< 1 Chronicles 10 >

1 Nísinsin yìí, àwọn ará Filistini dojú ìjà kọ Israẹli, àwọn ará Israẹli sì sálọ kúrò níwájú wọn, a sì pa ọ̀pọ̀ wọn sí orí òkè Gilboa.
Forsothe Filisteis fouyten ayens Israel, and the sones of Israel fledden Palestyns, and felden doun woundid in the hil of Gelboe.
2 Àwọn ará Filistini sí lépa Saulu gidigidi àti àwọn ọmọ rẹ̀. Wọ́n sì pa àwọn ọmọ rẹ̀. Jonatani, Abinadabu àti Malikiṣua.
And whanne Filisteis hadde neiyed pursuynge Saul and hise sones, thei killiden Jonathan, and Abynadab, and Melchisue, the sones of Saul.
3 Ogun náà sí gbóná janjan fún Saulu, nígbà tí àwọn tafàtafà sì lé e bá, wọ́n sì ṣá a lọ́gbẹ́.
And the batel was agreggid ayens Saul; and men archeris foundun hym, and woundiden hym with dartis.
4 Saulu sì sọ fún ẹni tí ó gbé ìhámọ́ra rẹ̀ pé, “Fa idà rẹ yọ, kí o sì fi gún mi, kí àwọn aláìkọlà wọ̀nyí má wá láti bú mi.” Ṣùgbọ́n ẹni tí ó ń gbé ìhámọ́ra rẹ̀ ń bẹ̀rù, kò sì le ṣe é, bẹ́ẹ̀ ni Saulu mú idà tirẹ̀ ó sì ṣubú lé e.
And Saul seide to his squiere, Drawe out thi swerd, and sle me, leste these vncircumcidid men come, and scorne me. Sothli his squyer was aferd bi drede, and nolde do this; therfor Saul took a swerd, and felde on it.
5 Nígbà tí agbé-ìhámọ́ra rí pé Saulu ti kú, òhun pẹ̀lú ṣubú lórí idà tirẹ̀, ó sì kú.
And whanne his squyer hadde seyn this, that is, that Saul was deed, he felde also on his swerd, and was deed.
6 Bẹ́ẹ̀ ni Saulu àti ọmọ rẹ̀ mẹ́tẹ̀ẹ̀ta kú, gbogbo ilé rẹ̀ sì kú ṣọ̀kan, lọ́jọ́ kan náà.
Therfor Saul perischide, and hise thre sones, and al his hows felde doun togidere.
7 Nígbà tí gbogbo àwọn ọmọ Israẹli tí ó wà ní pẹ̀tẹ́lẹ̀ rí wí pé àwọn ọmọ-ogun ti sálọ àti pé Saulu àti àwọn ọmọ rẹ̀ ti kú wọ́n kọ àwọn ìlú wọn sílẹ̀, wọ́n sì sálọ. Àwọn ará Filistini wá, wọ́n sì jókòó nínú wọn.
And whanne the men of Israel, that dwelliden in feeldi places, hadden seyn this, thei fledden; and whanne Saul and hise sones weren deed, thei forsoken her citees, and weren scaterid hidur and thidur; and Filisteis camen, and dwelliden in tho.
8 Ní ọjọ́ kejì, nígbà tí àwọn ará Filistini wá láti kó òkú, wọ́n rí Saulu àti àwọn ọmọ rẹ̀ tí wọ́n ṣubú sórí òkè Gilboa.
Therfor in the tother day Filisteis drowen awei the spuylis of slayn men, and founden Saul and hise sones liggynge in the hil of Gelboe.
9 Wọ́n bọ́ ní aṣọ, wọ́n sì gbé orí rẹ̀ àti ìhámọ́ra rẹ̀, wọ́n sì rán ìránṣẹ́ lọ káàkiri ilẹ̀ àwọn ará Filistini láti kéde ìròyìn náà láàrín àwọn òrìṣà wọn àti àwọn ènìyàn wọn.
And whanne thei hadden spuylid hym, and hadden gird of the heed, and hadden maad hym nakid of armeris, thei senten in to her lond, that it schulde be borun aboute, and schulde be schewid in the templis of idols and to puplis;
10 Wọ́n gbé ìhámọ́ra rẹ̀ sí inú ilé tí wọ́n kọ́ fún òrìṣà wọn, wọ́n sì fi orí rẹ̀ kọ́ sí inú ilé Dagoni.
forsothe thei halewiden his armeris in the temple of her god, and thei settiden the heed in the temple of Dagon.
11 Nígbà tí gbogbo àwọn olùgbé Jabesi—Gileadi gbọ́ gbogbo ohun tí àwọn ará Filistini ṣe fún Saulu,
Whanne men of Jabes of Galad hadden herd this, that is, alle thingis whiche the Filisteis diden on Saul,
12 gbogbo àwọn akọni ọkùnrin wọn lọ láti mú àwọn ará Saulu àti àwọn ọmọ rẹ̀, wọ́n sì kó wọn wá sí Jabesi. Nígbà náà, wọ́n sin egungun wọn sábẹ́ igi óákù ní Jabesi, wọ́n sì gbààwẹ̀ fún ọjọ́ méje.
alle stronge men risiden togidere, and took the deed bodies of Saul and of hise sones, and brouyten tho in to Jabes; and thei birieden the boonus of hem vndur an ook, that was in Jabes; and thei fastiden seuene daies.
13 Saulu kú nítorí kò ṣe òtítọ́ sí Olúwa, kò pa ọ̀rọ̀ Olúwa mọ́ pẹ̀lú, ó tọ abókùúsọ̀rọ̀ lọ fún ìtọ́sọ́nà.
Therfor Saul was deed for hise wickidnessis, for he brak the comaundement of the Lord, whiche he comaundide, and kepte not it, but ferthirmore also he took counsel at a womman hauynge a feend spekynge in the wombe, and he hopide not in the Lord;
14 Kò sì béèrè lọ́wọ́ Olúwa, bẹ́ẹ̀ ni Olúwa pa á, Ó sì yí ìjọba náà padà sọ́dọ̀ Dafidi ọmọ Jese.
for which thing both the Lord killide hym, and translatide his rewme to Dauid, sone of Ysay.

< 1 Chronicles 10 >