< 1 Chronicles 11 >

1 Gbogbo àwọn Israẹli kó ara wọn jọ pọ̀ sí ọ̀dọ̀ Dafidi ní Hebroni, wọ́n sì wí pé, “Ẹran-ara rẹ àti ẹ̀jẹ̀ rẹ ni àwa í ṣe.
Ensuite, tout Israël, alla trouver David à Hébron, disant: Vois, nous sommes tes os et ta chair.
2 Ní àtijọ́, kódà nígbà tí Saulu jẹ ọba, ìwọ ni ẹni tí ó darí Israẹli ní ojú ogun wọn. Olúwa Ọlọ́run rẹ sì wí fún ọ pé, ‘Ìwọ yóò sì jẹ́ olùṣọ́ Israẹli ènìyàn mi, ìwọ yóò sì jẹ́ olórí fún wọn.’”
Précédemment, quand Saül régnait encore, c'est toi qui conduisais et ramenais Israël, et le Seigneur notre Dieu avait dit: Tu seras le pasteur d'Israël, tu seras le chef de mon peuple.
3 Nígbà tí gbogbo àwọn ìjòyè Israẹli tí wọ́n ti wá sọ́dọ̀ ọba Dafidi ni Hebroni. Ó sì ṣe májẹ̀mú pẹ̀lú wọn ní Hebroni níwájú Olúwa, wọ́n sì fi òróró yan Dafidi ní ọba lórí Israẹli, gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ Olúwa láti ọwọ́ Samuẹli.
Et tous les anciens d'Israël allèrent en Hébron auprès du roi, et David fit alliance avec eux devant le Seigneur, en Hébron, et ils le sacrèrent roi d'Israël, selon la parole du Seigneur transmise par Samuel.
4 Dafidi àti gbogbo àwọn ọmọ Israẹli jáde lọ sí Jerusalẹmu (tí ṣe Jebusi). Àwọn Jebusi ara ilẹ̀ náà ń gbé níbẹ̀.
Et le roi et ses hommes partirent pour Jérusalem, la même que Jébus; les Jébuséens habitaient cette terre.
5 Àwọn ará ìlú Jebusi sì wí fún Dafidi pé, “Ìwọ kò sì gbọdọ̀ wọ ìhín yìí wá.” Ṣùgbọ́n Dafidi kó ìlú odi Sioni—èyí tí í ṣe ìlú Dafidi.
Et ils dirent à David: Tu n'entreras pas ici. Et il prit la forteresse de Sion, la même que la ville de David.
6 Dafidi ti wí pé, “Ẹnikẹ́ni tí ó bá tètè kọlu àwọn ará Jebusi ni yóò di olórí àti balógun.” Joabu ọmọ Seruiah sì kọ́kọ́ gòkè lọ, bẹ́ẹ̀ ni ó sì gba olórí.
Or, David avait dit: Celui qui, le premier, frappera le Jébuséen, sera général de mon armée; et Joab, fils de Sarvia, monta le premier à l'assaut, et il fut nommé général.
7 Dafidi sì ń gbé inú ìlú odi, nítorí náà ni wọ́n fi ń pè é ni ìlú Dafidi.
Et David s'établit dans la forteresse. A cause de cela, il l'appela Ville de David.
8 Ó sì kọ́ àwọn ìlú náà yíkákiri; láti Millo yíkákiri; Joabu sì tún ìyókù àwọn ìlú náà ṣe.
Et il bâtit la ville alentour.
9 Bẹ́ẹ̀ ni Dafidi ń ga, ó sì pọ̀ sí i, nítorí pé Olúwa àwọn ọmọ-ogun wà pẹ̀lú rẹ̀.
David alla ainsi grandissant, et le Seigneur tout-puissant était avec lui.
10 Àwọn wọ̀nyí sì ni ìjòyè alágbára ọkùnrin Dafidi, àwọn pẹ̀lú gbogbo àwọn ọmọ Israẹli, wọ́n sì fún ìjọba rẹ̀ ní àtìlẹ́yìn tó lágbára láti mú un tàn káàkiri gbogbo ilẹ̀, gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti ṣèlérí.
Voici les chefs des vaillants qui étaient avec David, et qui l'aidèrent à affermir son pouvoir sur tout Israël, selon la parole du Seigneur.
11 Èyí sì ni iye àwọn akọni ọkùnrin Dafidi: Jaṣobeamu ọmọ Hakumoni, òun sì ni olórí nínú àwọn ìjòyè, ó sì gbé ọ̀kọ̀ rẹ̀ sókè lórí àwọn ọ̀ọ́dúnrún ènìyàn, àwọn ẹni tí ó pa ní ogun ẹ̀ẹ̀kan.
Voici les noms des vaillants de David: Jésebada, fils d'Achaman, le premier des trente. Ce fut lui qui tira l'épée seul contre trois cents, et les tua tous en une fois.
12 Lẹ́yìn rẹ̀ sì ni Eleasari ọmọ Dodo àwọn ará Ahohi, ọ̀kan lára àwọn mẹ́ta ọkùnrin alágbára.
Après lui, Eléazar (Eléanan), fils de Dudi l'Ahonite; celui-ci était de la première triade.
13 Ó sì wà pẹ̀lú Dafidi ní Pasi-Dammimu nígbà tí àwọn ará Filistini kó ara wọn jọ láti jagun, níbi tí ilẹ̀ kan wà tí ó kún fún ọkà barle. Àwọn ènìyàn sì sálọ kúrò níwájú Filistini.
Il était avec David à Phasodamin, et les Philistins s'y réunirent pour livrer bataille. Or, il y avait un champ en partie couvert d'orge, et le peuple s'enfuit devant les Philistins.
14 Ṣùgbọ́n wọ́n mú ìdúró wọn ní àárín pápá náà. Wọ́n sì gbà a wọ́n sì gún àwọn ará Filistini mọ́lẹ̀, Olúwa sì mú ìgbàlà ńlá fún wọn.
Pour lui, il s'arrêta au milieu du champ, et il le sauva; il tailla en pièces les Philistins, et le Seigneur opéra une grande délivrance.
15 Mẹ́ta nínú àwọn ọgbọ̀n ìjòyè sọ̀kalẹ̀ tọ́ Dafidi wá lọ sí orí àpáta nínú ihò Adullamu, nígbà tí àwọn ẹgbẹ́ Filistini sì dúró ní àfonífojì ní orí òkè Refaimu.
Et trois, des trente chefs, se rendirent auprès de David, en la caverne d'Odollam, quand les Philistins étaient campés dans le val des Géants.
16 Ní àsìkò náà Dafidi sì ń bẹ nínú ìlú odi, ẹgbẹ́ ogun àwọn ará Filistini sì ń bẹ ní Bẹtilẹhẹmu.
David se tenait dans sa forteresse, et les Philistins avaient un poste à Bethléem.
17 Dafidi sí pòǹgbẹ fún omi ó sì wí pé, “Háà, ẹnìkan yóò ha bu omi láti inú kànga ní ẹ̀gbẹ́ ẹnu-bodè Bẹtilẹhẹmu fún un mu?”
Et David eut un désir, et il dit: Qui m'apportera à boire de l'eau de la citerne qui est sous la porte de Bethléem?
18 Bẹ́ẹ̀ ni àwọn mẹ́ta náà sì là láti ogun ará Filistini, ó sì fa omi jáde láti inú kànga ní ẹ̀gbẹ́ ẹnu-bodè Bẹtilẹhẹmu ó sì gbé padà tọ Dafidi wá. Ṣùgbọ́n ó kọ̀ láti mu ú: dípò, ó sì tú jáde níwájú Olúwa.
Et les trois vaillants s'ouvrirent un passage à travers le camp des Philistins, et ils puisèrent de l'eau dans la citerne sous la porte de Bethléem, et ils l'emportèrent, et ils la présentèrent à David; mais il ne voulut pas la boire, et il en fit une libation au Seigneur.
19 “Kí Ọlọ́run má jẹ́ kí èmi ó má ṣe ṣe èyí!” ó wí pé. “Ṣé kí èmi kí ó mú ẹ̀jẹ̀ ọkùnrin yí ẹni tí ó fi ẹ̀mí rẹ̀ wéwu?” Nítorí wọ́n fi ẹ̀mí wọn wéwu láti mú padà wá, Dafidi kò ní mu ú. Nǹkan wọ̀nyí ni àwọn akọni mẹ́ta ọkùnrin náà ṣe ohun ìyanu ńlá.
Et il dit: Dieu me protège, je n'en ferai rien; je croirais boire le sang des hommes qui ont exposé leur vie. Et il ne voulut point boire; voilà ce qu'avaient fait les trois vaillants.
20 Abiṣai arákùnrin Joabu ìjòyè àwọn mẹ́ta. Ó sì gbé ọ̀kọ̀ rẹ̀ sókè lórí àwọn ọ̀ọ́dúnrún àwọn ènìyàn, àwọn ẹni tí ó pa, bẹ́ẹ̀ ni ó sì di olókìkí gẹ́gẹ́ bí àwọn mẹ́ta.
Il y avait encore Abisaï (Abessa), frère de Joab; celui-ci était chef d'une seconde triade; il avait tiré l'épée contre trois cents qu'il avait tués tous en une fois, et il s'était fait un nom parmi les trois.
21 Ó sì gba ìlọ́po ọlá lórí àwọn mẹ́tẹ̀ẹ̀ta ó sì di olórí wọn, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé a kò ka kún ara wọn.
Et, dans sa triade, il fut illustre, et il en devint le chef; mais il n'alla pas aussi loin que ceux de la première triade.
22 Benaiah ọmọ Jehoiada ó sì jẹ́ akọni oníjà láti Kabṣeeli, ẹni tí ó ṣe iṣẹ́ agbára ńlá. Ó sì pa àwọn ọmọ Arieli méjì ti Moabu, ó sì tún sọ̀kalẹ̀ lọ sí inú ihò lákokò yìnyín dídì, ó sì pa kìnnìún kan
Il y avait aussi Banaïas, fils d'un homme vaillant, fils de Joad; il avait fait beaucoup de belles actions en faveur de Cabséel; ce fut lui qui tua deux Ariel de Moab, et qui descendit dans une citerne, un jour de neige, et qui y tua un lion.
23 Ó sì pa ara Ejibiti ẹni tí ó ga ní ìwọ̀n ẹsẹ̀ méje àti ààbọ̀ ṣùgbọ́n àwọn ará Ejibiti wọn ní ọ̀kọ̀ gẹ́gẹ́ bí ìdábùú igi ahunṣọ àti ọ̀pá ní ọwọ́ rẹ̀, Benaiah sọ̀kalẹ̀ lórí rẹ̀ pẹ̀lú kùmọ̀. Ó sì gba ọ̀kọ̀ náà láti ọwọ́ ará Ejibiti ó sì pa á pẹ̀lú ọ̀kọ̀ rẹ̀.
Il tua encore un Égyptien, homme prodigieux, haut de cinq coudées, qui tenait dans sa main une javeline semblable au mât d'un tisserand; il l'attaqua, n'ayant qu'un bâton, il lui arracha des mains sa javeline, et il le tua avec cette javeline.
24 Nǹkan wọ̀nyí sì ní ìwà akin Benaiah ọmọ Jehoiada; ohun náà pẹ̀lú sì di olókìkí gẹ́gẹ́ bí àwọn akọni ọkùnrin mẹ́ta.
Voilà ce que fit Banaïas, fils de Joad, et son nom figurait dans la seconde triade.
25 Ó sì ní ọlá púpọ̀ ju àwọn ọgbọ̀n lọ, ṣùgbọ́n a kò kà á láàrín àwọn mẹ́tẹ̀ẹ̀ta. Dafidi sì fi sí ìkáwọ́ àwọn ẹ̀ṣọ́.
Et il fut plus illustre que les trente; mais il n'alla pas si loin que la première triade, et David le mit à la tête de sa maison.
26 Àwọn akọni ọkùnrin náà nìyí: Asaheli arákùnrin Joabu, Elhanani ọmọ Dodo láti Bẹtilẹhẹmu,
Et les vaillants de l'armée étaient: Asaël, frère de Joab; Eléanan, fils de Dudi de Bethléem.
27 Ṣamotu ará Harori, Helesi ará Peloni
Samoth d'Arori, Hellès de Pheloni,
28 Ira ọmọ Ikẹsi láti Tekoa, Abieseri láti Anatoti,
Ora, fils d'Eccis de Thécoé; Abiézer d'Anathoth,
29 Sibekai ará Huṣati, láti ará Ahohi
Soboch d'Usathi, Héli d'Achoni,
30 Maharai ará Netofa, Heledi ọmọ Baanah ará Netofa,
Maraï de Netophath; Thaod, fils de Nooza de Netophath;
31 Itai ọmọ Ribai láti Gibeah ní Benjamini, Benaiah ará Piratoni,
Aïri, fils de Rebié de la montagne de Benjamin; Banaïas de Pharathon;
32 Hurai láti àfonífojì Gaaṣi, Abieli ará Arbati,
Uri de Nachali-Gaas, Abiel de Garabeth,
33 Asmafeti ará Bahurimu Eliaba ará Ṣaalboni.
Azbon de Baromi, Eliaba de Salaboni,
34 Àwọn ọmọ Haṣemu ará Gisoni Jonatani ọmọ Ṣage ará Harari.
Fils d'Aasam le Gizonéen; Jonathas, fils de Sola d'Arari;
35 Ahiamu ọmọ Sakari ará Harari, Elifali ọmọ Uri
Achim, fils d'Achar d'Arari; Elphat, fils de Thyrophar,
36 Heferi ará Mekerati, Ahijah ará Peloni,
De Mechorathri; Achias de Pheloni,
37 Hesro ará Karmeli Naarai ọmọ Esbai,
Eseré de Chadmadaïm; Naaré, fils d'Azobé;
38 Joẹli arákùnrin Natani Mibari ọmọ Hagari,
Johel, fils de Nathan; Mebaal, fils d'Agari;
39 Seleki ará Ammoni, Naharai ará Beroti ẹni tí ó jẹ́ ẹni tí n ru ìhámọ́ra Joabu ọmọ Seruiah.
Selé, fils de l'Ammonite; Nachor de Beroth, qui portait les armes du fils de Sarvia.
40 Ira ará Itri, Garebu ará Itri,
Iras de Jéther, Gaber de Jéther,
41 Uriah ará Hiti Sabadi ọmọ Ahlai.
Urie l'Hettéen; Zabet, fils d'Achaïas;
42 Adina ọmọ Ṣisa ará Reubeni, ẹni tí ó jẹ́ ìjòyè ará Reubeni, àti pẹ̀lú ọgbọ́n rẹ̀.
Adina, fils de Saiza, l'un des chefs de Ruben; et il y en avait trente avec lui.
43 Hanani ọmọ Maaka. Jehoṣafati ará Mitini.
Anan, fils de Moocha; Josaphat le Matthanéen,
44 Ussia ará Asiterati, Ṣama àti Jeieli àwọn ọmọ Hotami ará Aroeri,
Ozias d'Astaroth; Samatha et Jehiel, fils de Hothan d'Arari;
45 Jediaeli ọmọ Ṣimri, àti arákùnrin Joha ará Tisi
Jediel, fils de Sameri; et Jozaé son frère le Thosaïte,
46 Elieli ará Mahafi Jeribai àti Joṣafia àwọn ọmọ Elnaamu, Itimah ará Moabu,
Elihel le Mahoïte, et Jaribi, et Josias son fils, et Jethama le Moabite,
47 Elieli, Obedi àti Jaasieli ará Mesoba.
Daliel, et Obeth, et Jersiel le Mesobéen.

< 1 Chronicles 11 >