< 1 Chronicles 12 >

1 Àwọn wọ̀nyí ni ọkùnrin tí ó wá sí ọ̀dọ̀ Dafidi ní Siklagi, nígbà tí ó sá kúrò níwájú Saulu ọmọ Kiṣi (wọ́n wà lára àwọn jagunjagun ẹni tí ó ràn án lọ́wọ́ láti ibi ìjà.
Et voici ceux qui vinrent auprès de David à Tsiklag, pendant qu'il fuyait Saül, fils de Kish. Ils étaient parmi les hommes forts, ses aides dans la guerre.
2 Wọ́n sì mú wọn pẹ̀lú ìtẹríba wọ́n sì lágbára láti ta ọfà tàbí láti ta kànnàkànnà òkúta ní ọwọ́ òsì tàbí ní ọwọ́ ọ̀tún, wọ́n sì jẹ́ ìbátan ọkùnrin Saulu láti ẹ̀yà Benjamini):
Ils étaient armés d'arcs et pouvaient se servir de la main droite et de la main gauche pour lancer des pierres et tirer des flèches de l'arc. Ils étaient de la famille de Saül, de la tribu de Benjamin.
3 Ahieseri olórí wọn àti Joaṣi àwọn ọmọ Ṣemaah ará Gibeah: Jeṣieli àti Peleti ọmọ Asmafeti, Beraka, Jehu ará Anatoti.
Le chef était Ahiézer, puis Joas, fils de Shemaa, le Gibéen; Jeziel et Pelet, fils d'Azmaveth; Beraca; Jéhu, l'Anathothite;
4 Àti Iṣmaiah ará Gibeoni, ọkùnrin alágbára kan lára àwọn ọgbọ̀n ẹni tí ó jẹ́ olórí nínú àwọn ọgbọ̀n; Jeremiah, Jahasieli, Johanani, Josabadi ará Gedera,
Ismaeja, le Gibéonite, homme puissant parmi les trente et chef des trente; Jérémie; Jahaziel, Jochanan, Jozabad, de Guéderath,
5 Elusai, Jerimoti, Bealiah, Ṣemariah àti Ṣefatia ará Harufiti;
Eluzaï, Jerimoth, Bealia, Shemaria, Shephathia, d'Haruph,
6 Elkana, Iṣiah, Asareeli, Joeseri àti Jaṣobeamu ará Kora;
Elkana, Ischia, Azarel, Jœzer et Jashobeam, de Koré,
7 àti Joẹla, àti Sebadiah àwọn ọmọ Jerohamu láti Gedori.
Joéla et Zebadia, fils de Jerocham, de Guedor.
8 Díẹ̀ lára àwọn ará Gadi yà sọ́dọ̀ Dafidi ní ibi gíga ní aginjù. Wọ́n sì jẹ́ onígboyà ológun tí ó múra fún ogun tí ó sì lágbára láti di asà àti ẹṣin mú. Ojú wọn sì dàbí ojú kìnnìún, wọ́n sì yára bí àgbọ̀nrín lórí àwọn òkè.
Des Gadites se joignirent à David dans la forteresse du désert, hommes vaillants, entraînés à la guerre, sachant manier le bouclier et la lance; leur visage était semblable à celui des lions, et ils étaient aussi rapides que les gazelles sur les montagnes:
9 Eseri sì jẹ́ ìjòyè, Obadiah sì jẹ́ igbákejì akọgun, Eliabu ẹlẹ́ẹ̀kẹta,
Ezer, le chef, Abdias, le second, Éliab, le troisième,
10 Miṣimana ẹlẹ́ẹ̀kẹrin, Jeremiah ẹlẹ́ẹ̀karùnún
Mischmanna, le quatrième, Jérémie, le cinquième,
11 Attai ẹlẹ́ẹ̀kẹfà, Elieli èkeje,
Attaï, le sixième, Éliel, le septième,
12 Johanani ẹlẹ́ẹ̀kẹjọ Elsabadi ẹlẹ́ẹ̀kẹsàn-án
Jochanan, le huitième, Elzabad, le neuvième,
13 Jeremiah ẹlẹ́ẹ̀kẹwàá àti Makbannai ẹlẹ́ẹ̀kọkànlá.
Jérémie, le dixième, et Machbannaï, le onzième.
14 Àwọn ará Gadi wọ́n sì jẹ́ olórí ogun; ẹni tí ó kéré jù sì jẹ́ àpapọ̀ ọgọ́rùn-ún, àti fún ẹni tí ó pọ̀jù fún ẹgbẹ̀rún.
Ceux-ci, parmi les fils de Gad, étaient chefs de l'armée. Le plus petit était égal à cent, et le plus grand à mille.
15 Àwọn ni ẹni tí ó rékọjá Jordani ní oṣù àkọ́kọ́ nígbà tí ó kún bo gbogbo bèbè rẹ̀, wọ́n sì lé gbogbo àwọn tí ó ń gbé nínú àfonífojì, lọ sí ìlà-oòrùn àti níhà ìwọ̀-oòrùn.
Ce sont ceux qui passèrent le Jourdain au premier mois, quand il avait débordé sur toutes ses rives, et qui mirent en fuite tous les habitants des vallées, à l'est et à l'ouest.
16 Ìyókù ará Benjamini àti àwọn díẹ̀ ọkùnrin láti Juda lọ sí ọ̀dọ̀ Dafidi ní ibi gíga.
Quelques-uns des enfants de Benjamin et de Juda vinrent à la forteresse auprès de David.
17 Dafidi sì lọ láti lọ pàdé wọn ó sì wí fún wọn pé, “Tí ẹ bá wá sọ́dọ̀ mi lálàáfíà, láti ràn mí lọ́wọ́ mo ṣetán láti mú un yín wà ní ìṣọ̀kan pẹ̀lú mi ṣùgbọ́n tí ẹ bá wá láti dá mi sí fún àwọn ọ̀tá mi nígbà tí ọwọ́ mi bá mọ́ kúrò nínú ìwà agbára, kí Ọlọ́run àwọn baba wa kí ó sì ri kí ó sì ṣe ìdájọ́.”
David alla au-devant d'eux et leur répondit: « Si vous êtes venus pacifiquement à moi pour m'aider, mon cœur s'unira à vous; mais si vous êtes venus pour me livrer à mes adversaires, puisqu'il n'y a pas de mal dans mes mains, que le Dieu de nos pères voie cela et le réprouve. »
18 Nígbà náà Ẹ̀mí Mímọ́ wa sórí Amasai ìjòyè àwọn ọgbọ̀n, ó sì wí pé, “Tìrẹ ni àwa ń ṣe, ìwọ Dafidi! Àwa pẹ̀lú rẹ, ìwọ ọmọ Jese! Àlàáfíà, àlàáfíà fún ọ, àti àlàáfíà fún àwọn tí ó ràn ó lọ́wọ́, nítorí Ọlọ́run rẹ̀ yóò ràn ọ́ lọ́wọ́.” Bẹ́ẹ̀ ni Dafidi sì gbà wọ́n ó sì mú wọn jẹ olórí ẹgbẹ́ ogun.
Alors l'Esprit vint sur Amasaï, qui était le chef des trente, et il dit: « Nous sommes à toi, David, et de ton côté, toi, fils de Jessé. Que la paix, la paix soit avec toi, et que la paix soit avec ceux qui te soutiennent, car ton Dieu te soutient. » Alors David les reçut et les nomma chefs de la troupe.
19 Díẹ̀ nínú àwọn ọkùnrin Manase sì yà sí ọ̀dọ̀ Dafidi nígbà tí ó lọ pẹ̀lú àwọn ará Filistini láti bá Saulu jà. (Òun àti àwọn ọkùnrin rẹ̀ wọn kò sì ran ará Filistini lọ́wọ́ nítorí, lẹ́yìn tiwọn sọ̀rọ̀ papọ̀, àwọn olórí wọn rán wọn jáde, wọ́n sì wí pé, “Yóò jẹ́ ìparun fún wa tí ó bá padà tọ ọ̀gá rẹ̀ Saulu lọ.”)
Quelques-uns de Manassé se joignirent aussi à David lorsqu'il vint combattre avec les Philistins contre Saül, mais ils ne les aidèrent pas, car les chefs des Philistins le renvoyèrent après l'avoir consulté, en disant: « Il va déserter vers son maître Saül au péril de nos têtes. »
20 Nígbà tí Dafidi lọ sí Siklagi, àwọn wọ̀nyí ni ọkùnrin ti Manase ẹni tí ó sì yà sọ́dọ̀ rẹ̀. Adina, Josabadi, Jediaeli, Mikaeli, Josabadi, Elihu àti Siletai, àwọn olórí ìrẹ́pọ̀ ti ẹgbẹẹgbẹ̀rún ní Manase.
Comme il allait à Ziklag, des gens de Manassé se joignirent à lui: Adna, Jozabad, Jediaël, Michel, Jozabad, Elihu et Zillethaï, chefs de milliers qui étaient de Manassé.
21 Wọ́n sì ran Dafidi lọ́wọ́ lórí ẹgbẹ́ ogun náà, nítorí gbogbo wọn ni akọni ènìyàn àwọn sì tún ni olórí nínú àwọn ọmọ-ogun rẹ̀.
Ils aidèrent David à combattre la bande de pillards, car ils étaient tous des hommes vaillants et des chefs de l'armée.
22 Ọjọ́ dé ọjọ́ ni àwọn ọkùnrin wá láti ran Dafidi lọ́wọ́, títí tí ó fi ní àwọn ológun ńlá, bí ogun Ọlọ́run.
Car de jour en jour, des hommes venaient à David pour l'aider, jusqu'à ce qu'il y ait une grande armée, comme l'armée de Dieu.
23 Àwọn wọ̀nyí sì ni iye ọkùnrin tí ó ti di ìhámọ́ra fún ogun àwọn ẹni tí ó wá sọ́dọ̀ Dafidi ní Hebroni láti yí ìjọba Dafidi padà sí ọ̀dọ̀ rẹ̀, gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti sọ.
Voici le nombre des têtes de ceux qui étaient armés pour la guerre et qui vinrent auprès de David à Hébron pour lui remettre le royaume de Saül, selon la parole de l'Éternel.
24 Ọkùnrin Juda, tí o ń gbé asà àti ọ̀kọ̀, ẹgbàáta lé lẹ́gbẹ̀rin tí ó ti di ìhámọ́ra fún ogun.
Les fils de Juda qui portaient le bouclier et la lance étaient six mille huit cents, armés pour la guerre.
25 Àwọn ọkùnrin Simeoni, akọni tó mú fún ogun sì jẹ́ ẹ̀ẹ́dẹ́gbàárin ó lé ọgọ́rùn-ún;
Des fils de Siméon, hommes vaillants pour la guerre: sept mille cent.
26 àwọn ọkùnrin Lefi ẹgbàajì ó le ẹgbẹ̀ta,
des fils de Lévi: quatre mille six cents.
27 pẹ̀lú Jehoiada, olórí ìdílé Aaroni pẹ̀lú ẹgbẹ̀rún mẹ́ta ó lé ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀rin ènìyàn,
Jehojada était le chef de la maison d'Aaron; il avait avec lui trois mille sept cents hommes,
28 àti Sadoku akọni ọ̀dọ́mọkùnrin, pẹ̀lú àwọn méjìlélógún ìjòyè láti ọ̀dọ̀ àwọn ìdílé rẹ̀;
Zadok, jeune homme vaillant, et vingt-deux chefs de la maison de son père.
29 àwọn arákùnrin Benjamini ìbátan ọkùnrin Saulu ẹgbẹ̀rún mẹ́ta, ọ̀pọ̀ nínú àwọn ẹni tí ó si kù ní olóòtítọ́ sí ilé Saulu títí di ìgbà náà;
Des fils de Benjamin, parents de Saül: trois mille, car jusqu'alors, la plus grande partie d'entre eux avaient gardé leur allégeance à la maison de Saül.
30 àwọn arákùnrin Efraimu, ògbójú akọni, ènìyàn Ọlọ́run ni wọ́n nílé baba wọn ogún ẹgbẹ̀rún ó le ẹgbẹ̀rin;
des fils d'Éphraïm: vingt mille huit cents, vaillants hommes, célèbres dans la maison de leurs pères.
31 àwọn ọkùnrin nínú ààbọ̀ ẹ̀yà Manase, tí a yàn nípa orúkọ láti wá àti láti yan Dafidi gẹ́gẹ́ bí ọba, ẹgbàá mẹ́sàn.
de la demi-tribu de Manassé: dix-huit mille, qui furent nommément désignés pour venir faire roi David.
32 Àti ní ti àwọn ọmọ Isakari, àwọn ẹni tí ó ní òye àkókò, láti mọ ohun tí Israẹli ìbá máa ṣe; olórí wọn jẹ́ ìgbà; àti gbogbo àwọn ìbátan wọn ń bẹ ní ìkáwọ́ wọn.
Des fils d'Issacar, hommes qui avaient l'intelligence des temps, pour savoir ce qu'Israël devait faire: leurs têtes étaient deux cents, et tous leurs frères étaient à leurs ordres.
33 Àwọn ọkùnrin Sebuluni, àti àwọn jagunjagun tí ó ti nípa ogun múra fún ogun pẹ̀lú oríṣìíríṣìí ohun èlò ìjà, láti ran Dafidi lọ́wọ́ pẹ̀lú àwọn tí kò fi iyèméjì ṣe ìjólóòótọ́ wọn jẹ́ ẹgbàá mẹ́ẹ̀ẹ́dọ́gbọ̀n.
De Zabulon, ceux qui étaient capables d'aller à l'armée, qui pouvaient se mettre en ordre de bataille avec toutes sortes d'instruments de guerre: cinquante mille qui pouvaient commander et qui n'avaient pas le cœur double.
34 Àwọn ọkùnrin Naftali, ẹgbẹ̀rún ìjòyè àpapọ̀ pẹ̀lú ẹgbàá méjìdínlógún. Ọkùnrin tí wọ́n gbé asà àti ọ̀kọ̀ wọn.
De Nephtali: mille chefs, et avec eux, avec le bouclier et la lance, trente-sept mille.
35 Àwọn ọkùnrin Dani, tí wọ́n ṣetán fún ogun ẹgbàá mẹ́tàlá.
des Danites qui savaient se mettre en ordre de bataille: vingt-huit mille six cents.
36 Àwọn ọkùnrin Aṣeri, àwọn tí ó ti ní ìmọ̀ ogun múra fún ogun ọ̀kẹ́ méjì.
d'Aser, ceux qui étaient capables d'aller à l'armée et de se ranger en bataille: quarante mille.
37 Láti ìlà-oòrùn Jordani, ọkùnrin Reubeni, Gadi, àti ìdajì ẹ̀yà Manase, dìmọ́ra pẹ̀lú gbogbo onírúurú ohun èlò ìjà ọ̀kẹ́ mẹ́fà.
De l'autre côté du Jourdain, des Rubénites, des Gadites et de la demi-tribu de Manassé, avec toutes sortes d'instruments de guerre pour le combat: cent vingt mille.
38 Gbogbo èyí ni àwọn ọkùnrin ológun tí ó fi ara wọn fún ogun láti ṣe iṣẹ́ fún nínú ẹgbẹ́. Wọ́n wá sí Hebroni tí ó kún fún ìpinnu láti fi Dafidi jẹ́ ọba lórí gbogbo Israẹli. Gbogbo àwọn ìyókù lára àwọn ọmọ Israẹli sì jẹ́ onínú kan láti fi Dafidi jẹ ọba.
Tous ceux-là étaient des hommes de guerre capables d'ordonner le dispositif de combat, et ils vinrent à Hébron avec un cœur parfait pour faire de David le roi de tout Israël; et tout le reste d'Israël était aussi d'un même cœur pour faire de David le roi.
39 Àwọn ọkùnrin náà lo ọjọ́ mẹ́ta níbẹ̀ pẹ̀lú Dafidi, wọ́n jẹ, wọ́n sì ń mu, nítorí ìdílé wọn ti pèsè oúnjẹ fún wọn.
Ils restèrent là trois jours avec David, mangeant et buvant, car leurs frères leur avaient fourni des provisions.
40 Àwọn aládùúgbò láti ọ̀nà jíjìn gẹ́gẹ́ bí Isakari, Sebuluni àti Naftali gbé oúnjẹ wá lórí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́, lórí ràkunmí, àti lórí ìbáaka àti lórí màlúù, àní oúnjẹ ti ìyẹ̀fun, èso àjàrà gbígbẹ, èso ọ̀pọ̀tọ́, àkàrà dídùn, ọtí wáìnì, òróró, màlúù àti àgùntàn, nítorí ọ̀pọ̀lọpọ̀ ayọ̀ wà ní Israẹli.
Ceux qui étaient près d'eux, jusqu'à Issacar, Zabulon et Nephtali, apportèrent du pain sur des ânes, des chameaux, des mulets et des bœufs, des provisions de farine, des gâteaux de figues, des grappes de raisins secs, du vin, de l'huile, du bétail et des moutons en abondance, car il y avait de la joie en Israël.

< 1 Chronicles 12 >