< 1 Chronicles 11 >

1 Gbogbo àwọn Israẹli kó ara wọn jọ pọ̀ sí ọ̀dọ̀ Dafidi ní Hebroni, wọ́n sì wí pé, “Ẹran-ara rẹ àti ẹ̀jẹ̀ rẹ ni àwa í ṣe.
And gathered are all Israel unto David to Hebron, saying, 'Lo, thy bone and thy flesh [are] we;
2 Ní àtijọ́, kódà nígbà tí Saulu jẹ ọba, ìwọ ni ẹni tí ó darí Israẹli ní ojú ogun wọn. Olúwa Ọlọ́run rẹ sì wí fún ọ pé, ‘Ìwọ yóò sì jẹ́ olùṣọ́ Israẹli ènìyàn mi, ìwọ yóò sì jẹ́ olórí fún wọn.’”
even in time past, even in Saul's being king, it is thou who art taking out and bringing in Israel, and Jehovah thy God saith to thee: Thou dost feed My people Israel, and thou art leader over My people Israel.'
3 Nígbà tí gbogbo àwọn ìjòyè Israẹli tí wọ́n ti wá sọ́dọ̀ ọba Dafidi ni Hebroni. Ó sì ṣe májẹ̀mú pẹ̀lú wọn ní Hebroni níwájú Olúwa, wọ́n sì fi òróró yan Dafidi ní ọba lórí Israẹli, gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ Olúwa láti ọwọ́ Samuẹli.
And all the elders of Israel come in unto the king to Hebron, and David maketh with them a covenant in Hebron before Jehovah, and they anoint David for king over Israel, according to the word of Jehovah by the hand of Samuel.
4 Dafidi àti gbogbo àwọn ọmọ Israẹli jáde lọ sí Jerusalẹmu (tí ṣe Jebusi). Àwọn Jebusi ara ilẹ̀ náà ń gbé níbẹ̀.
And David goeth, and all Israel, to Jerusalem — it [is] Jebus — and there the Jebusite, the inhabitants of the land.
5 Àwọn ará ìlú Jebusi sì wí fún Dafidi pé, “Ìwọ kò sì gbọdọ̀ wọ ìhín yìí wá.” Ṣùgbọ́n Dafidi kó ìlú odi Sioni—èyí tí í ṣe ìlú Dafidi.
And the inhabitants of Jebus say to David, 'Thou dost not come in hither;' and David captureth the fortress of Zion — it [is] the city of David.
6 Dafidi ti wí pé, “Ẹnikẹ́ni tí ó bá tètè kọlu àwọn ará Jebusi ni yóò di olórí àti balógun.” Joabu ọmọ Seruiah sì kọ́kọ́ gòkè lọ, bẹ́ẹ̀ ni ó sì gba olórí.
And David saith, 'Whoever smiteth the Jebusite first doth become head and prince;' and go up first doth Joab son of Zeruiah and becometh head.
7 Dafidi sì ń gbé inú ìlú odi, nítorí náà ni wọ́n fi ń pè é ni ìlú Dafidi.
And David dwelleth in the fortress, therefore they have called it, 'City of David;'
8 Ó sì kọ́ àwọn ìlú náà yíkákiri; láti Millo yíkákiri; Joabu sì tún ìyókù àwọn ìlú náà ṣe.
and he buildeth the city round about, from Millo, and unto the circumference, and Joab restoreth the rest of the city.
9 Bẹ́ẹ̀ ni Dafidi ń ga, ó sì pọ̀ sí i, nítorí pé Olúwa àwọn ọmọ-ogun wà pẹ̀lú rẹ̀.
And David goeth, going on and becoming great, and Jehovah of Hosts [is] with him.
10 Àwọn wọ̀nyí sì ni ìjòyè alágbára ọkùnrin Dafidi, àwọn pẹ̀lú gbogbo àwọn ọmọ Israẹli, wọ́n sì fún ìjọba rẹ̀ ní àtìlẹ́yìn tó lágbára láti mú un tàn káàkiri gbogbo ilẹ̀, gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti ṣèlérí.
And these [are] heads of the mighty ones whom David hath, who are strengthening themselves with him in his kingdom, with all Israel, to cause him to reign, according to the word of Jehovah, over Israel.
11 Èyí sì ni iye àwọn akọni ọkùnrin Dafidi: Jaṣobeamu ọmọ Hakumoni, òun sì ni olórí nínú àwọn ìjòyè, ó sì gbé ọ̀kọ̀ rẹ̀ sókè lórí àwọn ọ̀ọ́dúnrún ènìyàn, àwọn ẹni tí ó pa ní ogun ẹ̀ẹ̀kan.
And this [is] an account of the mighty ones whom David hath: Jashobeam son of a Hachmonite [is] head of the thirty; he is lifting up his spear against three hundred — wounded, at one time.
12 Lẹ́yìn rẹ̀ sì ni Eleasari ọmọ Dodo àwọn ará Ahohi, ọ̀kan lára àwọn mẹ́ta ọkùnrin alágbára.
And after him [is] Eleazar son of Dodo the Ahohite, he [is] among the three mighty;
13 Ó sì wà pẹ̀lú Dafidi ní Pasi-Dammimu nígbà tí àwọn ará Filistini kó ara wọn jọ láti jagun, níbi tí ilẹ̀ kan wà tí ó kún fún ọkà barle. Àwọn ènìyàn sì sálọ kúrò níwájú Filistini.
he hath been with David in Pas-Dammim, and the Philistines have been gathered there to battle, and a portion of the field is full of barley, and the people have fled from the face of the Philistines,
14 Ṣùgbọ́n wọ́n mú ìdúró wọn ní àárín pápá náà. Wọ́n sì gbà a wọ́n sì gún àwọn ará Filistini mọ́lẹ̀, Olúwa sì mú ìgbàlà ńlá fún wọn.
and they station themselves in the midst of the portion, and deliver it, and smite the Philistines, and Jehovah saveth — a great salvation.
15 Mẹ́ta nínú àwọn ọgbọ̀n ìjòyè sọ̀kalẹ̀ tọ́ Dafidi wá lọ sí orí àpáta nínú ihò Adullamu, nígbà tí àwọn ẹgbẹ́ Filistini sì dúró ní àfonífojì ní orí òkè Refaimu.
And three of the thirty heads go down on the rock unto David, unto the cave of Adullam, and the host of the Philistines is encamping in the valley of Rephaim,
16 Ní àsìkò náà Dafidi sì ń bẹ nínú ìlú odi, ẹgbẹ́ ogun àwọn ará Filistini sì ń bẹ ní Bẹtilẹhẹmu.
and David [is] then in the fortress, and the station of the Philistines [is] then in Beth-Lehem,
17 Dafidi sí pòǹgbẹ fún omi ó sì wí pé, “Háà, ẹnìkan yóò ha bu omi láti inú kànga ní ẹ̀gbẹ́ ẹnu-bodè Bẹtilẹhẹmu fún un mu?”
and David longeth, and saith, 'Who doth give me to drink water from the well of Beth-Lehem, that [is] at the gate!'
18 Bẹ́ẹ̀ ni àwọn mẹ́ta náà sì là láti ogun ará Filistini, ó sì fa omi jáde láti inú kànga ní ẹ̀gbẹ́ ẹnu-bodè Bẹtilẹhẹmu ó sì gbé padà tọ Dafidi wá. Ṣùgbọ́n ó kọ̀ láti mu ú: dípò, ó sì tú jáde níwájú Olúwa.
And the three break through the camp of the Philistines, and draw water from the well of Beth-Lehem, that [is] at the gate, and bear and bring in unto David, and David hath not been willing to drink it, and poureth it out to Jehovah,
19 “Kí Ọlọ́run má jẹ́ kí èmi ó má ṣe ṣe èyí!” ó wí pé. “Ṣé kí èmi kí ó mú ẹ̀jẹ̀ ọkùnrin yí ẹni tí ó fi ẹ̀mí rẹ̀ wéwu?” Nítorí wọ́n fi ẹ̀mí wọn wéwu láti mú padà wá, Dafidi kò ní mu ú. Nǹkan wọ̀nyí ni àwọn akọni mẹ́ta ọkùnrin náà ṣe ohun ìyanu ńlá.
and saith, 'Far be it from me, by my God, to do this; the blood of these men do I drink with their lives? for with their lives they have brought it;' and he was not willing to drink it; these [things] did the three mighty ones.
20 Abiṣai arákùnrin Joabu ìjòyè àwọn mẹ́ta. Ó sì gbé ọ̀kọ̀ rẹ̀ sókè lórí àwọn ọ̀ọ́dúnrún àwọn ènìyàn, àwọn ẹni tí ó pa, bẹ́ẹ̀ ni ó sì di olókìkí gẹ́gẹ́ bí àwọn mẹ́ta.
And Abishai brother of Joab, he hath been head of the three: and he is lifting up his spear against three hundred — wounded, and hath a name among three.
21 Ó sì gba ìlọ́po ọlá lórí àwọn mẹ́tẹ̀ẹ̀ta ó sì di olórí wọn, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé a kò ka kún ara wọn.
Of the three by the two he is honoured, and becometh their head; and unto the [first] three he hath not come.
22 Benaiah ọmọ Jehoiada ó sì jẹ́ akọni oníjà láti Kabṣeeli, ẹni tí ó ṣe iṣẹ́ agbára ńlá. Ó sì pa àwọn ọmọ Arieli méjì ti Moabu, ó sì tún sọ̀kalẹ̀ lọ sí inú ihò lákokò yìnyín dídì, ó sì pa kìnnìún kan
Benaiah son of Jehoiada, son of a man of valour, of great deeds, from Kabzeel: he hath smitten the two lion-like Moabites, and he hath gone down and smitten the lion in the midst of the pit, in the day of snow.
23 Ó sì pa ara Ejibiti ẹni tí ó ga ní ìwọ̀n ẹsẹ̀ méje àti ààbọ̀ ṣùgbọ́n àwọn ará Ejibiti wọn ní ọ̀kọ̀ gẹ́gẹ́ bí ìdábùú igi ahunṣọ àti ọ̀pá ní ọwọ́ rẹ̀, Benaiah sọ̀kalẹ̀ lórí rẹ̀ pẹ̀lú kùmọ̀. Ó sì gba ọ̀kọ̀ náà láti ọwọ́ ará Ejibiti ó sì pa á pẹ̀lú ọ̀kọ̀ rẹ̀.
And he hath smitten the man, the Egyptian — a man of measure, five by the cubit — and in the hand of the Egyptian [is] a spear like a beam of weavers, and he goeth down unto him with a rod, and taketh violently away the spear out of the hand of the Egyptian, and slayeth him with his own spear.
24 Nǹkan wọ̀nyí sì ní ìwà akin Benaiah ọmọ Jehoiada; ohun náà pẹ̀lú sì di olókìkí gẹ́gẹ́ bí àwọn akọni ọkùnrin mẹ́ta.
These [things] hath Benaiah son of Jehoiada done, and hath a name among the three mighty ones.
25 Ó sì ní ọlá púpọ̀ ju àwọn ọgbọ̀n lọ, ṣùgbọ́n a kò kà á láàrín àwọn mẹ́tẹ̀ẹ̀ta. Dafidi sì fi sí ìkáwọ́ àwọn ẹ̀ṣọ́.
Of the thirty, lo, he [is] honoured, and unto the [first] three he hath not come, and David setteth him over his guard.
26 Àwọn akọni ọkùnrin náà nìyí: Asaheli arákùnrin Joabu, Elhanani ọmọ Dodo láti Bẹtilẹhẹmu,
And the mighty ones of the forces [are] Asahel brother of Joab, Elhanan son of Dodo of Beth-Lehem,
27 Ṣamotu ará Harori, Helesi ará Peloni
Shammoth the Harorite, Helez the Pelonite,
28 Ira ọmọ Ikẹsi láti Tekoa, Abieseri láti Anatoti,
Ira son of Ikkesh the Tekoite, Abi-Ezer the Annethothite,
29 Sibekai ará Huṣati, láti ará Ahohi
Sibbecai the Hushathite, Ilai the Ahohite,
30 Maharai ará Netofa, Heledi ọmọ Baanah ará Netofa,
Maharai the Netophathite, Heled son of Baanah the Netophathite,
31 Itai ọmọ Ribai láti Gibeah ní Benjamini, Benaiah ará Piratoni,
Ithai son of Ribai of Gibeah, of the sons of Benjamin, Benaiah the Pirathonite,
32 Hurai láti àfonífojì Gaaṣi, Abieli ará Arbati,
Hurai of the brooks of Gaash, Abiel the Arbathite,
33 Asmafeti ará Bahurimu Eliaba ará Ṣaalboni.
Azmaveth the Baharumite, Eliahba the Shaalbonite,
34 Àwọn ọmọ Haṣemu ará Gisoni Jonatani ọmọ Ṣage ará Harari.
the sons of Hashem the Gizonite, Jonathan son of Shage the Hararite,
35 Ahiamu ọmọ Sakari ará Harari, Elifali ọmọ Uri
Ahiam son of Sacar the Hararite, Eliphal son of Ur,
36 Heferi ará Mekerati, Ahijah ará Peloni,
Hepher the Mecherathite, Ahijah the Pelonite,
37 Hesro ará Karmeli Naarai ọmọ Esbai,
Hezor the Carmelite, Naarai son of Ezbai,
38 Joẹli arákùnrin Natani Mibari ọmọ Hagari,
Joel brother of Nathan, Mibhar son of Haggeri,
39 Seleki ará Ammoni, Naharai ará Beroti ẹni tí ó jẹ́ ẹni tí n ru ìhámọ́ra Joabu ọmọ Seruiah.
Zelek the Ammonite, Naharai the Berothite, bearer of the weapons of Joab son of Zeruiah,
40 Ira ará Itri, Garebu ará Itri,
Ira the Ithrite, Gareb the Ithrite,
41 Uriah ará Hiti Sabadi ọmọ Ahlai.
Uriah the Hittite, Zabad son of Ahlai,
42 Adina ọmọ Ṣisa ará Reubeni, ẹni tí ó jẹ́ ìjòyè ará Reubeni, àti pẹ̀lú ọgbọ́n rẹ̀.
Adina son of Shiza the Reubenite, head of the Reubenites, and by him thirty,
43 Hanani ọmọ Maaka. Jehoṣafati ará Mitini.
Hanan son of Maachah, and Joshaphat the Mithnite,
44 Ussia ará Asiterati, Ṣama àti Jeieli àwọn ọmọ Hotami ará Aroeri,
Uzzia the Ashterathite, Shama and Jehiel sons of Hothan the Aroerite,
45 Jediaeli ọmọ Ṣimri, àti arákùnrin Joha ará Tisi
Jediael son of Shimri, and Joha his brother the Tizite,
46 Elieli ará Mahafi Jeribai àti Joṣafia àwọn ọmọ Elnaamu, Itimah ará Moabu,
Eliel the Mahavite, and Jeribai, and Joshaviah, sons of Elnaam, and Ithmah the Moabite,
47 Elieli, Obedi àti Jaasieli ará Mesoba.
Eliel, and Obed, and Jaasiel the Mesobaite.

< 1 Chronicles 11 >