< Qɵl-bayawandiki sǝpǝr 21 >
1 Jǝnubta turuxluⱪ Arad mǝmlikitining Ⱪanaaniylardin bolƣan padixaⱨi Israillarning Atarim yoli bilǝn keliwatⱪanliⱪini anglap, qiⱪip ular bilǝn soⱪuxup, nǝqqǝylǝnni tutⱪun ⱪilip kǝtti.
Nígbà tí ọba Aradi ará Kenaani, tí ń gbé ní gúúsù gbọ́ wí pé Israẹli ń bọ̀ wá ní ojú ọ̀nà Atarimu, ó bá Israẹli jà ó sì fi agbára mú díẹ̀ lára wọn.
2 Andin Israillar Pǝrwǝrdigarƣa ⱪǝsǝm iqip: «Əgǝr bu hǝlⱪni bizning ⱪolimizƣa pütünlǝy tapxuridiƣan bolsang, ularning xǝⱨǝrlirini wǝyran ⱪilip taxlaymiz» — dedi.
Nígbà náà ni Israẹli jẹ́ ẹ̀jẹ́ fún Olúwa pé, “Bí o bá lè fi àwọn ènìyàn yìí lé wa lọ́wọ́, gbogbo ìlú wọn ni a ó parun.”
3 Pǝrwǝrdigar Israillarning pǝryadini anglap, Ⱪanaanliylarni ularning ⱪoliƣa tapxurdi, xuning bilǝn ular Ⱪanaaniylarni ularning xǝⱨǝrliri bilǝn ⱪoxup wǝyran ⱪildi; xu sǝwǝbtin ular xu yǝrni «Hormaⱨ» dǝp atidi.
Olúwa gbọ́ ẹ̀bẹ̀ àwọn ọmọ Israẹli, ó sì fi àwọn ará Kenaani lé wọn lọ́wọ́. Wọ́n pa wọ́n run pátápátá; torí náà ni a ṣe ń pe ibẹ̀ ní Horma.
4 Ular Ⱨor teƣidin yolƣa qiⱪip, Edom zeminini aylinip ɵtüx üqün, Ⱪizil dengiz boyidiki yolni boylap mangdi; hǝlⱪ muxu yol sǝwǝbidin kɵnglidǝ tolimu taⱪǝtsiz bolup,
Wọ́n rin ìrìnàjò láti òkè Hori lọ sí ọ̀nà tó lọ sí Òkun Pupa, láti kọjá yípo Edomu. Ṣùgbọ́n àwọn ènìyàn bínú ní ojú ọ̀nà;
5 Hudaƣa wǝ Musaƣa ⱪarxi qiⱪip: — Silǝr nemǝ üqün bizni qɵl-jǝziridǝ ɵlsun dǝp Misir zeminidin baxlap qiⱪⱪansilǝr? Bu yǝrdǝ ya axliⱪ, ya su yoⱪ, kɵnglimiz bu ǝrzimǝs nanlardin bizar boldi, deyixti.
wọ́n sì sọ̀rọ̀ lòdì sí Ọlọ́run àti Mose, wọ́n wí pé, “Èéṣe tí ìwọ fi mú wa jáde láti Ejibiti kí a ba le wá kú sí aginjù yìí? Kò sí oúnjẹ! Kò sì sí omi! Àwa sì kórìíra oúnjẹ tí kò dára yìí!”
6 Xu sǝwǝbtin Pǝrwǝrdigar ularning arisiƣa zǝⱨǝrlik yilanlarni ǝwǝtti; yilanlar ularni qaⱪti, xu sǝwǝbtin Israillardin nurƣun adǝm ɵlüp kǝtti.
Nígbà náà ni Olúwa rán ejò olóró sí àárín wọn; wọ́n gé àwọn ènìyàn jẹ, ọ̀pọ̀ àwọn ọmọ Israẹli sì kú.
7 Hǝlⱪ Musaning aldiƣa kelip uningƣa: — Biz aƣzimizni buzup, Pǝrwǝrdigarƣa ⱨǝm sanga ⱨujum ⱪilip, yaman gǝp ⱪilip gunaⱨ ⱪilduⱪ; Pǝrwǝrdigarƣa tilawǝt ⱪilsang, u bu yilanlarni arimizdin elip kǝtkǝy, — dewidi, Musa hǝlⱪ üqün dua ⱪildi.
Àwọn ènìyàn sì wá sí ọ̀dọ̀ Mose wọn wí pé, “A ti dá ẹ̀ṣẹ̀ nígbà tí asọ̀rọ̀-òdì sí Olúwa àti sí ìwọ pẹ̀lú. Gba àdúrà pé kí Olúwa mú ejò náà kúrò lọ́dọ̀ wa.” Nígbà náà ni Mose gbàdúrà fún àwọn ènìyàn.
8 Pǝrwǝrdigar Musaƣa: — Sǝn bir zǝⱨǝrlik yilanning xǝklini yasap hadiƣa esip ⱪoyƣin; yilan qeⱪiwalƣan ⱨǝrbiri uningƣa ⱪarisila ⱪayta ⱨayatⱪa erixidu, — dedi.
Olúwa sọ fún Mose pé, “Rọ ejò, a ó sì gbé e kọ́ sókè lórí igi, ẹni tí ejò bá ti gé jẹ lè wò ó yóò sì yè.”
9 Musa mistin bir yilan yasitip hadiƣa esip ⱪoydi; wǝ xundaⱪ boldiki, yilan birkimni qeⱪiwalƣan bolsa, u bu mis yilanƣa ⱪarisila, ular ⱨayat ⱪaldi.
Nígbà náà ni Mose sì rọ ejò onírin ó sì gbé e kọ́ sórí igi, bí ejò bá sì bu ẹnikẹ́ni jẹ bí ó bá ti wò ó yóò sì yè.
10 Israillar yǝnǝ yolƣa qiⱪip Obotⱪa kelip qedir tikti.
Àwọn ọmọ Israẹli tẹ̀síwájú wọ́n sì péjọ sí Obotu.
11 Yǝnǝ Obottin yolƣa qiⱪip, Moab zeminining udulida kün qiⱪix tǝrǝptiki Iyǝ-Ibarimƣa kelip qedir tikti.
Wọ́n gbéra ní Obotu wọ́n sì pa ibùdó sí Iye-Abarimu, ní aginjù tí ó kọjú sí Moabu ní ìdojúkọ ìlà-oòrùn.
12 Ular yǝnǝ u yǝrdin yolƣa qiⱪip Zǝrǝd jilƣisida qedir tikti.
Láti ibẹ̀ ni wọ́n ti gbéra wọ́n sì pa ibùdó ní àfonífojì Seredi.
13 Yǝnǝ u yǝrdin mengip Amoriylarning zeminining qetidin qiⱪip qɵl-bayawandin ɵtüp, eⱪip turƣan Arnon dǝryasining u ⱪetida qedir tikti (qünki Arnon dǝryasi Moabiylarning qegrisi bolup, Moabiylar bilǝn Amoriylarning otturisida idi.
Láti ibẹ̀ lọ, wọn ṣí, wọ́n sì dó sí ìhà kejì Arnoni, tí ó wà ní aginjù tí ó wà ní agbègbè ilẹ̀ àwọn ọmọ Amori. Arnoni jẹ́ ààlà fún ilẹ̀ Moabu, láàrín Moabu àti Amori.
14 Xunga «Pǝrwǝrdigarning jǝngnamisi» degǝn kitabta: — «Sufaⱨdiki Waⱨǝb wǝ dǝrya-wadiliri, Arnon dǝryasi wǝ jilƣilirining yanbaƣirliri, Arning turalƣusiƣiqǝ yetip, Moabning qegrisiƣa qüxidu» dǝp pütülgǝnidi).
Ìdí nìyìí tí ìwé ogun Olúwa se wí pé, “…Wahebu ní Sufa, Òkun Pupa àti ní odò Arnoni
àti ní ìṣàn odò tí ó darí sí ibùjókòó Ari tí ó sì fi ara ti ìpínlẹ̀ Moabu.”
16 [Israillar] yǝnǝ u yǝrdin mengip Bǝǝrgǝ kǝldi; «[Bǝǝr]» ⱪuduⱪ degǝn mǝnidǝ bolup, ilgiri Pǝrwǝrdigar Musaƣa: «Sǝn hǝlⱪni yiƣ, Mǝn ularƣa iqidiƣan su berǝy» degǝndǝ xu ⱪuduⱪni kɵzdǝ tutⱪan.
Láti ibẹ̀ ni wọ́n ti bẹ̀rẹ̀ rìn dé Beeri, èyí ni kànga tí Olúwa sọ fún Mose, “Kó àwọn ènìyàn jọ èmi ó sì fún wọn ní omi.”
17 Xu qaƣda Israillar munu nahxini eytixⱪan: — «Aⱨ ⱪuduⱪ, qiⱪsun süyüng bulduⱪlap, Nahxa eytinglar, ⱪuduⱪⱪa beƣixlap:
Nígbà náà ni Israẹli kọ orin yìí pé, “Sun jáde, ìwọ kànga! Ẹ máa kọrin nípa rẹ̀,
18 Bu ⱪuduⱪni ǝmirlǝr, Hǝlⱪning kattiliri ⱪazƣan, Ⱪanun qiⱪarƣuqining sɵzi bilǝn, Ⱨasiliri bilǝn ⱪazƣan». Israillar qɵl-bayawandin yǝnǝ Mattanaⱨⱪa,
nípa kànga tí àwọn ọmọ-aládé gbẹ́, nítorí àwọn ọlọ́lá ènìyàn ni ó gbẹ́ ẹ; tí àwọn ọlọ́lá àwọn ènìyàn sì fi ọ̀pá aládé àti ọ̀pá oyè wọn gbẹ́.” Nígbà náà wọ́n kúrò láti aginjù lọ sí Mattana,
19 Mattanaⱨtin Naⱨaliyǝlgǝ, Naⱨaliyǝldin Bamotⱪa,
láti Mattana lọ sí Nahalieli, láti Nahalieli lọ sí Bamoti,
20 Bamottin Moab dalasidiki jilƣiƣa, yǝnǝ qɵl-bayawan tǝrǝpkǝ ⱪarap turƣan Pisgaⱨ teƣining qoⱪⱪisiƣa yetip bardi.
àti láti Bamoti lọ sí àfonífojì ní Moabu níbi tí òkè Pisga, tí ó wà ní òkè ilé omi ti kọjú sí aginjù.
21 Israillar Amoriylarning padixaⱨi Siⱨonning aldiƣa ǝlqilǝrni ǝwǝtip:
Israẹli rán oníṣẹ́ láti sọ fún Sihoni ọba àwọn ará Amori wí pé,
22 — Bizning ɵz zeminliridin ɵtüweliximizgǝ ijazǝt bǝrgǝyla; biz silining etizliⱪliriƣa wǝ üzümzarliⱪliriƣa kirmǝymiz, ⱪuduⱪliridin sumu iqmǝymiz; tǝwǝliridin ɵtüp kǝtküqǝ «Han yoli»din qiⱪmaymiz, — dedi.
“Jẹ́ kí a kọjá ní orílẹ̀-èdè rẹ. A kò ní kọjá sí inú oko pápá tàbí ọgbà àjàrà àbí mu omi láti inú kànga. A máa gba òpópónà náà ti ọba títí tí a ó fi la ilẹ̀ rẹ kọjá.”
23 Siⱨon Israillarni ɵz qegrisidin ɵtkili ⱪoymayla ⱪalmastin, ǝksiqǝ u Israillar bilǝn soⱪuximǝn dǝp, ɵzining barliⱪ hǝlⱪini yiƣip qɵlgǝ ⱪarap atlandi. U Yaⱨazƣa kelip Israilƣa ⱨujum ⱪildi.
Ṣùgbọ́n Sihoni kò ní jẹ́ kí àwọn Israẹli kọjá ní ilẹ̀ wọn. Ó pe àwọn ọmọ-ogun rẹ̀ jọ wọ́n sì wọ́de ogun lọ sí aginjù nítorí àwọn ọmọ Israẹli. Nígbà tí ó dé Jahasi, ó bá àwọn ọmọ Israẹli jà.
24 Israillar uni ⱪiliq bilǝn qepip ɵltürüp, uning yurtini Arnon dǝryasidin Yabbok dǝryasiƣiqǝ, yǝni Ammoniylarning qegrisiƣiqǝ igilidi; Ammoniylarning qegrisi bolsa bǝk mustǝⱨkǝm idi.
Àmọ́, Israẹli ṣẹ́gun, wọn fi ojú idà pa wọ́n, wọ́n sì gba ilẹ̀ láti ọwọ́ Arnoni lọ dé Jabbok, títí tí ó fi dé ilẹ̀ àwọn ará Ammoni, nítorí pé ààlà wọn jẹ́ olódi.
25 Israillar bu yǝrdiki ⱨǝmmǝ xǝⱨǝrni igilidi ⱨǝm Amoriylarning xǝⱨǝrlirigǝ, yǝni Ⱨǝxbonƣa wǝ uningƣa tǝwǝ barliⱪ yeza-ⱪixlaⱪlarƣimu kirip orunlaxti.
Israẹli sì gba gbogbo ìlú Amori wọ́n sì ń gbé ibẹ̀ pẹ̀lú Heṣboni, àti gbogbo ibùgbé ìlú tó yí i ká.
26 Qünki Ⱨǝxbon ǝslidǝ Amoriylarning padixaⱨi Siⱨonning mǝrkiziy xǝⱨiri idi; Siⱨon ǝslidǝ Moabning ilgiriki padixaⱨi bilǝn soⱪuxⱪan, uning Arnon dǝryasiƣiqǝ bolƣan ⱨǝmmǝ zeminini tartiwalƣanidi.
Heṣboni ni ìlú Sihoni ọba àwọn ará Amori, ẹni tí ó bá ọba Moabu ti tẹ́lẹ̀ jà tí ó sì gba gbogbo ilẹ̀ rẹ̀ ní ọwọ́ rẹ̀ títí dé Arnoni.
27 Xu sǝwǝbtin xairlar: — «Ⱨǝxbonƣa kelinglar! Mana Siⱨonning xǝⱨiri yengiwaxtin ⱪurulsun, Siⱨonning xǝⱨiri mǝⱨkǝm ⱪilinsun.
Ìdí nìyìí tí akọrin sọ wí pé, “Wá sí Heṣboni kí ẹ jẹ́ kí a tún un kọ́; jẹ́ kí ìlú Sihoni padà bọ̀ sípò.
28 Qünki Ⱨǝxbonning ɵzidin qiⱪti bir ot, Siⱨonning xǝⱨiridin bir yalⱪun yalⱪunlap, Yutuwǝtti Moabtiki Ar xǝⱨirini, Arnondiki egiz jaylarning ǝmirlirini.
“Iná jáde láti Heṣboni, ọ̀wọ́-iná láti Sihoni. Ó jó Ari àti Moabu run, àti ìlú àwọn olùgbé ibi gíga Arnoni.
29 Way sanga ǝy Moab! Ⱨǝy Kemoxning ümmiti, tügǝxtinglar! Qünki [Kemox] ɵz oƣullirini ⱪaqⱪunƣa aylandurdi, Ⱪizlirini ǝsirlikkǝ berip, Amoriylarning padixaⱨi Siⱨonƣa tutup bǝrdi!
Ègbé ní fún ọ, ìwọ Moabu! Ẹ ti parun, ẹ̀yin ènìyàn Kemoṣi! Ó ti fi ọmọ rẹ̀ ọkùnrin sílẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ìsáǹsá àti ọmọ rẹ̀ obìnrin gẹ́gẹ́ bí ìgbèkùn fún Sihoni ọba àwọn Amori.
30 Biz ularni yiⱪitiwǝttuⱪ, Ⱨǝxbon taki Dibonƣiqǝ ⱨalak boldi; Biz ⱨǝtta Nofaⱨⱪiqǝ (Nofaⱨtin Mǝdǝbaƣa yetidu) ularning yurtini wǝyran ⱪiliwǝttuⱪ!» — dǝp xeir yezixⱪanidi.
“Ṣùgbọ́n àti bì wọ́n ṣubú; a ti pa ìjẹgàba Heṣboni run, a pa wọ́n run títí dé Diboni. A sì ti bì wọ́n lulẹ̀ títí dé Nofa, tí ó sì fi dé Medeba.”
31 Xuning bilǝn Israillar ǝnǝ xu tǝriⱪidǝ Amoriylarning yurtiƣa orunlaxti.
Nígbà náà ni àwọn ọmọ Israẹli sì ń gbé ní ilẹ̀ Amori.
32 Musa Yaazǝrni qarlap kelixkǝ qarliƣuqilarni ǝwǝtti; andin Israillar Yaazǝrning yeza-ⱪixlaⱪlirini ixƣal ⱪilip, u yǝrlǝrdiki Amoriylarni yeridin ⱪoƣliwǝtti.
Lẹ́yìn ìgbà tí Mose rán ayọ́lẹ̀wò lọ sí Jaseri, àwọn ọmọ Israẹli sì gba àwọn agbègbè tó yí wọn ká wọ́n sì lé àwọn Amori tó wà níbẹ̀ jáde.
33 Xuningdin keyin Israillar burulup, Baxanning yolini boylap mangdi; Baxanning padixaⱨi Og wǝ uning barliⱪ hǝlⱪi qiⱪip Ədrǝydǝ Israillar bilǝn jǝng ⱪilixⱪa sǝp tüzdi.
Nígbà náà wọ́n pẹ̀yìndà wọ́n sì gòkè lọ sí Baṣani, Ogu ọba ti Baṣani àti gbogbo àwọn ọmọ-ogun tí ó wọ́de ogun jáde láti pàdé wọn ní ojú ogun ní Edrei.
34 Pǝrwǝrdigar Musaƣa: — Ⱪorⱪma, Mǝn uni, uning barliⱪ hǝlⱪi ⱨǝm zeminini ⱪolungƣa tapxurimǝn; sǝn uni ilgiri Ⱨǝxbonda turuxluⱪ Amoriylarning padixaⱨi Siⱨonni ⱪilƣandǝk ⱪilisǝn, — dedi.
Olúwa sọ fún Mose pé, “Má ṣe bẹ̀rù rẹ̀, nítorí tí mó tí fi òun lé ọ lọ́wọ́, àti àwọn ọmọ-ogun rẹ̀, àti ilẹ̀ rẹ̀, kí ìwọ kí ó ṣe sí i gẹ́gẹ́ bí ìwọ ti ṣe sí Sihoni ọba Amori ẹni tí ó ń jẹ ọba ní Heṣboni.”
35 Xuning bilǝn ular Og bilǝn uning oƣullirini ⱨǝm barliⱪ hǝlⱪining birini ⱪoymay ⱪirip taxlidi wǝ uning zeminini igilidi.
Wọ́n sì pa á, pẹ̀lú àwọn ọmọ rẹ̀ àti gbogbo àwọn ọmọ-ogun rẹ̀, wọn kò fi ku ẹnìkan fún un láàyè. Wọ́n sì gba ìní ilẹ̀ rẹ̀.