< 1 Chronicles 10 >

1 Nísinsin yìí, àwọn ará Filistini dojú ìjà kọ Israẹli, àwọn ará Israẹli sì sálọ kúrò níwájú wọn, a sì pa ọ̀pọ̀ wọn sí orí òkè Gilboa.
Now the Philistines fought against Israel: and the men of Israel fled before the Philistines, and there fell down [many] slain on mount Gilboa'.
2 Àwọn ará Filistini sí lépa Saulu gidigidi àti àwọn ọmọ rẹ̀. Wọ́n sì pa àwọn ọmọ rẹ̀. Jonatani, Abinadabu àti Malikiṣua.
And the Philistines pursuing them overtook Saul and his sons; and the Philistines smote Jonathan, and 'Abinadab, and Malkishua', the sons of Saul.
3 Ogun náà sí gbóná janjan fún Saulu, nígbà tí àwọn tafàtafà sì lé e bá, wọ́n sì ṣá a lọ́gbẹ́.
And the battle was heavy against Saul, and he was found by the archers, and he was greatly in dread of the archers.
4 Saulu sì sọ fún ẹni tí ó gbé ìhámọ́ra rẹ̀ pé, “Fa idà rẹ yọ, kí o sì fi gún mi, kí àwọn aláìkọlà wọ̀nyí má wá láti bú mi.” Ṣùgbọ́n ẹni tí ó ń gbé ìhámọ́ra rẹ̀ ń bẹ̀rù, kò sì le ṣe é, bẹ́ẹ̀ ni Saulu mú idà tirẹ̀ ó sì ṣubú lé e.
And Saul said to his armor-bearer, Draw thy sword, and thrust me through therewith; lest these uncircumcised come and wantonly ill-use me. But his armor-bearer would not; for he was greatly afraid: wherefore Saul took the sword and fell upon it.
5 Nígbà tí agbé-ìhámọ́ra rí pé Saulu ti kú, òhun pẹ̀lú ṣubú lórí idà tirẹ̀, ó sì kú.
And when the armor-bearer saw that Saul was dead, then fell he likewise on the sword, and died.
6 Bẹ́ẹ̀ ni Saulu àti ọmọ rẹ̀ mẹ́tẹ̀ẹ̀ta kú, gbogbo ilé rẹ̀ sì kú ṣọ̀kan, lọ́jọ́ kan náà.
Thus died Saul and his three sons; and all his household died together.
7 Nígbà tí gbogbo àwọn ọmọ Israẹli tí ó wà ní pẹ̀tẹ́lẹ̀ rí wí pé àwọn ọmọ-ogun ti sálọ àti pé Saulu àti àwọn ọmọ rẹ̀ ti kú wọ́n kọ àwọn ìlú wọn sílẹ̀, wọ́n sì sálọ. Àwọn ará Filistini wá, wọ́n sì jókòó nínú wọn.
And when all the men of Israel that were in the valley saw that they had fled, and that Saul and his sons were dead: they forsook their cities, and fled, and the Philistines came and dwelt in them.
8 Ní ọjọ́ kejì, nígbà tí àwọn ará Filistini wá láti kó òkú, wọ́n rí Saulu àti àwọn ọmọ rẹ̀ tí wọ́n ṣubú sórí òkè Gilboa.
And it came to pass on the morrow, that the Philistines came to strip the slain; and they found Saul and his sons fallen on mount Gilboa'.
9 Wọ́n bọ́ ní aṣọ, wọ́n sì gbé orí rẹ̀ àti ìhámọ́ra rẹ̀, wọ́n sì rán ìránṣẹ́ lọ káàkiri ilẹ̀ àwọn ará Filistini láti kéde ìròyìn náà láàrín àwọn òrìṣà wọn àti àwọn ènìyàn wọn.
And they stripped him, and they carried away his head, and his armor, and sent them into the land of the Philistines round about, to publish it to their idols, and to the people.
10 Wọ́n gbé ìhámọ́ra rẹ̀ sí inú ilé tí wọ́n kọ́ fún òrìṣà wọn, wọ́n sì fi orí rẹ̀ kọ́ sí inú ilé Dagoni.
And they put his armor in the house of their gods, and his skull they fastened in the temple of Dagon.
11 Nígbà tí gbogbo àwọn olùgbé Jabesi—Gileadi gbọ́ gbogbo ohun tí àwọn ará Filistini ṣe fún Saulu,
And when all Yabesh-gil'ad heard all the Philistines had done to Saul:
12 gbogbo àwọn akọni ọkùnrin wọn lọ láti mú àwọn ará Saulu àti àwọn ọmọ rẹ̀, wọ́n sì kó wọn wá sí Jabesi. Nígbà náà, wọ́n sin egungun wọn sábẹ́ igi óákù ní Jabesi, wọ́n sì gbààwẹ̀ fún ọjọ́ méje.
Then arose all the valiant men, and carried away the body of Saul, and the bodies of his sons, and brought them to Yabesh; and they buried their bones under the terebinth in Yabesh, and they fasted seven days.
13 Saulu kú nítorí kò ṣe òtítọ́ sí Olúwa, kò pa ọ̀rọ̀ Olúwa mọ́ pẹ̀lú, ó tọ abókùúsọ̀rọ̀ lọ fún ìtọ́sọ́nà.
And [so] died Saul for his unfaithfulness which he had committed against the Lord, because of the word of the Lord which he had not kept, and also for asking one of a familiar spirit to inquire of the same;
14 Kò sì béèrè lọ́wọ́ Olúwa, bẹ́ẹ̀ ni Olúwa pa á, Ó sì yí ìjọba náà padà sọ́dọ̀ Dafidi ọmọ Jese.
And had not inquired of the Lord: therefore he slew him, and turned over the kingdom unto David the son of Jesse.

< 1 Chronicles 10 >