< Qɵl-bayawandiki sǝpǝr 14 >
1 Xuning bilǝn barliⱪ jamaǝt dad-pǝryad kɵtürüp yiƣlidi; ular keqiqǝ yiƣa-zar ⱪilixip qiⱪti.
Gbogbo ìjọ ènìyàn sì gbóhùn sókè, wọ́n sì sọkún ní òru ọjọ́ náà.
2 Israillar Musa bilǝn Ⱨarunƣa tapa-tǝnǝ ⱪilip: — Biz baldurla Misirda ɵlüp kǝtsǝk boptikǝn! Muxu qɵl-jǝziridǝ ɵlüp kǝtsǝk boptikǝn!
Gbogbo ọmọ Israẹli sì kùn sí Mose àti Aaroni, gbogbo ìjọ ènìyàn Israẹli sì wí fún wọn pé, “Àwa ìbá kúkú ti kú ní ilẹ̀ Ejibiti. Tàbí kí a kúkú kú sínú aginjù yìí.
3 Pǝrwǝrdigar nemixⱪa bizni ⱪiliq astida ɵlsun, hotun bala-qaⱪilirimiz bulinip, [düxmǝnning] oljisi bolsun dǝp bizni bu yǝrgǝ baxlap kǝlgǝndu? Uningdin kɵrǝ, Misirƣa ⱪaytip kǝtkinimiz yahxi ǝmǝsmu? — dǝp ƣotuldaxti.
Kí ló dé tí Olúwa fi mú wa wá sí ilẹ̀ yìí láti fi idà pa wá? Àwọn ìyàwó wa, àwọn ọmọ wa yóò sì di ìjẹ. Ǹjẹ́ kò wa, ní í dára fún wa bí a bá padà sí Ejibiti?”
4 Xuning bilǝn ular bir-birigǝ: — Baxⱪidin bir baxliⱪ tiklǝp Misirƣa ⱪaytip ketǝyli, — deyixti.
Wọ́n sì sọ fún ara wọn pé, “Ẹ jẹ́ kí á yan olórí kí á sì padà sí Ejibiti.”
5 Musa bilǝn Ⱨarun pütün Israil jamaiti aldida yiⱪilip düm yatti.
Nígbà náà ni Mose àti Aaroni dojúbolẹ̀ níwájú gbogbo ìjọ ọmọ Israẹli.
6 Xu yǝrni qarlap kǝlgǝnlǝr iqidiki Nunning oƣli Yǝxua bilǝn Yǝfunnǝⱨning oƣli Kalǝb kiyimlirini yirtip,
Joṣua ọmọ Nuni àti Kalebu ọmọ Jefunne, tí wọ́n wà lára àwọn to lọ yẹ ilẹ̀ wò sì fa aṣọ wọn ya.
7 pütün Israil jamaǝtqilikigǝ: — Biz qarlap kelixkǝ ɵtüp barƣan zemin intayin bǝk yahxi zemin ikǝn.
Wọ́n sì sọ fún gbogbo ìjọ ènìyàn Israẹli pé, “Ilẹ̀ tí a là kọjá láti yẹ̀ wò náà jẹ́ ilẹ̀ tí ó dára lọ́pọ̀lọ́pọ̀.
8 Əgǝr Pǝrwǝrdigar bizdin sɵyünsǝ, bizni xu zeminƣa, yǝni ⱨǝsǝl bilǝn süt eⱪip turidiƣan xu zeminƣa baxlap berip, uni bizgǝ beridu.
Bí inú Olúwa bá dùn sí wa, yóò mú wa dé ilẹ̀ náà, ilẹ̀ tó ń sàn fún wàrà àti fún oyin, yóò fún wa ní ilẹ̀ náà.
9 Silǝr pǝⱪǝt Pǝrwǝrdigarƣa asiyliⱪ ⱪilmanglar! U zeminidikilǝrdin ⱪorⱪmanglar, qünki ular bizgǝ nisbǝtǝn bir ƣizadur; ularning panaⱨdarliri ulardin kǝtti, Pǝrwǝrdigar bolsa biz bilǝn billǝ; ulardin ⱪorⱪmanglar, — dedi.
Ṣùgbọ́n ẹ má ṣe ṣọ̀tẹ̀ sí Olúwa. Kí ẹ sì má bẹ̀rù àwọn ènìyàn ìlú náà, nítorí pé a ó gbé wọn mì, ààbò wọn ti fi wọ́n sílẹ̀, Olúwa sì wà pẹ̀lú àwa, ẹ má ṣe bẹ̀rù wọn.”
10 Ⱨalbuki, pütkül jamaǝt tǝrǝp-tǝrǝptin: — U ikkisini qalma-kesǝk ⱪilip ɵltürüwetǝyli, deyixti. Lekin Pǝrwǝrdigarning julasi jamaǝt qedirida Israillarƣa ayan boldi.
Ṣùgbọ́n gbogbo ìjọ ènìyàn sì ń sọ pé àwọn yóò sọ wọ́n lókùúta pa. Nígbà náà ni ògo Olúwa fi ara hàn ní àgọ́ ìpàdé níwájú àwọn ọmọ Israẹli.
11 Pǝrwǝrdigar Musaƣa: — Bu hǝlⱪ Meni ⱪaqanƣiqǝ mǝnsitmǝydu? Gǝrqǝ ularning otturisida xunqǝ mɵjizilik alamǝtlǝrni yaratⱪan bolsammu, lekin ular Manga ⱪaqanƣiqǝ ixinixmǝydikǝn?
Olúwa sọ fún Mose pé, “Fún ìgbà wo ni àwọn ènìyàn yìí yóò ti kẹ́gàn mi tó? Báwo ni yóò ti pẹ́ tó tí wọ́n ó fi kọ̀ jálẹ̀ láti gbà mí gbọ́, pẹ̀lú gbogbo iṣẹ́ àmì tí mo ṣe láàrín wọn?
12 Mǝn ularni waba bilǝn urup yoⱪitimǝn, xuning bilǝn seni ulardin tehimu qong wǝ ⱪudrǝtlik bir ǝl ⱪilimǝn, — dedi.
Èmi ó kọlù wọ́n pẹ̀lú àjàkálẹ̀-ààrùn, èmi ó gba ogún wọn lọ́wọ́ wọn, èmi ó sì pa wọ́n run ṣùgbọ́n èmi ó sọ ọ́ di orílẹ̀-èdè ńlá tó sì lágbára jù wọ́n lọ.”
13 Musa bolsa Pǝrwǝrdigarƣa mundaⱪ dedi: — «Bundaⱪ bolidiƣan bolsa bu ixni misirliⱪlar anglap ⱪalidu, qünki Sǝn uluƣ ⱪudriting bilǝn bu hǝlⱪni ularning arisidin elip qiⱪⱪaniding;
Ṣùgbọ́n Mose sọ fún Olúwa pé, “Nígbà náà ni àwọn ará Ejibiti yóò gbọ́! Nítorí pé nípa agbára rẹ ni ìwọ fi mú àwọn ènìyàn wọ̀nyí jáde kúrò láàrín wọn.
14 wǝ Misirliⱪlar bu ixni xu zemindiki hǝlⱪlǝrgimu eytidu. U zemindiki aⱨalimu Sǝn Pǝrwǝrdigarning bu hǝlⱪning arisida ikǝnlikingni, Sǝn Pǝrwǝrdigarning ularning aldida yüzmuyüz kɵrüngǝnlikingni, Sening buluting daim ularƣa sayǝ qüxürüp kǝlgǝnlikini, xundaⱪla Sening kündüzi bulut tüwrükidǝ, keqisi ot tüwrükidǝ ularning aldida mangƣanliⱪingni angliƣanidi.
Wọ́n ó sì sọ fún àwọn olùgbé ilẹ̀ yìí. Àwọn tó ti mọ̀ tẹ́lẹ̀ pé ìwọ Olúwa wà láàrín àwọn ènìyàn wọ̀nyí àti pé wọ́n rí ìwọ, Olúwa, ní ojúkojú, àti pé ìkùùkuu àwọsánmọ̀ rẹ dúró lórí wọn, bẹ́ẹ̀ ni ìwọ sì ń lọ níwájú wọn pẹ̀lú ìkùùkuu àwọsánmọ̀ ní ọ̀sán àti pẹ̀lú ọ̀wọ́n iná ní òru.
15 Əmdi Sǝn bu hǝlⱪni huddi bir adǝmni ɵltürgǝndǝk ɵltürüwǝtsǝng, Sening nam-xɵⱨritingni angliƣan ǝllǝrning ⱨǝmmisi:
Bí ìwọ bá pa àwọn ènìyàn wọ̀nyí lẹ́ẹ̀kan ṣoṣo, àwọn orílẹ̀-èdè tó bá gbọ́ ìròyìn yìí nípa rẹ yóò wí pé,
16 «Pǝrwǝrdigar bu hǝlⱪni Ɵzi ularƣa berixkǝ ⱪǝsǝm ⱪilƣan zeminƣa baxlap baralmaydiƣanliⱪi üqün, xunga ularni ǝxu qɵl-jǝziridǝ ɵltürüwetiptu» dǝp ⱪalidu.
‘Nítorí pé Olúwa kò le è mú àwọn ènìyàn wọ̀nyí dé ilẹ̀ tí ó ṣèlérí fún wọn; torí èyí ló ṣe pa wọ́n sínú aginjù yìí.’
17 Əmdi ɵtünimǝnki, Rǝbbim ⱪudritingni jari ⱪildurƣaysǝn, Ɵzüngning:
“Báyìí, mo gbàdúrà, jẹ́ kí agbára Olúwa tóbi gẹ́gẹ́ bí ìwọ ti sọ pé,
18 «Pǝrwǝrdigar asanliⱪqǝ aqqiⱪlanmaydu, Uning meⱨir-muⱨǝbbiti texip turidu; U gunaⱨ wǝ itaǝtsizlikni kǝqüridu, lekin gunaⱨkarlarni ⱨǝrgiz gunaⱨsiz dǝp ⱪarimaydu, atilarning ⱪǝbiⱨlikini atisidin balisiƣiqǝ, ⱨǝtta nǝwrǝ-qǝwrilirigiqǝ ularning üstigǝ yüklǝydu» deginingdǝk ⱪilƣaysǝn.
‘Olúwa lọ́ra láti bínú, ó sì pọ̀ ní ìfẹ́ tó dúró ṣinṣin, tí ń dárí ẹ̀ṣẹ̀ àti ìrékọjá jì. Bẹ́ẹ̀ ni kì í jẹ́ kí ẹlẹ́bi lọ láìjìyà; tó ń fi ìyà ẹ̀ṣẹ̀ baba jẹ ọmọ títí dé ìran kẹta àti ìran kẹrin.’
19 Meⱨriy-xǝpⱪitingning kǝngriliki boyiqǝ, Misirdiki qaƣdin taki ⱨazirƣiqǝ daim kǝqürüp kǝlginingdǝk, bu hǝlⱪning ⱪǝbiⱨlikini kǝqürgǝysǝn!».
Dárí ẹ̀ṣẹ̀ àwọn ènìyàn yìí jì wọ́n, mo bẹ̀ ọ́, gẹ́gẹ́ bí ìfẹ́ ńlá rẹ, bí o ti ṣe ń dárí ẹ̀ṣẹ̀ wọn jì wọ́n láti ìgbà tí o ti kó wọn kúrò ní Ejibiti di ìsin yìí.”
20 Pǝrwǝrdigar: — «Boptu, sǝn degǝndǝk ularni kǝqürdüm.
Olúwa sì dáhùn pé, “Mo ti dáríjì wọ́n gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ rẹ.
21 Lekin Ɵz ⱨayatim bilǝn ⱪǝsǝm ⱪilimǝnki, pütkül yǝr yüzi Mǝn Pǝrwǝrdigarning xan-xǝripi bilǝn tolidu.
Ṣùgbọ́n nítòótọ́ bí mo ti wà láààyè, gbogbo ayé yóò kún fún ògo Olúwa.
22 Ⱨalbuki, Mening julayimni, Misirda wǝ qɵl-jǝziridǝ kɵrsǝtkǝn mɵjizilik alamǝtlirimni kɵrüp turupmu Meni muxundaⱪ on ⱪetimlap sinap yǝnǝ awazimƣa ⱪulaⱪ salmiƣanlar,
Kò sí ọ̀kan nínú àwọn ènìyàn tó rí ògo mi àti àwọn iṣẹ́ àmì tí mo ṣe ní ilẹ̀ Ejibiti àti nínú aginjù ṣùgbọ́n tí wọ́n ṣe àìgbọ́ràn sí mi, tí wọn sì dán mi wò ní ìgbà mẹ́wàá yìí,
23 Mǝn ⱪǝsǝm iqip ularning ata-bowiliriƣa miras ⱪilip berimǝn degǝn u zeminni ⱨǝrgiz kɵrǝlmǝydu; Meni mǝnsitmigǝnlǝrdin birimu u yurtni kɵrǝlmǝydu.
ọ̀kan nínú wọn kò ní rí ilẹ̀ náà tí mo ṣe ìlérí ní ìbúra láti fún baba ńlá wọn. Kò sí ọ̀kan nínú àwọn tó kẹ́gàn mi tí yóò rí ilẹ̀ náà.
24 Lekin ɵzidǝ baxⱪiqǝ bir roⱨning bolƣini, pütün ⱪǝlbi bilǝn Manga ǝgǝxkini üqün ⱪulum Kalǝbni u kirgǝn yǝrgǝ baxlap kirimǝn; uning ǝwladlirimu u yǝrgǝ mirashor bolidu.
Ṣùgbọ́n nítorí pé Kalebu ìránṣẹ́ mi ní ẹ̀mí ọ̀tọ̀, tí ó sì tún tẹ̀lé mi tọkàntọkàn, èmi ó mu dé ilẹ̀ náà tó lọ yẹ̀ wò, irú àwọn ọmọ rẹ̀ yóò sì jogún rẹ̀.
25 (xu qaƣda Amalǝklǝr bilǝn Ⱪanaaniylar [taƣliⱪ] jilƣilarda turuwatatti) — Ətǝ silǝr yolunglardin burulup, Ⱪizil Dengizƣa baridiƣan yol bilǝn mengip qɵlgǝ sǝpǝr ⱪilinglar» — dedi.
Níwọ́n ìgbà tí àwọn ará Amaleki àti àwọn ará Kenaani ń gbé ní àfonífojì, ẹ yípadà lọ́la kí ẹ sì dojúkọ aginjù lọ́nà Òkun Pupa.”
26 Pǝrwǝrdigar Musa bilǝn Ⱨarunƣa sɵz ⱪilip mundaⱪ dedi:
Olúwa sọ fún Mose àti Aaroni pé,
27 — Mǝn Mening yaman gepimni ⱪilip ƣotuldixidiƣan bu rǝzil jamaǝtkǝ ⱪaqanƣiqǝ qidixim kerǝk? Israillarning Mening yaman gepimni ⱪilƣanliri, xu [tohtawsiz] ƣotuldaxlirining ⱨǝmmisini anglidim.
“Báwo ni yóò ti pẹ́ tó tí àwọn ìjọ ènìyàn búburú yìí yóò fi máa kùn sí mi? Mo ti gbọ́ kíkùn tí àwọn ọmọ Israẹli ń kùn sí mi.
28 Sǝn ularƣa: — Pǝrwǝrdigar mundaⱪ dǝydu: «Mǝn ⱨayatim bilǝn ⱪǝsǝm ⱪilimǝnki, hǝp, Mǝn silǝrgǝ ⱪuliⱪimƣa kirgǝn sɵzliringlar boyiqǝ muamilǝ ⱪilmaydiƣan bolsam!
Sọ fún wọn, bí mo ti wà láààyè nítòótọ́ ni Olúwa wí, gẹ́gẹ́ bí ohun tí ẹ wí létí mi ni èmi ó ṣe fún un yín.
29 Silǝrning ɵlükünglar muxu qɵldǝ yatidu; silǝrning iqinglarda sanaⱪtin ɵtküzülgǝnlǝr, yǝni yexi yigirmidin axⱪan, Mening yaman gepimni ⱪilip ƣotuldiƣanlarning ⱨǝmmisi pütün sani boyiqǝ
Nínú aginjù yìí ni ẹ ó kú sí, gbogbo ẹ̀yin tí ẹ kùn láti ọmọ ogún ọdún ó lé àní gbogbo ẹ̀yin tí a kà.
30 Silǝrgǝ ⱪol kɵtürüp [ⱪǝsǝm ⱪilip], turalƣunglar ⱪilip berimǝn degǝn zeminƣa ⱨeq kirǝlmǝydu; pǝⱪǝt Yǝfunnǝⱨning oƣli Kalǝb bilǝn Nunning oƣli Yǝxuala kiridu.
Ọ̀kan nínú yín kò ní í dé ilẹ̀ tí mo búra nípa ìgbọ́wọ́sókè láti fi ṣe ibùgbé yín, bí kò ṣe Kalebu ọmọ Jefunne àti Joṣua ọmọ Nuni.
31 Silǝrning kiqik baliliringlar, yǝni «Bulinip, düxmǝnning oljisi bolup ⱪalidu» deyilgǝnlǝrni Mǝn baxlap kirimǝn, ular silǝr kǝmsitkǝn u zemindin bǝⱨrimǝn bolidu.
Ṣùgbọ́n ní ti àwọn ọmọ yín tí ẹ wí pé wọn ó di ìjẹ, àwọn ni n ó mú dé bẹ̀ láti gbádùn ilẹ̀ tí ẹ kọ̀sílẹ̀.
32 Biraⱪ silǝr bolsanglar, silǝr yiⱪilip, ɵlükünglar bu qɵldǝ ⱪalidu.
Ṣùgbọ́n ẹ̀yin, òkú yín yóò ṣubú ní aginjù yìí.
33 Silǝrning baliliringlar buzuⱪluⱪ-wapasizliⱪinglarning ǝlimini tartip, ɵlükünglar qɵldǝ yoⱪalƣuqǝ, bu qɵldǝ ⱪiriⱪ yil sǝrgǝrdan bolup yüridu.
Àwọn ọmọ wẹ́wẹ́ yín yóò sì máa rin kiri nínú aginjù fun ogójì ọdún wọn ó máa jìyà nítorí àìnígbàgbọ́ yín, títí tí ọkàn gbogbo yín yóò fi ṣòfò tán ní aginjù.
34 Silǝrning xu zeminni qarliƣan künliringlarning sani boyiqǝ, ⱪiriⱪ künning ⱨǝrbir künini bir yil ⱨesablap, ⱪǝbiⱨlikliringlarni ⱪiriⱪ yil ɵz üstünglarƣa elip yürisilǝr; xu qaƣda Mening ɵzünglardin yatlaxⱪinimning nemǝ ikǝnlikini bilip yetisilǝr» — degin.
Fún ogójì ọdún èyí jẹ́ ọdún kan fún ọjọ́ kọ̀ọ̀kan nínú ogójì ọjọ́ tí ẹ fi yẹ ilẹ̀ náà wò ẹ̀yin ó sì jìyà fún ẹ̀ṣẹ̀ yín, ẹ ó sì mọ bí ó ti rí láti lòdì sí mi.
35 Mǝn Pǝrwǝrdigar xundaⱪ degǝnikǝnmǝn, yiƣilip Manga ⱪarxi qiⱪⱪan bu rǝzil hǝlⱪ jamaitigǝ Mǝn qoⱪum xundaⱪ ⱪilimǝn; ular muxu qɵl-jǝziridǝ yǝwetilidu, xu yǝrdǝ ɵlidu.
Èmi, Olúwa, lo sọ bẹ́ẹ̀; Èmi ó sì ṣe àwọn nǹkan wọ̀nyí sí ìjọ ènìyàn búburú yìí tí wọ́n kó ra wọn jọ lòdì sí mi. Nínú aginjù yìí ni òpin yóò dé bá wọn, ibẹ̀ ni wọn yóò kú sí.”
36 Musa u zeminni qarlap kelixkǝ ǝwǝtkǝnlǝr ⱪaytip kǝlgǝndǝ, u zemin toƣruluⱪ yaman hǝwǝr elip kelix bilǝn pütün jamaǝtni ƣotulditip, Musaning yaman gepini ⱪilƣuzƣanlar,
Àwọn ọkùnrin tí Mose rán láti yẹ ilẹ̀ wò, tí wọ́n sì mú gbogbo ìjọ kùn sí i nípa ìròyìn búburú tí wọ́n mú wá nípa ilẹ̀ náà;
37 yǝni u zemin toƣruluⱪ yaman hǝwǝr ǝkǝlgǝn bu kixilǝrning ⱨǝmmisi waba kesili tegip Pǝrwǝrdigarning aldida ɵldi.
Olúwa sì kọlu àwọn ọkùnrin tó mú ìròyìn búburú wá nípa ilẹ̀ náà, àjàkálẹ̀-ààrùn sì pa wọ́n níwájú Olúwa.
38 Zeminni qarlap kelixkǝ barƣan adǝmlǝr iqidin pǝⱪǝt Nunning oƣli Yǝxua bilǝn Yǝfunnǝⱨning oƣli Kalǝbla ⱨayat ⱪaldi.
Nínú gbogbo àwọn tó lọ yẹ ilẹ̀ náà wò, Joṣua ọmọ Nuni àti Kalebu ọmọ Jefunne ló yè é.
39 Musa bu gǝplǝrni pütkül Israil jamaitigǝ eytiwidi, ⱨǝmmisi bǝk ⱨǝsrǝt qǝkti.
Nígbà tí Mose sọ gbogbo ọ̀rọ̀ yìí fún àwọn ọmọ Israẹli, wọ́n sì sọkún gidigidi.
40 Ular ǝtigǝn tang atⱪanda turup taƣⱪa qiⱪip: — Mana biz kǝlduⱪ! Pǝrwǝrdigar eytⱪan yurtⱪa qiⱪip ⱨujum ⱪilayli; qünki biz gunaⱨ ⱪilduⱪ, — deyixti.
Wọ́n dìde ní àárọ̀ ọjọ́ kejì wọ́n sì gòkè lọ sí ìlú orí òkè, wọ́n wí pé, “Àwa ti ṣẹ̀, àwa yóò lọ sí ibi tí Olúwa ṣèlérí fún wa.”
41 — Silǝr yǝnǝ nemixⱪa Pǝrwǝrdigarning ǝmrigǝ hilapliⱪ ⱪilisilǝr? — dedi Musa, — Bu ix ƣǝlibilik bolmaydu!
Mose sì dá wọn lóhùn pé, “Kí ló dé tí ẹ fi ṣẹ̀ sí òfin Olúwa? Èyí kò le yọrí sí rere!
42 Pǝrwǝrdigar aranglarda bolmiƣaqⱪa, düxmǝnning ⱪiliqi astida ɵlüp, mǝƣlup bolmasliⱪinglar üqün ⱨujumƣa qiⱪmanglar.
Ẹ má ṣe gòkè lọ nítorí pé Olúwa kò sí láàrín yín. Ki á má ba à lù yín bolẹ̀ níwájú àwọn ọ̀tá yín.
43 Qünki Amalǝklǝr bilǝn Ⱪanaaniylar u yurtta, silǝrning aldinglarda turidu; silǝr ⱪiliq astida ɵlüp ketisilǝr; qünki silǝr Pǝrwǝrdigardin tenip kǝttinglar, Pǝrwǝrdigar silǝr bilǝn billǝ bolmaydu.
Nítorí pé àwọn ará Amaleki àti àwọn ará Kenaani ń bẹ níwájú yín, ẹ̀yin yóò sì ti ipa idà ṣubú. Nítorí pé, ẹ ti yà kúrò ní ọ̀nà Olúwa, Olúwa kò sì ní í wà pẹ̀lú yín.”
44 Lekin, gǝrqǝ Pǝrwǝrdigarning ǝⱨdǝ sanduⱪi wǝ Musa bargaⱨtin ⱪozƣalmiƣan bolsimu, ular yǝnila ɵz mǝyliqǝ taƣⱪa qiⱪip ⱨujumƣa ɵtti.
Síbẹ̀síbẹ̀, pẹ̀lú àìfarabalẹ̀ wọn, wọ́n gòkè lọ sórí òkè náà, láìjẹ́ pé àpótí ẹ̀rí Olúwa tàbí Mose kúrò nínú ibùdó.
45 Xuning bilǝn Amalǝklǝr bilǝn xu taƣda turuxluⱪ Ⱪanaaniylar qüxüp ularni taki Hormaⱨƣiqǝ ⱪoƣlap, bitqit ⱪilip ⱪirƣin ⱪildi.
Àwọn ará Amaleki àti àwọn ará Kenaani tó ń gbé lórí òkè sọ̀kalẹ̀ tọ̀ wọ́n, wọ́n bá wọn jà, wọ́n sì lé wọn títí dé Horma.