< 1 Chronicles 12 >

1 Àwọn wọ̀nyí ni ọkùnrin tí ó wá sí ọ̀dọ̀ Dafidi ní Siklagi, nígbà tí ó sá kúrò níwájú Saulu ọmọ Kiṣi (wọ́n wà lára àwọn jagunjagun ẹni tí ó ràn án lọ́wọ́ láti ibi ìjà.
These also are they that came to Dauid to Ziklag, while he was yet kept close, because of Saul the sonne of Kish: and they were among the valiant and helpers of the battel.
2 Wọ́n sì mú wọn pẹ̀lú ìtẹríba wọ́n sì lágbára láti ta ọfà tàbí láti ta kànnàkànnà òkúta ní ọwọ́ òsì tàbí ní ọwọ́ ọ̀tún, wọ́n sì jẹ́ ìbátan ọkùnrin Saulu láti ẹ̀yà Benjamini):
They were weaponed with bowes, and could vse the right and the left hand with stones and with arrowes and with bowes, and were of Sauls brethren, euen of Beniamin.
3 Ahieseri olórí wọn àti Joaṣi àwọn ọmọ Ṣemaah ará Gibeah: Jeṣieli àti Peleti ọmọ Asmafeti, Beraka, Jehu ará Anatoti.
The chiefe were Ahiezer, and Ioash the sonnes of Shemaah a Gibeathite, and Ieziel, and Pelet the sonnes of Asinaueth, Berachah and Iehu the Antothite,
4 Àti Iṣmaiah ará Gibeoni, ọkùnrin alágbára kan lára àwọn ọgbọ̀n ẹni tí ó jẹ́ olórí nínú àwọn ọgbọ̀n; Jeremiah, Jahasieli, Johanani, Josabadi ará Gedera,
And Ishmaiah the Gibeonite, a valiant man among thirtie, and aboue the thirtie, and Ieremiah, and Iehaziel, and Iohanan, and Ioshabad the Gederathite,
5 Elusai, Jerimoti, Bealiah, Ṣemariah àti Ṣefatia ará Harufiti;
Eluzai, and Ierimoth, and Bealiah, and Shemariah, and Shephatiah the Haruphite,
6 Elkana, Iṣiah, Asareeli, Joeseri àti Jaṣobeamu ará Kora;
Elkanah, and Ishiah, and Azariel, and Ioezer, Iashobeam of Hakorehim,
7 àti Joẹla, àti Sebadiah àwọn ọmọ Jerohamu láti Gedori.
And Ioelah, and Zebadiah, the sonnes of Ieroham of Gedor,
8 Díẹ̀ lára àwọn ará Gadi yà sọ́dọ̀ Dafidi ní ibi gíga ní aginjù. Wọ́n sì jẹ́ onígboyà ológun tí ó múra fún ogun tí ó sì lágbára láti di asà àti ẹṣin mú. Ojú wọn sì dàbí ojú kìnnìún, wọ́n sì yára bí àgbọ̀nrín lórí àwọn òkè.
And of the Gadites there separated them selues some vnto Dauid into the holde of the wildernesse, valiant men of warre, and men of armes, and apt for battel, which coulde handle speare and shielde, and their faces were like the faces of lyons, and were like the roes in the mountaines in swiftnesse,
9 Eseri sì jẹ́ ìjòyè, Obadiah sì jẹ́ igbákejì akọgun, Eliabu ẹlẹ́ẹ̀kẹta,
Ezer the chiefe, Obadiah the second, Eliab the third,
10 Miṣimana ẹlẹ́ẹ̀kẹrin, Jeremiah ẹlẹ́ẹ̀karùnún
Mishmanah the fourth, Ieremiah the fift,
11 Attai ẹlẹ́ẹ̀kẹfà, Elieli èkeje,
Attai the sixt, Eliel the seuenth,
12 Johanani ẹlẹ́ẹ̀kẹjọ Elsabadi ẹlẹ́ẹ̀kẹsàn-án
Iohanan the eight, Elzabad the ninth,
13 Jeremiah ẹlẹ́ẹ̀kẹwàá àti Makbannai ẹlẹ́ẹ̀kọkànlá.
Ieremiah the tenth, Macbannai the eleuenth.
14 Àwọn ará Gadi wọ́n sì jẹ́ olórí ogun; ẹni tí ó kéré jù sì jẹ́ àpapọ̀ ọgọ́rùn-ún, àti fún ẹni tí ó pọ̀jù fún ẹgbẹ̀rún.
These were the sonnes of Gad, captaines of the hoste: one of the least could resist an hundreth, and the greatest a thousand.
15 Àwọn ni ẹni tí ó rékọjá Jordani ní oṣù àkọ́kọ́ nígbà tí ó kún bo gbogbo bèbè rẹ̀, wọ́n sì lé gbogbo àwọn tí ó ń gbé nínú àfonífojì, lọ sí ìlà-oòrùn àti níhà ìwọ̀-oòrùn.
These are they that went ouer Iorden in the first moneth when he had filled ouer all his bankes, and put to flight all them of the valley, toward the East and the West.
16 Ìyókù ará Benjamini àti àwọn díẹ̀ ọkùnrin láti Juda lọ sí ọ̀dọ̀ Dafidi ní ibi gíga.
And there came of the children of Beniamin, and Iudah to the hold vnto Dauid,
17 Dafidi sì lọ láti lọ pàdé wọn ó sì wí fún wọn pé, “Tí ẹ bá wá sọ́dọ̀ mi lálàáfíà, láti ràn mí lọ́wọ́ mo ṣetán láti mú un yín wà ní ìṣọ̀kan pẹ̀lú mi ṣùgbọ́n tí ẹ bá wá láti dá mi sí fún àwọn ọ̀tá mi nígbà tí ọwọ́ mi bá mọ́ kúrò nínú ìwà agbára, kí Ọlọ́run àwọn baba wa kí ó sì ri kí ó sì ṣe ìdájọ́.”
And Dauid went out to meete them, and answered and sayde vnto them, If yee be come peaceably vnto me to helpe me, mine heart shall be knit vnto you, but if you come to betray me to mine aduersaries, seeing there is no wickednes in mine handes, the God of our fathers beholde it, and rebuke it.
18 Nígbà náà Ẹ̀mí Mímọ́ wa sórí Amasai ìjòyè àwọn ọgbọ̀n, ó sì wí pé, “Tìrẹ ni àwa ń ṣe, ìwọ Dafidi! Àwa pẹ̀lú rẹ, ìwọ ọmọ Jese! Àlàáfíà, àlàáfíà fún ọ, àti àlàáfíà fún àwọn tí ó ràn ó lọ́wọ́, nítorí Ọlọ́run rẹ̀ yóò ràn ọ́ lọ́wọ́.” Bẹ́ẹ̀ ni Dafidi sì gbà wọ́n ó sì mú wọn jẹ olórí ẹgbẹ́ ogun.
And the spirit came vpon Amasai, which was the chiefe of thirtie, and he said, Thine are we, Dauid, and with thee, O sonne of Ishai. Peace, peace be vnto thee, and peace be vnto thine helpers: for thy God helpeth thee. Then Dauid receiued them, and made them captaines of the garison.
19 Díẹ̀ nínú àwọn ọkùnrin Manase sì yà sí ọ̀dọ̀ Dafidi nígbà tí ó lọ pẹ̀lú àwọn ará Filistini láti bá Saulu jà. (Òun àti àwọn ọkùnrin rẹ̀ wọn kò sì ran ará Filistini lọ́wọ́ nítorí, lẹ́yìn tiwọn sọ̀rọ̀ papọ̀, àwọn olórí wọn rán wọn jáde, wọ́n sì wí pé, “Yóò jẹ́ ìparun fún wa tí ó bá padà tọ ọ̀gá rẹ̀ Saulu lọ.”)
And of Manasseh some fell to Dauid, when he came with the Philistims against Saul to battell, but they helped them not: for the Princes of the Philistims by aduisement sent him away, saying, He will fall to his master Saul for our heads.
20 Nígbà tí Dafidi lọ sí Siklagi, àwọn wọ̀nyí ni ọkùnrin ti Manase ẹni tí ó sì yà sọ́dọ̀ rẹ̀. Adina, Josabadi, Jediaeli, Mikaeli, Josabadi, Elihu àti Siletai, àwọn olórí ìrẹ́pọ̀ ti ẹgbẹẹgbẹ̀rún ní Manase.
As he went to Ziklag, there fell to him of Manasseh, Adnah, and Iozabad, and Iediael, and Michael, and Iozabad, and Elihu, and Ziltai, heads of the thousands that were of Manasseh.
21 Wọ́n sì ran Dafidi lọ́wọ́ lórí ẹgbẹ́ ogun náà, nítorí gbogbo wọn ni akọni ènìyàn àwọn sì tún ni olórí nínú àwọn ọmọ-ogun rẹ̀.
And they helped Dauid against that bad: for they were all valiant men and were captaines in the hoste.
22 Ọjọ́ dé ọjọ́ ni àwọn ọkùnrin wá láti ran Dafidi lọ́wọ́, títí tí ó fi ní àwọn ológun ńlá, bí ogun Ọlọ́run.
For at that time day by day there came to Dauid to helpe him, vntill it was a great hoste, like the hoste of God.
23 Àwọn wọ̀nyí sì ni iye ọkùnrin tí ó ti di ìhámọ́ra fún ogun àwọn ẹni tí ó wá sọ́dọ̀ Dafidi ní Hebroni láti yí ìjọba Dafidi padà sí ọ̀dọ̀ rẹ̀, gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti sọ.
And these are the nombers of the captaines that were armed to battell, and came to Dauid to Hebron to turne the kingdome of Saul to him, according to the worde of the Lord.
24 Ọkùnrin Juda, tí o ń gbé asà àti ọ̀kọ̀, ẹgbàáta lé lẹ́gbẹ̀rin tí ó ti di ìhámọ́ra fún ogun.
The children of Iudah that bare shield and speare, were sixe thousand and eight hundreth armed to the warre.
25 Àwọn ọkùnrin Simeoni, akọni tó mú fún ogun sì jẹ́ ẹ̀ẹ́dẹ́gbàárin ó lé ọgọ́rùn-ún;
Of the children of Simeon valiant men of warre, seuen thousand and an hundreth.
26 àwọn ọkùnrin Lefi ẹgbàajì ó le ẹgbẹ̀ta,
Of the children of Leui foure thousande and sixe hundreth.
27 pẹ̀lú Jehoiada, olórí ìdílé Aaroni pẹ̀lú ẹgbẹ̀rún mẹ́ta ó lé ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀rin ènìyàn,
And Iehoiada was the chiefe of them of Aaron: and with him three thousande and seuen hundreth.
28 àti Sadoku akọni ọ̀dọ́mọkùnrin, pẹ̀lú àwọn méjìlélógún ìjòyè láti ọ̀dọ̀ àwọn ìdílé rẹ̀;
And Zadok a yong man very valiant, and of his fathers housholde came two and twentie captaines.
29 àwọn arákùnrin Benjamini ìbátan ọkùnrin Saulu ẹgbẹ̀rún mẹ́ta, ọ̀pọ̀ nínú àwọn ẹni tí ó si kù ní olóòtítọ́ sí ilé Saulu títí di ìgbà náà;
And of the children of Beniamin the brethren of Saul three thousande: for a great part of them vnto that time kept the warde of the house of Saul.
30 àwọn arákùnrin Efraimu, ògbójú akọni, ènìyàn Ọlọ́run ni wọ́n nílé baba wọn ogún ẹgbẹ̀rún ó le ẹgbẹ̀rin;
And of the children of Ephraim twentie thousande, and eight hundreth valiant men and famous men in the housholde of their fathers.
31 àwọn ọkùnrin nínú ààbọ̀ ẹ̀yà Manase, tí a yàn nípa orúkọ láti wá àti láti yan Dafidi gẹ́gẹ́ bí ọba, ẹgbàá mẹ́sàn.
And of the halfe tribe of Manasseh eighteene thousand, which were appointed by name to come and make Dauid King.
32 Àti ní ti àwọn ọmọ Isakari, àwọn ẹni tí ó ní òye àkókò, láti mọ ohun tí Israẹli ìbá máa ṣe; olórí wọn jẹ́ ìgbà; àti gbogbo àwọn ìbátan wọn ń bẹ ní ìkáwọ́ wọn.
And of the children of Issachar which were men that had vnderstanding of the times, to knowe what Israel ought to doe: the heades of them were two hundreth, and all their brethren were at their commandement.
33 Àwọn ọkùnrin Sebuluni, àti àwọn jagunjagun tí ó ti nípa ogun múra fún ogun pẹ̀lú oríṣìíríṣìí ohun èlò ìjà, láti ran Dafidi lọ́wọ́ pẹ̀lú àwọn tí kò fi iyèméjì ṣe ìjólóòótọ́ wọn jẹ́ ẹgbàá mẹ́ẹ̀ẹ́dọ́gbọ̀n.
Of Zebulun that went out to battel, expert in warre, and in all instruments of warre, fiftie thousande which could set the battell in aray: they were not of a double heart.
34 Àwọn ọkùnrin Naftali, ẹgbẹ̀rún ìjòyè àpapọ̀ pẹ̀lú ẹgbàá méjìdínlógún. Ọkùnrin tí wọ́n gbé asà àti ọ̀kọ̀ wọn.
And of Naphtali a thousand captaines, and with them with shielde and speare seuen and thirtie thousande.
35 Àwọn ọkùnrin Dani, tí wọ́n ṣetán fún ogun ẹgbàá mẹ́tàlá.
And of Dan expert in battell, eyght and twentie thousande, and sixe hundreth.
36 Àwọn ọkùnrin Aṣeri, àwọn tí ó ti ní ìmọ̀ ogun múra fún ogun ọ̀kẹ́ méjì.
And of Asher that went out to the battell and were trained in the warres, fourtie thousand.
37 Láti ìlà-oòrùn Jordani, ọkùnrin Reubeni, Gadi, àti ìdajì ẹ̀yà Manase, dìmọ́ra pẹ̀lú gbogbo onírúurú ohun èlò ìjà ọ̀kẹ́ mẹ́fà.
And of the other side of Iorden of the Reubenites, and of the Gadites, and of the halfe tribe of Manasseh with all instruments of warre to fight with, an hundreth and twentie thousand.
38 Gbogbo èyí ni àwọn ọkùnrin ológun tí ó fi ara wọn fún ogun láti ṣe iṣẹ́ fún nínú ẹgbẹ́. Wọ́n wá sí Hebroni tí ó kún fún ìpinnu láti fi Dafidi jẹ́ ọba lórí gbogbo Israẹli. Gbogbo àwọn ìyókù lára àwọn ọmọ Israẹli sì jẹ́ onínú kan láti fi Dafidi jẹ ọba.
All these men of warre that coulde leade an armie, came with vpright heart to Hebron to make Dauid King ouer all Israel: and all the rest of Israel was of one accorde to make Dauid King:
39 Àwọn ọkùnrin náà lo ọjọ́ mẹ́ta níbẹ̀ pẹ̀lú Dafidi, wọ́n jẹ, wọ́n sì ń mu, nítorí ìdílé wọn ti pèsè oúnjẹ fún wọn.
And there they were with Dauid three dayes, eating and drinking: for their brethren had prepared for them.
40 Àwọn aládùúgbò láti ọ̀nà jíjìn gẹ́gẹ́ bí Isakari, Sebuluni àti Naftali gbé oúnjẹ wá lórí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́, lórí ràkunmí, àti lórí ìbáaka àti lórí màlúù, àní oúnjẹ ti ìyẹ̀fun, èso àjàrà gbígbẹ, èso ọ̀pọ̀tọ́, àkàrà dídùn, ọtí wáìnì, òróró, màlúù àti àgùntàn, nítorí ọ̀pọ̀lọpọ̀ ayọ̀ wà ní Israẹli.
Moreouer they that were neere them vntill Issachar, and Zebulun, and Naphtali brought bread vpon asses, and on camels, and on mules, and on oxen, euen meate, floure, figges, and reisins, and wine and oyle, and beeues and sheepe abundantly: for there was ioy in Israel.

< 1 Chronicles 12 >