< 1 Chronicles 11 >
1 Gbogbo àwọn Israẹli kó ara wọn jọ pọ̀ sí ọ̀dọ̀ Dafidi ní Hebroni, wọ́n sì wí pé, “Ẹran-ara rẹ àti ẹ̀jẹ̀ rẹ ni àwa í ṣe.
Então todo o Israel se ajuntou a David em Hebron, dizendo: Eis que somos teus ossos e tua carne.
2 Ní àtijọ́, kódà nígbà tí Saulu jẹ ọba, ìwọ ni ẹni tí ó darí Israẹli ní ojú ogun wọn. Olúwa Ọlọ́run rẹ sì wí fún ọ pé, ‘Ìwọ yóò sì jẹ́ olùṣọ́ Israẹli ènìyàn mi, ìwọ yóò sì jẹ́ olórí fún wọn.’”
E tambem já d'antes, sendo Saul ainda rei, eras tu o que fazias sair e entrar a Israel: tambem o Senhor teu Deus te disse: Tu apascentarás o meu povo Israel, e tu serás chefe sobre o meu povo Israel.
3 Nígbà tí gbogbo àwọn ìjòyè Israẹli tí wọ́n ti wá sọ́dọ̀ ọba Dafidi ni Hebroni. Ó sì ṣe májẹ̀mú pẹ̀lú wọn ní Hebroni níwájú Olúwa, wọ́n sì fi òróró yan Dafidi ní ọba lórí Israẹli, gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ Olúwa láti ọwọ́ Samuẹli.
Tambem vieram todos os anciãos d'Israel ao rei, a Hebron, e David fez com elles alliança em Hebron, perante o Senhor: e ungiram a David rei sobre Israel, conforme a palavra do Senhor pelo ministerio de Samuel.
4 Dafidi àti gbogbo àwọn ọmọ Israẹli jáde lọ sí Jerusalẹmu (tí ṣe Jebusi). Àwọn Jebusi ara ilẹ̀ náà ń gbé níbẹ̀.
E partiu David e todo o Israel para Jerusalem, que é Jebus: porque ali estavam os jebuseos, moradores da terra.
5 Àwọn ará ìlú Jebusi sì wí fún Dafidi pé, “Ìwọ kò sì gbọdọ̀ wọ ìhín yìí wá.” Ṣùgbọ́n Dafidi kó ìlú odi Sioni—èyí tí í ṣe ìlú Dafidi.
E disseram os moradores de Jebus a David: Tu não entrarás aqui. Porém David ganhou a fortaleza de Sião, que é a cidade de David.
6 Dafidi ti wí pé, “Ẹnikẹ́ni tí ó bá tètè kọlu àwọn ará Jebusi ni yóò di olórí àti balógun.” Joabu ọmọ Seruiah sì kọ́kọ́ gòkè lọ, bẹ́ẹ̀ ni ó sì gba olórí.
Porque disse David: Qualquer que primeiro ferir os jebuseos será chefe e maioral. Então Joab, filho de Zeruia, subiu primeiro a ella; pelo que foi feito chefe.
7 Dafidi sì ń gbé inú ìlú odi, nítorí náà ni wọ́n fi ń pè é ni ìlú Dafidi.
E David habitou na fortaleza; pelo que se chamou a cidade de David.
8 Ó sì kọ́ àwọn ìlú náà yíkákiri; láti Millo yíkákiri; Joabu sì tún ìyókù àwọn ìlú náà ṣe.
E edificou a cidade ao redor, desde Millo até ao circuito: e Joab renovou o resto da cidade.
9 Bẹ́ẹ̀ ni Dafidi ń ga, ó sì pọ̀ sí i, nítorí pé Olúwa àwọn ọmọ-ogun wà pẹ̀lú rẹ̀.
E ia-se David cada vez mais augmentando e crescendo; porque o Senhor dos Exercitos era com elle.
10 Àwọn wọ̀nyí sì ni ìjòyè alágbára ọkùnrin Dafidi, àwọn pẹ̀lú gbogbo àwọn ọmọ Israẹli, wọ́n sì fún ìjọba rẹ̀ ní àtìlẹ́yìn tó lágbára láti mú un tàn káàkiri gbogbo ilẹ̀, gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti ṣèlérí.
E estes foram os chefes dos varões que David tinha, e que o apoiaram fortemente no seu reino, com todo o Israel, para o fazerem rei, conforme a palavra do Senhor, tocante a Israel.
11 Èyí sì ni iye àwọn akọni ọkùnrin Dafidi: Jaṣobeamu ọmọ Hakumoni, òun sì ni olórí nínú àwọn ìjòyè, ó sì gbé ọ̀kọ̀ rẹ̀ sókè lórí àwọn ọ̀ọ́dúnrún ènìyàn, àwọn ẹni tí ó pa ní ogun ẹ̀ẹ̀kan.
E estes foram do numero dos varões que David tinha: Jasobeam, hachmonita, o principal dos capitães, o qual, brandindo a sua lança contra trezentos, d'uma vez os matou.
12 Lẹ́yìn rẹ̀ sì ni Eleasari ọmọ Dodo àwọn ará Ahohi, ọ̀kan lára àwọn mẹ́ta ọkùnrin alágbára.
E, depois d'elle, Eleazar, filho de Dodo, o ahohita: elle estava entre os tres varões.
13 Ó sì wà pẹ̀lú Dafidi ní Pasi-Dammimu nígbà tí àwọn ará Filistini kó ara wọn jọ láti jagun, níbi tí ilẹ̀ kan wà tí ó kún fún ọkà barle. Àwọn ènìyàn sì sálọ kúrò níwájú Filistini.
Este esteve com David em Pas-dammim, quando os philisteos ali se ajuntaram á peleja, e o pedaço de campo estava cheio de cevada: e o povo fugiu de diante dos philisteos.
14 Ṣùgbọ́n wọ́n mú ìdúró wọn ní àárín pápá náà. Wọ́n sì gbà a wọ́n sì gún àwọn ará Filistini mọ́lẹ̀, Olúwa sì mú ìgbàlà ńlá fún wọn.
E pozeram-se no meio d'aquelle pedaço, e o defenderam, e feriram os philisteos; e obrou o Senhor um grande livramento.
15 Mẹ́ta nínú àwọn ọgbọ̀n ìjòyè sọ̀kalẹ̀ tọ́ Dafidi wá lọ sí orí àpáta nínú ihò Adullamu, nígbà tí àwọn ẹgbẹ́ Filistini sì dúró ní àfonífojì ní orí òkè Refaimu.
E tres dos trinta chefes desceram á penha, a David, na caverna d'Adullam: e o arraial dos philisteos estava acampado no valle de Rephaim.
16 Ní àsìkò náà Dafidi sì ń bẹ nínú ìlú odi, ẹgbẹ́ ogun àwọn ará Filistini sì ń bẹ ní Bẹtilẹhẹmu.
E David estava então no logar forte: e o alojamento dos philisteos estava então em Beth-lehem.
17 Dafidi sí pòǹgbẹ fún omi ó sì wí pé, “Háà, ẹnìkan yóò ha bu omi láti inú kànga ní ẹ̀gbẹ́ ẹnu-bodè Bẹtilẹhẹmu fún un mu?”
E desejou David, e disse: Quem me dará a beber da agua do poço de Beth-lehem, que está junto á porta?
18 Bẹ́ẹ̀ ni àwọn mẹ́ta náà sì là láti ogun ará Filistini, ó sì fa omi jáde láti inú kànga ní ẹ̀gbẹ́ ẹnu-bodè Bẹtilẹhẹmu ó sì gbé padà tọ Dafidi wá. Ṣùgbọ́n ó kọ̀ láti mu ú: dípò, ó sì tú jáde níwájú Olúwa.
Então aquelles tres romperam pelo arraial dos philisteos, e tiraram agua do poço de Beth-lehem, que estava á porta, e tomaram d'ella, e a trouxeram a David; porém David não a quiz beber, mas a derramou ao Senhor,
19 “Kí Ọlọ́run má jẹ́ kí èmi ó má ṣe ṣe èyí!” ó wí pé. “Ṣé kí èmi kí ó mú ẹ̀jẹ̀ ọkùnrin yí ẹni tí ó fi ẹ̀mí rẹ̀ wéwu?” Nítorí wọ́n fi ẹ̀mí wọn wéwu láti mú padà wá, Dafidi kò ní mu ú. Nǹkan wọ̀nyí ni àwọn akọni mẹ́ta ọkùnrin náà ṣe ohun ìyanu ńlá.
E disse: Nunca meu Deus permitta que faça tal! beberia eu o sangue d'estes varões com as suas vidas? Pois com perigo das suas vidas a trouxeram. E elle não a quiz beber: isto fizeram aquelles tres varões.
20 Abiṣai arákùnrin Joabu ìjòyè àwọn mẹ́ta. Ó sì gbé ọ̀kọ̀ rẹ̀ sókè lórí àwọn ọ̀ọ́dúnrún àwọn ènìyàn, àwọn ẹni tí ó pa, bẹ́ẹ̀ ni ó sì di olókìkí gẹ́gẹ́ bí àwọn mẹ́ta.
E tambem Abisai, irmão de Joab, foi chefe de tres, o qual, brandindo a sua lança contra trezentos, os feriu: e teve nome entre os tres.
21 Ó sì gba ìlọ́po ọlá lórí àwọn mẹ́tẹ̀ẹ̀ta ó sì di olórí wọn, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé a kò ka kún ara wọn.
Dos tres foi mais illustre do que os outros dois, pelo que foi chefe d'elles; porém não chegou aos primeiros tres.
22 Benaiah ọmọ Jehoiada ó sì jẹ́ akọni oníjà láti Kabṣeeli, ẹni tí ó ṣe iṣẹ́ agbára ńlá. Ó sì pa àwọn ọmọ Arieli méjì ti Moabu, ó sì tún sọ̀kalẹ̀ lọ sí inú ihò lákokò yìnyín dídì, ó sì pa kìnnìún kan
Tambem Benaias, filho de Joiada filho de um valente varão, grande em obras, de Kabseel: elle feriu a dois fortes leões de Moab; e tambem desceu, e feriu um leão dentro d'uma cova, no tempo da neve.
23 Ó sì pa ara Ejibiti ẹni tí ó ga ní ìwọ̀n ẹsẹ̀ méje àti ààbọ̀ ṣùgbọ́n àwọn ará Ejibiti wọn ní ọ̀kọ̀ gẹ́gẹ́ bí ìdábùú igi ahunṣọ àti ọ̀pá ní ọwọ́ rẹ̀, Benaiah sọ̀kalẹ̀ lórí rẹ̀ pẹ̀lú kùmọ̀. Ó sì gba ọ̀kọ̀ náà láti ọwọ́ ará Ejibiti ó sì pa á pẹ̀lú ọ̀kọ̀ rẹ̀.
Tambem feriu elle a um homem egypcio, homem de grande altura, de cinco covados: e trazia o egypcio uma lança na mão, como o orgão do tecelão; mas desceu contra elle com uma vara, e arrancou a lança da mão do egypcio, e o matou com a sua propria lança
24 Nǹkan wọ̀nyí sì ní ìwà akin Benaiah ọmọ Jehoiada; ohun náà pẹ̀lú sì di olókìkí gẹ́gẹ́ bí àwọn akọni ọkùnrin mẹ́ta.
Estas coisas fez Benaias, filho de Joiada; pelo que teve nome entre aquelles tres varões.
25 Ó sì ní ọlá púpọ̀ ju àwọn ọgbọ̀n lọ, ṣùgbọ́n a kò kà á láàrín àwọn mẹ́tẹ̀ẹ̀ta. Dafidi sì fi sí ìkáwọ́ àwọn ẹ̀ṣọ́.
Eis que dos trinta foi elle o mais illustre; comtudo não chegou aos tres: e David o poz sobre os da sua guarda.
26 Àwọn akọni ọkùnrin náà nìyí: Asaheli arákùnrin Joabu, Elhanani ọmọ Dodo láti Bẹtilẹhẹmu,
E foram os varões dos exercitos: Asael, irmão de Joab, Elhanan, filho de Dodo, de Beth-lehem,
27 Ṣamotu ará Harori, Helesi ará Peloni
Sammoth, o harodita, Heles, o pelonita,
28 Ira ọmọ Ikẹsi láti Tekoa, Abieseri láti Anatoti,
Ira, filho de Ikkes, o tekoita, Abiezer, o anathothita,
29 Sibekai ará Huṣati, láti ará Ahohi
Sibbechai, o husathita, Ilai, o ahohita,
30 Maharai ará Netofa, Heledi ọmọ Baanah ará Netofa,
Maharai, o netophathita, Heled, filho de Baena, o netophathita,
31 Itai ọmọ Ribai láti Gibeah ní Benjamini, Benaiah ará Piratoni,
Ithai, filho de Ribai, de Gibeah, dos filhos de Benjamin, Benaias, o pirathonita,
32 Hurai láti àfonífojì Gaaṣi, Abieli ará Arbati,
Hurai, do ribeiro de Gaas, Abiel, o arbathita,
33 Asmafeti ará Bahurimu Eliaba ará Ṣaalboni.
Asmaveth, o baharumita, Eliahba, o saalbonita.
34 Àwọn ọmọ Haṣemu ará Gisoni Jonatani ọmọ Ṣage ará Harari.
Dos filhos de Hasem, o gizonita: Jonathan, filho de Sage, o hararita,
35 Ahiamu ọmọ Sakari ará Harari, Elifali ọmọ Uri
Ahiam, filho de Sachar, o hararita, Eliphal, filho de Ur,
36 Heferi ará Mekerati, Ahijah ará Peloni,
Hepher, o mecheratita, Ahias, o pelonita,
37 Hesro ará Karmeli Naarai ọmọ Esbai,
Hesro, o carmelita, Naari, filho d'Esbai,
38 Joẹli arákùnrin Natani Mibari ọmọ Hagari,
Joel, irmão de Nathan, Mibhar, filho de Geri,
39 Seleki ará Ammoni, Naharai ará Beroti ẹni tí ó jẹ́ ẹni tí n ru ìhámọ́ra Joabu ọmọ Seruiah.
Zelek, o ammonita, Nahrai, o berothita, escudeiro de Joab, filho de Zeruia,
40 Ira ará Itri, Garebu ará Itri,
Ira, o ithrita, Gareb, o ithrita,
41 Uriah ará Hiti Sabadi ọmọ Ahlai.
Urias, o hethita, Zabad, filho de Ahlai,
42 Adina ọmọ Ṣisa ará Reubeni, ẹni tí ó jẹ́ ìjòyè ará Reubeni, àti pẹ̀lú ọgbọ́n rẹ̀.
Adina, filho de Siza, o rubenita, chefe dos rubenitas; todavia sobre elle havia trinta;
43 Hanani ọmọ Maaka. Jehoṣafati ará Mitini.
Hanam, filho de Maacha, e Josaphat, o mithnita,
44 Ussia ará Asiterati, Ṣama àti Jeieli àwọn ọmọ Hotami ará Aroeri,
Uzias, o astharathita, Sama e Jeiel, filhos de Hotham, o aroerita,
45 Jediaeli ọmọ Ṣimri, àti arákùnrin Joha ará Tisi
Jediael, filho de Simri, e Joha, seu irmão, o tisita,
46 Elieli ará Mahafi Jeribai àti Joṣafia àwọn ọmọ Elnaamu, Itimah ará Moabu,
Eliel, o mahavita, e Jeribai, e Joshavias, filhos d'Elnaam, e Ithma, o moabita,
47 Elieli, Obedi àti Jaasieli ará Mesoba.
Eliel, e Obed, e Jaasiel, e Mesobaia.