, ariũ a Azimavethu; na Beraka, na Jehu ũrĩa Mũanathothu,
4 Àti Iṣmaiah ará Gibeoni, ọkùnrin alágbára kan lára àwọn ọgbọ̀n ẹni tí ó jẹ́ olórí nínú àwọn ọgbọ̀n; Jeremiah, Jahasieli, Johanani, Josabadi ará Gedera,
na Ishimaia ũrĩa Mũgibeoni, mũndũ warĩ njamba thĩinĩ wa andũ arĩa Mĩrongo Ĩtatũ, nake aarĩ mũtongoria ũmwe thĩinĩ wa acio Mĩrongo Ĩtatũ; na Jeremia, na Jahazieli, na Johanani, na Jozabadu ũrĩa Mũgederathi,
5 Elusai, Jerimoti, Bealiah, Ṣemariah àti Ṣefatia ará Harufiti;
na Eluzai, na Jerimothu, na Bealia, na Shemaria, na Shefatia ũrĩa Mũharufi;
6 Elkana, Iṣiah, Asareeli, Joeseri àti Jaṣobeamu ará Kora;
na Elikana, na Ishia, na Azareli, na Joezeru, na Jashobeamu arĩa maarĩ a mbarĩ ya Kora;
7 àti Joẹla, àti Sebadiah àwọn ọmọ Jerohamu láti Gedori.
na Joela, na Zebadia, ariũ a Jerohamu kuuma Gedori.
8 Díẹ̀ lára àwọn ará Gadi yà sọ́dọ̀ Dafidi ní ibi gíga ní aginjù. Wọ́n sì jẹ́ onígboyà ológun tí ó múra fún ogun tí ó sì lágbára láti di asà àti ẹṣin mú. Ojú wọn sì dàbí ojú kìnnìún, wọ́n sì yára bí àgbọ̀nrín lórí àwọn òkè.
Agadi amwe nĩmagarũrũkire magĩcooka mwena wa Daudi o kũu werũ-inĩ kĩĩhitho-inĩ gĩake. Maarĩ njamba cia ita irĩ ũrũme ciehaarĩirie gũthiĩ mbaara, na nĩmooĩ kũhũthĩra ngo na itimũ. Mothiũ mao maahaanaga ta mothiũ ma mĩrũũthi, na maarĩ ihenya ta thwariga irĩ irĩma-inĩ.
9 Eseri sì jẹ́ ìjòyè, Obadiah sì jẹ́ igbákejì akọgun, Eliabu ẹlẹ́ẹ̀kẹta,
Ezeri nĩwe warĩ mũnene wao, na Obadia aarĩ mũnini wake; nake Eliabu aarĩ wa gatatũ,
10 Miṣimana ẹlẹ́ẹ̀kẹrin, Jeremiah ẹlẹ́ẹ̀karùnún
na Mishimana aarĩ wa kana, na Jeremia aarĩ wa gatano,
11 Attai ẹlẹ́ẹ̀kẹfà, Elieli èkeje,
na Atai aarĩ wa gatandatũ, na Elieli aarĩ wa mũgwanja,
12 Johanani ẹlẹ́ẹ̀kẹjọ Elsabadi ẹlẹ́ẹ̀kẹsàn-án
na Johanani aarĩ wa kanana, na Elizabadu aarĩ wa kenda,
13 Jeremiah ẹlẹ́ẹ̀kẹwàá àti Makbannai ẹlẹ́ẹ̀kọkànlá.
na Jeremia aarĩ wa ikũmi, na Makabanai aarĩ wa ikũmi na ũmwe.
14 Àwọn ará Gadi wọ́n sì jẹ́ olórí ogun; ẹni tí ó kéré jù sì jẹ́ àpapọ̀ ọgọ́rùn-ún, àti fún ẹni tí ó pọ̀jù fún ẹgbẹ̀rún.
Agadi acio maarĩ anene a mbũtũ cia ita; ũrĩa warĩ mũnini mũno wao aarũaga mbaara ĩrĩa ĩngĩarũirwo nĩ andũ igana, nake ũrĩa warĩ mũnene mũno wao aarũaga mbaara ĩrĩa ĩngĩarũirwo nĩ andũ ngiri ĩmwe.
15 Àwọn ni ẹni tí ó rékọjá Jordani ní oṣù àkọ́kọ́ nígbà tí ó kún bo gbogbo bèbè rẹ̀, wọ́n sì lé gbogbo àwọn tí ó ń gbé nínú àfonífojì, lọ sí ìlà-oòrùn àti níhà ìwọ̀-oòrùn.
Nĩo maaringire Rũũĩ rwa Jorodani mweri wa mbere rĩrĩa rwaiyũrĩte nginya rũkoina hũgũrũrũ ciaruo ciothe, na makĩingatithia andũ arĩa othe maaikaraga cianda-inĩ cia mwena wa irathĩro na mwena wa ithũĩro.
16 Ìyókù ará Benjamini àti àwọn díẹ̀ ọkùnrin láti Juda lọ sí ọ̀dọ̀ Dafidi ní ibi gíga.
Andũ amwe a kuuma Benjamini na angĩ a kuuma Juda o nao magĩũka kũrĩ Daudi kũu kĩĩhitho-inĩ gĩake.
17 Dafidi sì lọ láti lọ pàdé wọn ó sì wí fún wọn pé, “Tí ẹ bá wá sọ́dọ̀ mi lálàáfíà, láti ràn mí lọ́wọ́ mo ṣetán láti mú un yín wà ní ìṣọ̀kan pẹ̀lú mi ṣùgbọ́n tí ẹ bá wá láti dá mi sí fún àwọn ọ̀tá mi nígbà tí ọwọ́ mi bá mọ́ kúrò nínú ìwà agbára, kí Ọlọ́run àwọn baba wa kí ó sì ri kí ó sì ṣe ìdájọ́.”
Daudi agĩthiĩ kũmatũnga, akĩmeera atĩrĩ, “Angĩkorwo mũrooka kũrĩ niĩ na thayũ kũndeithia-rĩ, nĩndĩhaarĩirie kũmwamũkĩra tũtuĩke kĩndũ kĩmwe; no angĩkorwo mũũkĩte kũngunyanĩra kũrĩ thũ ciakwa o rĩrĩa itarenda haaro-rĩ, Ngai wa maithe maitũ arorora ũndũ ũcio na amũtuĩre ciira.”
18 Nígbà náà Ẹ̀mí Mímọ́ wa sórí Amasai ìjòyè àwọn ọgbọ̀n, ó sì wí pé, “Tìrẹ ni àwa ń ṣe, ìwọ Dafidi! Àwa pẹ̀lú rẹ, ìwọ ọmọ Jese! Àlàáfíà, àlàáfíà fún ọ, àti àlàáfíà fún àwọn tí ó ràn ó lọ́wọ́, nítorí Ọlọ́run rẹ̀ yóò ràn ọ́ lọ́wọ́.” Bẹ́ẹ̀ ni Dafidi sì gbà wọ́n ó sì mú wọn jẹ olórí ẹgbẹ́ ogun.
Hĩndĩ ĩyo Roho agĩikũrũkĩra Amasai, mũnene wa arĩa Mĩrongo Ĩtatũ, akiuga atĩrĩ: “Tũrĩ aku, wee Daudi! Tũrĩ hamwe nawe, wee mũrũ wa Jesii! Ũrogaacĩra, ũgaacĩre ki, na arĩa magũteithagia marogaacĩra, nĩgũkorwo Ngai waku nĩegũgũteithia.” Nĩ ũndũ ũcio Daudi akĩmaamũkĩra na akĩmatua atongoria a mbũtũ ciake cia gũtharĩkĩra thũ.
19 Díẹ̀ nínú àwọn ọkùnrin Manase sì yà sí ọ̀dọ̀ Dafidi nígbà tí ó lọ pẹ̀lú àwọn ará Filistini láti bá Saulu jà. (Òun àti àwọn ọkùnrin rẹ̀ wọn kò sì ran ará Filistini lọ́wọ́ nítorí, lẹ́yìn tiwọn sọ̀rọ̀ papọ̀, àwọn olórí wọn rán wọn jáde, wọ́n sì wí pé, “Yóò jẹ́ ìparun fún wa tí ó bá padà tọ ọ̀gá rẹ̀ Saulu lọ.”)
Andũ amwe a Manase nĩmagarũrũkire magĩthiĩ mwena wa Daudi rĩrĩa aathiire na Afilisti kũhũũrana na Saũlũ. (Daudi na andũ ake matiateithirie Afilisti, tondũ thuutha wa kwaranĩria, aathani ao nĩmamũingatire. Maamwĩrire atĩrĩ, “Tũkaarĩha na mĩoyo iitũ angĩgatũtiganĩria acookerere mwathi wake Saũlũ.”)
20 Nígbà tí Dafidi lọ sí Siklagi, àwọn wọ̀nyí ni ọkùnrin ti Manase ẹni tí ó sì yà sọ́dọ̀ rẹ̀. Adina, Josabadi, Jediaeli, Mikaeli, Josabadi, Elihu àti Siletai, àwọn olórí ìrẹ́pọ̀ ti ẹgbẹẹgbẹ̀rún ní Manase.
Hĩndĩ ĩrĩa Daudi aathiire Zikilagi, aya nĩo andũ a Manase arĩa maagarũrũkire magĩthiĩ mwena wake: Adina, na Jozabadu, na Jediaeli, na Mikaeli, na Jozabadu, na Elihu, na Zilethai, atongoria a ikundi cia ngiri kũu Manase.
21 Wọ́n sì ran Dafidi lọ́wọ́ lórí ẹgbẹ́ ogun náà, nítorí gbogbo wọn ni akọni ènìyàn àwọn sì tún ni olórí nínú àwọn ọmọ-ogun rẹ̀.
Nĩmateithirie Daudi kuuma kũrĩ mbũtũ iria ciamũtharĩkĩire, nĩgũkorwo othe maarĩ njamba cia ita irĩ ũrũme, na maarĩ anene a ita ciake.
22 Ọjọ́ dé ọjọ́ ni àwọn ọkùnrin wá láti ran Dafidi lọ́wọ́, títí tí ó fi ní àwọn ológun ńlá, bí ogun Ọlọ́run.
Mũthenya o mũthenya andũ nĩmookaga gũteithia Daudi, o nginya akĩgĩa na mbũtũ nene, o ta mbũtũ ya Ngai.
23 Àwọn wọ̀nyí sì ni iye ọkùnrin tí ó ti di ìhámọ́ra fún ogun àwọn ẹni tí ó wá sọ́dọ̀ Dafidi ní Hebroni láti yí ìjọba Dafidi padà sí ọ̀dọ̀ rẹ̀, gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti sọ.
Ũyũ nĩguo mũigana wa andũ arĩa meehaarĩirie gũthiĩ mbaara arĩa maathiire Hebironi kũrĩ Daudi nĩgeetha magarũre ũthamaki wa Saũlũ, maũnengere Daudi, o ta ũrĩa Jehova oigĩte:
24 Ọkùnrin Juda, tí o ń gbé asà àti ọ̀kọ̀, ẹgbàáta lé lẹ́gbẹ̀rin tí ó ti di ìhámọ́ra fún ogun.
andũ a Juda arĩa meehaarĩirie kũrũa mbaara maakuĩte ngo na matimũ, maarĩ 6,800;
25 Àwọn ọkùnrin Simeoni, akọni tó mú fún ogun sì jẹ́ ẹ̀ẹ́dẹ́gbàárin ó lé ọgọ́rùn-ún;
andũ a Simeoni arĩa njamba cia ita meehaarĩirie kũrũa mbaara, maarĩ 7,100;
26 àwọn ọkùnrin Lefi ẹgbàajì ó le ẹgbẹ̀ta,
andũ a Alawii maarĩ 4,600;
27 pẹ̀lú Jehoiada, olórí ìdílé Aaroni pẹ̀lú ẹgbẹ̀rún mẹ́ta ó lé ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀rin ènìyàn,
amwe ao maarĩ Jehoiada, mũtongoria wa nyũmba ya Harũni ũrĩa warĩ na andũ 3,700,
28 àti Sadoku akọni ọ̀dọ́mọkùnrin, pẹ̀lú àwọn méjìlélógún ìjòyè láti ọ̀dọ̀ àwọn ìdílé rẹ̀;
na Zadoku, mwanake mũnini warĩ njamba ya ita ĩrĩ ũrũme, ũrĩa warĩ na anene a thigari mĩrongo ĩĩrĩ na eerĩ kuuma nyũmba yake;
29 àwọn arákùnrin Benjamini ìbátan ọkùnrin Saulu ẹgbẹ̀rún mẹ́ta, ọ̀pọ̀ nínú àwọn ẹni tí ó si kù ní olóòtítọ́ sí ilé Saulu títí di ìgbà náà;
andũ a Benjamini, na nĩo maarĩ a mbarĩ ĩmwe na Saũlũ, maarĩ 3,000; aingĩ ao maatũũrĩte maathĩkagĩra nyũmba ya Saũlũ, o nginya hĩndĩ ĩyo;
30 àwọn arákùnrin Efraimu, ògbójú akọni, ènìyàn Ọlọ́run ni wọ́n nílé baba wọn ogún ẹgbẹ̀rún ó le ẹgbẹ̀rin;
andũ a Efiraimu, njamba cia ita irĩ ũrũme na irĩ ngumo mĩhĩrĩga-inĩ yao, maarĩ 20,800;
31 àwọn ọkùnrin nínú ààbọ̀ ẹ̀yà Manase, tí a yàn nípa orúkọ láti wá àti láti yan Dafidi gẹ́gẹ́ bí ọba, ẹgbàá mẹ́sàn.
andũ a nuthu ya mũhĩrĩga wa Manase, arĩa maagwetetwo na marĩĩtwa nĩguo mathiĩ matue Daudi mũthamaki, maarĩ 18,000;
32 Àti ní ti àwọn ọmọ Isakari, àwọn ẹni tí ó ní òye àkókò, láti mọ ohun tí Israẹli ìbá máa ṣe; olórí wọn jẹ́ ìgbà; àti gbogbo àwọn ìbátan wọn ń bẹ ní ìkáwọ́ wọn.
andũ a Isakaru, arĩa maarĩ na ũmenyo wa mahinda, na makamenya ũrĩa Isiraeli magĩrĩirwo nĩ gwĩka, maarĩ anene 200 arĩa maathaga andũ othe a nyũmba ciao;
33 Àwọn ọkùnrin Sebuluni, àti àwọn jagunjagun tí ó ti nípa ogun múra fún ogun pẹ̀lú oríṣìíríṣìí ohun èlò ìjà, láti ran Dafidi lọ́wọ́ pẹ̀lú àwọn tí kò fi iyèméjì ṣe ìjólóòótọ́ wọn jẹ́ ẹgbàá mẹ́ẹ̀ẹ́dọ́gbọ̀n.
andũ a Zebuluni, thigari iria ciamenyerete mbaara, na nĩmehaarĩirie kũrũa mbaara me na mĩthemba yothe ya indo cia mbaara, nĩguo mateithie Daudi marĩ na ngoro ĩmwe, nao maarĩ 50,000;
34 Àwọn ọkùnrin Naftali, ẹgbẹ̀rún ìjòyè àpapọ̀ pẹ̀lú ẹgbàá méjìdínlógún. Ọkùnrin tí wọ́n gbé asà àti ọ̀kọ̀ wọn.
andũ a Nafitali maarĩ anene 1,000 hamwe na andũ 37,000 arĩa makuuĩte ngo na matimũ;
35 Àwọn ọkùnrin Dani, tí wọ́n ṣetán fún ogun ẹgbàá mẹ́tàlá.
andũ a Dani arĩa mehaarĩirie kũrũa mbaara, maarĩ 28,600;
36 Àwọn ọkùnrin Aṣeri, àwọn tí ó ti ní ìmọ̀ ogun múra fún ogun ọ̀kẹ́ méjì.
andũ a Asheri, thigari iria ciamenyerete mbaara na mehaarĩirie kũrũa mbaara, maarĩ 40,000;
37 Láti ìlà-oòrùn Jordani, ọkùnrin Reubeni, Gadi, àti ìdajì ẹ̀yà Manase, dìmọ́ra pẹ̀lú gbogbo onírúurú ohun èlò ìjà ọ̀kẹ́ mẹ́fà.
na kuuma mwena wa irathĩro wa Jorodani, andũ a Rubeni, na Gadi, na nuthu ya mũhĩrĩga wa Manase, marĩ na mĩthemba yothe ya indo cia mbaara, maarĩ 120,000.
38 Gbogbo èyí ni àwọn ọkùnrin ológun tí ó fi ara wọn fún ogun láti ṣe iṣẹ́ fún nínú ẹgbẹ́. Wọ́n wá sí Hebroni tí ó kún fún ìpinnu láti fi Dafidi jẹ́ ọba lórí gbogbo Israẹli. Gbogbo àwọn ìyókù lára àwọn ọmọ Israẹli sì jẹ́ onínú kan láti fi Dafidi jẹ ọba.
Acio othe maarĩ andũ a kũrũa arĩa meerutĩte gũtungata marĩ ita-inĩ. Magĩũka Hebironi marĩ na ngoro ĩmwe ya gũtua Daudi mũthamaki wa Isiraeli guothe. Andũ a Isiraeli arĩa angĩ othe o nao maarĩ na rĩciiria o rĩmwe rĩa gũtua Daudi mũthamaki.
39 Àwọn ọkùnrin náà lo ọjọ́ mẹ́ta níbẹ̀ pẹ̀lú Dafidi, wọ́n jẹ, wọ́n sì ń mu, nítorí ìdílé wọn ti pèsè oúnjẹ fún wọn.
Andũ acio maikarire kũu na Daudi mĩthenya ĩtatũ makĩrĩa na makĩnyua, nĩgũkorwo andũ a nyũmba ciao nĩmaheanĩte irio nĩ ũndũ wao.
40 Àwọn aládùúgbò láti ọ̀nà jíjìn gẹ́gẹ́ bí Isakari, Sebuluni àti Naftali gbé oúnjẹ wá lórí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́, lórí ràkunmí, àti lórí ìbáaka àti lórí màlúù, àní oúnjẹ ti ìyẹ̀fun, èso àjàrà gbígbẹ, èso ọ̀pọ̀tọ́, àkàrà dídùn, ọtí wáìnì, òróró, màlúù àti àgùntàn, nítorí ọ̀pọ̀lọpọ̀ ayọ̀ wà ní Israẹli.
O na ningĩ andũ arĩa maatũũraga hakuhĩ nao kuuma Isakaru, na Zebuluni, na Nafitali nĩmarehire irio ikuuĩtwo nĩ ndigiri, na ngamĩĩra, na nyũmbũ, na ndegwa. Nĩ kwarehetwo mũtu mũingĩ, na ngũmba cia ngũyũ na cia thabibũ nyũmũ, na ndibei, na maguta, na ngʼombe, na ngʼondu, nĩgũkorwo kwarĩ na gĩkeno kũu Isiraeli.