< Qɵl-bayawandiki sǝpǝr 11 >

1 Wǝ xundaⱪ boldiki, hǝlⱪ ƣotuldixatti, ularning ƣotuldaxliri Pǝrwǝrdigarning ⱪuliⱪiƣa yetip intayin rǝzil anglandi; U bu sɵzlǝrni anglidi wǝ Uning ƣǝzipi ⱪozƣaldi; Pǝrwǝrdigarning ot-yalⱪuni ularning arisida tutixip, bargaⱨning qetidiki bǝzilǝrni kɵydürüxkǝ baxlidi.
Àwọn ènìyàn ń ṣe àròyé nípa wàhálà wọn sí etí ìgbọ́ Olúwa. Ìbínú Olúwa sì ru sókè nígbà tí ó gbọ́ àròyé yìí. Nígbà náà ni iná jáde láti ọ̀dọ̀ Olúwa bọ́ sí àárín wọn, ó sì run àwọn tó wà ní òpin ibùdó.
2 Hǝlⱪ bu qaƣda Musaƣa yalwuriwidi, Musa Pǝrwǝrdigardin tilidi; xuning bilǝn ot pǝsiyip ɵqti.
Nígbà náà ni àwọn ènìyàn kígbe sí Mose, Mose sì gbàdúrà sí Olúwa iná náà sì kú.
3 Pǝrwǝrdigarning oti ularning otturisida tutaxⱪanliⱪi üqün u u yǝrgǝ «Tabǝraⱨ» dǝp at ⱪoydi.
Wọ́n sì ń pe ibẹ̀ ní Tabera nítorí pé, iná láti ọ̀dọ̀ Olúwa jó láàrín wọn.
4 Ularning arisidiki xalƣut kixilǝrning nǝpsi taⱪildap kǝtti, Israillarmu yǝnǝ yiƣlaxⱪa baxlidi: «Əmdi bizgǝ kim gɵx beridu?
Àwọn ọ̀pọ̀ ènìyàn aláìníláárí tó wà láàrín àwọn ọmọ Israẹli pẹ̀lú ọkàn ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ wọn fi ìtara béèrè fún oúnjẹ mìíràn, àwọn ọmọ Israẹli náà bá bẹ̀rẹ̀ sí í sọkún wí pé, “Bí i pé kí á rí ẹran jẹ báyìí!
5 Ⱨelimu esimizdiki, biz Misirdiki qaƣlarda pul hǝjlimǝy turupmu beliⱪ yeyǝlǝyttuⱪ, yǝnǝ tǝrhǝmǝk, tawuz, piyaz wǝ küdǝ piyaz bilǝn samsaⱪmu bar idi.
Àwa rántí ẹja tí à ń jẹ lọ́fẹ̀ẹ́ ní Ejibiti, apálà, bàrà, ewébẹ̀, àlùbọ́sà àti àwọn ẹ̀fọ́ mìíràn.
6 Mana bu yǝrdǝ ⱨazir kɵz aldimizda mannadin baxⱪa ⱨeqnemǝ yoⱪ, ǝmdi bizning jenimizmu ⱪurup ketiwatidu» deyixti.
Ṣùgbọ́n báyìí gbogbo ara wa ti gbẹ, kò sí ohun mìíràn láti jẹ àfi manna nìkan tí a rí yìí!”
7 Manna goya yumƣaⱪsüt uruⱪiƣa, kɵrünüxi goya kǝⱨriwaƣa ohxaytti.
Manna náà dàbí èso korianderi, ìrísí rẹ̀ sì dàbí oje igi.
8 Kixilǝr uyan-buyan qepip uni yiƣip, bǝzidǝ yarƣunqaⱪta ezip, bǝzidǝ ⱨawanqida soⱪup, ya bǝzidǝ ⱪazanda pixurup nan ⱪilip yǝytti; tǝmi zǝytun mayliⱪ toⱪaqlarƣa ohxaytti.
Àwọn ènìyàn náà ń lọ káàkiri láti kó o, wọn ó lọ̀ ọ́ lórí ọlọ tàbí kí wọ́n gún un nínú odó. Wọ́n le sè é nínú ìkòkò tàbí kí wọn ó fi ṣe àkàrà, adùn rẹ̀ yóò sì dàbí adùn ohun tí a fi òróró ṣe.
9 Keqidǝ bargaⱨⱪa xǝbnǝm qüxkǝndǝ, mannamu xuning üstigǝ qüxǝtti.
Nígbà tí ìrì bá ẹ̀ sí ibùdó lórí ni manna náà máa ń bọ́ pẹ̀lú rẹ̀.
10 Musa hǝlⱪning ailimu-ailǝ ⱨǝrbiri ɵz qedirining ixiki aldida yiƣa-zar ⱪilixiwatⱪinini anglidi; buningƣa Pǝrwǝrdigarning ƣǝzipi ⱪattiⱪ ⱪozƣaldi, bu ix Musaning nǝziridimu yaman kɵründi.
Mose sì gbọ́ tí àwọn ènìyàn ń sọkún ní gbogbo ìdílé wọn, oníkálùkù ní ẹnu-ọ̀nà àgọ́ tirẹ̀. Olúwa sì bínú gidigidi. Inú Mose sì bàjẹ́ pẹ̀lú.
11 Musa Pǝrwǝrdigarƣa: — Sǝn bu barliⱪ hǝlⱪning eƣir yükini manga artip ⱪoyup, mǝn ⱪulungni nemixⱪa bundaⱪ ⱪiynaysǝn; nemixⱪa mǝn Sening aldingda iltipat tapmaymǝn?
Mose sì béèrè lọ́wọ́ Olúwa pé, “Kí ló dé tí o fi mú wàhálà yìí bá ìránṣẹ́ rẹ? Kí ni mo ṣe tí n kò fi tẹ ọ lọ́rùn tí ìwọ fi di ẹrù àwọn ènìyàn wọ̀nyí lé mi lórí.
12 Ya mǝn bu pütün hǝlⱪⱪǝ ⱨamilidar bolup, ularni tuƣdummu? Sǝn tehi manga: «Sǝn ularni Mǝn ⱪǝsǝm iqip ularning ata-bowiliriƣa miras ⱪilƣan xu yǝrgǝ yǝtküzgüqǝ, huddi baⱪⱪan atisi ǝmqǝktiki bowaⱪni baƣriƣa alƣandǝk baƣringƣa elip kɵtürüp mang» dǝwatisǝn?
Èmi ni mo ha lóyún gbogbo àwọn ènìyàn wọ̀nyí bí? Àbí èmi ló bí wọn? Tí ìwọ fi sọ fún mi pé, máa gbé wọn sí oókan àyà rẹ, gẹ́gẹ́ bí abiyamọ ti máa ń gbe ọmọ ọmú lọ sí ilẹ̀ tí o ti búra láti fún àwọn baba ńlá wọn.
13 Mǝn bu hǝlⱪⱪǝ nǝdin gɵx tepip berǝlǝymǝn? Qünki ular manga yiƣlap: «Sǝn bizgǝ yegüdǝk gɵx tepip bǝr!» deyixmǝktǝ.
Níbo ni n ó ti rí ẹran fún àwọn ènìyàn wọ̀nyí? Nítorí wọ́n ń sọkún sí mi pé, ‘Fún wa lẹ́ran jẹ́!’
14 Mǝn bu hǝlⱪni kɵtürüxni yalƣuz üstümgǝ elip ketǝlmǝydikǝnmǝn, bu ix manga bǝk eƣir keliwatidu.
Èmi nìkan kò lè dágbé wàhálà àwọn ènìyàn wọ̀nyí, ẹrù wọn ti wúwo jù fún mi.
15 Əgǝr Sǝn manga muxundaⱪ muamilǝ ⱪilmaⱪqi bolsang, mǝn ɵtünüp ⱪalay, bu harab ⱨalitimni manga kɵrsǝtmǝy, iltipat ⱪilip meni ɵltürüwǝt! — dedi.
Bí ó bá sì ṣe pé báyìí ni ìwọ ó ṣe máa ṣe fún mi, kúkú pa mí báyìí, tí mo bá ti bá ojúrere rẹ pàdé—kí ojú mi má ba à rí ìparun mi.”
16 Pǝrwǝrdigar Musaƣa mundaⱪ dedi: — Israil aⱪsaⱪalliri iqidin, sǝn yenimƣa tonuydiƣan hǝlⱪ aⱪsaⱪalliri wǝ bǝglǝrdin yǝtmixni tallap yiƣⱪin, ularni jamaǝt qedirining aldiƣa ǝkǝl. Ular sening bilǝn billǝ xu yǝrdǝ tursun.
Nígbà náà ni Olúwa sọ fún Mose pé, “Mú àádọ́rin ọkùnrin nínú àwọn àgbàgbà àwọn ọmọ Israẹli, àwọn tí o mọ̀ gẹ́gẹ́ bí olórí àti olóyè láàrín àwọn ènìyàn wá sínú àgọ́ ìpàdé, kí wọ́n lé dúró níwájú mi.
17 Mǝn xu yǝrgǝ qüxüp sening bilǝn sɵzliximǝn; wǝ sening üstüngdǝ turuwatⱪan Roⱨni elip ularning üstigimu bɵlüp ⱪoyimǝn. Xuning bilǝn ular sǝn bilǝn billǝ hǝlⱪni kɵtürüx mǝs’uliyitini üstigǝ alidu, andin sǝn uni ɵzüng yalƣuz kɵtürmǝydiƣan bolisǝn.
Èmi ó sì sọ̀kalẹ̀ wá bá yín sọ̀rọ̀ níbẹ̀. Èmi ó sì mú díẹ̀ nínú agbára Ẹ̀mí tí ń bẹ lára rẹ láti fi sí orí àwọn ènìyàn wọ̀nyí. Wọn ó sì máa ràn ọ́ lọ́wọ́ láti ru àjàgà àwọn ènìyàn kí ó má ṣe pé ìwọ nìkan ni ó o máa ru àjàgà náà.
18 Sǝn hǝlⱪⱪǝ mundaⱪ degin: «Ətǝ gɵx yiyixkǝ tǝyyarlinip ɵzǝnglǝrni [Hudaƣa] atap paklanglar; qünki silǝr Pǝrwǝrdigarning ⱪuliⱪini aƣritip yiƣlap: «Əmdi kim bizgǝ gɵx beridu? Aⱨ, Misirdiki ⱨalimiz bǝk yahxi idi!» degǝnidinglar ǝmǝsmu? Pǝrwǝrdigar dǝrwǝⱪǝ silǝrgǝ gɵx beridu, silǝr uningdin yǝysilǝr.
“Sọ fún àwọn ènìyàn náà pé, ‘Ẹ ya ara yín sí mímọ́ ní ìmúrasílẹ̀ fún ọ̀la, ẹ ó sì jẹ ẹran. Nítorí pé Olúwa ti gbọ́ igbe ẹkún yín, èyí tí ẹ sun pé, “Ìbá ṣe pé a lè rí ẹran jẹ ni! Ó sàn fún wa ní Ejibiti jù báyìí lọ!” Nítorí náà ni Olúwa yóò fi fún yín ní ẹran, ẹ ó sì jẹ ẹ́.
19 Silǝr bir kün, ikki kün ǝmǝs, bǝx kün, on kün ǝmǝs, yigirmǝ künmu ǝmǝs,
Ẹ kò ní i jẹ ẹ́ fún ọjọ́ kan, ọjọ́ méjì, ọjọ́ márùn-ún, ọjọ́ mẹ́wàá tàbí ogúnjọ́ lásán,
20 bǝlki pütün bir ay yǝysilǝr, taki burninglardin etilip qiⱪip ⱨɵ bolƣuqǝ yǝysilǝr; qünki silǝr aranglarda turuwatⱪan Pǝrwǝrdigarni mǝnsitmǝy, uning aldida yiƣlap turup: «Biz nemǝ üqün Misirdin qiⱪtuⱪ?» — dedinglar».
ṣùgbọ́n fún odidi oṣù kan, títí tí ẹran náà yóò fi máa yọ ní imú yín, tí yóò sì sú yín, nítorí pé ẹ ti kẹ́gàn Olúwa tí ó wà láàrín yín, ẹ sì ti sọkún fún un wí pé, “Kí ló dé tí a fi kúrò ní Ejibiti gan an?”’”
21 Musa: — Mǝn ularning arisida turuwatⱪan bu hǝlⱪtin yolƣa qiⱪalaydiƣan ǝrkǝklǝr altǝ yüz ming tursa, Sǝn tehi: «Mǝn ularni gɵx yǝydiƣan, ⱨǝtta pütün bir ay gɵx yǝydiƣan ⱪilimǝn» dǝysǝn;
Ṣùgbọ́n Mose sọ pé, “Mo wà láàrín ọgbọ̀n ọ̀kẹ́ ènìyàn ni ìrìnkiri, ó sì sọ pé, ‘Èmi ó fún wọn ní ẹran láti jẹ fún oṣù kan gbáko!’
22 ǝmisǝ ⱪoy, kala padilirining ⱨǝmmisi soyulsa ularƣa yetǝmdu? Yaki dengizdiki ⱨǝmmǝ beliⱪ ularƣa tutup berilsǝ, ularning yiyixigǝ yitǝrmu? — dedi.
Ǹjẹ́ bí a tilẹ̀ pa àgbò ẹran àti ọmọ ẹran, yóò ha tó wọn bí? Tàbí bí a tilẹ̀ pa gbogbo ẹja inú omi fún wọn, yóò wa tó bí?”
23 Xuning bilǝn Pǝrwǝrdigar Musaƣa: — Pǝrwǝrdigarning ⱪoli ⱪisⱪa bolup ⱪaptimu? Əmdi kɵrüp baⱪⱪinǝ, Mening sanga degǝn sɵzüm ǝmǝlgǝ axurulamdu-yoⱪ? — dedi.
Olúwa sì dá Mose lóhùn pé, “Ọwọ́ Olúwa ha kúrú bí? Ìwọ yóò ri nísinsin yìí bóyá ọ̀rọ̀ tí mo sọ yóò ṣẹ tàbí kò ni í ṣẹ.”
24 Xuning bilǝn Musa qiⱪip Pǝrwǝrdigarning sɵzini hǝlⱪⱪǝ yǝtküzdi wǝ hǝlⱪ iqidiki aⱪsaⱪallardin yǝtmix adǝmni tallap yiƣip ularni jamaǝt qedirining ǝtrapida turƣuzdi.
Mose sì jáde, ó sọ ohun tí Olúwa wí fún àwọn ènìyàn. Ó mú àwọn àádọ́rin àgbàgbà Israẹli dúró yí àgọ́ ká.
25 Andin Pǝrwǝrdigar bulut iqidin qüxüp, Musa bilǝn sɵzlixip, uningdiki Roⱨtin elip yǝtmix aⱪsaⱪalƣa ⱪoydi; Roⱨ ularning üstigǝ ⱪonuxi bilǝn ular bexarǝt berixkǝ kirixti. Lekin xu waⱪittin keyin ular undaⱪ ⱪilmidi.
Nígbà náà ni Olúwa sọ̀kalẹ̀ nínú àwọ̀ sánmọ̀ ó sì bá wọn sọ̀rọ̀, ó sì mú lára Ẹ̀mí tó wà lára Mose sí ara àwọn àádọ́rin àgbàgbà náà, Ó sì ṣẹlẹ̀ pé nígbà tí Ẹ̀mí náà bà lé wọn, wọ́n sọtẹ́lẹ̀, ṣùgbọ́n lẹ́yìn èyí wọn kò sọtẹ́lẹ̀ mọ́.
26 Lekin u qaƣda ulardin ikki adǝm bargaⱨta ⱪaldi; birsining ismi Əldad, ikkinqisi Medad idi (ular ǝslidǝ aⱪsaⱪallarning arisida tizimlanƣanidi, lekin ibadǝt qediriƣa qiⱪmay ⱪalƣanidi). Roⱨ ularning üstidimu ⱪondi wǝ ular bargaⱨ iqidǝ bexarǝt berixkǝ baxlidi.
Àwọn ọkùnrin méjì, tí orúkọ wọn ń jẹ́ Eldadi àti Medadi kò kúrò nínú àgọ́. Orúkọ wọn wà lára àádọ́rin àgbàgbà yìí ṣùgbọ́n wọn kò jáde nínú àgọ́ síbẹ̀ Ẹ̀mí náà bà lé wọn, wọ́n sì sọtẹ́lẹ̀ nínú àgọ́.
27 Yax bir yigit yügürüp kelip Musaƣa: — Əldad bilǝn Medad bargaⱨta bexarǝt beriwatidu, — dedi.
Ọmọkùnrin kan sì sáré lọ sọ fún Mose pé, “Eldadi àti Medadi ń sọtẹ́lẹ̀ nínú àgọ́.”
28 Musaning hizmǝtkari, Musa talliƣan sǝrhil yigitliridin biri, Nunning oƣli Yǝxua ⱪopup: — I hojam Musa, ularni tosuƣayla, — dedi.
Joṣua ọmọ Nuni tí í ṣe ìránṣẹ́ Mose, láti kékeré tó jẹ́ ọ̀kan nínú àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ dáhùn pé, “Mose olúwa mi, dá wọn lẹ́kun!”
29 Lekin Musa uningƣa: — Sǝn mening sǝwǝbimdin ⱨǝsǝt ⱪiliwatamsǝn? Pǝrwǝrdigarning pütün hǝlⱪi pǝyƣǝmbǝr bolup kǝtsǝ idi, Pǝrwǝrdigar Ɵzining Roⱨini ularning üstigǝ ⱪoysa idi! — dedi.
Mose sì wí fún un pé, “Àbí ìwọ ń jowú nítorí mi? Ìbá ti wù mí tó, kí gbogbo àwọn ènìyàn Olúwa jẹ́ wòlíì, kí Olúwa sì fi Ẹ̀mí rẹ̀ sí wọn lára!”
30 Xuning bilǝn Musa bilǝn Israil aⱪsaⱪallirining ⱨǝmmisi bargaⱨⱪa ⱪaytip ketixti.
Mose àti àwọn àgbàgbà Israẹli yìí sì padà sínú àgọ́.
31 Əmdi Pǝrwǝrdigar aldidin bir xamal qiⱪip, u dengiz tǝrǝptin bɵdünilǝrni uqurtup kelip, bargaⱨning ǝtrapiƣa yeyiwǝtti; bɵdünilǝr bargaⱨning u tǝripidimu bir künlük yol, bu tǝripidimu bir künlük yol kǝlgüdǝk yǝr yüzini ikki gǝz egizliktǝ kǝlgüdǝk ⱪaplidi.
Afẹ́fẹ́ sì jáde láti ọ̀dọ̀ Olúwa ó sì kó àparò wá láti inú Òkun. Ó sì dà wọ́n káàkiri gbogbo ibùdó ní ìwọ̀n gíga ẹsẹ̀ bàtà mẹ́ta sórí ilẹ̀, bí ìwọ̀n ìrìn ọjọ́ kan ní gbogbo àyíká.
32 Hǝlⱪ ornidin turup pütkül xu küni, xu keqisi wǝ ǝtisi pütün kün bɵdünǝ tutup yiƣdi, ǝng az degǝnlirimu alaⱨazǝl ikki homir yiƣdi; ular bularni bargaⱨning tɵt ǝtrapiƣa ɵzliri üqün yeyixti.
Ní gbogbo ọjọ́ náà àti òru, títí dé ọjọ́ kejì ni àwọn ènìyàn fi ń kó àparò yìí, ẹni tó kó kéré jùlọ kó ìwọ̀n homeri mẹ́wàá, wọ́n sì ṣà wọ́n sílẹ̀ fún ara wọn yí gbogbo ibùdó.
33 Ular gɵxni qaynap ezip bolmay, gɵx tehi qixliri arisida turƣanda, Pǝrwǝrdigarning ƣǝzipi ularƣa ⱪozƣilip, hǝlⱪni intayin eƣir bir waba bilǝn urdi.
Ṣùgbọ́n nígbà tí ẹran náà sì wà láàrín eyín wọn, kó tó di pé wọ́n jẹ ẹ́, ìbínú Olúwa sì ru sí àwọn ènìyàn, ó sì pa wọ́n pẹ̀lú àjàkálẹ̀-ààrùn.
34 Xunga kixilǝr xu yǝrni «Ⱪibrot-Ⱨattawaⱨ» dǝp atidi; qünki ular xu yǝrdǝ nǝpsi taⱪildiƣan kixilǝrni yǝrlikkǝ ⱪoyƣanidi.
Torí èyí ni wọ́n ṣe pe ibẹ̀ ní Kibirotu-Hattaafa nítorí pé níbẹ̀ ni wọ́n gbé sìnkú àwọn ènìyàn tó ní ọ̀kánjúwà oúnjẹ sí.
35 Keyin hǝlⱪ Ⱪibrot-Ⱨattawaⱨtin yolƣa qiⱪip Ⱨazirotⱪa kelip, Ⱨazirotta tohtidi.
Àwọn ènìyàn yòókù sì gbéra láti Kibirotu-Hattaafa lọ pa ibùdó sí Haserotu wọ́n sì dúró níbẹ̀.

< Qɵl-bayawandiki sǝpǝr 11 >