< Markus 12 >

1 Andin, u ularƣa tǝmsillǝr bilǝn sɵzlǝxkǝ baxlidi: — Bir kixi bir üzümzarliⱪ bǝrpa ⱪilip, ǝtrapini qitlaptu; u bir xarab kɵlqiki ⱪeziptu wǝ bir kɵzǝt munarini yasaptu. Andin u üzümzarliⱪni baƣwǝnlǝrgǝ ijarigǝ berip, ɵzi yaⱪa yurtⱪa ketiptu.
Lẹ́yìn ìgbà tí Jesu pa àwọn olórí ẹ̀sìn lẹ́nu mọ́, ó bẹ̀rẹ̀ sí í fi òwe bá wọn sọ̀rọ̀ pé, “Ọkùnrin kan gbin ọgbà àjàrà kan. Ó ṣe ọgbà yìí ká, ó sì wá ibi ìfúntí wáìnì, ó sì kọ́ ilé ìṣọ́ sí i ó sì fi ṣe àgbàtọ́jú fún àwọn olùṣọ́gbà, ó sì lọ sí ìrìnàjò tí ó jìnnà.
2 Üzüm pǝsli kǝlgǝndǝ, baƣwǝnlǝrdin üzümzarliⱪtiki mewilǝrdin [tegixlikini] ǝkelix üqün bir ⱪulini ularning yeniƣa ǝwǝtiptu.
Lákokò ìkórè, ọkùnrin náà rán ọ̀kan nínú àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀ sí àwọn olùṣọ́gbà náà, kí ó gbà nínú èso ọgbà àjàrà náà lọ́wọ́ àwọn olùṣọ́gbà.
3 Lekin ular uni tutuwelip dumbalap, ⱪuruⱪ ⱪol ⱪayturuptu.
Ṣùgbọ́n àwọn àgbẹ̀ wọ̀n-ọn-nì lu ìránṣẹ́ ọkùnrin náà, wọ́n sì rán an padà lọ́wọ́ òfo.
4 Hojayin yǝnǝ bir ⱪulni ularning yeniƣa ǝwǝtiptu. Uni bolsa ular qalma-kesǝk ⱪilip, bax-kɵzini yerip, ⱨaⱪarǝtlǝp ⱪayturuptu.
Ó sì tún rán ọmọ ọ̀dọ̀ mìíràn sí wọn. Bí àwọn àgbẹ̀ ti tún rí ọmọ ọ̀dọ̀ tí ó rán sí wọn; wọ́n lù ú. Àní, wọ́n tilẹ̀ dá ọgbẹ́ sí i lórí, wọn rán an lọ ni ìtìjú.
5 Hojayin yǝnǝ birsini ǝwǝtiptu. Lekin uni ular ɵltürüptu. U yǝnǝ tola ⱪullarni ǝwǝtiptu, lekin ular bǝzilirini dumbalap, bǝzilirini ɵltürüptu.
Ó sì tún rán òmíràn, èyí n nì wọ́n sì pa, àti ọ̀pọ̀ mìíràn, wọ́n lu òmíràn wọ́n sì pa òmíràn.
6 Hojayinning yenida pǝⱪǝt uning sɵyümlük bir oƣlila ⱪalƣaqⱪa, ular oƣlumniƣu ⱨɵrmǝt ⱪilar dǝp, u uni ǝng ahiri bolup baƣwǝnlǝrning yeniƣa ǝwǝtiptu.
“Ìránṣẹ́ kan ṣoṣo ló kù tí Baba olóko kò ì tí ì rán níṣẹ́, èyí ni ọmọ òun tìkára rẹ̀. Níkẹyìn ó ran an sí àwọn olùṣọ́gbà náà, pẹ̀lú èrò pé, ‘Wọn yóò bu ọlá fún ọmọ òun.’
7 Lekin xu baƣwǝnlǝr ɵzara: «Bu bolsa mirashor; kelinglar, uni ɵltürüwetǝyli, xuning bilǝn mirasi bizningki bolidu!» deyixiptu.
“Ṣùgbọ́n àwọn olùṣọ́gbà wọ̀n-ọn-nì wí fún ara wọn pé, ‘Èyí yìí ni àrólé. Ẹ wá, ẹ jẹ́ kí a pa á, ogún rẹ̀ yóò sì jẹ́ tiwa.’
8 Xunga ular uni tutup ɵltürüp, üzümzarliⱪning sirtiƣa taxliwetiptu.
Báyìí ni wọ́n mú ọmọ náà tí wọ́n pa á. Wọ́n sì wọ́ òkú rẹ̀ jáde kúrò nínú ọgbà àjàrà náà.
9 Əmdi üzümzarliⱪning hojayini ⱪandaⱪ ⱪilidu? U ɵzi kelip baƣwǝnlǝrni ɵltüridu wǝ üzümzarliⱪni baxⱪilarƣa beridu.
“Kí ni olúwa ọgbà àjàrà yóò ṣe nígbà tí ó bá gbọ́ ohun tí ó ṣẹlẹ̀. Dájúdájú yóò pa àwọn ẹni ibi wọ̀nyí. Yóò sì gba àwọn olùtọ́jú mìíràn sínú oko rẹ̀.
10 Əmdi silǝr muⱪǝddǝs yazmilardin munu ayǝtni oⱪup baⱪmiƣanmusilǝr? — «Tamqilar taxliwǝtkǝn tax bolsa, Burjǝk texi bolup tiklǝndi.
Tàbí ẹ̀yin kò ì tí ka ẹsẹ yìí nínú ìwé mímọ́: “‘Òkúta tí àwọn ọ̀mọ̀lé kọ̀sílẹ̀ òun náà ni ó di pàtàkì igun ilé.
11 Bu ix Pǝrwǝrdigardindur, Kɵzimiz aldida karamǝt bir ixtur»
Èyí ni iṣẹ́ Olúwa ó sì jẹ́ ìyàlẹ́nu lójú tiwa’?”
12 Ular uning bu tǝmsilni ɵzlirigǝ ⱪaritip eytⱪanliⱪini qüxǝndi; xunga ular uni tutux yolini izdǝxti; ⱨalbuki, halayiⱪtin ⱪorⱪuxup, uni taxlap ketip ⱪaldi.
Àwọn olórí àlùfáà àti àwọn olùkọ́ òfin pẹ̀lú àwọn àgbàgbà fẹ́ mú Jesu lákokò náà. Nítorí tí wọ́n mọ̀ pé àwọn ló ń pòwe mọ́ nínú ọ̀rọ̀ rẹ̀. Àwọn ni alágbàtọ́jú búburú nínú ìtàn rẹ̀. Ṣùgbọ́n ẹ̀rù ń bà wọ́n láti fọwọ́ kàn án nítorí pé wọ́n bẹ̀rù ìhùwàsí ọ̀pọ̀ ènìyàn tó wà lọ́dọ̀ rẹ̀. Nítorí náà wọ́n fi í sílẹ̀ lọ.
13 Xuningdin keyin, ular birnǝqqǝ Pǝrisiy wǝ Ⱨerodning tǝrǝpdarlirini uni ɵz sɵzi bilǝn ⱪiltaⱪⱪa qüxürüx mǝⱪsitidǝ uning aldiƣa ǝwǝtti.
Ṣùgbọ́n wọ́n rán àwọn Farisi pẹ̀lú àwọn kan tí í ṣe ọmọ-ẹ̀yìn Herodu wá sọ́dọ̀ Jesu, láti fi ọ̀rọ̀ wá a lẹ́nu wò, títí yóò fi sọ ohun kan kí wọn lè rí fi mú.
14 Ular kelip uningƣa: — Ustaz, silini sǝmimiy adǝm, adǝmlǝrgǝ ⱪǝt’iy yüz-hatirǝ ⱪilmaydu, ⱨeqkimgǝ yan basmaydu, bǝlki kixilǝrgǝ Hudaning yolini sadiⱪliⱪ bilǝn ɵgitip keliwatidu, dǝp bilimiz. [Siliqǝ], [Rim imperatori] Ⱪǝysǝrgǝ baj-seliⱪ tapxurux Tǝwrat ⱪanuniƣa uyƣunmu-yoⱪ?
Bí wọn ti dé ọ̀dọ̀ rẹ̀, wọ́n wí pé, “Olùkọ́, àwa mọ̀ pé ìwọ máa ń sọ òtítọ́ láìsí ìbẹ̀rù ẹnikẹ́ni. Ṣùgbọ́n òtítọ́ ọ̀rọ̀ Ọlọ́run ni ìwọ máa ń kọ́ni. Nísinsin yìí, sọ fún wa, ó tọ́ tàbí kò tọ́ láti máa san owó orí fún Kesari?”
15 Zadi baj tapxuramduⱪ-tapxurmamduⱪ? — deyixti. Lekin u ularning sahtipǝzlikini bilip ularƣa: — Nemixⱪa meni sinimaⱪqisilǝr? Manga bir «dinar» pulni ǝkelinglar, mǝn kɵrüp baⱪay, — dedi.
Kí àwa kí ó fi fún un, tàbí kí a máa fi fún un? Ṣùgbọ́n Jesu mọ ìwà àgàbàgebè wọn. Ó sì wí pé, “Èéṣe tí ẹ̀yin fi n fi èyí dán mi wo? Ẹ mú owó idẹ kan wá kí n wò ó.”
16 Ular pulni elip kǝldi, u ulardin: — Buning üstidiki sürǝt wǝ nam-isim kimning? — dǝp soridi. — Ⱪǝysǝrning, — deyixti ular.
Nígbà tí wọ́n mú owó idẹ náà fún un, ó bi wọ́n léèrè pé, “Ẹ wò ó! Àwòrán àti orúkọ ta ni ó wà níbẹ̀?” Wọ́n dáhùn pé, “Àwòrán àti orúkọ Kesari ni.”
17 Əysa ularƣa jawabǝn: — [Undaⱪ bolsa], Ⱪǝysǝrning ⱨǝⱪⱪini Ⱪǝysǝrgǝ, Hudaning ⱨǝⱪⱪini Hudaƣa tapxurunglar, — dedi. Xuning bilǝn ular uningƣa intayin ⱨǝyran ⱪelixti.
Nígbà náà ni Jesu wí fún wọn pé, “Bí ó bá rí bẹ́ẹ̀, ẹ fi ohun tí ó bá jẹ́ ti Kesari fún Kesari. Ṣùgbọ́n ẹ fi ohun gbogbo tí í ṣe ti Ọlọ́run fún Ọlọ́run.” Ẹnu sì yà wọ́n gidigidi sí èsì rẹ̀.
18 Andin «Ɵlgǝnlǝr tirilmǝydu» dǝydiƣan Saduⱪiylar uning aldiƣa kelip ⱪistap soal ⱪoydi:
Àwọn Sadusi tún wá sọ́dọ̀ rẹ̀, àwọn wọ̀nyí kò gbàgbọ́ pé àjíǹde ń bẹ. Ìbéèrè wọn ni pé,
19 — Ustaz, Musa [pǝyƣǝmbǝr] Tǝwratta bizgǝ: «Bir kixi ɵlüp ketip, ayali tul ⱪelip, pǝrzǝnt kɵrmigǝn bolsa, uning aka yaki inisi tul ⱪalƣan yǝnggisini ǝmrigǝ elip, ⱪerindixi üqün nǝsil ⱪalduruxi lazim» dǝp yazƣan.
“Olùkọ́, Mose fún wa ní òfin pé, nígbà tí ọkùnrin kan bá kú láìbí ọmọ, arákùnrin rẹ̀ gbọdọ̀ ṣú ìyàwó náà lópó kí wọn sì bímọ ní orúkọ ọkọ tí ó kú náà.
20 Burun yǝttǝ aka-uka bar idi. Qongi ɵylinip pǝrzǝnt ⱪaldurmayla ɵldi.
Ǹjẹ́ àwọn arákùnrin méje kan wà, èyí tí ó dàgbà jùlọ gbéyàwó, ó sì kú ní àìlọ́mọ.
21 Ikkinqi ⱪerindixi yǝnggisini ǝmrigǝ elip, umu pǝrzǝnt kɵrmǝy ɵldi. Üqinqisining ǝⱨwalimu uningkigǝ ohxax boldi.
Arákùnrin rẹ̀ kejì ṣú obìnrin tí ó fi sílẹ̀ lópó, láìpẹ́, òun pẹ̀lú tún kú láìbímọ. Arákùnrin kẹta tó ṣú obìnrin yìí lópó tún kú bákan náà láìbímọ.
22 Xu tǝriⱪidǝ yǝttisi ohxaxla uni elip pǝrzǝnt kɵrmǝy kǝtti. Ahirda, u ayalmu alǝmdin ɵtti.
Àwọn méjèèje sì ṣú u lópó, wọn kò sì fi ọmọ sílẹ̀. Ní ìkẹyìn gbogbo wọn, obìnrin náà kú pẹ̀lú.
23 Əmdi tirilix künidǝ ular tirilgǝndǝ, bu ayal ⱪaysisining ayali bolidu? Qünki yǝttisining ⱨǝmmisi uni hotunluⱪⱪa alƣan-dǝ! — deyixti.
Ǹjẹ́ ní àjíǹde, nígbà tí wọ́n bá jíǹde, aya ta ni yóò ha ṣe nínú wọn? Àwọn méjèèje ni ó sá ni ní aya?”
24 Əysa ularƣa mundaⱪ jawab bǝrdi: — Silǝr nǝ muⱪǝddǝs yazmilarni nǝ Hudaning ⱪudritini bilmigǝnlikinglar sǝwǝbidin muxundaⱪ azƣan ǝmǝsmusilǝr?
Jesu dáhùn ó wí fún wọn pé, “Kì í há ṣe nítorí èyí ni ẹ ṣe ṣìnà, pé ẹ̀yin kò mọ ìwé Mímọ́, tàbí agbára Ọlọ́run.
25 Qünki ɵlümdin tirilgǝndǝ insanlar ɵylǝnmǝydu, ǝrgǝ tǝgmǝydu, bǝlki ǝrxtiki pǝrixtilǝrgǝ ohxax bolidu.
Nítorí pé, nígbà tí àwọn arákùnrin méje yìí àti obìnrin náà bá jí dìde nínú òkú, a kò ní ṣe ìgbéyàwó fún wọn. Wọn yóò dàbí àwọn angẹli tí ń bẹ ní ọ̀run.
26 Əmdi ɵlgǝnlǝrning tirilixi mǝsilisi ⱨǝⱪⱪidǝ [Tǝwratta], yǝni Musaƣa qüxürülgǝn kitabtiki «tikǝnlik» wǝⱪǝsidǝ, Hudaning uningƣa ⱪandaⱪ eytⱪinini, yǝni: «Mǝn Ibraⱨimning Hudasi, Isⱨaⱪning Hudasi wǝ Yaⱪupning Hudasidurmǝn!» deginini oⱪumidinglarmu?
Ṣùgbọ́n nísinsin yìí, nípa bóyá àjíǹde yóò wà. Àbí ẹ̀yin kò ì tí ka ìwé Eksodu, nípa Mose àti pápá tí ń jó? Ọlọ́run sọ fún Mose pé, ‘Èmi ni Ọlọ́run Abrahamu, Ọlọ́run Isaaki àti Ọlọ́run Jakọbu.’
27 U ɵlüklǝrning Hudasi ǝmǝs, bǝlki tiriklǝrning Hudasidur! Xunga silǝr ⱪattiⱪ ezip kǝtkǝnsilǝr!
Òun kì í ṣe Ọlọ́run àwọn òkú bí kò ṣe Ọlọ́run àwọn alààyè: nítorí ẹ̀yin ṣe àṣìṣe gidigidi.”
28 Ularƣa yeⱪin kǝlgǝn, munazirilǝxkǝnlirini angliƣan wǝ Əysaning ularƣa yahxi jawab bǝrgǝnlikini kɵrgǝn bir Tǝwrat ustazi uningdin: — Pütün ǝmrlǝrning iqidǝ ǝng muⱨimi ⱪaysi? — dǝp soridi.
Ọ̀kan nínú àwọn olùkọ́ òfin ti ó dúró níbẹ̀ tí ó sì fetísílẹ̀ dáradára sí àròyé yìí ṣàkíyèsí pé, Jesu ti dáhùn dáradára. Òun pẹ̀lú sì béèrè lọ́wọ́ Jesu pé, “Nínú gbogbo òfin, èwo ló ṣe pàtàkì jùlọ?”
29 Əysa mundaⱪ jawab bǝrdi: — Əng muⱨim ǝmr xuki, «Angliƣin, ǝy Israil! Pǝrwǝrdigar Hudayimiz bolƣan Rǝb birdur.
Jesu dá ọkùnrin yìí lóhùn pé, “Èyí tó ṣe pàtàkì jùlọ nínú àwọn òfin ni èyí tí ó kà báyìí pé, ‘Gbọ́ Israẹli; Olúwa Ọlọ́run wa Olúwa kan ni.
30 Pǝrwǝrdigar Hudayingni pütün ⱪǝlbing, pütün jening, pütün zeⱨning wǝ pütün küqüng bilǝn sɵygin». Mana bu ǝng muⱨim ǝmr.
Kí ìwọ kí ó fi gbogbo àyà rẹ, àti gbogbo ọkàn rẹ, àti gbogbo ẹ̀mí rẹ, àti gbogbo agbára rẹ fẹ́ Olúwa Ọlọ́run rẹ, èyí ní òfin kìn-ín-ní.’
31 Uningƣa ohxaydiƣan ikkinqi ǝmr bolsa: — «Ⱪoxnangni ɵzüngni sɵygǝndǝk sɵy». Heqⱪandaⱪ ǝmr bulardin üstün turmaydu.
Èkejì ni pé: ‘Fẹ́ ọmọnìkejì rẹ.’ Kò sí òfin mìíràn tó ga ju méjèèjì yìí lọ.”
32 Tǝwrat ustazi uningƣa: — Toƣra eyttingiz, ustaz, ⱨǝⱪiⱪǝt boyiqǝ sɵzlidingiz; qünki U birdur, Uningdin baxⱪisi yoⱪtur;
Olùkọ́ òfin náà dáhùn pé, “Olùkọ́, ìwọ sọ òtítọ́ nípa pé Ọlọ́run kan ni ó ń bẹ, àti pé kò sí òmíràn àfi òun nìkan.
33 insanning Uni pütün ⱪǝlbi, pütün ǝⱪli, pütün jeni wǝ pütün küqi bilǝn sɵyüxi ⱨǝm ⱪoxnisinimu ɵzini sɵygǝndǝk sɵyüxi barliⱪ kɵydürmǝ ⱪurbanliⱪlar ⱨǝm baxⱪa ⱪurbanliⱪ-ⱨǝdiyǝlǝrdinmu artuⱪtur.
Àti kí a fi gbogbo àyà, àti gbogbo òye, àti gbogbo ọkàn àti gbogbo agbára fẹ́ ẹ, àti fẹ́ ọmọnìkejì ẹni bí ara ẹni, ó ju gbogbo ẹbọ sísun, àti ẹbọ lọ.”
34 Əysa uning aⱪilanilik bilǝn jawab bǝrginini kɵrüp: — Sǝn Hudaning padixaⱨliⱪidin yiraⱪ ǝmǝssǝn, — dedi. Xuningdin keyin, ⱨeqkim uningdin soal soraxⱪa petinalmidi.
Jesu rí i dájú pé òye ọkùnrin yìí ga, nítorí náà, Jesu sọ fún un pé, “Arákùnrin, ìwọ kò jìnà sí à ti dé ìjọba Ọ̀run.” Láti ìgbà náà lọ, ẹnikẹ́ni kò tún béèrè ohun kan lọ́wọ́ Jesu.
35 Ibadǝthana ⱨoylilirida tǝlim bǝrgǝndǝ, Əysa bularƣa jawabǝn mundaⱪ soalni otturiƣa ⱪoydi: Tǝwrat ustazlirining Mǝsiⱨni «Dawutning oƣli» deginini ⱪandaⱪ qüxinisilǝr?
Lẹ́yìn náà, nígbà tí Jesu ń kọ́ àwọn ènìyàn nínú tẹmpili, ó béèrè lọ́wọ́ wọn pé, “Èéṣe tí àwọn olùkọ́ òfin fi gbà wí pé Kristi náà ní láti jẹ́ ọmọ Dafidi?
36 Qünki Dawut ɵzi Muⱪǝddǝs Roⱨta mundaⱪ degǝnƣu: — «Pǝrwǝrdigar mening Rǝbbimgǝ eyttiki: — «Mǝn sening düxmǝnliringni tǝhtipǝring ⱪilƣuqǝ, Mening ong yenimda olturƣin!».
Nítorí tí Dafidi tìkára rẹ̀, ti ń ti ipa Ẹ̀mí Mímọ́ sọ̀rọ̀ wí pé: “‘Olúwa sọ fún Olúwa mi pé: “Jókòó ní ọwọ́ ọ̀tún mi, títí èmi yóò fi sọ àwọn ọ̀tá rẹ di àpótí ìtìsẹ̀ rẹ.”’
37 Dawut [Mǝsiⱨni] xundaⱪ «Rǝbbim» dǝp atiƣan tursa, ǝmdi [Mǝsiⱨ] ⱪandaⱪmu [Dawutning] oƣli bolidu? U yǝrdiki top-top hǝlⱪ uning sɵzini hursǝnlik bilǝn anglaytti.
Níwọ́n ìgbà tí Dafidi tìkára rẹ̀ pè é ní ‘Olúwa,’ báwo ni ó túnṣe lè jẹ́ ọmọ rẹ̀?” Ọ̀pọ̀ ènìyàn sì fi ayọ̀ gbọ́ ọ̀rọ̀ rẹ̀.
38 U ularƣa tǝlim bǝrginidǝ mundaⱪ dedi: — Tǝwrat ustazliridin ⱨoxyar bolunglar. Ular uzun tonlarni kiyiwalƣan ⱨalda kerilip yürüxkǝ, bazarlarda kixilǝrning ularƣa bolƣan [uzun] salamliriƣa,
Ó sì wí fún wọn nínú ẹ̀kọ́ rẹ̀ pé, “Ẹ ṣọ́ra fun àwọn olùkọ́ òfin tí wọ́n fẹ́ láti máa wọ aṣọ gígùn káàkiri, tí wọ́n sì fẹ́ ìkíni ní ọjà,
39 sinagoglarda aldinⱪi orunlarda, ziyapǝtlǝrdǝ tɵrdǝ olturuxⱪa amraⱪ kelidu.
àti ibùjókòó ọlá nínú Sinagọgu àti ipò ọlá níbi àsè.
40 Ular tul ayallarning barliⱪ ɵy-besatlirini yǝwalidu wǝ kɵz-kɵz ⱪilip yalƣandin uzundin-uzun dualar ⱪilidu. Ularning tartidiƣan jazasi tehimu eƣir bolidu!
Àwọn tí wọ́n jẹ ilé àwọn opó rún, tí wọ́n sì ń gbàdúrà gígùn fún àṣehàn, nítorí èyí, ìjìyà wọn yóò pọ̀ púpọ̀.”
41 U ibadǝthanidiki sǝdiⱪǝ sanduⱪining udulida olturup, uningƣa pullirini taxlawatⱪan halayiⱪⱪa ⱪarap turatti. Nurƣun baylar uningƣa heli kɵp pul taxlaxti.
Jesu jókòó ní òdìkejì kọjú sí àpótí ìṣúra: ó ń wo ìjọ ènìyàn ti ń sọ owó sínú àpótí ìṣúra, ọ̀pọ̀ àwọn ọlọ́rọ̀ sì sọ púpọ̀ sí i.
42 Namrat bir tul ayalmu kelip, tiyinning tɵttin biri ⱪimmitidiki ikki lǝptonni taxlidi.
Ṣùgbọ́n obìnrin opó kan wà, ó sì fi ààbọ̀ owó idẹ méjì síbẹ̀, tí ì ṣe ìdá méjì owó-babà kan sínú rẹ̀.
43 U muhlislirini yeniƣa qaⱪirip, ularƣa mundaⱪ dedi: — Mǝn silǝrgǝ bǝrⱨǝⱪ xuni eytip ⱪoyayki, bu namrat tul ayalning ianǝ sanduⱪiƣa taxliƣini baxⱪilarning ⱨǝmmisining taxliƣanliridin kɵptur.
Jesu pe àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀, ó sọ fún wọn wí pé, “Lóòótọ́ ni mo wí fún yin pé, tálákà opó yìí sọ sínú àpótí ìṣúra ju gbogbo àwọn ìyókù to sọ sínú rẹ lọ.
44 Qünki baxⱪilar ɵzlirining exip taxⱪanliridin sǝdiⱪǝ ⱪildi; lekin bu ayal namrat turupmu, ɵzining bar-yoⱪini — tirikqilik ⱪilidiƣinining ⱨǝmmisini sǝdiⱪǝ ⱪilip taxlidi.
Nítorí pé, àwọn ìyókù mú nínú ọ̀pọ̀ ìní wọ́n, ṣùgbọ́n ní tirẹ̀, nínú àìní rẹ̀, ó sọ gbogbo ohun tí ó ní náà sílẹ̀ àní gbogbo ìní rẹ̀.”

< Markus 12 >